< Deuteronomy 1 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
Oto słowa, które Mojżesz wypowiedział do całego Izraela po tej stronie Jordanu na pustyni, na równinie, naprzeciw Morza Czerwonego, pomiędzy Faran, Tofel, Laban, Chaserot a Dizahab.
2 (Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
A jedenaście dni drogi jest od Horebu [przez] górę Seir do Kadesz-Barnea.
3 Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
W czterdziestym roku, jedenastego miesiąca, pierwszego dnia [tego] miesiąca, Mojżesz powiedział synom Izraela to wszystko, co PAN mu dla nich rozkazał.
4 Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
Gdy pobił Sichona, króla Amorytów, który mieszkał w Cheszbonie, i Oga, króla Baszanu, który mieszkał w Asztarot w Edrei;
5 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
Po tej stronie Jordanu, w ziemi Moabu, Mojżesz zaczął objaśniać to prawo:
6 Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
PAN, nasz Bóg, przemówił do nas na Horebie: Dość długo przebywacie na tej górze.
7 Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
Zawróćcie i wyruszcie, a idźcie w stronę góry Amorytów oraz do wszystkich miejsc leżących w jej pobliżu, na równinie, w górach i w dolinie, na południu i na wybrzeżu morza, do ziemi Kanaan i do Libanu, aż do wielkiej rzeki, rzeki Eufrat.
8 Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
Oto położyłem przed wami tę ziemię. Wejdźcie [do niej] i weźcie w posiadanie tę ziemię, którą PAN przysiągł dać waszym ojcom: Abrahamowi, Izaakowi i Jakubowi oraz ich potomstwu po nich.
9 Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
I powiedziałem wam w tamtym czasie: Nie mogę [już] sam was nosić.
10 Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
PAN, wasz Bóg, rozmnożył was, a oto jesteście dziś tak liczni jak gwiazdy na niebie.
11 Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
Niech PAN, Bóg waszych ojców, rozmnoży was jeszcze tysiąckroć i błogosławi wam, tak jak wam obiecał.
12 Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
Jak mogę sam znosić troskę o was, wasz ciężar i wasze spory?
13 Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
Wybierzcie spośród siebie mężczyzn mądrych, rozumnych i doświadczonych w waszych pokoleniach, a ja ustanowię ich waszymi przywódcami.
14 Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
Wtedy odpowiedzieliście mi: Dobra to rzecz, którą nakazałeś uczynić.
15 Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
I wybrałem naczelników z waszych pokoleń, mężczyzn mądrych i doświadczonych, i ustanowiłem ich waszymi zwierzchnikami: przełożonymi nad tysiącami, nad setkami, nad pięćdziesięcioma i nad dziesięcioma oraz urzędnikami dla waszych pokoleń.
16 Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
I rozkazałem waszym sędziom w tym czasie: Wysłuchujcie [spraw] między waszymi braćmi i sądźcie sprawiedliwie pomiędzy [każdym] mężczyzną a jego bratem czy obcym.
17 Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
Nie miejcie względu na osoby w sądzie; wysłuchujcie zarówno małego, jak i wielkiego. Nie bójcie się nikogo, ponieważ jest to sąd Boga. Jeśli sprawa będzie dla was zbyt trudna, przedstawcie ją mnie i ja jej wysłucham.
18 Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
I przykazałem wam w tamtym czasie wszystko, co macie czynić.
19 Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
Potem wyruszyliśmy z Horebu i przeszliśmy przez całą tę wielką i straszną pustynię, którą widzieliście po drodze do góry Amorytów, jak nakazał nam PAN, nasz Bóg, i przyszliśmy aż do Kadesz-Barnea.
20 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
I powiedziałem do was: Przyszliście do góry Amorytów, którą daje nam PAN, nasz Bóg.
21 Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
Oto PAN, twój Bóg, położył przed tobą tę ziemię. Idź i weź ją w posiadanie, jak ci powiedział PAN, Bóg twoich ojców; nie bój się i nie lękaj się.
22 Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
I przyszliście do mnie wszyscy, i tak powiedzieliście: Wyślijmy mężczyzn przed sobą, aby wyszpiegowali nam tę ziemię i zdali nam sprawę o drodze, którą mamy iść, i o miastach, do których mamy wejść.
