< Ezekiel 18 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
І було́ мені слово Господнє таке:
2 “Kín ni ẹ̀yin rò tí ẹ̀yin fi ń pa òwe nípa Israẹli wí pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà kíkan, eyín àwọn ọmọ sì kan.’
„Що́ це вам, що ви складаєте припові́стку на Ізраїлеву землю, говорячи: „Батьки їли неспіле, а оско́ма в синів на зуба́х!“
3 “Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, ẹ̀yin kí yóò pa òwe yìí mọ́ ni Israẹli.
Як живий Я, — говорить Господь Бог, — не бу́дете вже складати тієї припові́стки в Ізраїлі!
4 Nítorí pé èmi ló ní gbogbo ọkàn, ọkàn baba tèmi bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ọmọ pàápàá jẹ tèmi, ọkàn tó bá ṣẹ̀ ní yóò kú.
Тож усі душі Мої: як душа ба́тькова, так і душа синова — Мої вони! Душа, що грішить, — вона помре.
5 “Bí ọkùnrin olódodo kan bá wà, tó ń ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ
А чоловік, коли він справедливий, і робить право та справедливість,
6 tí kò bá wọn jẹun lórí òkè gíga, tí kò gbójú rẹ̀ sókè sí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Israẹli, ti kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́ tàbí kí ó sùn ti obìnrin ni àsìkò èérí rẹ̀.
на гора́х жертве́нного не їсть, і очей своїх не зводить до божкі́в Ізраїлевого дому, і жі́нки свого ближнього не занечищує, а до жінки в ча́сі її нечистоти́ не набли́жується,
7 Kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, ó sì sanwó fún onígbèsè rẹ̀ gẹ́gẹ́ bó ṣe ṣe ìlérí fún un, kò fi ipá jalè ṣùgbọ́n ó fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ, tí ó sì fi ẹ̀wù wọ àwọn tí ó wà ní ìhòhò.
і ніко́го не тисне, боржникові заста́ву його конче зверта́є, грабу́нку не чинить, хліб свій дає голодному, а голого покриває одежею,
8 Ẹni tí kò fi fún ni láti gba ẹ̀dá, tàbí kò gba èlé tó pọ̀jù. Ó yọ ọwọ́ rẹ̀ kúrò nínú ìwà ẹ̀ṣẹ̀, ó sì ń ṣe ìdájọ́ òtítọ́ láàrín ọkùnrin kan àti èkejì rẹ̀.
на ли́хву не дає, а відсотків не бере, від кривди відверта́є руку свою, чинить правдивий суд поміж чоловіком та чоловіком,
9 Tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ mi, tí ó sì ń pa òfin mi mọ́ lóòtítọ́ àti lódodo. Ó jẹ́ olódodo, yóò yè nítòótọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.
уста́вами Моїми ходить, а прав Моїх дотримує, щоб чинити правду, — справедливий такий конче буде жити, говорить Господь Бог!
10 “Bí ó bá bi ọmọkùnrin, oníwà ipá, tó ń jalè, tó tún ń pànìyàn, tó sì ń ṣe gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí sí arákùnrin rẹ̀
А як поро́дить він сина наси́льника, що кров проливає, і робить хоч тільки одне з того,
11 (tí kò sì ṣe ọ̀kan nínú gbogbo iṣẹ́ wọ̀n-ọn-nì): “Ó ń jẹun lójúbọ lórí òkè gíga, tí ó sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́.
чого він усього того не робив, а також на гора́х жертве́нне їв, і жінку свого ближнього занечи́щував,
12 Ó ni àwọn tálákà àti aláìní lára, ó ń fipá jalè, kì í dá padà gẹ́gẹ́ bí ìlérí, o gbójú sókè sí òrìṣà, ó sì ń ṣe ohun ìríra.
убогого й бідаря́ утискав, грабу́нки чинив, застави боржнико́ві не зверта́в, і до божкі́в зво́див свої очі, гидо́ту робив,
13 Ó ń fi owó ya ni pẹ̀lú èlé, ó sì tún ń gba èlé tó pọ̀jù. Ǹjẹ́ irú ọkùnrin yìí wa le è yè bí? Òun kì yóò wá láààyè! Nítorí pé òun ti ṣe àwọn ohun ìríra yìí, kíkú ni yóò kú, ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wá lórí rẹ̀.
