< Deuteronomy 4 >

1 Gbọ́ Israẹli, gbọ́ òfin àti ìlànà tí èmi yóò kọ́ ọ yín. Ẹ tẹ̀lé wọn kí ẹ ba à lè yè, kí ẹ ba à lè lọ láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín yóò fi fún un yín.
"Ja nyt, Israel, kuule ne käskyt ja säädökset, jotka minä teille opetan, että seuraisitte niitä, eläisitte ja ottaisitte omaksenne sen maan, jonka Herra, teidän isienne Jumala, teille antaa.
2 Ẹ má ṣe fi kún àwọn ohun tí mo pàṣẹ fún un yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ yọ kúrò nínú wọn, ṣùgbọ́n ẹ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín tí mo fún un yín mọ́.
Älkää lisätkö mitään siihen, mitä minä teille määrään, älkääkä ottako siitä mitään pois, vaan noudattakaa Herran, teidän Jumalanne, käskyjä, jotka minä teille annan.
3 Ẹ ti fi ojú ara yín rí ohun tí Olúwa ṣe ní Baali-Peori. Olúwa Ọlọ́run yín run gbogbo àwọn tí ó tẹ̀lé òrìṣà Baali-Peori kúrò ní àárín yín.
Te olette omin silmin nähneet, mitä Herra teki Baal-Peorin asiassa, kuinka Herra, sinun Jumalasi, hävitti sinun keskuudestasi jokaisen, joka lähti kulkemaan Baal-Peorin perässä.
4 Ṣùgbọ́n gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run láìyẹsẹ̀ ni ẹ wà láààyè lónìí.
Mutta te, jotka riipuitte kiinni Herrassa, teidän Jumalassanne, te kaikki olette elossa vielä tänä päivänä.
5 Ẹ kíyèsi i, mo ti kọ́ ọ yín ní àwọn òfin àti àṣẹ bí Olúwa Ọlọ́run mi ti pàṣẹ fún mi, kí ẹ ba à le tẹ̀lé wọn ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń lọ láti ní ní ìní.
Katso, minä olen opettanut teille käskyt ja säädökset, niinkuin Herra, minun Jumalani, on minua käskenyt, että seuraisitte niitä siinä maassa, jota te menette ottamaan omaksenne.
6 Ẹ máa kíyèsi wọn dáradára. Èyí ni yóò fi ọgbọ́n àti òye yín han àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn tí wọn yóò gbọ́ nípa àwọn ìlànà wọ̀nyí, tí wọn yóò sì máa wí pé, “Dájúdájú, orílẹ̀-èdè ńlá yìí kún fún ọgbọ́n àti òye.”
Noudattakaa ja seuratkaa niitä, sillä se on oleva teidän viisautenne ja ymmärryksenne kansojen silmissä. Kun he kuulevat kaikki nämä käskyt, sanovat he: 'Totisesti, viisas ja ymmärtäväinen kansa on tämä suuri kansa'.
7 Orílẹ̀-èdè olókìkí wo ni ọlọ́run wọn tún súnmọ́ wọn, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti súnmọ́ wa nígbàkígbà tí a bá ń ké pè é?
Sillä onko toista suurta kansaa, jonka jumalat ovat sitä niin lähellä, kuin Herra, meidän Jumalamme, on lähellä meitä, niin usein kuin me häntä rukoilemme?
8 Orílẹ̀-èdè wo ló tún le lókìkí láti ní àwọn ìlànà òdodo, àti òfin gẹ́gẹ́ bí àwọn òfin wọ̀nyí tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.
Ja onko toista suurta kansaa, jolla on niin vanhurskaat käskyt ja säädökset, kuin on koko tämä laki, jonka minä tänä päivänä teille annan?
9 Kìkì i kí ẹ kíyèsára, kí ẹ sì ṣọ́ra a yín gidigidi kí ẹ má ba à gbàgbé àwọn ohun tí ojú yín ti rí, kí wọn má sì ṣe sá kúrò lóókan àyà yín níwọ̀n ìgbà tí ẹ sì wà láààyè. Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn wọn.
