< Ezekiel 16 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
و کلام خداوند بر من نازل شده، گفت:۱
2 “Ọmọ ènìyàn, mú kí Jerusalẹmu mọ gbogbo ìwà ìríra rẹ̀.
«ای پسر انسان اورشلیم را ازرجاساتش آگاه ساز!۲
3 Sọ pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Jerusalẹmu, ìran rẹ àti ilẹ̀ ìbí rẹ wà ní ilẹ̀ Kenaani; ará Amori ni baba rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ ará Hiti.
و بگو خداوند یهوه به اورشلیم چنین می‌فرماید: اصل و ولادت تو اززمین کنعان است. پدرت اموری و مادرت حتی بود.۳
4 Ní ọjọ́ tí a bí ọ, a kò gé okùn ìwọ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fi omi wẹ̀ ọ́ láti mú kí o mọ́, a kò fi iyọ̀ pa ọ́ lára rárá, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi aṣọ wé ọ.
و اما ولادت تو. در روزی که متولد شدی نافت را نبریدند و تو را به آب غسل ندادند و طاهرنساختند و نمک نمالیدند و به قنداقه نپیچیدند.۴
5 Kò sí ẹni tó ṣàánú tàbí kẹ́dùn rẹ dé bi à ti ṣe nǹkan kan nínú ìwọ̀nyí fún ọ, ṣùgbọ́n lọ́jọ́ ìbí rẹ, ìta la jù ọ́ sí torí wọ́n kórìíra rẹ.
چشمی بر تو شفقت ننمود و بر تو مرحمت نفرمود تا یکی از اینکارها را برای تو بعمل آورد. بلکه در روز ولادتت جان تو را خوار شمرده، تورا بر روی صحرا انداختند.۵
6 “‘Nígbà tí mo sì kọjá tí mo rí ọ tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ, mo sọ fún ọ pé, “Yè!” Nítòótọ́, nígbà tí ìwọ wà nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ pé, “Yè.”
و من از نزد تو گذرنمودم و تو را در خونت غلطان دیدم. پس تو راگفتم: ای که به خونت آلوده هستی زنده شو! بلی گفتم: ای که به خونت آلوده هستی، زنده شو!۶
7 Mo mú ọ dàgbà bí ohun ọ̀gbìn inú oko. O ga sókè, o sì dàgbà, o wá di arẹwà jùlọ, ọmú rẹ yọ, irun rẹ gùn, ìwọ tí o wà ní ìhòhò láìfi nǹkan kan bora.
وتو را مثل نباتات صحرا بسیار افزودم تا نمو کرده، بزرگ شدی و به زیبایی کامل رسیدی. پستانهایت برخاسته و مویهایت بلند شد، لیکن برهنه و عریان بودی.۷
8 “‘Nígbà tí mo tún kọjá, tí mo rí ọ, mo rí i pé àsìkò àti nífẹ̀ẹ́ rẹ ti tó, mo fi ìṣẹ́tí aṣọ mi bo ìhòhò rẹ. Mo búra fún ọ, èmi sì bá ọ dá májẹ̀mú ìwọ sì di tèmi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
«و چون از تو گذر کردم برتو نگریستم واینک زمان تو زمان محبت بود. پس دامن خود رابر تو پهن کرده، عریانی تو را مستور ساختم و خداوند یهوه می‌گوید که با تو قسم خوردم و با توعهد بستم و از آن من شدی.۸
9 “‘Nígbà náà ni mo fi omi wẹ ẹ̀jẹ̀ kúrò ní ara rẹ, mo fi ìpara pa ọ́ lára.
و تو را به آب غسل داده، تو را از خونت طاهر ساختم و تو را به روغن تدهین کردم.۹
10 Mo fi aṣọ oníṣẹ́-ọnà sí ọ lára láti wọ̀ ọ́, mo wọ bàtà aláwọ fún ọ. Mo fi aṣọ funfun gbòò àti aṣọ olówó iyebíye ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́.
