< Deuteronomy 2 >

1 Nígbà náà ni a yípadà, tí a sì mú ọ̀nà wa pọ̀n lọ sí aginjù, a gba ọ̀nà Òkun Pupa, bí Olúwa ti darí mi. Ìgbà pípẹ́ ni a fi ń rìn kiri yíká agbègbè àwọn ìlú olókè Seiri.
Potem zawróciliśmy i wyruszyliśmy na pustynię, drogą w kierunku Morza Czerwonego, tak jak mi PAN powiedział, i przez wiele dni krążyliśmy dokoła góry Seir.
2 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé,
I PAN powiedział do mnie:
3 “Ẹ ti rìn yí agbègbè ilẹ̀ olókè yìí pẹ́ tó, nísinsin yìí, ẹ yípadà sí ìhà àríwá.
Dosyć krążyliście dokoła tej góry. Skierujcie się na północ;
4 Fún àwọn ènìyàn náà ní àwọn òfin wọ̀nyí: ‘Ẹ ti fẹ́ la ilẹ̀ àwọn arákùnrin yín kọjá, àwọn ọmọ Esau; àwọn ará Edomu tí ń gbé ní Seiri. Ẹ̀rù yín yóò bà wọ́n, ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi.
I rozkaż ludowi: Będziecie przechodzić przez granicę waszych braci, synów Ezawa, którzy mieszkają w Seirze. Oni będą się was bać, lecz wy strzeżcie się bardzo.
5 Ẹ má ṣe wá wọn níjà torí pé èmi kò ní fún un yín ní èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn. Bí ó ti wù kí ó kéré mọ èmi kò ní fún un yín. Mo ti fi ilẹ̀ òkè Seiri fún Esau gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.
Nie prowokujcie ich, gdyż nie dam wam ich ziemi nawet na szerokość stopy, bo Ezawowi dałem w posiadanie górę Seir.
6 Ẹ san owó oúnjẹ tí ẹ bá jẹ fún wọn àti omi tí ẹ bá mu.’”
Żywność będziecie kupowali od nich za pieniądze, abyście mieli co jeść; także wodę od nich będziecie kupować za pieniądze, abyście mieli co pić.
7 Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín. Ó ti mójútó ìrìnàjò yín nínú aginjù ńlá yìí. Olúwa Ọlọ́run yín wà pẹ̀lú u yín ní ogójì ọdún wọ̀nyí, dé bi pé ẹ̀yin kò ṣaláìní ohunkóhun.
Gdyż PAN, twój Bóg, błogosławił cię w każdym dziele twoich rąk i znał twoją drogę na tej wielkiej pustyni. Już przez czterdzieści lat PAN, twój Bóg, był z tobą, a niczego ci nie brakowało.
8 Bẹ́ẹ̀ ni a kọjá ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wa, àwọn ọmọ Esau tí ń gbé ní Seiri. A yà kúrò ní ọ̀nà Arabah èyí tí ó wá láti Elati àti Esioni-Geberi, a sì rìn gba ọ̀nà aginjù Moabu.
Ominęliśmy więc naszych braci, synów Ezawa, mieszkających w Seirze, drogą równinną od Elat i od Esjon-Geber, po czym skręciliśmy i udaliśmy się w stronę pustyni Moabu.
9 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ẹ má ṣe dẹ́rùba àwọn ará Moabu bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe bá wọn jagun torí pé n kò ní fi èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn fún un yín. Mo ti fi Ari fún àwọn ọmọ Lọti bí i ìní.”
I PAN powiedział do mnie: Nie napadaj na Moabitów ani nie rozniecaj z nimi wojny, bo nie dam ci ich ziemi w posiadanie; Ar bowiem dałem w posiadanie synom Lota.
10 (Àwọn Emimu ti gbé ibẹ̀ rí, àwọn ènìyàn tó síngbọnlẹ̀ tó sì pọ̀, wọ́n ga bí àwọn Anaki.
Poprzednio mieszkali w niej Emici, lud potężny, liczny i wysoki jak Anakici;
11 Gẹ́gẹ́ bí Anaki àwọn ènìyàn náà pè wọ́n ní ará Refaimu ṣùgbọ́n àwọn ará Moabu pè wọ́n ní Emimu.
Uważano ich też za olbrzymów jak Anakitów, lecz Moabici nazywają ich Emitami.
12 Àwọn ará Hori gbé ní Seiri, kí àwọn ọmọ Esau tó lé wọn kúrò níwájú wọn. Wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn, wọ́n tẹ̀dó sí ààyè wọn gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli tí ṣe ní ilẹ̀ tí Olúwa yóò fún wọn ní ìní wọn.)
Przedtem w Seirze mieszkali również Choryci, ale synowie Ezawa wypędzili ich i wyniszczyli przed sobą, po czym zamieszkali na ich miejscu, jak uczynił Izrael w ziemi swego posiadania, którą dał im PAN.
