< Deuteronomy 26 >

1 Nígbà tí ìwọ bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìní tí ìwọ sì ti jogún, tí ìwọ sì ti ń gbé níbẹ̀,
Rĩrĩa ũgaatoonya bũrũri ũrĩa Jehova Ngai waku egũkũhe ũrĩ igai, na ũwĩgwatĩre na ũtũũre kuo,
2 mú díẹ̀ nínú ohun tí o pèsè láti inú erùpẹ̀ ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ, kó wọn sínú agbọ̀n. Nígbà náà kí o lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibi tí orúkọ rẹ̀ yóò máa gbé.
nĩũkoya maciaro mamwe ma mbere ma kĩrĩa gĩothe ũgaakũria tĩĩri-inĩ wa bũrũri ũcio Jehova Ngai arakũhe na ũmekĩre kĩondo. Ũcooke ũthiĩ handũ harĩa Jehova Ngai waku agaathuura ha gũtũũria Rĩĩtwa rĩake,
3 Kí o sì sọ fun àlùfáà tí ó wà ní ibi iṣẹ́ ní àsìkò náà, pé, “Mo sọ ọ́ di mí mọ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé mo ti wá sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba wa.”
wĩre mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa ũrĩ wĩra-inĩ hĩndĩ ĩyo atĩrĩ, “Nĩndoiga ũmũthĩ ndĩ mbere ya Jehova Ngai wakwa atĩ nĩndĩkĩtie gũkinya bũrũri ũrĩa Jehova eerĩire maithe maitũ ma tene na mwĩhĩtwa atĩ nĩagatũhe.”
4 Àlùfáà yóò gbé agbọ̀n náà kúrò ní ọwọ́ rẹ, yóò sì gbé e kalẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Nake mũthĩnjĩri-Ngai ũcio nĩakamũkĩra kĩondo kĩu kuuma moko-inĩ maku, akĩige hau mbere ya kĩgongona kĩa Jehova Ngai waku.
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní iwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Baba mi jẹ́ alárìnkiri ará Aramu, ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti pẹ̀lú ènìyàn díẹ̀, ó sì ń gbé níbẹ̀, ó sì wá di orílẹ̀-èdè olókìkí, alágbára, tí ó kún fún ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Ningĩ nĩũkoiga ũrĩ hau mbere ya Jehova Ngai waku atĩrĩ: “Baba aarĩ Mũsuriata watũũraga orũũraga, nake agĩikũrũka agĩthiĩ bũrũri wa Misiri marĩ na andũ mataarĩ aingĩ, nao magĩtũũra kuo na magĩtuĩka rũrĩrĩ rũnene rũrĩ hinya na rwa andũ aingĩ.
6 Ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti ṣe àìdára sí wa, wọ́n jẹ wá ní yà, wọ́n fún wa ní iṣẹ́ líle ṣe.
No andũ a Misiri nĩmatũnyamaririe na magĩtũma tũthĩĩnĩke, na magĩtũrutithia wĩra wa hinya.
7 Nígbà náà ni a kégbe pe Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wa, Olúwa sì gbọ́ ohùn wa, ó sì rí ìrora, làálàá àti ìnira wa.
Hĩndĩ ĩyo tũgĩkaĩra Jehova, o we Ngai wa maithe maitũ, nake Jehova akĩigua mũgambo witũ, na akĩona mĩtangĩko iitũ, na wĩra mũritũ na ũrĩa twahiinyagĩrĩrio.
8 Nígbà náà ni Olúwa mú wa jáde wá láti Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà, pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá àti iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu.
Nĩ ũndũ ũcio Jehova agĩtũruta bũrũri wa Misiri na guoko gwake kwa hinya, na gũtambũrũkĩtio, akĩhũthĩra maũndũ manene ma kũmakania, na akĩringa ciama, o na agĩĩka maũndũ ma magegania.
9 Ó mú wa wá síbí, ó sì fún wa ní ilẹ̀ yìí, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin;
Nĩatũrehire kũndũ gũkũ na agĩtũhe bũrũri ũyũ, bũrũri ũrĩ bũthi wa iria na ũũkĩ;
10 àti pé ní báyìí, mo mú àkọ́so ilẹ̀ tí ìwọ Olúwa ti fún mi wá.” Ìwọ yóò gbé agbọ̀n náà síwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì wólẹ̀ níwájú u rẹ̀.
na rĩrĩ, nĩndarehe maciaro ma mbere ma tĩĩri ũrĩa, Wee Jehova, ũheete.” Nawe ũkĩige kĩondo kĩu mbere ya Jehova Ngai waku na ũinamĩrĩre mbere yake.
11 Ìwọ àti àwọn ọmọ Lefi àti àjèjì láàrín yín yóò máa yọ̀ nínú gbogbo oore tí Olúwa ti fi fún ọ àti fún àwọn ará ilé rẹ.
Wee mwene, na Alawii, o na andũ a kũngĩ arĩa marĩ thĩinĩ wanyu, nĩmũgakenera maũndũ mothe mega marĩa Jehova Ngai wanyu amũheete na akahe andũ a nyũmba cianyu.
12 Nígbà tí ìwọ bá ṣetán láti ya ìdámẹ́wàá gbogbo ohun tí o ti mú jáde ní ọdún kẹta sọ́tọ̀ sí apá kan. Ọdún ìdámẹ́wàá, ìwọ yóò fi fún ọmọ Lefi, àjèjì, aláìní baba àti opó, kí wọn kí ó lè jẹ ní àwọn ìlú rẹ, kí wọn sì yó.
