< Deuteronomy 7 >

1 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá mú ọ dé ilẹ̀ náà, tí ìwọ yóò wọ̀ lọ láti gbà, tí ìwọ yóò sì lé ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè kúrò níwájú rẹ. Àwọn ará Hiti, Girgaṣi, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi. Àwọn orílẹ̀-èdè méje tí wọ́n lágbára tí wọ́n sì pọ̀jù ọ lọ,
Gdy PAN, twój Bóg, wprowadzi cię do ziemi, do której wchodzisz, by ją posiąść, i [gdy] wypędzi przed tobą wiele narodów: Chetytów, Girgaszytów, Amorytów, Kananejczyków, Peryzzytów, Chiwwitów i Jebusytów – siedem narodów liczniejszych i potężniejszych niż ty;
2 nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá sì ti fi wọ́n lé ẹ lọ́wọ́, tí ìwọ sì ti ṣẹ́gun wọn, kí ìwọ kí ó sì pa wọ́n run pátápátá. Má ṣe bá wọn ṣe àdéhùn àlàáfíà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣàánú fún wọn.
[Gdy] więc PAN, twój Bóg, wyda je tobie, wytępisz je, doszczętnie je wyniszczysz, nie zawrzesz z nimi przymierza i nie zlitujesz się nad nimi;
3 Ìwọ kò gbọdọ̀ bá wọn dá àna. Àwọn ọmọbìnrin rẹ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọkùnrin wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin rẹ,
Nie będziesz z nimi zawierał małżeństw: swej córki nie dasz ich synowi i ich córki nie weźmiesz dla swego syna;
4 torí pé wọ́n yóò yí àwọn ọmọ rẹ padà kúrò lẹ́yìn mi, láti jẹ́ kí wọn máa sin òrìṣà, ìbínú Olúwa yóò sì wá sórí rẹ, yóò sì run yín kíákíá.
Gdyż odwiodłaby twego syna od kroczenia za mną, by służyli innym bogom. Wtedy rozpaliłby się gniew PANA na was i prędko by was wytępił.
5 Èyí ni kí ẹ ṣe sí wọn, ẹ wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, ẹ bi òpó òkúta ibi mímọ́ òrìṣà wọn lulẹ̀, òpó òrìṣà Aṣerah wọn ni kí ẹ gé lulẹ̀ kí ẹ sì sun ère òrìṣà wọn ní iná.
Lecz tak z nimi postąpicie: Zburzycie ich ołtarze, pokruszycie ich pomniki, wytniecie ich gaje i spalicie ogniem ich rzeźbione posągi.
6 Torí pé ènìyàn mímọ́ ni ẹ jẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, Olúwa Ọlọ́run yín ti yàn yín láàrín gbogbo ènìyàn lórí ilẹ̀ ayé, láti jẹ́ ènìyàn rẹ̀: ohun ìní iyebíye rẹ̀.
Ty bowiem jesteś świętym ludem dla PANA, swego Boga: PAN, twój Bóg, wybrał cię, abyś był dla niego szczególnym ludem spośród wszystkich narodów, które są na ziemi.
7 Olúwa kò torí pé ẹ pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ju àwọn ènìyàn yòókù lọ yàn yín, ẹ̀yin sá à lẹ kéré jù nínú gbogbo ènìyàn.
PAN umiłował was i wybrał was nie dlatego, że byliście liczniejsi od innych narodów, gdyż byliście najmniej liczni ze wszystkich narodów;
8 Ṣùgbọ́n torí Olúwa fẹ́ràn yín, tí ó sì pa ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín mọ́ ni ó ṣe fi ọwọ́ agbára ńlá mú un yín jáde tí ó sì rà yín padà nínú oko ẹrú, àti láti ọwọ́ agbára Farao ọba Ejibiti.
Lecz ponieważ PAN was umiłował i chciał dochować przysięgi, którą złożył waszym ojcom, PAN wyprowadził was potężną ręką i wykupił was z domu niewoli, z ręki faraona, króla Egiptu.