13 Olúwa sì wí pé, “Ẹ dìde, kí ẹ sì la àfonífojì Seredi kọjá.” Bẹ́ẹ̀ ni a la àfonífojì náà kọjá.
Wstańcie więc i przeprawcie się przez potok Zered. I przeprawiliśmy się przez potok Zered.
14 Ó gbà wá ní ọdún méjìdínlógójì kí ó tó di wí pé a la àfonífojì Seredi kọjá láti ìgbà tí a ti kúrò ní Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà gbogbo ìran àwọn tí ó jẹ́ jagunjagun láàrín àwọn ènìyàn náà ti ṣègbé kúrò láàrín àwọn ènìyàn náà ní àsìkò yìí bí Olúwa ti búra fún wọn.
A czas, który upłynął od naszego wyjścia z Kadesz-Barnea aż do przeprawienia się przez potok Zered, wynosił trzydzieści osiem lat, aż wyginęło z obozu całe pokolenie wojowników, tak jak im to PAN poprzysiągł.
15 Ọwọ́ Olúwa sì wà lòdì sí wọn nítòótọ́, láti run wọn kúrò nínú ibùdó, títí gbogbo wọn fi run tan.
Ręka PANA bowiem zaciążyła nad nimi, aby wyniszczyć ich z obozu, aż wyginęli.
16 Lẹ́yìn tí ẹni tí ó gbẹ̀yìn pátápátá nínú àwọn jagunjagun àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti kú,
A gdy wszyscy wojownicy spośród ludu wyginęli i umarli;
17 Olúwa sọ fún mi pé,
PAN przemówił do mnie:
18 “Lónìí ni ẹ̀yin yóò la agbègbè Moabu kọjá ní Ari.
Dziś przejdziesz przez Ar, granicę Moabu;
19 Bí ẹ bá dé ọ̀dọ̀ àwọn ará Ammoni, ẹ má ṣe halẹ̀ mọ́ wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ bá wọn jagun, torí pé èmi kì yóò fi àwọn ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ará Ammoni fún un yín ní ìní. Mo ti fi fún àwọn ọmọ Lọti ní ìní.”
I zbliżysz się do synów Ammona; nie napadaj na nich i nie rozniecaj z nimi wojny, bo nie dam ci w posiadanie ziemi synów Ammona, dałem ją bowiem w posiadanie synom Lota.
20 (A ka ilẹ̀ yìí sí ilẹ̀ àwọn Refaimu, tí wọ́n ti gbé níbẹ̀ rí, ṣùgbọ́n àwọn ará Ammoni ń pè wọ́n ní ará Samsummimu.
(Także i tę ziemię uważano za ziemię olbrzymów. Olbrzymi mieszkali w niej wcześniej, a Ammonici nazywają ich Zamzummitami;
21 Wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tó lágbára, wọ́n sì pọ̀, wọ́n sì ga gogoro bí àwọn ará Anaki. Olúwa run wọn kúrò níwájú àwọn ará Ammoni, tí wọ́n lé wọn jáde tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.
Lud potężny, liczny i wysoki jak Anakici; lecz PAN wygubił ich przed nimi, a [Ammonici] ich wypędzili i zamieszkali na ich miejscu;
22 Bákan náà ni Olúwa ṣe fún àwọn ọmọ Esau, tí wọ́n ń gbé ní Seiri, nígbà tí ó pa àwọn ará Hori run níwájú wọn. Wọ́n lé wọn jáde wọ́n sì ń gbé ní ilẹ̀ wọn títí di òní.
Podobnie jak uczynił synom Ezawa mieszkającym w Seirze, przed którymi wytracił Chorytów; i wypędzili ich, i zamieszkali na ich miejscu aż do dziś.
23 Nípa ti àwọn ará Affimu, tí wọ́n ń gbé ní àwọn ìlú kéékèèké dé Gasa, àwọn ará Kaftorimu, tí wọ́n jáde láti Krete wá ni ó pa wọ́n run, wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.)
Także Awwitów, którzy mieszkali w Chazerim aż do Gazy, wytracili Kaftoryci, którzy wyszli z Kaftor, i zamieszkali na ich miejscu).
24 “Ẹ gbáradì, kí ẹ sì kọjá odò Arnoni. Kíyèsi, Mo ti fi Sihoni ará Amori, ọba Heṣboni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́. Ẹ bá ilẹ̀ náà jagun kí ẹ sì gbà á.
Wstańcie więc, wyruszcie i przeprawcie się przez rzekę Arnon. Oto daję w twoje ręce Sichona, króla Cheszbonu, Amorytę, oraz jego ziemię. Zacznij ją zajmować i rozpocznij z nim wojnę.
25 Èmi bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìbẹ̀rù àti ìfòyà yín sára gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run láti òní lọ. Wọn yóò gbọ́ ìròyìn in yín, wọn yóò sì wárìrì, wọn yóò sì wà nínú ìdààmú ọkàn torí i tiyín.”
