< 2 Samuel 22 >

1 Dafidi sì kọ ọ̀rọ̀ orin yìí sí Olúwa ní ọjọ́ tí Olúwa gbà á kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ Saulu.
Un Dāvids runāja Tā Kunga priekšā šīs dziesmas vārdus tai dienā, kad Tas Kungs viņu bija atpestījis no visu viņa ienaidnieku rokas un no Saula rokas; un viņš sacīja:
2 Ó sì wí pé, “Olúwa ni àpáta mi, àti Olùgbàlà mi;
Tas Kungs ir mans akmens kalns un mana pils un mans glābējs.
3 Ọlọ́run mi, àpáta mi, nínú ẹni tí èmi ní ààbò, àti ìwo ìgbàlà mi, ibi ìsádi gíga mi. Àti ibi ìlùmọ̀ mi, Olùgbàlà mi; ìwọ ni ó ti gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwà ipá.
Dievs ir mans patvērums, uz ko es paļaujos, manas priekšturamās bruņas un manas pestīšanas rags, mans augstais palīgs, un mana glābšana, mans Pestītājs, kas mani no varas darba atpestī.
4 “Èmi ké pe Olúwa, tí ó yẹ láti máa yìn, ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.
Es piesaukšu To Kungu, kas teicams, tad es tapšu atpestīts no saviem ienaidniekiem.
5 Nígbà tí ìbìlù ìrora ikú yí mi káàkiri; tí àwọn ìṣàn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
Jo nāves viļņi mani apņēma un posta upes mani izbiedēja,
6 Ọ̀já isà òkú yí mi káàkiri; ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí. (Sheol h7585)
Elles saites mani apņēma, un nāves valgi mani pārvarēja. (Sheol h7585)
7 “Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa, èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi. Ó sí gbóhùn mi láti tẹmpili rẹ̀ igbe mí wọ etí rẹ̀.
Savās bēdās es piesaucu To Kungu, es piesaucu savu Dievu; tad Viņš klausīja manu balsi no Sava nama, un mana brēkšana nāca Viņa ausīs.
8 Ilẹ̀ sì mì, ó sì wárìrì; ìpìlẹ̀ ọ̀run wárìrì, ó sì mì, nítorí tí ó bínú.
Zeme tapa kustināta un drebēja, un debesu stiprumi kustējās un trīcēja, kad Viņš apskaitās.
9 Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá, iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá, ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
Dūmi uzkāpa no Viņa nāsīm un rijoša uguns no Viņa mutes, zibeņi no Viņa iedegās.
10 Ó tẹ orí ọ̀run ba pẹ̀lú, ó sì sọ̀kalẹ̀; òkùnkùn biribiri sì ń bẹ ní àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
Viņš nolaida debesis un nokāpa, un tumsa bija apakš Viņa kājām.
11 Ó sì gun orí kérúbù, ó sì fò, a sì rí i lórí ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
Un Viņš brauca uz ķeruba un skrēja, un parādījās uz vēja spārniem.
12 Ó sì fi òkùnkùn ṣe ibùjókòó yí ara rẹ̀, àti àgbájọ omi, àní ìṣúdudu ìkùùkuu àwọ̀ sánmọ̀.
Viņš lika tumsu ap Sevi par telti, un melnus ūdeņus un biezus mākoņus.
13 Nípasẹ̀ ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀ ẹ̀yín iná ràn.
No spožuma Viņa priekšā iedegās ugunīgi zibeņi.
14 Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá, Ọ̀gá-ògo jùlọ sì fọhùn rẹ̀.
Tas Kungs lika pērkoniem rībēt no debesīm, un tas Visuaugstais pacēla Savu balsi.
15 Ó sì ta ọfà, ó sì tú wọn ká; ó kọ mànàmànà, ó sì ṣẹ́ wọn.
Un Viņš meta bultas un tos izklīdināja, Viņš meta zibeņus un tos iztrūcināja.
16 Ìṣàn ibú òkun sì fi ara hàn, ìpìlẹ̀ ayé fi ara hàn, nípa ìbáwí Olúwa, nípa fífún èémí ihò imú rẹ̀.
Jūras dibeni rādījās, zemes pamati tapa atklāti no Tā Kunga bāršanas, no Viņa nāšu dvašas pūšanas.
17 “Ó ránṣẹ́ láti òkè wá, ó mú mi; ó fà mí jáde láti inú omi ńlá wá.
Viņš izstiepa (roku) no augstības un satvēra mani, Viņš mani izvilka no lieliem ūdeņiem.
18 Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára, lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, nítorí pé wọ́n lágbára jù mí lọ.