на ли́хву давав, і відсо́ток брав, — то чи буде він жити? Не буде він жити! Він усі ті гидо́ти чинив, — він мусить конче померти, кров його буде на ньо́му!
14 “Bí ọkùnrin yìí bá bímọ ọkùnrin, tó sì rí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti baba rẹ ń ṣẹ̀ yìí, tó sì bẹ̀rù, ti kò ṣe irú rẹ̀:
А ось породив він сина, і той побачив усі гріхи свого батька, які той робив, і хоч бачив, та не робив, як той:
15 “Tí kò jẹun lójúbọ lórí òkè gíga tàbí kò gbójú sókè sí àwọn òrìṣà ilé Israẹli, tí kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́
на гора́х жертве́нного не їв, і очей своїх до божкі́в Ізраїлевого дому не зво́див, жінки свого ближнього не занечи́щував,
16 tí kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, tí kò dá ohun ògo dúró tí kò gba èlé tàbí kò fipá jalè ṣùgbọ́n tí ó ń fún ẹni tébi ń pa lóúnjẹ, tó sì fi aṣọ bo àwọn oníhòhò.
і ніко́го не утискав, заста́ви у за́став не брав, і грабунку не чинив, хліб свій голодному давав, а голого одежею покривав,
17 Ó ń yọ ọwọ́ rẹ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀, kò sì gba èlé tàbí èlé tó pọ̀jù, tí ó ń pa òfin mi mọ́, tí ó sì ń tẹ̀lé àwọn àṣẹ mi. Kò ní kú fún ẹ̀ṣẹ̀ baba rẹ̀, nítòótọ́ ní yóò yè!
від кривди свою руку відверта́в, ли́хви та відсо́тків не брав, права́ Мої чинив, уста́вами Моїми ходив, — такий не помре за провину свого батька, — він конче буде жити!
18 Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀, nítorí pé ó jẹ́ arẹ́nijẹ, ó jalè arákùnrin rẹ, ó ṣe ohun tí kò dára láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Батько ж його, за те, що у́тиском тиснув, грабу́нком грабував брата, і що недобре чинив серед наро́ду свого, то ось він помре за провину свою!
19 “Síbẹ̀, ẹ tún ń béèrè pé, ‘Kí ló dé ti ọmọ kò fi ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀?’ Níwọ́n ìgbà tí ọmọ ti ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ, tó sì ti kíyèsi ara láti pa gbogbo àṣẹ mi mọ́, nítòótọ́ ni pé yóò yè.
А скажете ви: „Чому́ той син не поніс провину за батька?“Але ж син той чинив право та справедливість, дотримував усі устави Мої й виконував їх, — він конче буде жити!
20 Ọkàn tí ó bá ṣẹ̀ ní yóò kú. Ọmọ kò ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni baba náà kò ní ru ẹ̀bi ọmọ rẹ̀. Ìwà rere ènìyàn rere yóò wà lórí rẹ̀, ìwà búburú ti ènìyàn búburú náà la ó kà sí i lọ́rùn.
Та душа, що грішить, вона помре. Син не понесе кари за ба́тькову провину, а ба́тько не понесе за провину си́нову, — справедливість справедливого буде на ньому, а несправедливість несправедливого на тому буде.
21 “Ṣùgbọ́n bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tó ti dá, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa àṣẹ mi mọ́, tó sì ń ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, nítòótọ́ ni yóò yè, kò sì ní kú.
А коли б несправедливий відвернувся від усіх гріхів своїх, яких нароби́в, і вико́нував усі устави Мої, і робив право та справедли́вість, — буде конче він жити, не помре!
22 A kò sì ní rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tó ti dá tẹ́lẹ̀ láti kà á sí lọ́rùn nítorí tí ìwà òdodo rẹ tó fihàn, yóò yè.
Усі його гріхи́, які наробив він, не згадаються йому, — він буде жити в своїй справедливості, яку чинив!
