< Daniel 11 >

1 Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ará Media, mo dúró láti tì í lẹ́yìn àti láti dáàbò bò ó.)
I KA makahiki mua o Dariu ka Media, ua ku no au iluna e hookupaa a e hooikaika ia ia.
2 “Ní ìsinsin yìí, mo sọ òtítọ́ fún ọ ọba mẹ́ta yóò dìde sí i ní Persia, àti ẹ̀kẹrin tí yóò jẹ́ ọlọ́rọ̀ ju gbogbo wọn lọ. Tí ó bá ti di alágbára nípa ọrọ̀ rẹ̀, yóò sì ru gbogbo wọn sókè lòdì sí ìjọba Giriki.
Ano e hai aku au ia oe i ka mea oiaio. Aia hoi, e ku mai auanei iluna ekolu alii ma Peresia; a o ka ha e oi nui aku kona waiwai mamua o ko lakou a pau; a ma kona ikaika no ka waiwai e hoala oia i na mea a pau e ku e i ke aupuni o Helene.
3 Nígbà náà ni ọba alágbára kan yóò fi ara hàn, yóò ṣe àkóso pẹ̀lú agbára ńlá, yóò sì ṣe bí ó ti wù ú.
E ku mai auanei iluna kekahi alii ikaika loa, e alii ana oia me ka ikaika nui, a e hana no hoi ia mamuli o kona makemake iho.
4 Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá fi ara hàn tán, ìjọba rẹ̀ yóò fọ́, yóò sì pín sí mẹ́rin ní orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé, ìjọba náà kò sì ṣọ́wọ́ àwọn ìran rẹ̀ tàbí kí ó ní agbára tí ó ń lò tẹ́lẹ̀, nítorí, a ó fa ìjọba rẹ̀ tu a ó sì fi fún àwọn mìíràn.
A i kona ku ana iluna e wawahiia kona aupuni, a maheleia ae la ma na makani eha o ka lani; aole ia no kana poe keiki, aole no mamuli o kona aupuni ka mea ana i malama ai; no ka mea, e hoohioloia kona aupuni, no kekahi poe e ae ia, aole no kana.
5 “Ọba ìhà gúúsù yóò di alágbára ṣùgbọ́n ọ̀kan lára àwọn aláṣẹ rẹ̀ yóò di alágbára jù ú lọ, yóò sì ṣe àkóso ìjọba rẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá.
A e lilo ana no ke alii o ke kukulu hema i mea ikaika, a o kekahi alii ona, e oi aku kona ikaika mamua o kela, a e alii ana oia; o kona aupuni he aupuni nui loa ia.
6 Lẹ́yìn ọdún púpọ̀ wọn yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà, ọmọbìnrin ọba gúúsù yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ọba àríwá láti bá a dá májẹ̀mú àlàáfíà, ṣùgbọ́n òun kì yóò lè di agbára apá a rẹ̀ mú, bẹ́ẹ̀ ni òun kì yóò lè dádúró, ṣùgbọ́n a ó tẹrí i rẹ̀ ba àti àwọn tí ó mú un wá, àti ọmọ tí ó bí, àti ẹni tí ó ń mu lọ́kàn le ní gbogbo àkókò wọ̀nyí.
A ma ka hope o na makahiki e kuikahi lakou ia lakou kekahi me kekahi; no ka mea, o hele mai ke kaikamahine a ke alii o ke kukulu hema i ke alii o ke kukulu akau e hookuikahi; aka, aole e mau ia ia ka ikaika o ka lima; aole ia e ku paa, aole kona lima; aka, e haawiia aku oia, a me ka poe nana ia i lawe mai, a me ka mea nana ia i hanau, a me ka mea i hooikaika ia ia ia mau la.
7 “Ọ̀kan lára àwọn ìdílé e rẹ̀, ọmọbìnrin ọba gúúsù yóò dìde láti gba ipò o rẹ̀. Yóò sì kọlu ogun ọba àríwá, yóò sì wó odi alágbára; yóò bá wọn jà yóò sì borí.
