< Deuteronomy 21 >

1 Tí a bá rí ọkùnrin tí a pa, ní ìdùbúlẹ̀ ní pápá nínú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ láti jogún, tí a kò sì mọ ẹni tí ó pa á,
Om i det land som HERREN, din Gud, vill giva dig till besittning en ihjälslagen människa påträffas liggande på marken, och man icke vet vem som har dödat honom,
2 àwọn àgbàgbà yín yóò jáde lọ láti wọn jíjìnnà ibi òkú sí ìlú tí ó wà nítòsí.
så skola dina äldste och dina domare gå ut och mäta upp avståndet från platsen där den ihjälslagne påträffas till de städer som ligga där runt omkring.
3 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí òkú yóò mú ẹgbọrọ abo màlúù tí kò ì ṣiṣẹ́ rí àti tí kò sì fà nínú àjàgà rí,
Och de äldste i den stad som ligger närmast denna plats skola taga en kviga som icke har blivit begagnad till arbete, och som icke såsom dragare har gått under ok.
4 kí àwọn àgbàgbà ìlú náà kí wọn mú ẹgbọrọ abo màlúù náà sọ̀kalẹ̀ wá sí àfonífojì tí ó ní omi ṣíṣàn kan, tí a kò ro, tí a kò sì gbìn, kí wọn kí ó sì ṣẹ́ ọrùn ẹgbọrọ màlúù náà níbẹ̀ ní àfonífojì náà.
Och de äldste i staden skola föra kvigan ned till en dalgång som icke har varit plöjd eller besådd; och där i dalen skola de krossa nacken på kvigan.
5 Àwọn àlùfáà, ọmọ Lefi yóò wá síwájú, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún un àti láti bùkún ní orúkọ Olúwa àti láti parí gbogbo ẹjọ́ àríyànjiyàn àti ọ̀rọ̀ ìlú.
Och prästerna, Levi söner, skola träda fram, ty dem har HERREN, din Gud, utvalt till att göra tjänst inför honom och till att välsigna i HERRENS namn, och såsom de bestämma skola alla tvister och alla misshandlingsmål behandlas.
6 Nígbà náà ni gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí yóò wẹ ọwọ́ wọn lórí ẹgbọrọ abo màlúù tí a ti kan ọrùn rẹ̀ ní àfonífojì,
Och alla de äldste i den staden, de som bo närmast platsen där den ihjälslagne påträffades, skola två sina händer över kvigan på vilken man hade krossat nacken i dalen;
7 wọn yóò sì sọ pé, “Ọwọ́ wa kò ta ẹ̀jẹ̀ yìí sílẹ̀, tàbí kí ojú wa rí i ní títa sílẹ̀.”
och de skola betyga och säga: "Våra händer hava icke utgjutit detta blod, och våra ögon hava icke sett dådet.
8 Dáríjì, Olúwa, àwọn ènìyàn rẹ ni Israẹli, tí ìwọ ti dá sílẹ̀, àti kí ìwọ má ṣe gba ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ ní àárín àwọn ènìyàn rẹ ní Israẹli. Ṣùgbọ́n kí a dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ yìí jì.
Förlåt ditt folk Israel, som du har förlossat, HERRE, och låt icke oskyldigt blod komma över någon i ditt folk Israel." Så bliver denna blodskuld dem förlåten.
9 Nígbà náà ni ìwọ wẹ̀ kúrò láàrín rẹ ẹ̀bi títa ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí o ti ṣe èyí tí ó tọ́ níwájú Olúwa.
Du skall skaffa bort ifrån dig skulden för det oskyldiga blodet, ty du skall göra vad rätt är i HERRENS ögon.
10 Nígbà tí o bá lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá rẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ tí o sì mú àwọn ìgbèkùn,
Om HERREN, din Gud, när du drager ut i krig mot dina fiender, giver dem i din hand, så att du tager fångar,
11 tí o sì rí obìnrin tí ó dára lára àwọn ìgbèkùn, tí o sì ní ìfẹ́ sí i, o lè mu u gẹ́gẹ́ bí aya à rẹ.
och du då bland fångarna får se någon skön kvinna som du fäster dig vid, och som du vill taga till hustru åt dig,
12 Mú u wá sí ilé e rẹ kí o sì jẹ́ kí ó fá irun orí rẹ̀, gé èékánná an rẹ̀,
så skall du föra henne in i ditt hus, och hon skall raka sitt huvud och ansa sina naglar.
13 kí o sì mú aṣọ tí ó wọ̀ nígbà tí ó di ìgbèkùn sí ẹ̀gbẹ́ kan. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ń gbé ilé rẹ tí ó sì ti ṣọ̀fọ̀ baba àti ìyá rẹ̀ fún odidi oṣù kan, nígbà náà ni o lè tọ̀ ọ́ lọ kí o sì ṣe ọkọ rẹ̀ kí ó jẹ́ aya rẹ.