23 Ǹjẹ́ èmi ha ni inú dídùn si ikú ènìyàn búburú bí í? Ní Olúwa Olódùmarè wí pé, dípò èyí inú mi kò ha ni i dùn nígbà tó ba yípadà kúrò ni àwọn ọ̀nà búburú rẹ̀ kí ó sì yè?
Чи Я маю вподо́бання в смерті несправедливого? — говорить Господь Бог, — чи ж не в тому, щоб він повернувся з доріг своїх та й жив?
24 “Ṣùgbọ́n bí ènìyàn rere bá yípadà kúrò ni ọ̀nà òdodo rẹ̀ tó sì ń dẹ́ṣẹ̀, tí ó sì tún ń ṣe àwọn ohun ìríra tí ènìyàn búburú ń ṣe, yóò wa yè bí? A kì yóò rántí ọ̀kankan nínú ìwà rere rẹ̀ mọ́, nítorí ó ti jẹ̀bi ìwà àrékérekè àti ẹ̀ṣẹ̀ tó dá, yóò sì kú.
А коли б справедливий відвернувся від своєї справедливости й став робити кривду, — усі ті гидо́ти, які робить несправедливий, то чи такий буде жити? Усі справедливості його, які він робив, не згадаються, — за своє спроневі́рення, що він спроневі́рив, і за гріх свій, що згрішив, за них він помре!
25 “Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin tún wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ ilé Israẹli. Ọ̀nà mi ni kò ha gún? Kì í wa ṣé pé ọ̀nà tiyín gan an ni kò gún?
А ви кажете: „Непра́ва Господня дорога!“Послухайте но, доме Ізраїлів, чи ж дорога Моя неправа? Чи не ваші дороги неправі?
26 Bí olódodo ba yípadà kúrò nínú olódodo rẹ̀, tó sì dẹ́ṣẹ̀, yóò ku fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá.
Коли б справедливий відверну́вся від своєї справедливости й чинив кривду, і за те помер, то він помре за кривду свою, яку він чинив.
27 Ṣùgbọ́n bi ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú tó ti ṣe, tó sì ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, yóò gba ẹ̀mí rẹ̀ là.
А коли б несправедливий відвернувся від своєї несправедливости, яку він чинив, і чинив би право та справедливість, він душу свою при житті збереже́.
28 Nítorí pé ó ronú lórí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá, ó sì yípadà kúrò nínú wọn, nítòótọ́ ni yóò yè; kì yóò sí kú.
І коли б він побачив, і відвернувся від усіх своїх гріхів, які він чинив, то конче буде він жити, не помре!
29 Síbẹ̀, ilé Israẹli wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Ọ̀nà mi kò ha tọ́ bí ilé Israẹli? Kì í wa ṣe pè ọ̀nà tiyín gan an ni ko gún?
А Ізраїлів дім каже: „Непра́ва Господня дорога!“Чи ж Мої дороги неправі, доме Ізраїлів? Чи ж то не ваші дороги неправі?
30 “Nítorí náà, ilé Israẹli, èmi yóò da yín lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ẹnìkọ̀ọ̀kan yín bá ṣe rí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ẹ yípadà! Kí ẹ si yí kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni ìrékọjá kì yóò jẹ́ ọ̀nà ìṣubú yín.
Тому́ буду судити вас, доме Ізраїлів, кожного за дорогами його, говорить Господь Бог. Покайтеся, і відверні́ться від усіх ваших гріхів, і не буде вам провина на спотика́ння!
31 Ẹ kọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti ẹ ti dá sílẹ̀, kí ẹ sì gba ọkàn àti ẹ̀mí tuntun. Nítorí kí ló fi máa kú, ilé Israẹli?
Поскида́йте з себе всі ваші гріхи, якими ви грішили, і створіть собі нове́ серце та ново́го духа! І на́що маєте померти, Ізраїлів доме?
32 Nítorí pé inú mi kò dùn sí ikú ẹnikẹ́ni ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí náà, ẹ yípadà kí ẹ sì yè!
Бо не жадаю Я смерти помира́ючого, говорить Господь Бог, але покайтеся та й живіть!

< Ezekiel 18 >