Aka, e ku mai auanei kekahi mailoko mai o ka lala o kona kumu ma kona hakahaka, ka mea nana e hele mai me na koa, a e komo hoi iloko o ka hulili o ke alii o ke kukulu akau, a hana ku e no hoi, a lanakila maluna iho;
8 Yóò gba òrìṣà wọn, ère dídá àti ohun èlò oníye lórí ti fàdákà àti ti wúrà, yóò sì kó wọn lọ sí Ejibiti. Fún ọdún díẹ̀ yóò fi ọba àríwá lọ́rùn sílẹ̀.
A lawe pio aku no hoi oia iloko o Aigupita i ko lakou mau akua, a me ko lakou mau kii i hooheheeia, a me ko lakou mau ipu maikai o ke kala a me ke gula; a e oi aku kona mau makahiki mamua o ke alii o ka akau.
9 Nígbà náà, ni ọba àríwá yóò gbógun ti ilẹ̀ ọba, gúúsù, ṣùgbọ́n yóò padà sí Orílẹ̀-èdè, òun fúnra rẹ̀.
Pela e komo mai ke alii o ka hema i ko aupuni, a e hoi hou i kona aina iho.
10 Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò múra ogun wọn yóò kó ogun ńlá jọ, èyí tí a ó gbá lọ bí àgbàrá omi ńlá, yóò sì gbá a lọ títí dé ìlú olódi rẹ̀.
Aka, o kana poe keiki o hoalaia mai lakou, a e hoakoakoa no lakou i na koa he lehulehu; oiaio, kekahi o lakou e hele mai no ia, a e hoohalana, a kahe aku hoi; alaila, e hoi mai ia a hoalaia e ku e aku i kona hulili.
11 “Nígbà náà ni ọba gúúsù yóò jáde pẹ̀lú ìbínú, yóò sì bá ọba àríwá jà, ẹni tí yóò kó ọmọ-ogun púpọ̀ jọ, ṣùgbọ́n ọba gúúsù yóò borí i wọn.
A e huhu ke alii o ke kukulu hema, a e hele mai ia e kaua pu me ia, me ke alii no o ka akau; a e hoomakaukau ia i na kanaka he lehulehu; aka, e haawiia ua poe lehulehu la iloko o kona lima.
12 Nígbà tí a bá kó ogun náà lọ, ọba gúúsù yóò kún fún agbára, yóò sì pa ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní ìpakúpa síbẹ̀ kì yóò ṣẹ́gun.
A i kona lawe ana i ua poe nui la, e hookiekieia kona naau; a e hoohiolo iho oia i na tausani he nui; aole nae ia e lilo i mea ikaika malaila.
13 Nítorí ọba àríwá yóò lọ kó ogun mìíràn jọ, tí ó pọ̀ ju ti àkọ́kọ́ lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún, yóò jáde pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun tí ó ti dira ogun fún dáradára.
No ka mea, e hoi mai auanei ke alii o ke kukulu akau, a e hoomakaukau i kekahi poe nui e oi aku ana i kela poe mamua, a hala kekahi mau makahiki, e hele mai no oia me ka poe koa he lehulehu, a me ka waiwai he nui.
14 “Ní àkókò ìgbà náà, ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò dìde sí ọba gúúsù. Àwọn ọlọ̀tẹ̀ nínú àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò ṣọ̀tẹ̀ ní ìmúṣẹ ìran náà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò borí.
Ia mau manawa he nui ka poe e ku e mai i ke alii o ke kukulu hema; ka poe powa o kou poe kanaka kekahi e hookiekie ia lakou iho e hooko i ka hihio; aka, e haule auanei lakou.
15 Nígbà náà ni ọba àríwá yóò wá yóò sì gbé ogun tì í, yóò sì kó ìlú olódi. Ogun ọba gúúsù kò ní ní agbára láti kọjú ìjà sí i; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọ̀wọ́ ogun tó dára jù kò ní ní agbára láti dúró.
E hele mai ke alii o ke kukulu akau e hana i puu, a e lawe pio i na kulanakauhale paa i ka pa; aole e ku paa na lima o ke kukulu hema, aole hoi kona poe i waeia, aole hoi on a ikaika e ku e ai.
