< Deuteronomy 9 >

1 Gbọ́, ìwọ Israẹli. Báyìí, ẹ̀yin ti gbáradì láti la Jordani kọjá, láti lọ gba ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n tóbi, tí wọ́n sì lágbára jù yín lọ, tí wọ́n ní àwọn ìlú ńlá ńlá, tí odi wọn kan ọ̀run.
Hear, Israel; you are about to cross over the Jordan today, to go in to dispossess nations greater and mightier than yourself, and cities that are great and fortified up to heaven,
2 Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga àní àwọn ọmọ Anaki ni wọ́n. Ẹ gbọ́ nípa wọn, ẹ sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọ nípa wọn pé, “Ta ni ó le è dojú ìjà kọ àwọn ọmọ Anaki (òmíràn)?”
a people great and tall, the sons of the Anakim, whom you know, and of whom you have heard people say, 'Who can stand before the sons of Anak?'
3 Ṣùgbọ́n kí ó dá a yín lójú lónìí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ń ṣáájú u yín lọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun. Yóò jó wọn run, yóò sì tẹ orí wọn ba níwájú yín. Ẹ̀yin yóò sì lé wọ́n jáde, ẹ̀yin yóò sì run wọ́n kíákíá, bí Olúwa ti ṣèlérí fún un yín.
Know therefore today that Yahweh your God is he who goes over before you like a devouring fire; he will destroy them, and he will subdue them before you; so will you drive them out and make them to perish quickly, as Yahweh has said to you.
4 Lẹ́yìn tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti lé wọn jáde níwájú u yín, ẹ má ṣe wí fún ara yín pé, “Torí òdodo mi ní Olúwa ṣe mú mi wá síbí láti gba ilẹ̀ náà.” Rárá, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa yóò ṣe lé wọn jáde níwájú u yín.
Do not say in your heart, after Yahweh your God has thrust them out from before you, 'It was because of my righteousness that Yahweh has brought me in to possess this land,' for it was because of the wickedness of these nations that Yahweh is driving them out from before you.
5 Kì í ṣe nítorí òdodo yín, tàbí ìdúró ṣinṣin ni ẹ ó fi wọ ìlú wọn lọ láti gba ilẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi lé wọn jáde kúrò níwájú u yín láti lè mú ohun tí ó búra fún àwọn baba ṣẹ: fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
It is not because of your righteousness or the uprightness of your heart that you are going in to possess their land, but it is because of the wickedness of these nations that your God is driving them out from before you, and so that he may make come true the word that he swore to your ancestors, to Abraham, Isaac, and Jacob.
6 Ṣùgbọ́n kí ó yé yín pé kì í ṣe nítorí òdodo yín ni Olúwa Ọlọ́run yín fi ń fún un yín ní ilẹ̀ rere náà, láti ní, nítorí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ jẹ́.
Know therefore, that Yahweh your God is not giving you this good land to possess because of your righteousness, for you are a stubborn people.
7 Ẹ rántí, ẹ má sì ṣe gbàgbé bí ẹ̀yin ti mú Olúwa Ọlọ́run yín bínú ní aginjù. Láti ọjọ́ ti ẹ tí kúrò ní Ejibiti ni ẹ̀yin ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa títí tí ẹ̀yin fi dé ìhín yìí.
Remember and do not forget how you provoked Yahweh your God to anger in the wilderness; from the day that you left the land of Egypt until you came to this place, you have been rebellious against Yahweh.
8 Ní Horebu ẹ̀yin ti mú kí Olúwa bínú, títí dé bi pé ó fẹ́ run yín.
Also at Horeb you provoked Yahweh to anger, and Yahweh was angry enough with you to destroy you.
9 Nígbà tí mo gòkè lọ láti lọ gba wàláà òkúta, wàláà májẹ̀mú ti Olúwa ti bá a yín dá. Ogójì ọ̀sán àti òru ni mo fi wà lórí òkè náà, èmi kò fẹnu kan oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni ń kò mu omi.
When I went up the mountain to receive the tablets of stone, the tablets of the covenant that Yahweh made with you, I stayed on the mountain for forty days and forty nights; I neither ate bread nor drank water.
10 Olúwa fún mi ní wàláà òkúta méjì tí a fi ìka Ọlọ́run kọ. Lórí wọn ni a kọ àwọn òfin tí Ọlọ́run sọ fún un yín lórí òkè láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀ sí.
Yahweh gave to me the two tablets of stone written with his finger; on them was written everything just like all the words that Yahweh announced to you on the mountain out of the middle of the fire on the day of the assembly.
11 Lópin ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí, Olúwa fún mi ní sílétì òkúta méjì, wàláà òkúta májẹ̀mú náà.
It happened at the end of those forty days and forty nights that Yahweh gave me the two tablets of stone, the tablets of the covenant.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ̀kalẹ̀ kúrò níhìn-ín kíákíá, torí pé àwọn ènìyàn rẹ tí o mú jáde láti Ejibiti ti hùwà ìbàjẹ́. Wọ́n ti yípadà kúrò, nínú ọ̀nà mi, wọ́n sì ti ṣe ère dídá fún ara wọn.”
Yahweh said to me, 'Arise, go down quickly from here, for your people, whom you brought out of Egypt, have corrupted themselves. They have quickly turned aside out of the path that I commanded them. They have made for themselves a cast figure.'
13 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle gbá à ni wọ́n.
