< 2 Samuel 3 >

1 Ogun náà sì pẹ́ títí láàrín ìdílé Saulu àti ìdílé Dafidi: agbára Dafidi sì ń pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n ìdílé Saulu ń rẹ̀yìn sí i.
HE kaua loa no iwaena o ka ohana a Saula a me ka ohana a Davida; aka, mahuahua ae la ko Davida ikaika, a emi iho la ka ohana a Saula a nawaliwali.
2 Dafidi sì bí ọmọkùnrin ní Hebroni: Amnoni ni àkọ́bí rẹ̀ tí Ahinoamu ará Jesreeli bí fún un.
Ua hanau na keikikane na Davida ma Heberona: o Amenona kana hanau mua na Ahinoama no Iezereela;
3 Èkejì rẹ̀ sì ni Kileabu, tí Abigaili aya Nabali ará Karmeli bí fún un; ẹ̀kẹta sì ni Absalomu ọmọ tí Maaka ọmọbìnrin Talmai ọba Geṣuri bí fún un.
A o kana lua, o Kileaba na Abigaila ka wahine a Nabala no Karemela: a o ke kolu, o Abesaloma ke keikikane a Maaka a ke kaikamahine a Talemai ke alii o Gesura;
4 Ẹ̀kẹrin sì ni Adonijah ọmọ Haggiti; àti ẹ̀karùnún ni Ṣefatia ọmọ Abitali;
A o ka ha, e Adoniia ke keikikaue a Hagita; a o ka lima, o Sepatia ke keikikane a Abitala:
5 Ẹ̀kẹfà sì ni Itreamu, tí Egla aya Dafidi bí fún un. Wọ̀nyí ni a bí fún Dafidi ni Hebroni.
A o ke ono, o Itereama na Egela ka wahine a Davida. Ua hanau keia poe na Davida ma Heberona.
6 Ó sì ṣe, nígbà tí ogun wà láàrín ìdílé Saulu àti ìdílé Dafidi, Abneri sì dì alágbára ní ìdílé Saulu.
A i ka wa kaua iwaena o ka ohana a Saula a me ka ohana a Davida, hooikaika loa iho la o Abenera no ka ohana a Saula.
7 Saulu ti ní àlè kan, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Rispa, ọmọbìnrin Aiah: Iṣboṣeti sì bi Abneri léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi wọlé tọ àlè baba mi lọ.”
A ia kekahi haiawahine a Saula, o Rizepa kona inoa, kekahi kaikamahine a Aia. I aku la o Iseboseta ia Abenera, No ke aha la oe i komo aku ai iloko i ka haiawahine a kuu makuakane?
8 Abneri sì bínú gidigidi nítorí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ti Iṣboṣeti sọ fún un, ó sì wí pé, “Èmi jẹ́ bí orí ajá ti Juda bí? Di òní yìí ni mo ṣàánú fún ìdílé Saulu baba rẹ, àti fún àwọn arákùnrin rẹ̀, àti fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, tí èmi kò sì fi ọ́ lé Dafidi lọ́wọ́, ìwọ sì kà ẹ̀ṣẹ̀ sí mí lọ́rùn nítorí obìnrin yìí lónìí?
Alaila, huhu loa o Abenera i na huaolelo a Iseboseta, i aku la, He poo ilio no anei au nana i lokomaikai aku i ka ohana a Saula a kou makuakane, i kona poe hoahanau, a me kona poe makamaka, ma ke ku ee ana i ka Iuda i keia manawa, aole hoi au i haawi aku ia oe maloko o ka lima o Davida, i hoahewa mai ai oe ia'u i neia la no ua wahine nei?
9 Bẹ́ẹ̀ ni kí Ọlọ́run ó ṣe Abneri, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí Olúwa ti búra fún Dafidi, bí èmi kò ní ṣe bẹ́ẹ̀ fún un.
Pela ke Akua e hana mai ai ia Abenera a nui aku, ke hana ole aku au ia Davida e like me ka Iehova i hoohiki aku ai ia ia;
10 Láti mú ìjọba náà kúrò ní ìdílé Saulu, àti láti gbé ìtẹ́ Dafidi kalẹ̀ lórí Israẹli, àti lórí Juda, láti Dani títí ó fi dé Beerṣeba.”
E lawe i ke aupuni mai ka ohana a Saula aku, a e kukulu i ka nohoalii o Davida maluna o ka Iseraela a o ka Iuda, mai Dana a hiki i Beeresaba.
11 Òun kò sì lè dá Abneri lóhùn kan nítorí tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
Aole no i hiki ia ia ke pane olelo hou aku ia Abenera; no ka mea, ua makau kela ia ia.