16 Ẹni tí ó gbóguntì í yóò máa ṣe bí ó ti wù ú, kò sì ṣí ẹni tí yóò le è dojúkọ ọ́. Yóò sì fún ara rẹ̀ ní ibùjókòó ní ilẹ̀ tí ó dára, yóò sì ní agbára láti bà á jẹ́.
Aka, o ka mea e hele ku o mai ia ia, e hana no ia mamuli o kona makemake, aole e hiki i kekahi ke ku imua ona; a e ku iho oia ma ka aina hanohano o hoopauia'i e kona lima.
17 Yóò pinnu láti wá pẹ̀lú agbára ìjọba rẹ̀, yóò sì ní májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú ọba gúúsù yóò sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ fún un láti fẹ́ ẹ ní ìyàwó nítorí kí ó lè gba ìjọba, ṣùgbọ́n ète rẹ̀ yìí kì yóò dúró tàbí ṣe ìrànlọ́wọ́ fún un.
A e haka pono kona maka e komo me ka ikaika a pau o kona aupuni, a me ka poe pololei pu me ia; pela no oia e hana'i; e haawi no hoi ia i ke kaikamahine o na wahine, e hoohaumia ana ia ia; aka, aole kela e ku me ia, aole hoi ma kona aoao.
18 Nígbà náà ni yóò yí ara padà sí ilẹ̀ etí Òkun, yóò mú ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n aláṣẹ kan yóò mú òpin bá àfojúdi rẹ̀, yóò sì yí àfojúdi rẹ̀ padà sí orí rẹ̀.
Mahope huli ae la oia i kona maka i na mokununi, a e lawe pio aku i na mea he lehulehu; aka, na kekahi lunakoa e hoopio i kona inaina nona iho: a e hoihoi ia ia i kona inaina maluna iho ona.
19 Lẹ́yìn èyí, yóò sì yí padà sí ìlú olódi ti orílẹ̀-èdè òun fúnra rẹ̀, ṣùgbọ́n yóò kọsẹ̀ yóò sì ṣubú, a kì yóò sì rí i mọ́.
Alaila, e huli ae la ia i kona maka i na hulili o kona aina iho; aka, e okupe auanei ia a hina ilalo, aole hoi e ike hou ia mai.
20 “Arọ́pò rẹ̀ yóò rán agbowó orí kan jáde láti fi ìdí ipò ọlá ọba múlẹ̀ ṣùgbọ́n ní ìwọ̀n ọdún díẹ̀, a ó pa á run, kì yóò jẹ́ nípa ìbínú tàbí nínú ogun.
Alaila, e ku mai iluna ma kona wahi kekahi mea nana e hoouna i ka mea auhau waiwai maluna o ka nani o ia aupuni; aka, aole e hala na la he nui a lukuia oia, aole na ka huhu, aole hoi na ke kaua.
21 “Ẹni tí kò níláárí kan yóò rọ́pò rẹ̀, ẹni tí a kò tí ì fi ọlá ọba fún rí. Yóò sì gbógun sí ìjọba nígbà tí ọkàn àwọn ènìyàn balẹ̀ láìbẹ̀rù, yóò sì gbà á pẹ̀lú àrékérekè.
A e ku mai no iluna ma kona hakahaka kekahi mea ino, aole lakou e haawi ia ia i ka hanohano o ke aupuni; aka, e hele mai oia i ka wa maluhia, a e loaa ia ia ke aupuni ma na olelo malimali.
22 Nígbà náà, ni a ó gbà ogunlọ́gọ̀ ogun kúrò níwájú u rẹ̀, pẹ̀lú òun àti ọmọ-aládé ti májẹ̀mú náà ni a ó parun.
A me ka ikaika o ka waikahe e lukuia'i lakou imua ona, a e haihai liilii ia, oia, o ke alii e kuikahi ana.
23 Lẹ́yìn tí ó wá ṣe ìpinnu pẹ̀lú u rẹ̀, yóò hùwà ẹ̀tàn, pẹ̀lú ìwọ̀nba ènìyàn kékeré ni yóò gba ìjọba.
A mahope o ke kuikahi ana me ia, e hana hoopunipuni oia; no ka mea, e pii oia iluna, a e lilo ia i mea ikaika me ka poe uuku.