Ole vain varuillasi ja ota itsestäsi tarkka vaari, ettet unhota, mitä omin silmin olet nähnyt, ja ettei se lähde sinun sydämestäsi koko elinaikanasi, vaan että ilmoitat sen lapsillesi ja lastesi lapsille:
10 Ẹ rántí ọjọ́ tí ẹ dúró níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní Horebu, nígbà tí ó wí fún mi pé, “Kó àwọn ènìyàn wọ̀nyí jọ síwájú mi láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí wọ́n lè kọ́ láti máa bu ọlá náà fún mi ní gbogbo ìgbà tí wọ́n bá gbé lórí ilẹ̀ náà, kí wọ́n sì le è fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ wọn.”
mitä tapahtui sinä päivänä, jona seisoit Herran, sinun Jumalasi, edessä Hoorebilla, kun Herra sanoi minulle: 'Kokoa kansa, niin minä julistan heille sanani, että he oppisivat pelkäämään minua, niin kauan kuin elävät maan päällä, ja opettaisivat lapsensakin siihen'.
11 Ẹ̀yin súnmọ́ tòsí, ẹ sì dúró ní ẹsẹ̀ òkè náà, òkè náà sì ń jóná dé agbede-méjì ọrun, pẹ̀lú òkùnkùn, àti àwọsánmọ̀, àti òkùnkùn biribiri.
Ja te astuitte esille ja jäitte seisomaan vuoren juurelle, ja vuori paloi tulena, joka loimusi sisimpään taivaaseen asti pimeyden ja synkkien pilvien keskellä.
12 Olúwa sì bá yín sọ̀rọ̀ láti àárín iná náà wá. Ẹ gbọ́ àwọn ìró ohùn, ṣùgbọ́n ẹ kò rí ẹnikẹ́ni, ohùn nìkan ni ẹ gbọ́.
Ja Herra puhui teille tulen keskeltä. Sanat te kuulitte, mutta ette nähneet hänen muotoansa, kuulitte vain äänen.
13 Ó sọ àwọn májẹ̀mú rẹ̀ fún un yín àní àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó pàṣẹ fún un yín láti máa tẹ̀lé, ó sì kọ wọ́n sórí wàláà òkúta méjì.
Ja hän ilmoitti teille liittonsa, jonka hän käski teidän pitää, nimittäin ne kymmenen käskysanaa; ja hän kirjoitti ne kahteen kivitauluun.
14 Olúwa sì pàṣẹ fún mi nígbà náà láti kọ yín ní ìlànà àti ìdájọ, kí ẹ̀yin kí ó lè máa ṣe wọ́n ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ẹ̀yin ń lọ láti gbà á.
Ja minun Herra silloin käski opettaa teille käskyt ja säädökset, että te seuraisitte niitä siinä maassa, jota te menette ottamaan omaksenne.
15 Ẹ kíyèsára gidigidi, torí pé, ẹ kò rí ìrísí ohunkóhun ní ọjọ́ tí Olúwa bá yín sọ̀rọ̀ ní Horebu láti àárín iná wá. Torí náà ẹ ṣọ́ra yín gidigidi,
Ottakaa siis itsestänne tarkka vaari-sillä te ette sinä päivänä, jona Herra puhui teille tulen keskeltä Hoorebilla, nähneet hänestä minkäänkaltaista muotoa-
16 kí ẹ ma ba à ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe ère fún ara yín, àní ère lóríṣìíríṣìí yálà èyí tí ó ní ìrísí ọkùnrin tàbí tí obìnrin,
ettette menettele kelvottomasti ettekä tee itsellenne jumalankuvaa, ette minkään muotoista patsasta, ette miehen tai naisen kuvaa,
17 tàbí ti ẹranko orí ilẹ̀, tàbí ti ẹyẹ tí ń fò ní òfúrufú,
ette maan päällä liikkuvan nelijalkaisen eläimen kuvaa, ette taivaan alla lentävän siivekkään linnun kuvaa,
18 tàbí ti àwòrán onírúurú ẹ̀dá tí ń fà lórí ilẹ̀, tàbí ti ẹja nínú omi.
ette maassa matelevaisen kuvaa ettekä vesissä maan alla olevan kalan kuvaa;
19 Bí ẹ bá wòkè tí ẹ rí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀: àwọn ohun tí a ṣe lọ́jọ̀ sójú ọ̀run, ẹ má ṣe jẹ́ kí wọ́n tàn yín jẹ dé bi pé ẹ̀yin yóò foríbalẹ̀ fún wọn, àti láti máa sin ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín dá fún gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run.
ja ettet, kun nostat silmäsi taivasta kohti ja katselet aurinkoa ja kuuta ja tähtiä, kaikkea taivaan joukkoa, anna vietellä itseäsi kumartamaan ja palvelemaan niitä, sillä Herra, sinun Jumalasi, on jakanut ne kaikille muille kansoille koko taivaan alla.