12 Abneri sì rán àwọn oníṣẹ́ sí Dafidi nítorí rẹ̀ wí pé, “Ti ta ni ilẹ̀ náà ń ṣe? Bá mi ṣe àdéhùn, èmi yóò si kó gbogbo Israẹli tọ̀ ọ́ wá.”
A hoouna mai la o Abenera i na elele io Davida la, i mai la, Nowai anei ka aina? wahi ana, E hookuikahi kaua, eia hoi me oe no kuu lima, e hoohuli aku ai i ka Iseraela a pau i ou la.
13 Òun sì wí pé, “Ó dára, èmi ó bá ọ ṣe àdéhùn, ṣùgbọ́n ohun kan ni èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ, èyí ni pé, ìwọ kì yóò rí ojú mi, àfi bí ìwọ bá kọ́ mú Mikali ọmọbìnrin Saulu wá, nígbà tí ìwọ bá wá, láti rí ojú mi.”
I aku la kela, Pono; e hookuikahi no kaua: hookahi hoi a'u mea e kanoha aku nei ia oe, wahi ana, Aole oe e ike mai i kuu maka, ke lawe ole mai oe mamua ia Mikala ke kaikamahine a Saula, i kou hele ana mai e ike i kuu maka.
14 Dafidi sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Iṣboṣeti ọmọ Saulu pé, “Fi Mikali obìnrin mi lé mi lọ́wọ́, ẹni tí èmi ti fi ọgọ́rùn-ún awọ iwájú orí àwọn Filistini fẹ́.”
Hoouna aku la o Davida i na elele io Iseboseta la ke keiki a Saula, i aku la, E haawi mai oe i ka'u wahine ia Mikala, a'u i kuai ai na'u i na omaka o na Pilisetia he haneri.
15 Iṣboṣeti sì ránṣẹ́, ó sì gbà á lọ́wọ́ ọkùnrin tí a ń pè ní Paltieli ọmọ Laiṣi.
Hoouna aku la o Iseboseta, a lawe ae la ia ia mai ke kane aku o Paletiela ke keiki a Laisa.
16 Ọkọ rẹ̀ sì ń bà a lọ, ó ń rìn, ó sì ń sọkún lẹ́yìn rẹ̀ títí ó fi dé Bahurimu Abneri sì wí fún un pé, “Padà sẹ́yìn!” Òun sì padà.
Hele pu mai la kana kane me ia e uwe ana mahope iho ona, a hiki i Bahurima. Alaila, i aku o Abenera ia ia, O hoi. A hoi aku la ia.
17 Abneri sì bá àwọn àgbàgbà Israẹli sọ̀rọ̀ pé, “Ẹ̀yin ti ń ṣe àfẹ́rí Dafidi ní ìgbà àtijọ́, láti jẹ ọba lórí yín.
Kamailio aku la o Abenera me na lunakahiko o ka Iseraela, i aku la, Ua imi aku oukou ia Davida i na manawa mamua i alii maluna o oukou.
18 Ǹjẹ́ ẹ ṣe, nítorí tí Olúwa ti sọ fún Dafidi pé, ‘Láti ọwọ́ Dafidi ìránṣẹ́ mi lé mi ó gba Israẹli ènìyàn mi là kúrò lọ́wọ́ àwọn Filistini àti lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a wọn.’”
Eia no ka manawa: no ka mea, ua olelo mai o Iehova no Davida, i ka i ana mai, Ma ka lima o ka'u kauwa o Davida e hoola au i ko'u poe kanaka i ka Iseraela, mailoko mai o ka lima o ka poe Pilisetia, a mailoko mai hoi o ka lima o ko lakou poe enemi a pau.
19 Abneri sì sọ̀rọ̀ létí Benjamini: Abneri sì lọ sọ létí Dafidi ní Hebroni, gbogbo èyí tí ó dára lójú Israẹli, àti lójú gbogbo ilé Benjamini.
Olelo aku la hoi o Abenera maloko o na pepeiao o ka Beniamina: hele aku la hoi o Abenera e hai aku maloko o na pepeiao o Davida ma Heberona i na mea a pau a ka Iseraela i makemake ai, a me na mea a pau i makemake ai ka Beniamina.
20 Abneri sì tọ Dafidi wá ní Hebroni, ogún ọmọkùnrin sì lọ pẹ̀lú rẹ̀ Dafidi sì ṣe àsè fún Abneri àti fún àwọn ọmọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀.
A hiki aku la o Abenera i Heberona io Davida la, oia me na kanaka he iwakalua. Hana iho la o Davida i ahaaina na Abenera a na ka poe kanaka me ia.
21 Abneri sì wí fún Dafidi pé, “Èmi ó dìde, èmi ó sì lọ, èmi ó sì kó gbogbo Israẹli jọ sọ́dọ̀ ọba olúwa mi, wọn ó sì bá a ṣe àdéhùn, ìwọ ó sì jẹ ọba gbogbo wọn bí ọkàn rẹ ti ń fẹ́.” Dafidi sì rán Abneri lọ; òun sì lọ ní àlàáfíà.