24 Nígbà tí àwọn agbègbè tí ó lọ́rọ̀ gidigidi wà láìbẹ̀rù ni yóò gbóguntì wọ́n, yóò ṣe ohun tí baba rẹ̀ tàbí baba ńlá rẹ̀ kò ṣe rí, yóò pín ìkógun ẹrù àti ọrọ̀ fún àwọn ọmọ lẹ́yìn in rẹ̀. Yóò pète àti bi àwọn ìlú olódi ṣubú, ṣùgbọ́n fún ìgbà díẹ̀ ni.
I ka wa maluhia e komo oia maloko o na wahi momona o ka aina; a e hana oia i na mea a kona poe makua i haua ole ai, aole hoi na makua o kona mau makua; e hooleilei wale aku iwaena o lakou i ka waiwai pio a me ka waiwai kailiia, a me ka waiwai maoli; oiaio, e hoomaopopo oia i kona manao e ku e i na wahi paa, a i kekahi manawa.
25 “Pẹ̀lú ogun púpọ̀, yóò sì ru agbára rẹ̀ àti ìgboyà rẹ̀ sókè sí ọba gúúsù. Ọba gúúsù yóò dìde ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ-ogun tí ó lágbára gidigidi, ṣùgbọ́n kò ní le è dúró, nítorí ọ̀tẹ̀ tí ó gbèrò sí i.
A e hoala oia i kona ikaika, me kona naaukoa, a me ke kaua nui e ku e i ke alii o ke kukulu hema; a o ke alii o ke kukulu hema e hoalaia mai no hoi ia me ka poe koa he nui a ikaika loa e kaua; aole nae e hiki ke ku paa; no ka mea, e manao ku e ana lakou ia ia.
26 Àwọn tí ó jẹ nínú oúnjẹ ọba yóò gbìyànjú láti parun, a ó gbá ogun rẹ̀ dànù, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni yóò ṣubú sí ogun.
Oiaio, o ka poe e ai ana i kana ai e luku lakou ia ia; a o ko ia la poe koa e halana lakou; a he nui ka poe e haule i ka pepehiia.
27 Àwọn ọba méjèèjì, ọkàn wọn tẹ̀ sí búburú, wọn yóò jókòó lórí tábìlì kan, wọn yóò máa parọ́ sí ara wọn, ṣùgbọ́n kò ní yọrí sí nǹkan kan nítorí òpin yóò wá ní àsìkò tí a yàn.
A noonoo na naau o ua mau alii elua la ma ke kolohe; a e olelo hoopunipuni no laua ma ka papaaina hookahi; aka, aole no ia e pomaikai ana; no ka mea, no ka manawa i hoopaaia'i ka hopena.
28 Ọba àríwá yóò padà sí ilẹ̀ rẹ̀ pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀, ṣùgbọ́n ọkàn rẹ̀ yóò lòdì sí májẹ̀mú mímọ́, yóò sì ṣiṣẹ́ lòdì sí i, yóò sì padà sí orílẹ̀-èdè òun fúnra rẹ̀.
A i kona hoi ana aku i kona aina me ka waiwai nui; alaila ku e kona naau i ka berita hoano; a e hana aku hoi ia i kona manao, a hoi no i kona aina iho.
29 “Ní àsìkò tí a yàn, yóò gbógun sí gúúsù lẹ́ẹ̀kan sí i, ṣùgbọ́n ní ìgbà yí àyọríṣí yóò yàtọ̀ sí ti ìṣáájú.
I ka manawa i hoopaaia'i e hoi hou mai no ia, a hele no hoi i ke kukuluhema; aka, aole e like me ko ka mua, aole hoi me ko ka hope.
30 Nítorí pé, ọkọ̀ ojú omi àwọn ilẹ̀ etídò ìwọ̀-oòrùn yóò takò ó, ọkàn rẹ̀ yóò sì pami. Nígbà náà, ni yóò padà, yóò sì bínú sí májẹ̀mú mímọ́, yóò sì padà, yóò sì fi ojúrere hàn sí àwọn tí ó kọ májẹ̀mú mímọ́ náà.