و تو را به لباس قلابدوزی ملبس ساختم و نعلین پوست خز به پایت کردم و تو را به کتان نازک آراسته و به ابریشم پیراسته ساختم.۱۰
11 Mo fi ohun ọ̀ṣọ́ ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́, mo fi ẹ̀gbà ọwọ́ sí ọ ní ọwọ́, mo fi ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn sí ọ ní ọrùn,
و تو را به زیورها زینت داده، دستبندها بردستت و گردن بندی بر گردنت نهادم.۱۱
12 mo sì tún fi òrùka sí ọ ní imú, mo fi yẹtí sí ọ ní etí, mo sì fi adé tó rẹwà dé ọ ní orí.
وحلقه‌ای در بینی و گوشواره‌ها در گوشهایت و تاج جمالی بر سرت نهادم.۱۲
13 Báyìí ni mo ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà; tí aṣọ rẹ jẹ́ funfun gbòò, aṣọ olówó iyebíye àti aṣọ tí a ṣiṣẹ́ ọnà sí. Ìyẹ̀fun kíkúnná, oyin àti òróró ni oúnjẹ rẹ. Ó di arẹwà títí ó fi dé ipò ayaba.
پس با طلا و نقره آرایش یافتی و لباست از کتان نازک و ابریشم قلابدوزی بود و آرد میده و عسل و روغن خوردی و بی‌نهایت جمیل شده، به درجه ملوکانه ممتاز گشتی.۱۳
14 Òkìkí rẹ sì kàn káàkiri orílẹ̀-èdè nítorí ẹwà rẹ, nítorí dídán tí mo fi ṣe ẹwà rẹ ní àṣepé, ni Olúwa Olódùmarè wí.
و آوازه تو به‌سبب زیباییت درمیان امت‌ها شایع شد. زیرا خداوند یهوه می‌گویدکه آن زیبایی از جمال من که بر تو نهاده بودم کامل شد.۱۴
15 “‘Ṣùgbọ́n, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ẹwà rẹ, ìwọ sì di alágbèrè nítorí òkìkí rẹ. Ìwọ sì fọ́n ojúrere rẹ káàkiri sí orí ẹni yówù tó ń kọjá lọ, ẹwà rẹ sì di tìrẹ.
«اما بر زیبایی خود توکل نمودی و به‌سبب آوازه خویش زناکار گردیدی و زنای خویش را برهر رهگذری ریختی و از آن او شد.۱۵
16 Ìwọ mú lára àwọn aṣọ rẹ, láti rán aṣọ aláràbarà fún ibi gíga òrìṣà tí ìwọ ti ń ṣe àgbèrè. Èyí kò yẹ kí ó rí bẹ́ẹ̀, tàbí kó tilẹ̀ ṣẹlẹ̀ rárá.
و ازلباسهای خود گرفتی و مکان های بلند رنگارنگ برای خود ساخته، بر آنها زنا نمودی که مثل اینکارها واقع نشده و نخواهد شد.۱۶
17 Ìwọ tún mú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ dáradára tí mo fi wúrà àti fàdákà ṣe fún ọ láti fi yá ère ọkùnrin tí ó ń bá ọ ṣe àgbèrè papọ̀.
و زیورهای زینت خود را از طلا و نقره (من که به تو داده بودم )گرفته، تمثالهای مردان را ساخته با آنها زنانمودی.۱۷
18 Ìwọ sì wọ aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ rẹ fún wọn, o sì tún gbé òróró àti tùràrí mi sílẹ̀ níwájú wọn.
و لباس قلابدوزی خود را گرفته، به آنها پوشانیدی و روغن و بخور مرا پیش آنهاگذاشتی.۱۸
19 Ìwọ tún gbé oúnjẹ tí mo fún ọ—ìyẹ̀fun dáradára, òróró àti oyin—fún wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun olóòórùn dídùn; ohun tó ṣẹlẹ̀ nìyìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.
و نان مرا که به تو داده بودم و آردمیده و روغن و عسل را که رزق تو ساخته بودم، پیش آنها برای هدیه خوشبویی نهادی و چنین شد. قول خداوند یهوه این است.۱۹
20 “‘Àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin tí o bí fún mi lo ti fi rú ẹbọ bí oúnjẹ fún àwọn òrìṣà. Ṣé ìwà àgbèrè rẹ kò ha tó bí?