9 Nítorí náà ẹ mọ̀ dájúdájú pé Olúwa Ọlọ́run yín, Òun ni Ọlọ́run, Ọlọ́run olóòtítọ́ ni, tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran, àwọn tí ó fẹ́ ẹ tí ó sì ń pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Uznaj więc, że PAN, twój Bóg, jest Bogiem, Bogiem wiernym, który zachowuje przymierze i miłosierdzie do tysiącznego pokolenia względem tych, którzy go miłują i przestrzegają jego przykazań;
10 Ṣùgbọ́n àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ni yóò san ẹ̀san fún ní gbangba nípa pípa wọ́n run; kì yóò sì jáfara láti san ẹ̀san fún àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ ní gbangba.
A odpłaca w twarz tym, którzy go nienawidzą, aby ich zniszczyć. Nie zwleka [z karą] dla tego, który go nienawidzi; odpłaci mu w twarz.
11 Nítorí náà ẹ kíyèsi láti máa tẹ̀lé àwọn àṣẹ, ìlànà àti òfin tí mo fun un yín lónìí.
Przestrzegaj więc przykazań, nakazów i praw, które ja dziś nakazuję ci wypełnić.
12 Bí ẹ bá ń kíyèsi àwọn òfin wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣọ́ra láti ṣe wọ́n, nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ fún un yín, bí ó ti búra fún àwọn baba ńlá a yín.
Jeśli będziecie słuchać tych praw, przestrzegać ich i wypełniać [je], wtedy PAN, twój Bóg, dochowa ci przymierza i miłosierdzia, które poprzysiągł twoim ojcom.
13 Yóò fẹ́ràn yín, yóò bùkún un yín yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i. Yóò bùkún èso inú yín, ọ̀gbìn ilẹ̀ yín, oúnjẹ yín, wáìnì tuntun àti òróró yín, àwọn màlúù, agbo ẹran yín, àti àwọn àgùntàn, ọ̀wọ́ ẹran yín, ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá yín láti fún un yín.
I będzie cię miłował, błogosławił ci i rozmnoży cię. I pobłogosławi owoc twego łona i owoc twojej ziemi: twoje zboże, twoje wino i twoją oliwę, przyrost twoich krów i trzody twoich owiec na ziemi, którą poprzysiągł twoim ojcom dać tobie.
14 A ó bùkún un yín ju gbogbo ènìyàn lọ, kò sí ẹni tí yóò yàgàn nínú ọkùnrin tàbí obìnrin yín, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ọ̀kan nínú àwọn ohun ọ̀sìn in yín tí yóò wà láìlọ́mọ.
Będziesz błogosławiony ponad wszystkie narody. Nie będzie niepłodnego i niepłodnej ani wśród ciebie, ani wśród twego bydła.
15 Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ààrùn gbogbo, kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí ààrùn búburú tí ẹ mọ̀ ní Ejibiti wá sára yín, ṣùgbọ́n yóò fi wọ́n lé ara gbogbo àwọn tí ó kórìíra yín.
PAN oddali też od ciebie każdą chorobę i nie ześle na ciebie żadnych dotkliwych chorób Egiptu, które poznałeś, lecz ześle je na wszystkich, którzy cię nienawidzą.
16 Gbogbo àwọn ènìyàn tí Olúwa Ọlọ́run yín fi lé yín lọ́wọ́ ni kí ẹ parun pátápátá. Ẹ má ṣe ṣàánú fún wọn, ẹ má ṣe sin olúwa ọlọ́run wọn torí pé ìdánwò ni èyí jẹ́ fún un yín.
I wytępisz wszystkie narody, które PAN, twój Bóg, tobie wyda; nie zlituje się nad nimi twoje oko. I nie będziesz służył ich bogom, bo byłoby to dla ciebie sidłem.
17 Ẹ lè máa rò láàrín ara yín pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè yìí lágbára jù wá lọ. Báwo ni a o ṣe lé wọn jáde?”
Jeśli powiesz w swym sercu: Te narody są liczniejsze ode mnie, jakże będę mógł je wypędzić?