Furthermore, Yahweh spoke to me and said, 'I have seen this people; they are a stubborn people.
14 Fi mí sílẹ̀, jẹ́ kí n run wọ́n, kí n sì pa orúkọ wọn rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì pọ̀jù wọ́n lọ.”
Let me alone, so that I may destroy them and blot out their name from under heaven, and I will make of you a nation mightier and greater than they.'
15 Báyìí ni mo yípadà, tí mó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà wá, orí òkè tí o ń yọ iná. Àwọn wàláà májẹ̀mú méjèèjì sì wà lọ́wọ́ mi.
So I turned around and came down the mountain, and the mountain was burning. The two tablets of the covenant were in my hands.
16 Ìgbà tí mo ṣàkíyèsí, mo rí i pé ẹ ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ ti ṣe ère òrìṣà ní ìrí ọ̀dọ́ màlúù, fún ara yín. Ẹ ti yípadà kánkán kúrò nínú ọ̀nà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un yín.
I looked, and behold, you had sinned against Yahweh your God. You had molded for yourselves a calf. You had quickly turned aside out of the path that Yahweh had commanded you.
17 Bẹ́ẹ̀ ni mó ju wàláà méjèèjì náà mọ́lẹ̀, mo sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ lójú u yín.
I took the two tablets and threw them out of my hands. I broke them before your eyes.
18 Lẹ́yìn náà mo tún wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi kò jẹ oúnjẹ kankan bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu omi, nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ tí dá, tí ẹ sì ń ṣe búburú lójú Olúwa, tí ẹ sì ń mú u bínú.
Again I lay facedown before Yahweh for forty days and forty nights; I neither ate bread nor drank water, because of all your sin that you had committed, in doing that which was evil in the sight of Yahweh, so as to provoke him to anger.
19 Mo bẹ̀rù ìbínú àti ìrunú Olúwa, nítorí pé inú bí i sí i yín dé bi wí pé ó fẹ́ pa yín run. Ṣùgbọ́n Olúwa tún fetí sí mi lẹ́ẹ̀kan sí i.
For I was afraid of the anger and hot displeasure with which Yahweh was angry enough against you to destroy you. But Yahweh listened to me that time also.
20 Inú sì bí Olúwa sí Aaroni láti pa á run, nígbà náà ni mo tún gbàdúrà fún Aaroni náà.
Yahweh was very angry with Aaron so as to destroy him; I prayed for Aaron also at the same time.
21 Bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú ohun tí ó mú un yín dẹ́ṣẹ̀, àní ère ẹgbọrọ màlúù tí ẹ ti ṣe, mo sì fi iná sun ún, bẹ́ẹ̀ ni mo gún un, mo sì lọ̀ ọ́ lúúlúú bí eruku lẹ́búlẹ́bú, mo sì da ẹ̀lọ̀ rẹ̀ sínú odò tí ń sàn nísàlẹ̀ òkè.
I took your sin, the calf that you had made, and burned it, beat it, and ground it very small, until it was as fine as dust. I threw its dust into the stream that came down from the mountain.
22 Ẹ̀yin tún mú Olúwa bínú ní Tabera, Massa àti ní Kibirotu-Hattaafa.
At Taberah, at Massah, and at Kibroth Hattaavah, you provoked Yahweh to wrath.
23 Nígbà tí Olúwa ran an yín jáde ní Kadeṣi-Barnea, Ó wí pé, “Ẹ gòkè lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín.” Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé e, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọ́ tirẹ̀.
When Yahweh sent you from Kadesh Barnea and said, 'Go up and take possession of the land that I have given you,' then you rebelled against the commandment of Yahweh your God, and you did not believe or listen to his voice.
24 Láti ìgbà tí mo ti mọ̀ yín ni ẹ ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa.
You have been rebellious against Yahweh from the day that I knew you.
25 Mo ti wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí nítorí pé Olúwa sọ pé Òun yóò pa yín run.
So I lay facedown before Yahweh those forty days and forty nights, because he had said that he would destroy you.
26 Mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, má ṣe run àwọn ènìyàn rẹ, àní ogún rẹ tí o ti rà padà, nípa agbára rẹ tí o sì fi agbára ńlá mú wọn jáde láti Ejibiti wá.
I prayed to Yahweh and said, 'O Lord Yahweh, do not destroy your people or your inheritance whom you have redeemed through your greatness, which you have brought out of Egypt with a mighty hand.
27 Rántí àwọn ìránṣẹ́ rẹ Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu. Fojú fo orí kunkun àwọn ènìyàn yìí, pẹ̀lú ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Call to mind your servants Abraham, Isaac, and Jacob; do not look at the stubbornness of this people, nor at their wickedness, nor at their sin,
28 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti mú wa jáde wá yóò wí pé, ‘Torí pé Olúwa kò lè mú wọn lọ sí ilẹ̀ náà tí ó ti ṣèlérí fún wọn, àti pé ó ti kórìíra wọn, ni ó fi mú wọn jáde láti pa wọ́n ní aginjù.’
so that the land from where you brought us should say, “Because Yahweh was not able to bring them into the land that he promised to them, and because he hated them, he has brought them out to kill them in the wilderness.”
29 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn rẹ ni wọ́n, ogún rẹ tí o ti fi ọwọ́ agbára rẹ àti nínà ọwọ́ rẹ mú jáde.”
Yet they are your people and your inheritance, whom you brought out by your great strength and by the display of your power.'

< Deuteronomy 9 >