و پسران ودخترانت را که برای من زاییده بودی گرفته، ایشان را به جهت خوراک آنها ذبح نمودی. آیا زنا کاری تو کم بود۲۰
21 Tí ìwọ ti pa àwọn ọmọ mí, ìwọ sì fà wọ́n fún ère gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun.
که پسران مرا نیز کشتی و ایشان راتسلیم نمودی که برای آنها از آتش گذرانیده شوند؟۲۱
22 Nínú gbogbo iṣẹ́ ìríra àti ìwà àgbèrè rẹ, ìwọ kò rántí ìgbà èwe rẹ, nígbà tí ìwọ wà ní ìhòhò, tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀.’
و در تمامی رجاسات و زنای خود ایام جوانی خود را حینی که عریان و برهنه بودی و درخون خود می‌غلطیدی بیاد نیاوردی.»۲۲
23 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Ègbé! Ègbé ni fún ọ. Lẹ́yìn gbogbo ìwà búburú rẹ,
و خداوند یهوه می‌گوید: «وای بر تو! وای بر تو! زیرا بعد از تمامی شرارت خود،۲۳
24 ìwọ kọ́lé amọ̀ fún ara rẹ, ìwọ sì kọ́ ojúbọ gíga sí gbogbo òpin ojú pópó.
خراباتها برای خود بنا نمودی و عمارات بلنددر هر کوچه برای خود ساختی.۲۴
25 Ní gbogbo ìkóríta ni ìwọ lọ kọ ojúbọ gíga sí, tí ìwọ sọ ẹwà rẹ di ìkórìíra, ìwọ sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ nípa fífi ara rẹ sílẹ̀ fún gbogbo ẹni tó ń kọjá lọ.
بسر هر راه عمارتهای بلند خود را بنا نموده، زیبایی خود رامکروه ساختی و برای هر راهگذری پایهای خویش را گشوده، زناکاریهای خود را افزودی.۲۵
26 Ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ará Ejibiti tí í ṣe aládùúgbò rẹ láti mú mi bínú ìwọ sì ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀.
و با همسایگان خود پسران مصر که بزرگ گوشت می‌باشند، زنا نمودی و زناکاری خود راافزوده، خشم مرا بهیجان آوردی.۲۶
27 Nítorí náà ni mo fi na ọwọ́ mi lé ọ lórí, mo sì ti bu oúnjẹ rẹ̀ kù; èmi yóò sì mú ìfẹ́ àwọn to kórìíra rẹ ṣẹ́ lé ọ lórí, àwọn ọmọbìnrin Filistini ti ìwàkiwà rẹ tì lójú.
لهذا اینک من دست خود را بر تو دراز کرده، وظیفه تو را قطع نمودم و تو را به آرزوی دشمنانت یعنی دختران فلسطینیان که از رفتار قبیح تو خجل بودند، تسلیم نمودم.۲۷
28 Nítorí àìnítẹ́lọ́rùn rẹ, ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara Asiria; ìwọ ti bá wọn ṣe àgbèrè, síbẹ̀síbẹ̀, kò sì lè tẹ́ ọ lọ́rùn.
و چونکه سیر نشدی با بنی آشور نیز زنا نمودی و با ایشان نیز زنا نموده، سیرنگشتی.۲۸
29 Ìwọ si ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ láti ilẹ̀ Kenaani dé ilẹ̀ Kaldea; síbẹ̀ èyí kò sì tẹ́ ọ lọ́rùn níhìn-ín yìí.’
و زناکاریهای خود را از زمین کنعان تازمین کلدانیان زیاد نمودی و از این هم سیرنشدی.»۲۹
30 “Olúwa Olódùmarè wí pé, ‘Báwo ni ọkàn rẹ ṣe jẹ aláìlera tó tí o ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí, bí iṣẹ́ àwọn agídí alágbèrè!