Och hon skall lägga av de kläder hon bar såsom fånge och skall bo i ditt hus och få begråta sin fader och sin moder en månads tid; därefter må du gå in till henne och äkta henne, så att hon bliver din hustru.
14 Bí inú rẹ̀ kò bá sì dùn sí i, jẹ́ kí ó lọ sí ibikíbi tí ó bá fẹ́. O kò gbọdọ̀ tà á tàbí lò ó bí ẹrú, lẹ́yìn ìgbà tí o ti dójútì í.
Och om du sedan icke mer finner behag i henne, så må du låta henne gå vart hon vill; du får icke sälja henne för penningar. Du får icke heller behandla henne såsom trälinna, då du nu har kränkt henne.
15 Bí ọkùnrin kan bá ní ìyàwó méjì, tí ó sì fẹ́ ọ̀kan ṣùgbọ́n tí kò fẹ́ èkejì, tí àwọn méjèèjì sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un ṣùgbọ́n tí àkọ́bí jẹ́ ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn.
Om en man har två hustrur, en som han älskar och en som han försmår, och båda hava fött honom söner, såväl den han älskar som den han försmår, och hans förstfödde son till den försmådda,
16 Nígbà tí ó bá ń pín ohun ìní rẹ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, kò gbọdọ̀ fi ẹ̀tọ́ àkọ́bí fún ọmọ ìyàwó tí kò fẹ́ràn.
så får mannen icke, när han åt sina söner utskiftar sin egendom såsom arv, giva förstfödslorätten åt sonen till den älskar, till förfång för sonen till den han försmår, då nu denne är den förstfödde,
17 Ó ní láti fi ipò ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn fun un gẹ́gẹ́ bí àkọ́bí i rẹ̀ nípa fífún un ní ìlọ́po ìpín gbogbo ohun tí ó ní. Ọmọ yẹn ni àmì àkọ́kọ́ agbára baba rẹ̀. Ẹ̀tọ́ àkọ́bí jẹ́ tirẹ̀.
utan han skall såsom sin förstfödde erkänna sonen till den försmådda och giva honom dubbel lott av allt vad han äger. Ty denne är förstlingen av hans kraft; honom tillhör förstfödslorätten.
18 Bí ọkùnrin kan bá ní aláìgbọ́ràn tàbí ọlọ̀tẹ̀ ọmọ tí kò gbọ́rọ̀ sí baba àti ìyá rẹ̀ tí kò sì ní í gbà tí wọ́n bá ń bá a wí,
Om någon har en vanartig och uppstudsig son, som icke lyssnar till sin faders och sin moders ord, och som, fastän de tukta honom, ändå icke hör på dem,
19 baba àti ìyá rẹ̀ yóò gbá a mú, wọn yóò mu wá fún àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú u rẹ̀.
så skola hans fader och hans moder taga honom och föra honom ut till de äldste i staden, till stadens port.
20 Wọn yóò sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ọmọ wa yìí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀. Kò ní gbọ́rọ̀ sí wa lẹ́nu. Ọ̀jẹun àti ọ̀mùtípara ni.”
Och de skola säga till de äldste i staden: "Denne vår son är vanartig och uppstudsig och vill icke lyssna till våra ord, utan är en frossare och drinkare."
21 Nígbà náà ni gbogbo ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò sọ ọ́ ní òkúta pa. Ìwọ yóò sì mú ìwà ibi kúrò láàrín yín, gbogbo Israẹli yóò gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n.
Då skall allt folket i staden stena honom till döds: du skall skaffa bort ifrån dig vad ont är. Och hela Israel skall höra det och frukta.
22 Bí ọkùnrin kan tí ó jẹ̀bi ẹ̀sùn bá ní láti kú tí ó sì kú, tí a sì gbé òkú rẹ̀ kọ́ sára igi,
Om på någon vilar en sådan synd som förtjänar döden, och han så bliver dödad och du hänger upp honom på trä,
23 o kò gbọdọ̀ fi òkú rẹ̀ sílẹ̀ sára igi ní gbogbo òru. Gbìyànjú láti sin ín ní ọjọ́ náà gan an, nítorí ẹni tí a bá gbé kọ́ sórí igi wà lábẹ́ ègún Ọlọ́run. Ìwọ kò gbọdọ̀ ba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún jẹ́.
så skall den döda kroppen icke lämnas kvar på träet över natten, utan du skall begrava den på samma dag, ty en Guds förbannelse är den som har blivit upphängd; och du skall icke orena det land som HERREN, din Gud, vill giva dig till arvedel.

< Deuteronomy 21 >