< Ezekiel 14 >

1 Díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá sọ́dọ̀ mi, wọ́n sì jókòó níwájú mi.
و کسانی چند از مشایخ اسرائیل نزد من آمده، پیش رویم نشستند.۱
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
آنگاه کلام خداوند بر من نازل شده، گفت:۲
3 “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti gbé òrìṣà kalẹ̀ sínú ọkàn wọn, wọ́n sì gbé àwọn ohun tó lè mú wọn ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú wọn; Èmi yóò ha jẹ́ kí wọ́n béèrè lọ́wọ́ mi rárá bí?
«ای پسر انسان این اشخاص، بتهای خویش را در دلهای خودجای دادند و سنگ مصادم گناه خویش را پیش روی خود نهادند. پس آیا ایشان از من مسالت نمایند؟۳
4 Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tó gbé òrìṣà sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ síwájú rẹ̀, tí ó sì wá sọ́dọ̀ wòlíì, Èmi Olúwa fúnra mi ni yóò dá ẹni tí ó wa lóhùn gẹ́gẹ́ bí ìwà ìbọ̀rìṣà rẹ.
لهذا ایشان را خطاب کن و به ایشان بگو: خداوند یهوه چنین می‌فرماید: هرکسی ازخاندان اسرائیل که بتهای خویش را در دل خودجای دهد و سنگ مصادم گناه خویش را پیش روی خود بنهد و نزد نبی بیاید، من که یهوه هستم آن را که می‌آید موافق کثرت بتهایش اجابت خواهم نمود۴
5 Èmi yóò ṣe èyí láti gba ọkàn àwọn ará Israẹli tó ti tẹ̀lé òrìṣà wọn lọ padà sí ọ̀dọ̀ mi.’
تا خاندان اسرائیل را در افکارخودشان گرفتار سازم چونکه جمیع ایشان به‌سبب بتهای خویش از من مرتد شده‌اند.۵
6 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ẹ ronúpìwàdà! Ẹ yípadà kúrò lọ́dọ̀ òrìṣà yín, kí ẹ̀yin sì kọ gbogbo ìwà ìríra yín sílẹ̀!
بنابراین به خاندان اسرائیل بگو خداوند یهوه چنین می‌فرماید: توبه کنید و از بتهای خود بازگشت نمایید و رویهای خویش را از همه رجاسات خود برگردانید.۶
7 “‘Bí ẹnikẹ́ni ní ilé Israẹli tàbí àlejò tó ń gbé ní ilẹ̀ Israẹli, bá ya ara rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi, tó gbé òrìṣà rẹ̀ sí ọkàn rẹ̀, tó tún gbé ohun tó mú ni ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀ síwájú rẹ, lẹ́yìn èyí tó tún lọ sọ́dọ̀ wòlíì láti béèrè nǹkan lọ́wọ́ mi! Èmi Olúwa fúnra ara mi ní èmi yóò dá a lóhùn.
زیرا هر کس چه از خاندان اسرائیل و چه از غریبانی که در اسرائیل ساکن باشند که از پیروی من مرتد شده، بتهای خویش را در دلش جای دهد و سنگ مصادم گناه خود راپیش رویش نهاده، نزد نبی آید تا به واسطه او ازمن مسالت نماید، من که یهوه هستم خود او راجواب خواهم داد.۷
8 Èmi yóò lòdì si irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀ lọ́nà òdì, Èmi yóò sì fi i ṣe àmì àti òwe. Èmi yóò sì gé e kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi. Nígbà náà, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
و من نظر خود را بر آن شخص دوخته، او را مورد دهشت خواهم ساخت تا علامتی و ضرب‌المثلی بشود و او را ازمیان قوم خود منقطع خواهم ساخت و خواهیددانست که من یهوه هستم.۸
9 “‘Bí wọ́n bá sì tan wòlíì náà láti sọtẹ́lẹ̀, Èmi Olúwa ló tan wòlíì náà, Èmi yóò nawọ́ sí i, èmi yóò sì pa á run kúrò láàrín àwọn ènìyàn mi Israẹli.
و اگر نبی فریب خورده، سخنی گوید، من که یهوه هستم آن نبی رافریب داده‌ام و دست خود را بر او دراز کرده، او رااز میان قوم خود اسرائیل منقطع خواهم ساخت.۹
10 Wọn yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wọn—ìjìyà kan náà là ó fún wòlíì àti ẹni tó lọ béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀.
و ایشان بار گناهان خود را متحمل خواهندشد و گناه مسالت کننده مثل گناه آن نبی خواهدبود.۱۰
11 Kí ilé Israẹli má ba à ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi mọ, kí wọ́n má ba à fi gbogbo ìrékọjá ba ara wọn jẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n kí wọ́n le jẹ́ ènìyàn mi, kí Èmi náà sì le jẹ́ Ọlọ́run wọn, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
تا خاندان اسرائیل دیگر از پیروی من گمراه نشوند و باز به تمامی تقصیرهای خویش نجس نگردند. بلکه خداوند یهوه می‌گوید: ایشان قوم من خواهند بود و من خدای ایشان خواهم بود.»۱۱
12 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
و کلام خداوند بر من نازل شده، گفت:۱۲
13 “Ọmọ ènìyàn bí orílẹ̀-èdè kan bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi nípa ìwà àìṣòdodo, èmi yóò nawọ́ mi jáde sí wọn, láti gé ìpèsè oúnjẹ wọn, èmi yóò rán ìyàn sí wọn, èmi yóò sì pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀,
«ای پسر انسان اگر زمینی خیانت کرده، به من خطا ورزد و اگر من دست خود را بر آن دراز کرده، عصای نانش را بشکنم و قحطی در آن فرستاده، انسان و بهایم را از آن منقطع سازم،۱۳
14 bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí. Noa, Daniẹli àti Jobu tilẹ̀ wà nínú rẹ, kìkì ẹ̀mí ara wọn nìkan ni wọ́n lé fi òdodo wọn gbàlà, Olúwa Olódùmarè wí.