خداوند یهوه می‌گوید: «دل تو چه قدرضعیف است که تمامی این اعمال را که کار زن زانیه سلیطه می‌باشد، بعمل آوردی.۳۰
31 Ni ti pé ìwọ kọ́ ilé gíga rẹ ni gbogbo ìkóríta, tí ìwọ sì ṣe gbogbo ibi gíga rẹ ni gbogbo ìta, ìwọ kò sì wa dàbí panṣágà obìnrin, ní ti pé ìwọ gan ọ̀yà.
که بسرهر راه خرابات خود را بنا نمودی و در هر کوچه عمارات بلند خود را ساختی و مثل فاحشه های دیگر نبودی چونکه اجرت را خوار شمردی.۳۱
32 “‘Ìwọ alágbèrè aya! Ìwọ fẹ́ràn ọkùnrin àjèjì ju ọkọ rẹ lọ!
‌ای زن زانیه که غریبان را به‌جای شوهر خودمی گیری!۳۲
33 Àwọn ọkùnrin máa ń sanwó fún àwọn panṣágà ni ṣùgbọ́n ìwọ lo tún ń sanwó fun wọn, tí ó tún ń fún àwọn olólùfẹ́ rẹ lẹ́bùn àti owó ẹ̀yìn kí wọn bá à le máa wá ọ wá láti gbogbo agbègbè fún àgbèrè ṣíṣe.
به جمیع فاحشه‌ها اجرت می‌دهند.۳۳
34 Nínú àgbèrè rẹ ìwọ yàtọ̀ sí àwọn alágbèrè obìnrin yòókù; nínú àgbèrè rẹ tí ẹnìkan kò tẹ̀lé ọ láti ṣe àgbèrè; àti ní ti pé ìwọ ń tọrẹ tí a kò sì tọrẹ fún ọ, nítorí náà ìwọ yàtọ̀.
و عادت تو درزناکاریت برعکس سایر زنان است. چونکه کسی به جهت زناکاری از عقب تو نمی آید و تو اجرت می‌دهی و کسی به تو اجرت نمی دهد. پس عادت تو بر عکس دیگران است.»۳۴
35 “‘Nítorí náà, ìwọ alágbèrè, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
بنابراین‌ای زانیه! کلام خداوند را بشنو!۳۵
36 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, “Nítorí pé ìwọ tú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ jáde, ìwọ sì fi ìhòhò rẹ hàn, nípa ṣíṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn olólùfẹ́ rẹ, àti nítorí gbogbo òrìṣà ìríra tí o fi ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ rẹ ṣe ìrúbọ fún,
خداوند یهوه چنین می‌گوید: «چونکه نقد توریخته شد و عریانی تو از زناکاریت با عاشقانت وبا همه بتهای رجاساتت و از خون پسرانت که به آنها دادی مکشوف گردید،۳۶
37 nítorí náà, Èmi yóò ṣa gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ jọ, àwọn ẹni ti ìwọ ti bá jayé àti gbogbo àwọn tí ìwọ ti fẹ́ àti àwọn tí ìwọ kórìíra. Èmi yóò sa gbogbo wọn káàkiri jọ, láti mú wọn lòdì sí ọ, èmi yóò sí aṣọ rẹ, níwájú wọn, wọn yóò sì rí ìhòhò rẹ.
لهذا هان من جمیع عاشقانت را که به ایشان ملتذ بودی و همه آنانی راکه دوست داشتی، با همه کسانی که از ایشان نفرت داشتی جمع خواهم نمود. و ایشان را از هرطرف نزد تو فراهم آورده، برهنگی تو را به ایشان مکشوف خواهم ساخت، تا تمامی عریانیت راببینند.۳۷
38 Èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí a ti dá obìnrin tó ba ìgbéyàwó jẹ́, tí wọn sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀; Èmi yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ ìbínú àti owú mi wá sórí rẹ.