I aku la o Abenera ia Davida, E ku ae au a hele aku e houluulu i ka Iseraela a pau i kuu haku i ke alii, i hana lakou i berita me oe, i nohoalii hoi oe maluna o na mea a pau a kou naau e makemake nei. Hoihoi aku la o Davida ia Abenera, a hele aku la ia me ka maluhia.
22 Sì wò ó, àwọn ìránṣẹ́ Dafidi àti Joabu sì ti ibi ìlépa ẹgbẹ́ ogun kan bọ̀, wọ́n sì mú ìkógun púpọ̀ bọ̀; ṣùgbọ́n Abneri kò sí lọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni; nítorí tí òun ti rán an lọ, òun sì ti lọ ní àlàáfíà.
Aia hoi, hele mai la na kanaka o Davida me Ioaba mai ke kaua mai, a lawe pu mai la me lakou i ka waiwai pio he nui: aole hoi o Abenera me Davida i Heberona; no ka mea, ua hoihoi kela ia ia, a ua hele aku ia me ka maluhia.
23 Nígbà tí Joabu àti gbogbo ogun tí ó pẹ̀lú rẹ̀ sì dé, wọ́n sì sọ fún Joabu pé Abneri, ọmọ Neri ti tọ ọba wá, òun sì ti rán an lọ, ó sì ti lọ ní àlàáfíà.
A hiki mai la o Ioaba a me ka poe kaua a pau pu me ia, hai mai la lakou ia Ioaba, i ka i ana mai, I hele mai nei o Abenera ke keiki a Nera i ke alii, a ua hoihoi aku kela ia ia, a ua hala aku ia me ka maluhia.
24 Joabu sì tọ ọba wá, ó sì sọ pé, “Kí ni ìwọ ṣe yìí? Wò ó, Abneri tọ̀ ọ́ wá; èéha ti ṣe tí ìwọ sì fi rán an lọ? Òun sì ti lọ.
Alaila, hele aku la o Ioaba i ke alii, i aku la, Heaha kau i hana'i? Aia hoi, ua hele mai nei o Abenera; heaha hoi kau i hoihoi aku ai ia ia, a ua hala loa kela?
25 Ìwọ mọ Abneri ọmọ Neri, pé ó wá láti tàn ọ́ jẹ ni, àti láti mọ ìjáde lọ rẹ, àti wíwọlé rẹ́ àti láti mọ gbogbo èyí tí ìwọ ń ṣe.”
Ua ike oe ia Abenera ke keiki a Nera, i hele mai nei ia e hoopunipuni ia oe, a e ike i kou hele ana aku a me kou hoi ana mai, a o ike hoi i ua mea a pau au e hana nei.
26 Nígbà tí Joabu sì jáde kúrò lọ́dọ̀ Dafidi, ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ láti lépa Abneri, wọ́n sì pè é padà láti ibi kànga Sira, Dafidi kò sì mọ̀.
A hoi mai o Ioaba iwaho, mai o Davida mai, kena aku la ia i na kanaka e kii ia Abenera, na lakou ia i hoihoi mai, mai ka punawai mai o Sira: aole hoi i ike o Davida.
27 Abneri sì padà sí Hebroni, Joabu sì bá a tẹ̀ láàrín ojú ọ̀nà láti bá a sọ̀rọ̀ ní àlàáfíà, ó sì gún un níbẹ̀ lábẹ́ inú, ó sì kú, nítorí ẹ̀jẹ̀ Asaheli arákùnrin rẹ̀.
A hoi hou mai la o Abenera i Heberona, kono aku la o Ioaba ia ia iwaena o ka ipuka e olelo malie aku ia ia, ilaila kela i hou aku ai ia ia malalo iho o ka lima o ka iwiaoao, a make iho la ia, no ke koko o Asahela o kona kaikaina.
28 Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi sì gbọ́ ọ, ó sì wí pé, “Èmi àti ìjọba mi sì jẹ́ aláìlẹ́bi níwájú Olúwa títí láé, ní ti ẹ̀jẹ̀ Abneri ọmọ Neri,
Mahope iho, a lohe ae la o Davida, i aku la ia, Imua o Iehova ua hala ole mau loa au a me kuu aupuni i ke koko o Abenera ke keiki a Nera.
29 jẹ́ kí ó wà ní orí Joabu, àti ní orí gbogbo ìdílé baba rẹ̀; kí a má sì fẹ́ ẹni ó tí ní ààrùn ìsun, tàbí adẹ́tẹ̀, tàbí ẹni tí ń tẹ ọ̀pá, tàbí ẹni tí a ó fi idà pa, tàbí ẹni tí ó ṣe aláìní oúnjẹ kù ní ilé Joabu.”
