< Ezekiel 14 >

1 Díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá sọ́dọ̀ mi, wọ́n sì jókòó níwájú mi.
Potem so prišli k meni nekateri izmed Izraelovih starešin in se usedli pred menoj.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
In k meni je prišla Gospodova beseda, rekoč:
3 “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti gbé òrìṣà kalẹ̀ sínú ọkàn wọn, wọ́n sì gbé àwọn ohun tó lè mú wọn ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú wọn; Èmi yóò ha jẹ́ kí wọ́n béèrè lọ́wọ́ mi rárá bí?
»Človeški sin, ti možje so si v srcih postavljali malike in so si pred svoj obraz postavljali kamen spotike svoje krivičnosti; ali naj bi me oni potem sploh spraševali?«
4 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tó gbé òrìṣà sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ síwájú rẹ̀, tí ó sì wá sọ́dọ̀ wòlíì, Èmi Olúwa fúnra mi ni yóò dá ẹni tí ó wa lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà ìbọ̀rìṣà rẹ.
Zato jim govori in jim povej: »Tako govori Gospod Bog: ›Vsak mož iz Izraelove hiše, ki si v svojem srcu postavlja malike in pred svoj obraz polaga kamen spotike svoje krivičnosti in prihaja k preroku; jaz, Gospod, bom odgovoril tistemu, ki prihaja, glede na množico njegovih malikov,
5 Èmi yóò ṣe èyí láti gba ọkàn àwọn ará Israẹli tó ti tẹ̀lé òrìṣà wọn lọ padà sí ọ̀dọ̀ mi.’
da bi Izraelovo hišo lahko ujel v njihovem lastnem srcu, ker so se zaradi svojih malikov vsi odtujili od mene.‹
6 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ẹ ronúpìwàdà! Ẹ yípadà kúrò lọ́dọ̀ òrìṣà yín, kí ẹ̀yin sì kọ gbogbo ìwà ìríra yín sílẹ̀!
Zato reci Izraelovi hiši: ›Tako govori Gospod Bog: ›Pokesajte se in odvrnite se od svojih malikov; odvrnite svoje obraze od vseh svojih ogabnosti.‹
7 “‘Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tàbí àlejò tó ń gbé ní ilẹ̀ Israẹli, bá ya ara rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi, tó gbé òrìṣà rẹ̀ sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun tó mú ni ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú rẹ, lẹ́yìn èyí tó tún lọ sọ́dọ̀ wòlíì láti béèrè nǹkan lọ́wọ́ mi! Èmi Olúwa fúnra ara mi ní èmi yóò dá a lóhùn.
Kajti vsakomur izmed Izraelove hiše, ali izmed tujca, ki začasno biva v Izraelu, ki se ločuje od mene in si v svojem srcu postavlja svoje malike in polaga kamen spotike svoje krivičnosti pred svoj obraz in prihaja k preroku, da bi od njega povprašal glede mene, mu bom jaz, Gospod, sam odgovoril.
8 Èmi yóò lòdì si irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀ lọ́nà òdì, Èmi yóò sì fi i ṣe àmì àti òwe. Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi. Nígbà náà, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Svoj obraz bom naravnal zoper tega moža in naredil ga bom za znamenje in pregovor in odrezal ga bom iz srede svojega ljudstva; in spoznali boste, da jaz sem Gospod.
9 “‘Bí wọ́n bá sì tan wòlíì náà láti sọtẹ́lẹ̀, Èmi Olúwa ló tan wòlíì náà, Èmi yóò nawọ́ sí i, èmi yóò sì pa á run kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi Israẹli.
Če pa je prerok zaveden, ko je govoril besedo, sem jaz, Gospod, zavedel tega preroka in jaz bom iztegnil svojo roko nanj in ga uničim iz srede svojega ljudstva Izraela.
10 Wọn yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wọn—ìjìyà kan náà là ó fún wòlíì àti ẹni tó lọ béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀.
Nosila bosta kazen svoje krivičnosti. Kazen preroka bo celo kakor kazen tistega, ki poizveduje k njemu;
11 Kí ilé Israẹli má ba à ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi mọ, kí wọ́n má ba à fi gbogbo ìrékọjá ba ara wọn jẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n kí wọ́n le jẹ́ ènìyàn mi, kí Èmi náà sì le jẹ́ Ọlọ́run wọn, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
da Izraelova hiša ne bo več zašla od mene niti ne bo več oskrunjena z vsemi svojimi prestopki; temveč da bodo lahko moje ljudstvo in bom jaz lahko njihov Bog, govori Gospod Bog.‹«
12 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Gospodova beseda je prišla ponovno k meni, rekoč:
13 “Ọmọ ènìyàn bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi nípa ìwà àìṣòdodo, èmi yóò nawọ́ mi jáde sí wọn, láti gé ìpèsè oúnjẹ wọn, èmi yóò rán ìyàn sí wọn, èmi yóò sì pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀,
»Človeški sin, kadar dežela greši zoper mene z mučnimi prekršitvami, takrat bom nadnjo iztegnil svojo roko in zlomil bom njeno oporo kruha in nadnjo bom poslal lakoto in iz nje bom iztrebil človeka in žival.