و بر تو فتوای زنانی را که زنا می‌کنند وخونریز می‌باشند، خواهم داد. و خون غضب وغیرت را بر تو وارد خواهم آورد.۳۸
39 Nígbà náà ni èmi yóò fà ọ lé àwọn olólùfẹ́ rẹ lọ́wọ́, wọn yóò sì wó gbogbo òkìtì rẹ pẹ̀lú àwọn ojúbọ rẹ palẹ̀. Wọn yóò tú aṣọ kúrò lára rẹ̀, gbogbo ọ̀ṣọ́ rẹ ni wọn yóò gbà, wọn yóò sì fi ọ sílẹ̀ ní ìhòhò àti ní àìwọṣọ.
و تو را به‌دست ایشان تسلیم نموده، خراباتهای تو راخراب و عمارات بلند تو را منهدم خواهندساخت. و لباست را از تو خواهند کند و زیورهای قشنگ تو را خواهند گرفت و تو را عریان و برهنه خواهند گذاشت.۳۹
40 Wọn yóò pe àjọ ènìyàn jọ lé ọ lórí, àwọn tí yóò sọ ọ́ ní òkúta, tiwọn yóò sì fi idà wọn gé ọ sí wẹ́wẹ́.
و گروهی بر تو آورده، تو رابه سنگها سنگسار خواهند کرد و به شمشیرهای خود تو را پاره پاره خواهند نمود.۴۰
41 Wọn yóò jo gbogbo ilé rẹ palẹ̀ wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ́ ní ojú àwọn obìnrin. Èmi yóò fi òpin sí àgbèrè ṣíṣe rẹ. Ìwọ kò sì ní san owó fún àwọn olólùfẹ́ rẹ mọ́.
و خانه های تو را به آتش سوزانیده، در نظر زنان بسیار بر توعقوبت خواهند رسانید. پس من تو را از زنا کاری بازخواهم داشت و بار دیگر اجرت نخواهی داد.۴۱
42 Nígbà náà ni ìbínú mi sí o yóò rọ̀, owú ìbínú mi yóò sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ; inú mi yóò rọ̀, èmi kò sì ní bínú mọ́.”
و حدت خشم خود را بر تو فرو خواهم نشانیدو غیرت من از تو خواهد برگشت و آرام گرفته، بار دیگر غضب نخواهم نمود.۴۲
43 “‘Nítorí pé ìwọ kò rántí ọjọ́ èwe rẹ ṣùgbọ́n ìwọ ń rí mi fín pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ó dájú pé, Èmi yóò mú gbogbo ohun tí ìwọ ti ṣe wa sí orí rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí, ìwọ kì yóò sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ yìí ni orí gbogbo ohun ìríra rẹ mọ́?
چونکه ایام جوانی خود را به یاد نیاورده، مرا به همه اینکارهارنجانیدی، از این جهت خداوند یهوه می‌گوید که اینک نیز رفتار تو را بر سرت وارد خواهم آورد وعلاوه بر تمامی رجاساتت دیگر این عمل قبیح رامرتکب نخواهی شد.۴۳
44 “‘Gbogbo àwọn to ń pòwe, ni yóò máa pòwe yìí mọ́ ọ pé: “Bí ìyá ṣe rí, bẹ́ẹ̀ ni ọmọ rẹ̀ obìnrin.”
«اینک هر‌که مثل می‌آورد این مثل را بر توآورده، خواهد گفت که مثل مادر، مثل دخترش می‌باشد.۴۴
45 Ìwọ ni ọmọ ìyá rẹ ti ó kọ ọkọ rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀; ìwọ ni arábìnrin àwọn arábìnrin rẹ tí ó kọ àwọn ọkọ wọn àti àwọn ọmọ wọn: ara Hiti ni ìyá rẹ, ara Amori sì ni baba rẹ.
تو دختر مادر خود هستی که ازشوهر و پسران خود نفرت می‌داشت. و خواهرخواهران خود هستی که از شوهران و پسران خویش نفرت می‌دارند. مادر شما حتی بود و پدرشما اموری.۴۵
46 Ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin ni Samaria, òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ n gbé ni apá àríwá rẹ, àti àbúrò rẹ obìnrin ní ń gbé ọwọ́ òsì rẹ̀, àti àbúrò rẹ obìnrin ti ń gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ obìnrin.