اگر‌چه این سه مرد یعنی نوح و دانیال و ایوب در آن باشند، خداوند یهوه می‌گوید که ایشان (فقط) جانهای خود را به عدالت خویش خواهند رهانید.۱۴
15 “Tàbí bí mo bá jẹ́ kí ẹranko búburú gba orílẹ̀-èdè náà kọjá, tí wọn sì bà á jẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ó di ahoro, tí kò sí ẹni tó le gba ibẹ̀ kọjá torí ẹranko búburú yìí,
واگر حیوانات درنده به آن زمین بیاورم که آن را ازاهل آن خالی سازند و چنان ویران شود که ازترس آن حیوانات کسی از آن گذر نکند،۱۵
16 bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta wọ̀nyí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, wọn kì yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là: àwọn nìkan ni a ó gbàlà, ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà yóò di ahoro.
اگرچه این سه مرد در میانش باشند، خداوند یهوه می‌گوید: به حیات خودم قسم که ایشان پسران ودختران را رهایی نخواهند داد. ایشان به تنهایی رهایی خواهند یافت ولی زمین ویران خواهدشد.۱۶
17 “Tàbí tí mo bá mú idà kọjá láàrín orílẹ̀-èdè náà tí mo wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí idà kọjá láàrín ilẹ̀ náà,’ tí mo sì tú ìbínú gbígbóná lé wọn lórí nípa ìtàjẹ̀ sílẹ̀, tí mo pa ènìyàn àti ẹranko inú rẹ.
یا اگر شمشیری به آن زمین آورم و بگویم: ای شمشیر از این زمین بگذر. و اگر انسان و بهایم را از آن منقطع سازم،۱۷
18 Bí àwọn ọkùnrin mẹ́ta yìí tilẹ̀ wà nínú rẹ̀, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà, wọn ki yóò gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin là, ṣùgbọ́n àwọn tìkára wọn nìkan ni a ó gbàlà.
اگر‌چه این سه مرد درمیانش باشند، خداوند یهوه می‌گوید: به حیات خودم قسم که پسران و دختران را رهایی نخواهند داد بلکه ایشان به تنهایی رهایی خواهندیافت.۱۸
19 “Tàbí bí mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn si ilẹ̀ náà, ti mo si da ìrunú mi lé e lórí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀, láti gé ènìyàn àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀,
یا اگر وبا در آن زمین بفرستم و خشم خود را بر آن با خون بریزم و انسان و بهایم را از آن منقطع بسازم،۱۹
20 bó tilẹ̀ jẹ́ pé Noa, Daniẹli àti Jobu wà nínú rẹ, bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, wọn kò le gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin wọn lá. Ara wọn nìkan ni ìwà òdodo wọn lè gbàlà.
اگر‌چه نوح و دانیال و ایوب درمیانش باشند خداوند یهوه می‌گوید: به حیات خودم قسم که نه پسری و نه دختری را رهایی خواهند داد بلکه ایشان (فقط) جانهای خود را به عدالت خویش خواهند رهانید.۲۰
21 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jerusalẹmu, èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-ààrùn láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!
پس خداوندیهوه چنین می‌گوید: چه قدر زیاده حینی که چهارعذاب سخت خود یعنی شمشیر و قحط و حیوان درنده و وبا را بر اورشلیم بفرستم تا انسان و بهایم را از آن منقطع سازم.۲۱
22 Síbẹ̀, yóò ṣẹ́kù àwọn díẹ̀, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí a ó kó jáde nínú rẹ̀. Wọn yóò wá bá yin, ẹ̀yin yóò rí ìwà àti ìṣe wọn, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rí ìtùnú nípa àjálù tí mo mú wá sórí Jerusalẹmu—àní gbogbo àjálù ní mo ti mú wá sórí rẹ̀.
لیکن اینک بقیتی ازپسران و دخترانی که بیرون آورده می‌شوند در آن واگذاشته خواهد شد. هان ایشان را نزد شمابیرون خواهند‌آورد و رفتار و اعمال ایشان راخواهید دید و از بلایی که بر اورشلیم وارد آورده و هر‌آنچه بر آن رسانیده باشم، تسلی خواهیدیافت.۲۲
23 Nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìwà àti ìṣe wọn, a ó tù yín nínú, nítorí pé ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi kò ṣe nǹkan kan láìnídìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
و چون رفتار و اعمال ایشان را ببینیدشما را تسلی خواهند داد و خداوند یهوه می‌گوید: شما خواهید دانست که هر‌آنچه به آن کردم بی‌سبب بجا نیاوردم.»۲۳

< Ezekiel 14 >