< Daniel 6 >

1 Ó dára lójú Dariusi láti yan ọgọ́fà àwọn baálẹ̀ sórí ìjọba,
Dariuszowi spodobało się ustanowić nad królestwem stu dwudziestu satrapów, którzy byliby po całym królestwie;
2 pẹ̀lú alákòóso mẹ́ta, Daniẹli sì jẹ́ ọ̀kan nínú wọn, kí àwọn baálẹ̀ lè wá máa jẹ́ ààbọ̀ fún wọn, kí ọba má ba à ní ìpalára.
A nad nimi trzech zwierzchników, z których Daniel był pierwszym. Im zdawali sprawozdanie satrapowie, aby król nie doznał żadnej szkody.
3 Daniẹli ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ láàrín àwọn alákòóso àti àwọn baálẹ̀ nítorí ẹ̀mí tí ó tayọ wà lára rẹ̀ dé bi pé ọba sì ń gbèrò láti fi ṣe olórí i gbogbo ìjọba.
A sam Daniel przewyższał tych książąt i satrapów, ponieważ był w nim nadzwyczajny duch, i król zamierzał ustanowić go nad całym królestwem.
4 Nítorí èyí, gbogbo àwọn alákòóso àti àwọn baálẹ̀ ń gbèrò láti wá ẹ̀ṣẹ̀ kà sí Daniẹli lọ́rùn nínú ètò ìṣèjọba rẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan kà sí i lọ́rùn, wọn kò rí ìwà ìbàjẹ́ kankan tí ó ṣe, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ kò sì ní ìwà ìjáfara.
Wtedy zwierzchnicy i satrapowie usiłowali znaleźć przeciwko Danielowi powód [oskarżenia] dotyczący królestwa; nie mogli jednak znaleźć żadnego pretekstu ani wady, ponieważ był on wierny i żadnej winy ani wady nie można było w nim znaleźć.
5 Nígbẹ̀yìn ni àwọn ọkùnrin wọ̀nyí sọ wí pé, “Àwa kò ní rí ìdí kankan láti kà ẹ̀ṣẹ̀ sí Daniẹli lọ́rùn, àfi èyí tí ó bá ní í ṣe pẹ̀lú òfin Ọlọ́run rẹ̀.”
Dlatego ci mężczyźni powiedzieli: Nie znajdziemy przeciwko temu Danielowi żadnego powodu [do oskarżenia], chyba że znajdziemy coś przeciwko niemu w prawie jego Boga.
6 Nígbà náà ni àwọn alákòóso àti àwọn baálẹ̀ lọ gẹ́gẹ́ bí ikọ̀ sí ọ̀dọ̀ ọba, wọ́n wí pé, “Ìwọ Dariusi ọba, kí o pẹ́!
Wtedy ci zwierzchnicy i satrapowie zgromadzili się przy królu i tak mu powiedzieli: Królu Dariuszu, żyj na wieki!
7 Àwọn alákòóso ọba, ìjòyè, baálẹ̀, olùdámọ̀ràn, àti àwọn olórí gbìmọ̀ pọ̀ wí pé kí ọba kéde òfin kan pé ẹnikẹ́ni tí ó bá gba àdúrà sí Ọlọ́run tàbí ènìyàn kankan fún ọgbọ̀n ọjọ́, yàtọ̀ fún ìwọ ọba, a ó ju ẹni náà sí inú ihò kìnnìún.
Wszyscy zwierzchnicy królestwa, przełożeni i satrapowie, urzędnicy i dowódcy uzgodnili, aby ustanowić dekret królewski i zatwierdzić prawo, że ktokolwiek w ciągu trzydziestu dni poprosi o cokolwiek któregokolwiek boga lub człowieka prócz ciebie, królu, zostanie wrzucony do lwiej jamy.
8 Nísinsin yìí, ìwọ ọba, gbé òfin yìí jáde, kí o sì kọ ọ́ sínú ìwé kí a má ba à yí i padà ní ìbámu pẹ̀lú òfin àwọn Media àti Persia, èyí tí kò ní le è parẹ́.”
I tak teraz, królu, zatwierdź to prawo i podaj je na piśmie, aby było nieodwołalne według prawa Medów i Persów, które nie może być cofnięte.
9 Nígbà náà, ni Dariusi ọba fi ọwọ́ sí ìwé àṣẹ náà.
Król Dariusz ogłosił więc na piśmie to prawo.
10 Lóòótọ́, Daniẹli mọ̀ pé a ti fi ọwọ́ sí ìwé òfin náà, síbẹ̀ ó wọ ilé e rẹ̀ lọ, nínú yàrá òkè, ó ṣí fèrèsé èyí tí ó kọjú sí Jerusalẹmu sílẹ̀. Ó kúnlẹ̀ lórí orúnkún un rẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lójoojúmọ́, ó gbàdúrà, ó fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀ tẹ́lẹ̀.