14 bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí. Noa, Daniẹli àti Jobu tilẹ̀ wà nínú rẹ, kìkì ẹ̀mí ara wọn nìkan ni wọ́n lé fi òdodo wọn gbàlà, Olúwa Olódùmarè wí.
Čeprav bi bili v njej ti trije možje: Noe, Daniel in Job, bi s svojo pravičnostjo rešili zgolj svoje lastne duše, ‹ govori Gospod Bog.
15 “Tàbí bí mo bá jẹ́ kí ẹranko búburú gba orílẹ̀-èdè náà kọjá, tí wọn sì bà á jẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ó di ahoro, tí kò sí ẹni tó le gba ibẹ̀ kọjá torí ẹranko búburú yìí,
›Če povzročim ogabnim živalim, da gredo skozi deželo, jo oplenijo tako, da je ta zapuščena, da zaradi živali noben človek ne bo mogel iti skoznjo;
16 bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta wọ̀nyí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, wọn kì yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là: àwọn nìkan ni a ó gbàlà, ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
čeprav bi bili ti trije možje v njej, kakor jaz živim, ‹ govori Gospod Bog, ›ne bodo osvobodili niti sinov niti hčera; samo oni sami bodo osvobojeni, toda dežela bo zapuščena.
17 “Tàbí tí mo bá mú idà kọjá láàrín orílẹ̀-èdè náà tí mo wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí idà kọjá láàrín ilẹ̀ náà,’ tí mo sì tú ìbínú gbígbóná lé wọn lórí nípa ìtàjẹ̀ sílẹ̀, tí mo pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ.
Ali če privedem meč nad to deželo in rečem: ›Meč, pojdi skozi to deželo; ‹ tako, da iz nje iztrebim ljudi in živali;
18 Bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà, wọn ki yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là, ṣùgbọ́n àwọn tìkára wọn nìkan ni a ó gbàlà.
čeprav bi bili ti trije možje v njej, kakor jaz živim, ‹ govori Gospod Bog, ›ne bi osvobodili niti sinov niti hčera; samo oni sami bi bili osvobojeni.
19 “Tàbí bí mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn si ilẹ̀ náà, ti mo si da ìrunú mi lé e lórí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀, láti gé ènìyàn àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀,
Ali če pošljem v to deželo kužno bolezen in če nanjo v krvi izlijem svojo razjarjenost, da iztrebim iz nje človeka in žival;
20 bó tilẹ̀ jẹ́ pé Noa, Daniẹli àti Jobu wà nínú rẹ, bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, wọn kò le gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin wọn lá. Ara wọn nìkan ni ìwà òdodo wọn lè gbàlà.
čeprav bi bili v njej Noe, Daniel in Job, kakor jaz živim, ‹ govori Gospod Bog, ›ne bi osvobodili niti sinov niti hčera, temveč bodo po svoji pravičnosti osvobodili zgolj svoje lastne duše.‹
21 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jerusalẹmu, èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-ààrùn láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!
Kajti tako govori Gospod Bog: ›Koliko bolj, ko pošljem svoje štiri boleče sodbe nad Jeruzalem: meč, lakoto in ogabno zver in kužno bolezen, da iztrebim iz nje ljudi in živali?
22 Síbẹ̀, yóò ṣẹ́kù àwọn díẹ̀, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí a ó kó jáde nínú rẹ̀. Wọn yóò wá bá yin, ẹ̀yin yóò rí ìwà àti ìṣe wọn, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìtùnú nípa àjálù tí mo mú wá sórí Jerusalẹmu—àní gbogbo àjálù ní mo ti mú wá sórí rẹ̀.
In vendar, glejte, bo tam ostal ostanek, ki bo izpeljan, tako sinov kakor hčera. Glejte, prišli bodo k vam in videli boste njihovo pot in njihova dejanja in potolaženi boste glede zla, ki sem ga privedel nad Jeruzalem, celó glede vsega, kar sem privedel nadenj.
23 Nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìwà àti ìṣe wọn, a ó tù yín nínú, nítorí pé ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi kò ṣe nǹkan kan láìnídìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
In potolažili vas bodo, ko boste videli njihove poti in njihova dejanja, in spoznali boste, da nisem brez vzroka storil vsega, kar sem storil v njem, ‹ govori Gospod Bog.‹«

< Ezekiel 14 >