E kau aku no ia maluna o ke poo o Ioaba, maluna hoi o ka ohana a pau o kona makuakane; aole hoi e nelo kekahi o ka ohana a Ioaba i ka mai puha, a i ka lepera paha, a i ke kanikookoo paha, a i ka haule paha maluna o ka pahikaua, a i ka ai ole paha.
30 (Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì pa Abneri, nítorí pé òun ti pa Asaheli arákùnrin wọn ní Gibeoni ní ogun.)
Pela o Ioaba me Abisai kona kaikaina i pepehi ai ia Abenera; no ka mea, ua pepehi iho oia i ko laua kaikaina ia Asahela i ke kaua ana ma Gibeona.
31 Dafidi sì wí fún Joabu àti fún gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ fa aṣọ yín ya, kí ẹ̀yin sì mú aṣọ ọ̀fọ̀, kí ẹ̀yin sì sọkún níwájú Abneri.” Dafidi ọba tìkára rẹ̀ sì tẹ̀lé pósí rẹ̀.
Olelo aku la o Davida ia Ioaba a me ka poe a pau me ia, E haehae iho i ko oukou kapa, a e kaei oukou i ke kapa inoino, a e kanikau imua o Abenera. A o ke alii o Davida i hele mahope o ka manele.
32 Wọ́n sì sin Abneri ní Hebroni, ọba sì gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì sọkún ní ibojì Abneri; gbogbo àwọn ènìyàn náà sì sọkún.
Kanu iho la lakou ia Abenera ma Heberona: hookiekie ae la ke alii i kona leo iluna ma ka hale kupapau o Abenera, a uwe iho la na kanaka a pau.
33 Ọba sì sọkún lórí Abneri, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ Abneri ó yẹ kí ó kú bí aṣiwèrè?
Kanikau iho la ke alii maluna o Abenera, i aku la, Ua make no anei o Abenera e like me ka make o ka naaupo?
34 A kò sá à dè ọ́ lọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò kan ẹsẹ̀ rẹ ní àbà. Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ń ṣubú níwájú àwọn ìkà ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ ṣubú.” Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì tún sọkún lórí rẹ̀.
Aole i nakiikiiia kou mau lima, aole hoi i paa na wawae i ka hao; me ka haule ana o kekahi imua o na kanaka hewa, pela no oe i haule iho ai. Uwe hou iho la na kanaka a pau maluna ona.
35 Nígbà tí gbogbo ènìyàn sì wá láti gba Dafidi ní ìyànjú kí ó jẹun, nígbà tí ọjọ́ sì ń bẹ, Dafidi sì búra wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni kí Ọlọ́run ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, bí èmi yóò bá tọ́ oúnjẹ wò, tàbí nǹkan mìíràn títí oòrùn yóò fi wọ̀!”
A hele mai na kanaka a pau e koi aku ia Davida e ai i ka ai oiai ka la: hoohiki aku la Davida, i aku la, Pela ke Aku a e hana mai ai ia'u a nui aku, ke hoao iho au i ka berena a i kekahi mea e ae, a napoo ka la.
36 Gbogbo àwọn ènìyàn sì kíyèsi i, ó sì dára lójú wọn, gbogbo èyí tí ọba ṣe sì dára lójú gbogbo àwọn ènìyàn náà.
Nana aku la na kanaka a pau, a ua oluolu lakou ia mea: no ka mea, ma na mea a pau a ke alii i hana'i, ua oluolu na kanaka a pau ilaila.
37 Gbogbo àwọn ènìyàn náà àti gbogbo Israẹli sì mọ̀ lọ́jọ́ náà pé, kì í ṣe ìfẹ́ ọba láti pa Abneri ọmọ Neri.
No ka mea, ua ike na kanaka a pau, a me ka Iseraela a pau ia la, aole no ke alii ka pepehi ia Abenera ke keiki a Nera.
38 Ọba sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin kò mọ̀ pé olórí àti ẹni ńlá kan ni ó ṣubú lónìí ní Israẹli.
Olelo aku la ke alii i kana poe kauwa, Aole anei oukou i ike, he kanaka nui i haule i neia la iwaena o ka Iseraela.
39 Èmi sì ṣe aláìlágbára lónìí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi èmi jẹ ọba; àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ọmọ Seruiah sì le jù mí lọ: Olúwa ni yóò san án fún ẹni tí ó ṣe ibi gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀!”
Ano hoi, ua nawaliwali au i poniia i alii; a o keia mau kanaka na keiki a Zeruia, ua oi aku ko laua koikoi i ko'u: e hoouku mai no nae o Iehova i ka mea hana ino e like me koua hewa.

< 2 Samuel 3 >