20 Olúwa Ọlọ́run yín sì ti mú ẹ̀yin jáde kúrò nínú iná ìléru ńlá, àní ní Ejibiti, láti lè jẹ́ ènìyàn ìní i rẹ̀, bí ẹ̀yin ti jẹ́ báyìí.
Onhan Herra ottanut teidät ja vienyt pois rautapätsistä, Egyptistä, että teistä tulisi hänen perintökansansa, niinkuin nyt on tapahtunut.
21 Inú Olúwa ru sí mi nítorí yín, ó sì ti búra pé èmi kì yóò la Jordani kọjá, èmi kì yóò sì wọ ilẹ̀ rere tí Olúwa Ọlọ́run fi fún un yín, ní ìní yín.
Mutta Herra vihastui minuun teidän tähtenne ja vannoi, etten minä saa mennä Jordanin yli enkä tulla siihen hyvään maahan, jonka Herra, sinun Jumalasi, antaa sinulle perintöosaksi,
22 Èmi yóò kú ní ilẹ̀ yìí, èmi kì yóò la Jordani kọjá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti fẹ́ rékọjá sí òdìkejì odò láti gba ilẹ̀ rere náà.
vaan että minä kuolen tässä maassa enkä mene Jordanin yli. Mutta te menette sen yli ja otatte tuon hyvän maan omaksenne.
23 Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti bá a yín dá. Ẹ má ṣe ṣe ère ní ìrísí ohunkóhun fún ara yín, èèwọ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín kà á sí.
Niin varokaa, ettette unhota Herran, teidän Jumalanne, liittoa, jonka hän on tehnyt teidän kanssanne, ettekä tee itsellenne jumalankuvaa, mitään sen muotoista kuvaa, jota Herra, sinun Jumalasi, on kieltänyt sinua tekemästä.
24 Torí pé iná ajónirun ni Olúwa Ọlọ́run yín, Ọlọ́run owú ni.
Sillä Herra, sinun Jumalasi, on kuluttava tuli, kiivas Jumala.
25 Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti ní àwọn ọmọ àti àwọn ọmọ ọmọ, tí ẹ sì ti gbé ní ilẹ̀ yìí pẹ́, bí ẹ bá wá ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe irú ère yówù tó jẹ́, tí ẹ sì ṣe búburú lójú Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì mú un bínú.
Kun sitten sinulle on syntynyt lapsia ja lasten lapsia ja te olette vanhentuneet maassa, ja jos te silloin menettelette kelvottomasti ja teette itsellenne jumalankuvan, minkämuotoisen kuvan hyvänsä, ja siten teette sitä, mikä on pahaa Herran, sinun Jumalasi, silmissä, ja vihoitatte hänet,
26 Mo pe ọ̀run àti ayé láti jẹ́rìí takò yín lónìí, pé kíákíá ni ẹ ó parun ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń la Jordani kọjá lọ láti gbà. Ẹ kò ní pẹ́ ní ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò run pátápátá.
niin minä otan tänä päivänä taivaan ja maan todistajiksi teitä vastaan, että teidät äkkiä hävitetään siitä maasta, johon te menette Jordanin yli ottamaan sen omaksenne; te ette saa kauan elää siellä, vaan teidät tuhotaan kokonaan.
27 Olúwa yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn ènìyàn náà, àwọn díẹ̀ nínú yín ni yóò yè láàrín orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò fọ́n yín sí.
Ja Herra hajottaa teidät kansojen sekaan, ja ainoastaan vähäinen joukko teitä on jäävä niiden pakanakansojen keskelle, joiden tykö Herra teidät kuljettaa.
28 Ẹ ó sì máa sin ọlọ́run tí á fi ọwọ́ ènìyàn ṣe: tí wọ́n fi igi àti òkúta ṣe, èyí tí kò le ríran, gbọ́rọ̀, jẹun tàbí gbọ́ òórùn.
Ja siellä te palvelette jumalia, jotka ovat ihmiskätten tekoa, puuta ja kiveä, jotka eivät näe eivätkä kuule, eivät syö eivätkä hajua tunne.
29 Bí ẹ̀yin bá wá Olúwa Ọlọ́run yín láti bẹ̀ ẹ́, ẹ ó ri i, bí ẹ bá wá a, pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà a yín.
Mutta sitten sinä siellä etsit Herraa, sinun Jumalaasi, ja sinä löydät hänet, kun kysyt häntä kaikesta sydämestäsi ja kaikesta sielustasi.