No ka mea, e holo ku e mai no na moku no Kitima ia ia; nolaila e kaumaha no, a hoi mai, a e huhu loa aku ia i ka berita hoano; pela no oia e hana'i; a hoi mai no ia, a e kuikahi pu me ka poe i haalele i ua berita hoano la.
31 “Agbára ọmọ-ogun rẹ̀ yóò dìde láti ba ohun mímọ́ ilé olódi tẹmpili jẹ́, yóò sì pa ẹbọ ojoojúmọ́ rẹ́. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ìríra tí ó fa ìsọdahoro kalẹ̀.
A e ku mai auanei na koa ma kona aoao, a e hoohaumia lakou i kahi hoano ikaika, a e hoopau i ka mohai o na la, a e hooku ae lakou i ka mea ino e hooneoneo ai.
32 Pẹ̀lú irú àwọn tí ń ṣe búburú sí májẹ̀mú ní yóò fi ọ̀rọ̀ ìpọ́nni mú ṣọ̀tẹ̀, ṣùgbọ́n, àwọn tí ó mọ Ọlọ́run wọn yóò mú ọkàn le. Wọn yóò sì máa ṣe iṣẹ́ agbára.
A o ka poe hoino aku i ka berita, e hoohuli oia ia lakou mamuli o na olelo malimali; aka, o ka poe i ike pono i ko lakou Akua, e ikaika lakou, a e hana aku no hoi.
33 “Àwọn tí ó mòye yóò máa kọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n fún ìgbà díẹ̀, wọn yóò máa ṣubú nípa idà tàbí kí a jó wọn tàbí ìgbèkùn tàbí nípa ìkógun.
A o ka poe naauao o na kanaka, e ao aku lakou i na mea he nui; aka, e haule auanei lakou i ka pahikaua, a me ka lapalapa ahi, e lawe pio ia, a e hao wale ia lakou i na la he nui.
34 Nígbà tí wọ́n bá ṣubú, wọn yóò rí ìrànlọ́wọ́ díẹ̀, ọ̀pọ̀ àwọn tó ṣe aláìṣòótọ́ yóò sì darapọ̀ mọ́ wọn.
A i ko lakou haule ana, e kokuaia mai lakou he wahi kokua iki no; aka, he nui ka poe e pili ia lakou me na olelo malimali.
35 Lára àwọn tí ó mòye yóò kọsẹ̀, nítorí kí a ba à tún wọn ṣe, wọ́n di mímọ́ àti aláìlábàwọ́n títí di ìgbà ìkẹyìn nítorí yóò sì wá ní àkókò tí a yàn.
A e haule no kekahi poe naauao, i mea e hoao ai ia lakou, a e hoomaemae ai ia lakou, e hookeokeo ai ia lakou, a hiki i ka manawa o ka hopena; no ka mea, aia no ia i ka wa i hoopaaia mai ai.
36 “Ọba yóò ṣe bí ó ti wù ú yóò sì gbé ara rẹ̀ ga, ju gbogbo òrìṣà lọ, yóò máa sọ àwọn ọ̀rọ̀ tí kò-ṣe-é-gbọ́-létí sí Ọlọ́run àwọn Ọlọ́run, yóò sì máa yege títí àkókò ìbínú yóò fi parí, nítorí ohun tí a ti pinnu yóò ṣẹlẹ̀.
A o ke alii e hana no ia mamuli o kona makemake iho; a e hookiekie ia ia iho maluna o na akua a pau, a e olelo i na mea kupaianaha ku e i ke Akua o na akua, a e pomaikai no nae ia a hiki i ka pau ana o ka huhuia mai; no ka mea, o ka mea i hoopaaia mai, e hookoia mai no ia.
37 Òun kò ní ka òrìṣà àwọn baba rẹ̀ sí tàbí èyí tí àwọn fẹ́, òun kò ní ka nǹkan kan sí, ṣùgbọ́n yóò gbé ara rẹ̀ ga ju gbogbo wọn lọ.
Aole oia e malama i ke Akua o kona poe kupuna, aole hoi i ka makemake o na wahine; aole pu hoi oia e malama i kekahi akua, aka, e hookiekie oia ia ia iho maluna o na mea a pau.