A gdy Daniel dowiedział się, że zostało podane na piśmie, wszedł do swego domu; a otwierając okna w swoim pokoju w stronę Jerozolimy, trzy razy dziennie klękał na kolanach, modlił się i chwalił swego Boga, jak to czynił przedtem.
11 Nígbà náà ni, àwọn ọlọ̀tẹ̀ yìí kó ara wọn jọ, wọ́n sì rí Daniẹli tí ó ń gba àdúrà, ó sì ń bẹ̀bẹ̀ fún àánú lọ́dọ̀ Ọlọ́run.
Wtedy ci mężczyźni zgromadzili się i kiedy znaleźli Daniela modlącego się i błagającego swego Boga;
12 Wọ́n lọ sí iwájú ọba, wọ́n sì rán ọba létí nípa òfin tí ó ṣe pé, “Ìwọ kò ha fi ọwọ́ sí òfin wí pé ní ìwọ̀n ọgbọ̀n ọjọ́ ẹnikẹ́ni tí ó bá gba àdúrà sí Ọlọ́run tàbí ènìyàn, láì bá ṣe ìwọ ọba, a ó gbé e jù sínú ihò kìnnìún?” Ọba sì dáhùn pé, “Àṣẹ náà dúró síbẹ̀, ní ìbámu pẹ̀lú òfin àwọn ará Media àti Persia, èyí tí a kò le è parẹ́.”
Przyszli i powiedzieli królowi o dekrecie królewskim: Czy nie wydałeś dekretu, że każdy człowiek, który w ciągu trzydziestu dni poprosi o cokolwiek któregokolwiek boga lub człowieka prócz ciebie, królu, zostanie wrzucony do lwiej jamy? Król odpowiedział: Prawdziwa to jest mowa, zgodnie z prawem Medów i Persów, które nie może być cofnięte.
13 Nígbà náà, ni wọ́n sọ fún ọba pé, “Daniẹli, ọ̀kan lára ìgbèkùn Juda, kò ka ìwọ ọba sí, tàbí àṣẹ ẹ̀ rẹ tí o fi ọwọ́ sí. Òun sì tún ń gba àdúrà ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lójúmọ́.”
Wtedy odezwali się i powiedzieli do króla: Ten Daniel, który jest z uprowadzonych synów Judy, nie liczy się z tobą, królu, ani z twoim dekretem, który wydałeś, bo trzy razy dziennie odmawia swoją modlitwę.
14 Nígbà tí ọba gbọ́ èyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi; ó pinnu láti kó Daniẹli yọ, títí oòrùn fi rọ̀, ó sa gbogbo ipá a rẹ̀ láti gba Daniẹli sílẹ̀.
Gdy król usłyszał te słowa, bardzo się zasmucił z tego powodu i postanowił wybawić Daniela; aż do zachodu słońca usiłował go uratować.
15 Nígbà náà, ni àwọn ọlọ̀tẹ̀ wọ̀nyí kó ara wọn jọ wá sí ọ̀dọ̀ ọba, wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ ọba rántí pé, ní ìbámu pẹ̀lú òfin àwọn Media àti Persia kò sí àṣẹ tàbí ìkéde tí ọba ṣe tí a le è yí i padà.”
Ale ci mężczyźni zgromadzili się przy królu i powiedzieli do niego: Wiedz, królu, że prawo u Medów i Persów jest takie, że żadne prawo ani [żaden] dekret, który król ustanowił, nie może być zmieniony.
16 Nígbà náà, ni ọba pàṣẹ, wọ́n sì mú Daniẹli, wọ́n sì sọ ọ́ sínú ihò kìnnìún. Ọba sì sọ fún Daniẹli pé, “Kí Ọlọ́run rẹ tí ìwọ ń sìn nígbà gbogbo kí ó gbà ọ́!”
Wtedy król rozkazał, aby przyprowadzono Daniela i wrzucono go do lwiej jamy. A król powiedział do Daniela: Twój Bóg, któremu nieustannie służysz, on wybawi cię.
17 A sì gbé òkúta kan wá, wọ́n sì fi dí ẹnu ihò náà, ọba sì dì í pa pẹ̀lú òrùka èdìdì rẹ̀ àti pẹ̀lú òrùka àwọn ọlọ́lá rẹ̀, nítorí kí a má ṣe yí ohunkóhun padà nítorí i Daniẹli.
I przyniesiono kamień, i położono [go] na otworze jamy, a król opieczętował go swoim sygnetem i sygnetami swoich książąt, aby dekret [wydany] przeciwko Danielowi nie był zmieniony.