30 Bí ẹ bá wà nínú wàhálà, bí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ṣẹlẹ̀ sí yín, láìpẹ́ ẹ ó tún padà tọ Olúwa Ọlọ́run yín wá, ẹ ó sì gbọ́ tirẹ̀.
Kun olet ahdistuksessa ja kaikki tämä kohtaa sinua aikojen lopussa, niin sinä palajat Herran, sinun Jumalasi, tykö ja kuulet hänen ääntänsä.
31 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín aláàánú ni, kò ní gbàgbé tàbí pa yín rẹ́ tàbí kó gbàgbé májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín, èyí tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ìbúra.
Sillä Herra, sinun Jumalasi, on laupias Jumala. Hän ei jätä sinua eikä hukuta sinua; hän ei unhota sinun isiesi kanssa tekemäänsä liittoa, jonka hän on heille valalla vahvistanut.
32 Ẹ béèrè báyìí nípa ti àwọn ọjọ́ ìgbàanì ṣáájú kí a tó bí i yín, láti ìgbà tí Ọlọ́run ti dá ènìyàn sórí ilẹ̀ ayé. Ẹ béèrè láti igun ọ̀run kan sí èkejì. Ǹjẹ́ irú nǹkan olókìkí báyìí: ti ṣẹlẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a ti gbọ́ irú u rẹ̀ rí?
Sillä kysy menneiltä ajoilta, jotka ovat olleet ennen sinua, alkaen siitä päivästä, jona Jumala loi ihmiset maan päälle, kysy taivaan äärestä toiseen: onko koskaan mitään näin suurta tapahtunut, tai onko mitään tällaista ikinä kuultu?
33 Ǹjẹ́ àwọn ènìyàn mìíràn tí ì gbọ́ ohùn Ọlọ́run rí, tí ó sọ̀rọ̀ jáde láti inú iná, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti gbọ́ tí ẹ sì yè?
Onko mikään kansa kuullut Jumalan äänen puhuvan tulen keskeltä, niinkuin sinä olet kuullut, ja kuitenkin jäänyt elämään?
34 Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ti gbìyànjú àti mú orílẹ̀-èdè kan jáde kúrò nínú òmíràn fúnra rẹ̀ rí, nípa ìdánwò, nípa iṣẹ́ àmì, àti iṣẹ́ ìyanu nípa ogun, tàbí nípa ọwọ́ agbára tàbí nína apá, àti nípa ẹ̀rù ńlá: gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe fún un yín ní Ejibiti ní ojú ẹ̀yin tìkára yín?
Tahi onko mikään jumala koettanut mennä ottamaan itsellensä kansaa toisen kansan keskuudesta koettelemuksilla, tunnusteoilla ja ihmeillä, sodalla, väkevällä kädellä ja ojennetulla käsivarrella ja suurilla, peljättävillä teoilla, minkä kaiken Herra, teidän Jumalanne, on tehnyt teille Egyptissä, sinun silmiesi edessä?
35 A fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn yín kí ẹ bá a lè gbà pé Olúwa ni Ọlọ́run. Kò sì sí ẹlòmíràn lẹ́yìn rẹ̀.
Sinun on annettu se nähdä, tietääksesi, että Herra on Jumala, eikä muuta jumalaa ole kuin hän.
36 Ó jẹ́ kí ẹ gbọ́ ohùn rẹ̀ láti ọ̀run wá, láti kọ́ ọ yín. Ní ayé, ó fi iná ńlá rẹ̀ hàn yín, ẹ sì gbọ́ ohùn rẹ̀ láti àárín iná wá,
Taivaasta hän antoi sinun kuulla äänensä opettaaksensa sinua, ja maan päällä hän antoi sinun nähdä suuren tulensa, ja sinä kuulit hänen sanansa tulen keskeltä.
37 torí pé ó fẹ́ràn àwọn baba ńlá yín, ó sì yan àwọn ọmọ wọn ní ipò lẹ́yìn wọn. Nípa ìwà láààyè àti nípa agbára ńlá rẹ̀ ni ó fi mú un yín kúrò ní Ejibiti.