Viņš mani atpestīja no mana stiprā ienaidnieka un no maniem nīdētājiem, jo tie bija jo varenāki nekā es.
19 Wọ́n wá láti borí mi lọ́jọ́ ìpọ́njú mi, ṣùgbọ́n Olúwa ni aláfẹ̀yìntì mi.
Tie cēlās pret mani manā bēdu laikā; bet Tas Kungs bija mans patvērums.
20 Ó sì mú mi wá sí ààyè ńlá, ó gbà mi, nítorí tí inú rẹ̀ dún sí mi.
Un Viņš mani izveda klajumā, Viņš mani izrāva, jo Viņam bija labs prāts uz mani.
21 “Olúwa sán án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi; ó sì san án fún mi gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi.
Tas Kungs man atmaksā pēc manas taisnības, Viņš man atlīdzina pēc manu roku šķīstības.
22 Nítorí pé èmi pa ọ̀nà Olúwa mọ́, èmi kò sì fi ìwà búburú yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.
Jo es sargāju Tā Kunga ceļus, un neesmu atkāpies no sava Dieva.
23 Nítorí pé gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ ni ó wà níwájú mi; àti ní ti òfin rẹ̀, èmi kò sì yapa kúrò nínú wọn.
Jo visas Viņa tiesas ir manā priekšā, un Viņa likumus es nelieku nost no sevis.
24 Èmi sì wà nínú ìwà títọ́ sí í, èmi sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Bet es biju bezvainīgs Viņa priekšā un sargājos noziegties.
25 Olúwa sì san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà mímọ́ mi níwájú rẹ̀.
Un Tas Kungs man atlīdzina pēc manas taisnības, pēc manas šķīstības priekš Viņa acīm.
26 “Fún aláàánú ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ni aláàánú, àti fún ẹni ìdúró ṣinṣin ní òdodo ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní ìdúró ṣinṣin ní òdodo.
Pie tiem svētiem Tu rādies svēts, un pie tiem sirdsskaidriem vīriem Tu rādies skaidrs.
27 Fún onínú funfun ni ìwọ fi ara rẹ hàn ní funfun; àti fún ẹni wíwọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní wíwọ́.
Pie tiem šķīstiem Tu rādies šķīsts, un pie tiem pārvērstiem (un pretdabiskiem) Tu pārvērties (un maldini).
28 Àwọn ènìyàn tí ó wà nínú ìyà ni ìwọ ó sì gbàlà; ṣùgbọ́n ojú rẹ wà lára àwọn agbéraga, láti rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Jo bēdīgus ļaudis Tu atpestī, un Tavas acis ir pret tiem lepniem, tos pazemot.
29 Nítorí ìwọ ni ìmọ́lẹ̀ mi, Olúwa; Olúwa yóò sì sọ òkùnkùn mi di ìmọ́lẹ̀.
Jo Tu Kungs esi mans spīdeklis. Tas Kungs dara manu tumsību gaišu.
30 Bẹ́ẹ̀ ni nítorí nípa rẹ̀ ni èmi ti la àárín ogun kọjá; nípa Ọlọ́run mi èmi ti fo odi kan.
Jo ar Tevi es varu sadauzīt karaspēku, ar savu Dievu es varu lēkt pār mūriem.
31 “Ọlọ́run yìí, pípé ni ọ̀nà rẹ̀; ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ti dánwò. Òun sì ni asà fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e.
Tā stiprā Dieva ceļš ir bezvainīgs, Tā Kunga valoda ir šķīsta, Viņš ir par priekšturamām bruņām visiem, kas uz Viņu paļaujas.
32 Nítorí ta ni Ọlọ́run, bí kò ṣe Olúwa? Ta ni àpáta, bí kò ṣe Ọlọ́run wa.
Jo kur ir kāds Dievs, kā vien Tas Kungs? Un kur ir kāds patvērums, kā vien mūsu Dievs?
33 Ọlọ́run alágbára ni ó fún mi ní agbára, ó sì sọ ọ̀nà mi di títọ́.
Tas stiprais Dievs ir mans varenais patvērums, un Viņš vada to taisno pa Savu ceļu.
34 Ó ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín; ó sì mú mi dúró ní ibi gíga mi.
Viņš man kājas dara kā stirnām, un mani uzceļ manā augstā vietā.
35 Ó kọ́ ọwọ́ mi ní ogun jíjà; tó bẹ́ẹ̀ tí apá mi fa ọrun idẹ.
Viņš manas rokas māca karot, ka mans elkonis uzvelk vara stopus.
36 Ìwọ sì ti fún mi ní asà ìgbàlà rẹ̀; ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ sì ti sọ mí di ńlá.