Rĩrĩa ũgaakorwo ũrĩkĩtie kwamũra gĩcunjĩ gĩa ikũmi kĩa maciaro maku mothe mwaka-inĩ wa gatatũ, mwaka ũcio wa kũrutwo gĩcunjĩ gĩa ikũmi, nĩũgakĩheana kũrĩ Alawii, na kũrĩ mũndũ wa kũngĩ, na kũrĩ mwana wa ngoriai, o na kũrĩ mũtumia wa ndigwa, nĩgeetha marĩe mahũũne marĩ kũu matũũra-inĩ manyu.
13 Nígbà náà ní kí o wí fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Èmi ti mú ohun mímọ́ kúrò nínú ilé mi, èmi sì ti fi fún àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó, gẹ́gẹ́ bí ohun gbogbo tí ìwọ ti pàṣẹ. Èmi kò yípadà kúrò nínú àṣẹ rẹ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbàgbé ọ̀kankan nínú wọn.
Ũcooke wĩre Jehova Ngai waku atĩrĩ, “Nĩndĩkĩtie kũruta gĩcunjĩ kĩrĩa kĩamũre kuuma nyũmba-inĩ yakwa, na nĩ ndĩkĩheanĩte kũrĩ Mũlawii, na kũrĩ mũndũ wa kũngĩ, na kũrĩ mwana wa ngoriai, na kũrĩ mũtumia wa ndigwa o ta ũrĩa wothe wathanĩte. Nditiganĩirie maathani maku o na kana ngariganĩrwo nĩ rĩmwe rĩamo.
14 Èmi kò jẹ lára ohun mímọ́ ní ìgbà tí mo ń ṣọ̀fọ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu nínú wọn ní ìgbà tí mo wà ní àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi nínú wọn fún òkú. Èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run mi, èmi sì ti ṣe gbogbo ohun tí ó pàṣẹ fún mi.
Ndirĩte gĩcunjĩ o na kĩmwe gĩa kĩrĩa kĩamũre hĩndĩ ya macakaya, kana ngeheria o na kĩmwe gĩakĩo rĩrĩa ndaarĩ mũthaahu, o na kana ngarutĩra arĩa akuũ kĩmwe gĩakĩo. Nĩnjathĩkĩire Jehova Ngai wakwa, nĩnjĩkĩte o ta ũrĩa wothe ũnjathĩte.
15 Wo ilẹ̀ láti ọ̀run wá, ibùgbé mímọ́ rẹ, kí o sì bùkún fún àwọn ènìyàn Israẹli, àti fún ilẹ̀ náà tí ìwọ ti fi fún wa, bí ìwọ ti búra fún àwọn baba ńlá wa, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin.”
Kĩrore ũrĩ o kũu igũrũ, o kũu gĩtũũro gĩaku gĩtheru, ũrathime andũ aku a Isiraeli na bũrũri ũyũ ũtũheete o ta ũrĩa werĩire maithe maitũ ma tene na mwĩhĩtwa, bũrũri ũrĩ bũthi wa iria na ũũkĩ.”
16 Olúwa Ọlọ́run rẹ pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa tẹ̀lé àwọn ìlànà àti òfin, kí o sì máa ṣe wọ́n pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo àyà rẹ.
Jehova Ngai waku egũgwatha ũmũthĩ ũrũmagĩrĩre irĩra cia watho wa kũrũmĩrĩrwo, na mawatho; ũmenyerere kũmaathĩkĩra na ngoro yaku yothe na muoyo waku wothe.
17 Ìwọ jẹ́wọ́ Olúwa ní òní pé Olúwa ni Ọlọ́run rẹ, àti pé ìwọ yóò máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, àti pé ìwọ yóò máa pa ìlànà rẹ̀, àṣẹ rẹ̀ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti pé ìwọ yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí i.
Nĩumbũrĩte ũmũthĩ atĩ Jehova nĩwe Ngai waku, na atĩ nĩũrĩthiiaga na njĩra ciake, na nĩũrĩathĩkagĩra irĩra cia watho wake wa kũrũmĩrĩrwo, na maathani make, o na mawatho, na atĩ nĩũrĩmwathĩkagĩra.
18 Ní òní ni Olúwa jẹ́wọ́ rẹ pé ìwọ ni ènìyàn òun, ilé ìṣúra rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí, àti pé ìwọ yóò máa pa gbogbo àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Nake Jehova nĩoimbũrĩte ũmũthĩ atĩ wee ũrĩ rũrĩrĩ rwake, rũrĩrĩ rwa bata mũno o ta ũrĩa eeranĩire, na nĩ ũrĩmenyagĩrĩra maathani make mothe.
19 Òun sì jẹ́wọ́ pé, òun yóò gbé ọ sókè ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí òun ti dá lọ, ní ìyìn, ní òkìkí àti ní ọlá; kí ìwọ kí ó le jẹ́ ènìyàn mímọ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí.
Nĩoimbũrĩte atĩ nĩagagũtũũgĩria, ũgĩe na ngumo na gĩtĩĩo gũkĩra ndũrĩrĩ ciothe iria oombĩte, na nĩũgatuĩka rũrĩrĩ rũtheru kũrĩ Jehova Ngai waku, o ta ũrĩa eeranĩire.

< Deuteronomy 26 >