و خواهر بزرگ تو سامره است که با دختران خود بطرف چپ تو ساکن می‌باشد. وخواهر کوچک تو سدوم است که با دختران خودبطرف راست تو ساکن می‌باشد.۴۶
47 Kì í sẹ pé ìwọ rìn ni ọ̀nà wọn nìkan, tàbí ṣe àfiwé ìwà ìríra wọn ṣùgbọ́n ní àárín àkókò kúkúrú díẹ̀, ìwọ bàjẹ́ jù wọ́n lọ
اما تو درطریق های ایشان سلوک نکردی و مثل رجاسات ایشان عمل ننمودی. بلکه گویا این سهل بود که تو در همه رفتار خود از ایشان زیاده فاسد شدی.»۴۷
48 Olúwa Olódùmarè wí pé, “Bí mo ṣe wà láààyè, Sodomu tí í ṣe ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ kò ṣe to ohun tí ìwọ àti ọmọbìnrin rẹ ṣe.”
پس خداوند یهوه می‌گوید: «به حیات خودم قسم که خواهر تو سدوم و دخترانش موافق اعمال تو و دخترانت عمل ننمودند.۴۸
49 “‘Wò ó, ẹ̀ṣẹ̀ tí Sodomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ obìnrin ṣẹ̀ nìyìí. Òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ gbéraga, wọ́n jẹ́ alájẹjù àti aláìbìkítà; wọn kò ran tálákà àti aláìní lọ́wọ́.
اینک گناه خواهرت سدوم این بود که تکبر وفراوانی نان و سعادتمندی رفاهیت برای او ودخترانش بود و فقیران و مسکینان را دستگیری ننمودند.۴۹
50 Nítorí náà, mo mu wọn kúrò níwájú mi lójú mi gẹ́gẹ́ bi ìwọ ti rò ó, nítorí ìgbéraga àti àwọn ohun ìríra tí wọ́n ṣe.
و مغرور شده، در حضور من مرتکب رجاسات گردیدند. لهذا چنانکه صلاح دیدم ایشان را از میان برداشتم.۵۰
51 Samaria kò ṣe ìdajì ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Ìwọ ṣe àwọn ohun ìríra ju tirẹ̀ lọ, ìwọ sì jẹ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo pẹ̀lú gbogbo ìwọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe.
و سامره نصف گناهانت را مرتکب نشد، بلکه تو رجاسات خودرا از آنها زیاده نمودی و خواهران خود را به تمامی رجاسات خویش که بعمل آوردی مبری ساختی.۵۱
52 Gba ìtìjú rẹ, nítorí ìwọ ti jẹ́ kí arábìnrin rẹ gba ìdáláre. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ti burú ju tí wọn lọ, wọn dàbí olódodo ju ìwọ lọ. Nítorí náà rú ìtìjú rẹ, kí o sì gba ẹ̀gàn rẹ pẹ̀lú nítorí ìwọ ti jẹ́ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo.
پس تو نیز که بر خواهران خود حکم دادی خجالت خود را متحمل بشو. زیرا به گناهانت که در آنها بیشتر از ایشان رجاسات نمودی ایشان از تو عادلتر گردیدند. لهذا تو نیزخجل شو و رسوایی خود را متحمل باش چونکه خواهران خود را مبری ساختی.۵۲
53 “‘Bi o tilẹ̀ jẹ pe èmi yóò mú ìgbèkùn wọn padà, ìgbèkùn Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, pẹ̀lú Samaria àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, nígbà náà ni èmi yóò tún mú ìgbèkùn àwọn òǹdè rẹ wá láàrín wọn,
و من اسیری ایشان یعنی اسیری سدوم و دخترانش و اسیری سامره و دخترانش و اسیری اسیران تو را در میان ایشان خواهم برگردانید.۵۳
54 kí ó bá à le rú ìtìjú rẹ, àti ẹ̀gàn gbogbo ohun tí ìwọ ṣe láti tù wọ́n nínú.