Un Tu man dod Savas pestīšanas priekšturamās bruņas, un Tava laipnība mani paaugstina.
37 Ìwọ sì sọ ìtẹ̀lẹ̀ di ńlá ní abẹ́ mi; tó bẹ́ẹ̀ tí ẹsẹ̀ mi kò fi yọ̀.
Maniem soļiem Tu esi darījis platu ceļu apakš manis, ka mani krimšļi nav slīdējuši.
38 “Èmi ti lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì ti run wọ́n, èmi kò pẹ̀yìndà títí èmi fi run wọ́n.
Es dzīšos pakaļ saviem ienaidniekiem, un tos iznīcināšu un negriezīšos atpakaļ, kamēr tos nebūšu izdeldējis.
39 Èmi ti pa wọ́n run, èmi sì ti fọ́ wọn, wọn kò sì le dìde mọ́, wọ́n ṣubú lábẹ́ mi.
Es tos izdeldēšu un tos satriekšu, ka tie nevarēs celties, tiem jākrīt apakš manām kājām.
40 Ìwọ sì ti fi agbára dì mí ní àmùrè fún ìjà; àwọn tí ó ti dìde sí mi ni ìwọ sì ti tẹ̀ lórí ba fún mi.
Jo Tu mani apjozīsi ar spēku uz karu, Tu nospiedīsi apakš manis, kas pret mani ceļas.
41 Ìwọ sì mú àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà fún mi, èmi ó sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
Tu maniem ienaidniekiem liksi bēgt manā priekšā un savus nīdētājus es iznīcināšu.
42 Wọ́n wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti gbà wọ́n; wọ́n wo Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá àwọn lóhùn.
Tie skatās visapkārt, bet glābēja nav, - uz To Kungu, bet Viņš tiem neatbild.
43 Nígbà náà ni èmi sì gún wọn wẹ́wẹ́ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, èmi sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ ìta, èmi sì tẹ́ wọn gbọrọ.
Es tos sagrūdīšu kā zemes pīšļus, es tos samīšu un izkaisīšu kā dubļus uz ielām.
44 “Ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìjà àwọn ènìyàn mi, ìwọ pa mi mọ́ ki èmi lè ṣe olórí àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè. Àwọn ènìyàn tí èmi kò tí mọ̀ yóò máa sìn mí.
Tu mani izglābi no manu ļaužu ķildām, Tu mani lieci par galvu tautām: ļaudis, ko es nepazinu, man kalpo.
45 Àwọn àjèjì wá láti tẹríba fún mi; bí wọ́n bá ti gbúròó mi, wọ́n á sì gbọ́ tèmi.
Svešinieku bērni mīlīgi izrādās manā priekšā; kad viņu auss dzird, tad tie man paklausa.
46 Àyà yóò pá àwọn àlejò, wọ́n ó sì fi ìbẹ̀rù sá kúrò níbi kọ́lọ́fín wọn.
Svešinieku bērni nonīkst un drebēdami iziet no savām pilīm.
47 “Olúwa ń bẹ́; olùbùkún sì ni àpáta mi! Gbígbéga sì ni Ọlọ́run àpáta ìgbàlà mi.
Tas Kungs ir dzīvs, un slavēts lai ir mans Patvērums, un augsti slavēts lai ir Dievs, manas pestīšanas Klints,
48 Ọlọ́run ni ẹni tí ń gbẹ̀san mi, àti ẹni tí ń rẹ àwọn ènìyàn sílẹ̀ lábẹ́ mi.
Tas stiprais Dievs, kas man dod atriebšanu, un tautas nomet apakš manis,
49 Àti ẹni tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi. Ìwọ sì gbé mi sókè ju àwọn tí ó kórìíra mi lọ; ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin oníwà ipá.
Un kas mani izvada no maniem ienaidniekiem. Un Tu mani paaugstini pār tiem, kas pret mani cēlās, no tiem varas darītājiem Tu mani izglābi.
50 Nítorí náà èmi ó fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa, láàrín àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè, èmi ó sì kọrin sí orúkọ rẹ.
Tāpēc es Tevi, Kungs, slavēšu starp tautām un dziedāšu Tavam vārdam.
51 “Òun ni ilé ìṣọ́ ìgbàlà fún ọba rẹ̀; ó sì fi àánú hàn fún ẹni àmì òróró rẹ̀, fún Dafidi, àti fún irú-ọmọ rẹ̀ títí láéláé.”
Viņš Savam ķēniņam parāda lielu pestīšanu un dara labu Savam svaidītam Dāvidam un viņa dzimumam mūžīgi.

< 2 Samuel 22 >