38 Ṣùgbọ́n dípò wọn, yóò bu ọlá fún òrìṣà àwọn ìlú olódi: òrìṣà tí àwọn baba rẹ̀ kò mọ̀ ni yóò bu ọlá fún pẹ̀lú wúrà àti fàdákà, pẹ̀lú òkúta iyebíye àti ẹ̀bùn tí ó lówó lórí.
Aka, ma ko ia la hakahaka e hoomana ai oia i ke akua o na pakaua; o ke akua a kona poe kupuna i ike ole ai, oia kana e hoonani ai me ke gula, a me ke kala, a me ka pohaku maikai, a me na mea nani hoi.
39 Yóò kọlu àwọn ìlú olódi tí ó lágbára pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ òrìṣà àjèjì, yóò sì bu ọláńlá fún ẹni tí ó jẹ́wọ́ rẹ̀. Yóò mú wọn ṣe alákòóso lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, yóò sì pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí èrè.
Pela oia e hana ai ma na pakaua no ua akua e la; e hoonani oia i ka poe manaoio aku ia ia, a e hoalii oia ia lakou maluna o na mea he nui loa, a e mahele oia i ka aina i uku.
40 “Ní ìgbà ìkẹyìn, ọba gúúsù yóò gbé ogun de sí i, ọba àríwá yóò sì jáde bí ìjì láti kọlù ú pẹ̀lú u kẹ̀kẹ́ ogun àti ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkọ̀ ojú omi. Yóò gbógun wọ orílẹ̀-èdè púpọ̀, yóò sì bo wọn mọ́lẹ̀ bí ìkún omi.
A i ka wa mahope e pahu aku no ke alii o ka hema ia ia; a e hele mai no hoi ke alii o ka akau me he puahiohio la, e ku e mai ia ia me na kaa kaua, a me na hoohololio, a me na moku he nui loa; a e komo ia iloko o na aina, a e halana e hele aku ma kela aoao.
41 Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì tún gbógun ti ilẹ̀ ológo náà pẹ̀lú, ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò ṣubú, ṣùgbọ́n Edomu, Moabu àti àwọn olórí Ammoni yóò bọ́ lọ́wọ́ rẹ̀.
A e komo no hoi ia iloko o ka aina nani, a e hookahuliia na mea he nui; aka, e hoopakeleia keia mau mea mai kona lima aku, o ko Edoma, a me ko Moaba, a me na pookela o na keiki a Amona.
42 Yóò lo agbára rẹ̀ lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè; Ejibiti kì yóò là.
E o aku hoi oia i kona lima maluna o na aina; aole no hoi e pakele ka aina o Aigupita.
43 Yóò gba àkóso ìṣúra wúrà àti fàdákà àti gbogbo ọrọ̀ Ejibiti, pẹ̀lú ti Libia àti Kuṣi nígbà tí ó mú wọn tẹríba.
Oia no ka mea maluna o na waiwai o ke gula, a me ke kala, a maluna o na mea maikai o Aigupita; a o ka poe Libuana, a me ko Aitiopa, aia lakou ma kona kapuwai.
44 Ṣùgbọ́n ìròyìn láti ìlà-oòrùn àti láti ìwọ̀-oòrùn yóò mú ìdáríjì bá a, yóò sì fi ìbínú ńlá jáde lọ láti parun, àti láti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ run pátápátá.
Aka, no kona lono ana i na olelo mai ka hikina mai, a mai ke kukulu akau mai, e pilikia oia; no ia mea, e hele aku la me ka huhu nui e pepehi aku, a e luku loa aku i na mea he nui wale.
45 Yóò sì pàgọ́ ọ rẹ̀ láàrín Òkun kọjú sí àárín òkè mímọ́ ológo. Síbẹ̀ yóò wá sí òpin rẹ̀, ẹnìkan kò ní ràn án lọ́wọ́.
A e kukulu iho oia i ka halelewa o kona halealii iwaena o na kai a me ka mauna nani hoano; aka, e hiki aku no oia i kona hope, aohe mea nana ia e kokua mai.

< Daniel 11 >