Koska hän siis rakasti sinun isiäsi ja valitsi heidän jälkeläisensä itselleen ja itse suurella voimallaan vei sinut pois Egyptistä
38 Láti lé àwọn orílẹ̀-èdè tí ó tóbi tí ó sì lágbára níwájú yín; láti le è mú un yín wá sí ilẹ̀ wọn kí ẹ lè jogún rẹ̀ bí ó ti rí lónìí.
karkoittaen sinun tieltäsi kansoja, suurempia ja väkevämpiä kuin sinä, ja tuoden sinut heidän maahansa antaakseen sen sinulle perintöosaksi, niinkuin nyt on tapahtunut,
39 Ẹ gbà kí ẹ sì fi sọ́kàn lónìí pé Olúwa ni Ọlọ́run lókè ọ̀run lọ́hùn ún àti ní ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ níhìn-ín. Kò sí òmíràn mọ́.
niin tiedä siis tänä päivänä ja paina se sydämeesi, että Herra on Jumala ylhäällä taivaassa ja alhaalla maan päällä, eikä muuta jumalaa ole.
40 Ẹ pa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ tí mo ń fún un yín lónìí; kí ó ba à le è yẹ yín, kí ẹ̀yin sì le è pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín ní gbogbo ìgbà.
Noudata hänen säädöksiänsä ja käskyjänsä, jotka minä tänä päivänä sinulle annan, että sinä ja sinun lapsesi sinun jälkeesi menestyisitte ja että eläisit kauan siinä maassa, jonka Herra, sinun Jumalasi, antaa sinulle ainiaaksi."
41 Mose sì ya àwọn ìlú mẹ́ta kan sọ́tọ̀ ní apá ìwọ̀-oòrùn Jordani.
Silloin Mooses erotti kolme kaupunkia tuolta puolelta Jordanin, auringon nousun puolelta,
42 Kí apànìyàn kí ó lè máa sá síbẹ̀, tí ó bá ṣi ẹnìkejì rẹ̀ pa, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, àti pé bí ó bá sá sí ọ̀kan nínú ìlú wọ̀nyí kí ó lè là.
että niihin voisi paeta tappaja, joka on tappanut toisen tahtomattaan ja häntä ennestään vihaamatta; paetkoon hän johonkin näistä kaupungeista, niin hän saa elää.
43 Àwọn ìlú mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà nìwọ̀nyí: Beseri ní ijù, ní ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, tí àwọn ọmọ Reubeni; Ramoti ní Gileadi, ti àwọn ọmọ Gadi àti Golani ní Baṣani, ti àwọn ará Manase.
Ne olivat: ruubenilaisille Beser erämaassa, ylätasangolla; gaadilaisille Raamot Gileadissa ja manasselaisille Goolan Baasanissa.
44 Èyí ni òfin tí Mose gbé kalẹ̀ fún àwọn ará Israẹli.
Tämä on se laki, jonka Mooses antoi israelilaisille,
45 Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀rí, àti ìlànà àti ìdájọ́ tí Mose fi lélẹ̀ fún ún àwọn ọmọ Israẹli, lẹ́yìn tí wọ́n ti jáde kúrò ní Ejibiti.
ja nämä ovat ne todistukset, käskyt ja oikeudet, jotka Mooses julisti israelilaisille, heidän lähdettyään Egyptistä,
46 Tí wọ́n sì wà ní ẹ̀bá àfonífojì Beti-Peori ní ìlà-oòrùn Jordani; ní ilẹ̀ Sihoni, ọba àwọn Amori tí ó jẹ ọba Heṣboni tí Mose àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun, bí wọ́n ṣe ń ti Ejibiti bọ̀.
tuolla puolella Jordanin, laaksossa, vastapäätä Beet-Peoria, Siihonin, amorilaisten kuninkaan, maassa, hänen, joka asui Hesbonissa ja jonka Mooses ja israelilaiset voittivat, lähdettyänsä Egyptistä.
47 Wọ́n gba ilẹ̀ rẹ̀, àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani àwọn ọba Amori méjèèjì tí ń bẹ ní ìlà-oòrùn Jordani.
Ja he ottivat omakseen hänen maansa ja Oogin, Baasanin kuninkaan, maan, kahden amorilaisten kuninkaan maat, jotka ovat tuolla puolella Jordanin, auringon nousuun päin,
48 Ilẹ̀ wọ̀nyí bẹ̀rẹ̀ láti Aroeri ní etí odò Arnoni dé orí òkè Sirioni (èyí ni Hermoni).
alkaen Aroerista, joka on Arnonjoen rannalla, aina Sirjonin vuoreen, se on Hermoniin, saakka,
49 Àti gbogbo aginjù ní ìlà-oòrùn Jordani títí dé Òkun Iyọ̀ ní ìsàlẹ̀ gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga.
sekä koko Aromaan, tuolla puolella Jordanin, idän puolella, aina Aromaan mereen saakka, Pisgan rinteiden juurelle.

< Deuteronomy 4 >