18 Nígbà náà ni ọba padà sí ààfin rẹ̀, ó sì lo gbogbo òru náà láì jẹun, kò sì gbọ́ orin kankan, bẹ́ẹ̀ ni kò sì le è sùn ní òru ọjọ́ náà.
Następnie król poszedł do swego pałacu i pościł przez całą noc. Nie dopuścił do siebie niczego, co mogłoby go weselić, i sen odszedł od niego.
19 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù, ni ọba dìde ó sì sáré lọ sí ibi ihò kìnnìún náà.
Potem król wstał bardzo wcześnie, o świcie, i spiesznie poszedł do lwiej jamy.
20 Nígbà tí ó súnmọ́ ibi ihò náà ní ibi tí Daniẹli wà, ó pe Daniẹli pẹ̀lú ìtara pé, “Daniẹli, ìránṣẹ́ Ọlọ́run alààyè, ṣé Ọlọ́run rẹ tí ìwọ ń sìn tọ̀sán tòru, lè gbà ọ́ lọ́wọ́ kìnnìún bí?”
A gdy się zbliżył do jamy, zawołał [do] Daniela żałosnym głosem. Król zapytał Daniela: Danielu, sługo Boga żywego, czy twój Bóg, któremu nieustannie służysz, mógł cię wybawić od lwów?
21 Daniẹli sì dáhùn wí pé, “Ọba kí ẹ pẹ́!
Wtedy Daniel odpowiedział królowi: Królu, żyj na wieki!
22 Ọlọ́run mi rán angẹli i rẹ̀, ó sì dí àwọn kìnnìún lẹ́nu. Wọn kò le è pa mí lára, nítorí a rí mi gẹ́gẹ́ bí aláìlẹ́ṣẹ̀ ní iwájú rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò hu ìwà ìbàjẹ́ kan níwájú rẹ ìwọ ọba.”
Mój Bóg posłał swego Anioła, który zamknął paszcze lwom, aby mi nie wyrządziły żadnej szkody, dlatego że przed nim znalazła się we mnie niewinność. Owszem, również przed tobą, królu, nic złego nie uczyniłem.
23 Inú ọba dùn gidigidi, ó sì pàṣẹ kí a mú Daniẹli jáde wá láti inú ihò. Nígbà tí a mú Daniẹli jáde nínú ihò, kò sí ojú ọgbẹ́ kan ní ara rẹ̀, nítorí tí ó gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run rẹ̀.
Wtedy król bardzo się ucieszył z tego i rozkazał wyciągnąć Daniela z jamy. I wyciągnięto Daniela z jamy i nie znaleziono na nim żadnej rany, bo wierzył w swojego Boga.
24 Ọba pàṣẹ pé, kí a mú àwọn alátakò Daniẹli wá, kí a jù wọ́n sí inú ihò kìnnìún, pẹ̀lú ìyàwó àti àwọn ọmọ wọn. Kí wọn tó dé ìsàlẹ̀ ihò, kìnnìún lágbára lórí i wọn, wọ́n sì fọ́ gbogbo egungun wọn.
I król rozkazał przyprowadzić tych mężczyzn, którzy oskarżyli Daniela, i wrzucono ich do lwiej jamy, ich samych, ich synów i ich żony. A zanim wpadli na dno jamy, lwy ich pochwyciły i zmiażdżyły wszystkie ich kości.
25 Nígbà náà ni Dariusi ọba kọ̀wé sí gbogbo ènìyàn orílẹ̀-èdè, àti gbogbo jákèjádò ilẹ̀ náà: “Kí ìre yín máa pọ̀ sí i!
Wtedy król Dariusz napisał do wszystkich ludzi, narodów i języków, którzy mieszkali po całej ziemi: Niech pokój wam się rozmnoży!
26 “Mo gbé àṣẹ kan jáde wí pé, ní gbogbo agbègbè ìjọba mi, gbogbo ènìyàn gbọdọ̀ bẹ̀rù, kí wọn kí ó sì bọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Daniẹli.
Wydaję dekret, aby w całym państwie mego królestwa [wszyscy] drżeli i bali się Boga Daniela, bo on jest Bogiem żywym i trwa na wieki, a jego królestwo nie będzie zniszczone i jego władza będzie [trwać] do końca.
27 Ó ń yọ ni, ó sì ń gbani là;
On wyrywa i wybawia, czyni znaki i cuda na niebie i na ziemi; on wyrwał Daniela z mocy lwów.
28 Daniẹli sì ṣe rere ní àkókò ìjọba Dariusi àti àkókò ìjọba Kirusi ti Persia.
A Danielowi dobrze się powodziło w królestwie Dariusza i w królestwie Cyrusa Persa.

< Daniel 6 >