23 Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
To mi się spodobało, więc wybrałem spośród was dwunastu mężczyzn, po jednym z każdego pokolenia.
24 Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
Oni zaś wyruszyli i weszli na górę, potem dotarli do doliny Eszkol i przebadali ziemię.
25 Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
Zabrali też ze sobą owoc tej ziemi i przynieśli do nas, i zdając nam o tym sprawę, powiedzieli: Ziemia, którą daje nam PAN, nasz Bóg, jest dobra.
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
Lecz nie chcieliście iść i buntowaliście się przeciw nakazowi PANA, swojego Boga.
27 Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
I szemraliście w swoich namiotach, mówiąc: Z nienawiści do nas PAN wyprowadził nas z ziemi Egiptu, aby nas wydać w ręce Amorytów na naszą zgubę.
28 Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
Dokąd pójdziemy? Nasi bracia napełnili nasze serca strachem, gdy mówili: Ten lud jest wyższy i roślejszy od nas, miasta [są] wielkie i obwarowane aż do nieba, a ponadto widzieliśmy tam synów Anakitów.
29 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
Wtedy mówiłem do was: Nie lękajcie się ani nie bójcie się ich.
30 Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
PAN, wasz Bóg, który idzie przed wami, będzie walczyć za was, tak jak wam uczynił w Egipcie na waszych oczach;
31 àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
I na pustyni, gdzie widziałeś, jak PAN, twój Bóg, nosił cię tak, jak ojciec nosi swego syna, przez całą drogę, którą szliście, aż przybyliście na to miejsce.
32 Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
Lecz mimo to nie uwierzyliście PANU, swojemu Bogu;
33 tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
Który szedł przed wami w drodze, wypatrując dla was miejsca do rozbicia obozu, nocą w ogniu, aby wskazać wam drogę, którą macie iść, we dnie zaś w obłoku.
34 Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
A PAN usłyszał głos waszych słów i bardzo się rozgniewał, i przysiągł tymi słowy:
35 “Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
Żaden człowiek z tego złego pokolenia nie zobaczy tej dobrej ziemi, którą przysiągłem dać waszym ojcom;
36 Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
Oprócz Kaleba, syna Jefunnego; on ją zobaczy i jemu dam ziemię, którą stąpał, a także jego synom, gdyż chodził całkowicie za PANEM.
37 Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
Także na mnie rozgniewał się PAN z waszego powodu, mówiąc: Ty również tam nie wejdziesz.
38 ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
Jozue, syn Nuna, który ci służy, on tam wejdzie. Umacniaj go, gdyż on ją poda w dziedzictwo Izraelowi.
39 Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
Także wasze dzieci, o których mówiliście, że staną się łupem, i wasi synowie, którzy w tym dniu nie odróżniali dobra od zła, oni tam wejdą i im ją oddam, a oni ją wezmą w posiadanie;
40 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
A wy zawróćcie i idźcie na pustynię drogą ku Morzu Czerwonemu.
41 Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
Wtedy odpowiedzieliście mi: Zgrzeszyliśmy przeciwko PANU, pójdziemy i będziemy walczyć zgodnie z tym wszystkim, co nakazał nam PAN, nasz Bóg. I każdy z was przypasał sobie broń wojenną i chcieliście wejść na górę.
42 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
I PAN powiedział do mnie: Powiedz im: Nie wstępujcie ani nie walczcie, gdyż nie ma mnie wśród was, abyście nie byli pobici przez swoich wrogów.
43 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
Powiedziałem wam o tym, lecz nie słuchaliście, ale zbuntowaliście się przeciw nakazowi PANA i uparliście się, i weszliście na górę.
44 Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
Wtedy Amoryci, którzy mieszkali na tej górze, wystąpili przeciwko wam i ścigali was, jak to czynią pszczoły, i pobili was w Seirze aż do Chorma.
45 Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
Potem wróciliście i płakaliście przed PANEM; lecz PAN nie wysłuchał waszego głosu i nie nakłonił ku wam swego ucha.
46 Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.
I mieszkaliście w Kadesz przez wiele dni, według [liczby] dni, ile tam mieszkaliście.

< Deuteronomy 1 >