تا خجالت خود رامتحمل شده، از هر‌چه کرده‌ای شرمنده شوی چونکه ایشان را تسلی داده‌ای.۵۴
55 Nígbà tí àwọn arábìnrin rẹ, Sodomu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ; Samaria àti àwọn ọmọbìnrin rẹ ba padà si ipò tí wọn wà tẹ́lẹ̀, ìgbà náà ni ìwọ náà yóò padà sí ipò àtijọ́ rẹ.
و خواهرانت یعنی سدوم و دخترانش به حالت نخستین خودخواهند برگشت. و سامره و دخترانش به حالت نخستین خود خواهند برگشت. و تو و دخترانت به حالت نخستین خود خواهید برگشت.۵۵
56 Ìwọ ko tilẹ̀ ní dárúkọ arábìnrin rẹ Sodomu ni ọjọ́ ìgbéraga rẹ,
اماخواهر تو سدوم در روز تکبر تو به زبانت آورده نشد.۵۶
57 kó tó di pé àṣírí ìwà búburú rẹ tú síta, báyìí ìwọ di ẹni ẹ̀gàn lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Edomu, Siria àti gbogbo agbègbè rẹ, àti lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Filistini àti lọ́dọ̀ àwọn tó yí ọ ká, tiwọn si ń kẹ́gàn rẹ.
قبل از آنکه شرارت تو مکشوف بشود. مثل آن زمانی که دختران ارام مذمت می‌کردند وجمیع مجاورانش یعنی دختران فلسطینیان که تورا از هر طرف خوار می‌شمردند.»۵۷
58 Èmi yóò gba ẹ̀san ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti àwọn iṣẹ́ ìríra rẹ ní Olúwa wí.’
پس خداوند می‌فرماید که «تو قباحت ورجاسات خود را متحمل خواهی شد.۵۸
59 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Èmi yóò hùwà sí ọ gẹ́gẹ́ bi ó ṣe tọ́ sí ọ, nítorí ó ti kẹ́gàn ẹ̀jẹ́ nípa dídà májẹ̀mú.
زیراخداوند یهوه چنین می‌گوید: به نهجی که تو عمل نمودی من با تو عمل خواهم نمود، زیرا که قسم را خوار شمرده، عهد را شکستی.۵۹
60 Síbẹ̀ èmi yóò rántí májẹ̀mú tí mo bá ọ ṣe nígbà èwe rẹ, èmi yóò sì bá ọ dá májẹ̀mú láéláé.
لیکن من عهد خود را که در ایام جوانیت با تو بستم به یادخواهم آورد و عهد جاودانی با تو استوار خواهم داشت.۶۰
61 Nígbà náà ni ìwọ yóò rántí àwọn ọ̀nà rẹ ojú yóò sì tì ọ́ nígbà tí mo bá gba àwọn ẹ̀gbọ́n àti àbúrò rẹ obìnrin padà. Fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọmọbìnrin, ṣùgbọ́n kì í ṣe lórí májẹ̀mú tí mo bá ọ dá.
و هنگامی که خواهران بزرگ و کوچک خود را پذیرفته باشی، آنگاه راههای خود را به یاد آورده، خجل خواهی شد. و من ایشان را به‌جای دختران به تو خواهم داد، لیکن نه از عهد تو.۶۱
62 Èmi yóò gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì mọ pé èmi ni Olúwa.
و من عهد خود را با تو استوار خواهم ساخت وخواهی دانست که من یهوه هستم.۶۲
63 Nígbà tí mo bá sì ti ṣe ètùtù fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tan, Èmi yóò sì rántí, ojú yóò tì ọ́, ìwọ kò sì ní le ya ẹnu rẹ mọ́ nítorí ìtìjú rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
تا آنکه به یاد آورده، خجل شوی. و خداوند یهوه می‌فرماید که چون من همه کارهای تو را آمرزیده باشم، بار دیگر به‌سبب رسوایی خویش دهان خود را نخواهی گشود.»۶۳

< Ezekiel 16 >