Od dziś zacznę wzbudzać strach i lęk przed tobą wśród narodów, które są pod całym niebem; kiedy usłyszą wieść o tobie, będą drżeć i będą się ciebie lękać.
26 Mo rán àwọn ìránṣẹ́ láti aginjù Kedemoti lọ́ sọ́dọ̀ Sihoni ọba Heṣboni pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àlàáfíà wí pé,
Wysłałem więc posłańców z pustyni Kedemot do Sichona, króla Cheszbonu, ze słowami pokoju:
27 “Jẹ́ kí a la ilẹ̀ ẹ yín kọjá. Àwa yóò gba ti òpópónà nìkan. A kò ní yà sọ́tùn tàbí sósì.
Pozwól mi przejść przez twoją ziemię. Pójdę tylko drogą, nie zboczę ani na prawo, ani na lewo.
28 Ẹ ta oúnjẹ tí a ó jẹ àti omi tí a ó mu fún wa ní iye owó wọn. Kìkì kí ẹ sá à jẹ́ kí a rìn kọjá:
Sprzedasz mi za pieniądze żywność, abym mógł się pożywić; wody także za pieniądze mi dasz, abym pił. Tylko przejdę pieszo;
29 gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Esau tí ó ń gbé ní Seiri àti àwọn ará Moabu tí ó ń gbé ní Ari, ti gbà wá láààyè títí a fi la Jordani já dé ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò fún wa.”
Jak mi to uczynili synowie Ezawa, którzy mieszkają w Seirze, i Moabici, którzy mieszkają w Ar, aż się przeprawię przez Jordan, do ziemi, którą daje nam PAN, nasz Bóg.
30 Ṣùgbọ́n Sihoni ọba Heṣboni kò gbà fún wa láti kọjá. Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti mú ọkàn rẹ̀ yigbì, àyà rẹ̀ sì kún fún agídí kí ó ba à le fi lé e yín lọ́wọ́, bí ó ti ṣe báyìí.
Lecz Sichon, król Cheszbonu, nie pozwolił nam przejść przez swoją [ziemię], gdyż PAN, twój Bóg, zatwardził jego ducha i uczynił jego serce uparte, aby go wydać w twoje ręce, jak to dzisiaj widzisz.
31 Olúwa sì bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kíyèsi i, mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi Sihoni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé e yín lọ́wọ́. Báyìí, ẹ máa ṣẹ́gun rẹ̀, kí ẹ sì gba ilẹ̀ rẹ̀.”
Wtedy PAN powiedział do mnie: Oto zacząłem już wydawać ci Sichona i jego ziemię. Zacznij ją zajmować, abyś odziedziczył jego ziemię.
32 Nígbà tí Sihoni àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde wá láti bá wa jagun ní Jahasi,
Wtedy Sichon wyruszył przeciwko nam, on i cały jego lud, aby zmierzyć się z nami w bitwie w Jahaz;
33 Olúwa Ọlọ́run wa fi lé wa lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ ni a ṣẹ́gun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo ológun rẹ̀.
Lecz PAN, nasz Bóg, wydał go nam i pobiliśmy go, jego synów i cały jego lud.
34 Nígbà náà, gbogbo ìlú wọn ni a kó tí a sì pa wọ́n run pátápátá tọkùnrin, tobìnrin àti gbogbo ọmọ wọn. A kò sì dá ẹnikẹ́ni sí.
I zdobyliśmy w tym czasie wszystkie jego miasta, i zniszczyliśmy doszczętnie we wszystkich miastach mężczyzn, kobiety i dzieci; nie pozostawiliśmy [spośród nich] nikogo.
35 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú tí a ṣẹ́gun fún ara wa.
Tylko bydło zagarnęliśmy dla siebie i łupy z miast, które zdobyliśmy.
36 Láti Aroeri, létí odò Arnoni àti láti àwọn ìlú tí ó wà lẹ́bàá odò náà títí ó fi dé Gileadi, kò sí ìlú tí ó lágbára jù fún wa, Olúwa Ọlọ́run wa fi gbogbo wọn fún wa.
Od Aroeru, leżącego nad brzegiem rzeki Arnon, i od miasta położonego w dolinie aż do Gileadu nie było miasta nie do zdobycia; wszystkie wydał nam PAN, nasz Bóg.
37 Ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa Ọlọ́run wa, ẹ kò súnmọ́ ọ̀kan nínú ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò dé ilẹ̀ tí ó lọ sí Jabbok, tàbí ilẹ̀ tí ó yí àwọn ìlú òkè e nì ká.
Tylko do ziemi synów Ammona nie zbliżyłeś się, do żadnego miejsca na brzegu rzeki Jabbok ani do miast w górach, ani do żadnych miejsc, których PAN, nasz Bóg, nam zabronił.

< Deuteronomy 2 >