18 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, ẹ rántí dáradára ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe sí Farao àti gbogbo Ejibiti.
Nie bój się ich, ale dobrze pamiętaj to, co PAN, twój Bóg, uczynił faraonowi i całemu Egiptowi;
19 Ẹ sá à fi ojú u yín rí àwọn àdánwò ńlá, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá, ọwọ́ agbára àti nínà ọwọ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi mú un yín jáde. Olúwa Ọlọ́run yín yóò ṣe bákan náà sí gbogbo àwọn ènìyàn náà tí ẹ ń bẹ̀rù.
Te wielkie doświadczenia, które twoje oczy widziały, te znaki, cuda, potężną rękę i wyciągnięte ramię, którymi PAN, twój Bóg, cię wyprowadził. Tak uczyni PAN, twój Bóg, wszystkim narodom, których się boisz.
20 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Olúwa Ọlọ́run yín yóò rán oyin sáàrín wọn títí tí àwọn tí ó sálà tí wọ́n sá pamọ́ fún un yín, yóò fi ṣègbé.
Ponadto PAN, twój Bóg, ześle na nich szerszenie, aż wyginą ci, którzy pozostali, i ci, którzy ukryli się przed tobą.
21 Ẹ má gbọ̀n jìnnìjìnnì torí wọn, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín tí ó wà láàrín yín, Ọlọ́run alágbára ni, àti Ọlọ́run tí ó tóbi lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Nie drżyj przed nimi, gdyż PAN, twój Bóg, [jest] pośród ciebie, Bóg wielki i straszliwy.
22 Olúwa Ọlọ́run yín yóò lé gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀n-ọn-nì kúrò níwájú u yín díẹ̀díẹ̀. A kò nígbà yín láààyè láti lé wọn dànù lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo. Kí àwọn ẹranko igbó má ba à gbilẹ̀ sí i láàrín yín.
I PAN, twój Bóg, wypędzi przed tobą te narody z wolna i po trosze: Nie będziesz mógł wytępić ich szybko, aby nie rozmnożyły się przeciw tobie zwierzęta polne.
23 Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́, yóò sì máa fà wọ́n sínú dàrúdàpọ̀ títí tí wọn yóò fi run.
Lecz PAN, twój Bóg, wyda je tobie i porazi je wielką klęską, aż będą wyniszczone.
24 Yóò fi àwọn ọba wọn lé e yín lọ́wọ́, ẹ̀yin ó sì pa orúkọ wọn rẹ́ lábẹ́ ọ̀run. Kò sí ẹni tí yóò lè dojú ìjà kọ yín títí tí ẹ ó fi pa wọ́n run.
I wyda ich królów w twoje ręce i zgładzisz ich imię spod nieba. Nikt nie ostoi się przed tobą, aż ich wytępisz.
25 Dá iná sun àwọn ère òrìṣà wọn, ẹ má ṣe ṣe ojúkòkòrò sí fàdákà tàbí wúrà tí ó wà lára wọn. Ẹ má ṣe mú un fún ara yín, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ yóò jẹ́ ìdẹ̀kùn fún un yín, torí pé ìríra ni sí Olúwa Ọlọ́run yín.
Rzeźbione posągi ich bogów spalisz w ogniu. Nie będziesz pożądał srebra ani złota, [które jest] na nich, ani nie będziesz brał go dla siebie, byś nie został przez nie usidlony, ponieważ to budzi odrazę u PANA, twego Boga.
26 Ẹ má ṣe mú ohun ìríra wá sí ilé yín, kí ìwọ má ba à di ẹni ìparun bí i rẹ̀. Ẹ kórìíra rẹ̀ kí ẹ sì kà á sí ìríra pátápátá, torí pé a yà á sọ́tọ̀ fún ìparun ni.
Nie wnoś [takiej] obrzydliwości do swego domu, abyś się nie stał przekleństwem tak jak i ona. Będziesz się nią bardzo brzydził i czuł do niej ogromny wstręt, gdyż to jest przekleństwo.

< Deuteronomy 7 >