< 2 Samuel 16 >

1 Nígbà tí Dafidi sì fi díẹ̀ kọjá orí òkè náà, sì wò ó, Ṣiba ìránṣẹ́ Mefiboṣeti sì ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, òun àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì tí a ti dì ní gàárì, àti igba ìṣù àkàrà lórí wọn, àti ọgọ́rùn-ún síírí àjàrà gbígbẹ, àti ọgọ́rùn-ún èso ẹ̀rún, àti ìgò ọtí wáìnì kan.
När David hade gått framåt ett litet stycke från bergstoppen, då mötte honom Siba, Mefibosets tjänare, med ett par lastade åsnor, som buro två hundra bröd, ett hundra russinkakor, ett hundra fruktkakor och en vinlägel.
2 Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Kí ni wọ̀nyí?” Ṣiba sì wí pé, “Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ̀nyí ni fún àwọn ará ilé ọba láti máa gùn àti àkàrà yìí, àti èso ẹ̀rún yìí ni fún àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin láti jẹ; àti ọtí wáìnì yìí ni fún àwọn aláàárẹ̀ ní ijù láti mu.”
Då sade konungen till Siba: "Vad vill du med detta?" Siba svarade: "Åsnorna skola vara för konungens husfolk till att rida på, brödet och fruktkakorna skola tjänarna hava att äta, och vinet skola de törstande hava att dricka i öknen."
3 Ọba sì wí pé, “Ọmọ olúwa rẹ dà?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, ó jókòó ní Jerusalẹmu; nítorí tí ó wí pé, ‘Lónìí ni ìdílé Israẹli yóò mú ìjọba baba mi padà wá fún mi.’”
Konungen sade: "Men var är din herres son?" Siba svarade konungen: "Han är kvar i Jerusalem; ty han tänkte: 'Nu skall Israels hus giva mig tillbaka min faders rike.'"
4 Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Wò ó, gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Mefiboṣeti jẹ́ tìrẹ.” Ṣiba sì wí pé, “Mo túúbá, jẹ́ kí n rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ, olúwa mi ọba.”
Då sade konungen till Siba: "Se, allt vad Mefiboset äger skall vara ditt." Siba svarade: "Jag faller ned för dig; låt mig finna nåd för dina ögon, min herre konung."
5 Dafidi ọba sì dé Bahurimu, sì wò ó, ọkùnrin kan ti ibẹ̀ jáde wá, láti ìdílé Saulu wá, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣimei, ọmọ Gera, ó sì ń bú èébú bí o tí ń bọ̀.
När sedan konung David hade kommit till Bahurim, då trädde därifrån ut en man som var besläktad med Sauls hus och hette Simei, Geras son; han trädde fram och for ut i förbannelser.
6 Ó sì sọ òkúta sí Dafidi, àti sí gbogbo ìránṣẹ́ Dafidi ọba, àti sí gbogbo ènìyàn, gbogbo àwọn alágbára ọkùnrin sì wà lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti lọ́wọ́ òsì rẹ̀.
Och han kastade stenar på David och på alla konung Davids tjänare, fastän allt folket och alla hjältarna omgåvo denne, både till höger och till vänster.
7 Báyìí ni Ṣimei sì wí nígbà tí ó ń yọ èébú, “Jáde, ìwọ ọkùnrin ẹ̀jẹ̀, ìwọ ọkùnrin Beliali.
Och Simeis ord, när han förbannade honom, voro dessa: "Bort, bort, du blodsman, du ogärningsman!
8 Olúwa mú gbogbo ẹ̀jẹ̀ ìdílé Saulu padà wá sí orí rẹ, ní ipò ẹni tí ìwọ jẹ ọba; Olúwa ti fi ìjọba náà lé Absalomu ọmọ rẹ lọ́wọ́: sì wò ó, ìwà búburú rẹ ni ó mú èyí wá bá ọ, nítorí pé ọkùnrin ẹ̀jẹ̀ ni ìwọ.”
HERREN låter nu allt Sauls hus' blod komma tillbaka över dig, du som har blivit konung i hans ställe; HERREN giver nu konungadömet åt din son Absalom. Se, nu har du kommit i den olycka du förtjänade, ty en blodsman är du."
9 Abiṣai ọmọ Seruiah sì wí fún ọba pé, “Èéṣe tí òkú ajá yìí fi ń bú olúwa mi ọba? Jẹ́ kí èmi kọjá, èmi bẹ̀ ọ́, kí èmi sì bẹ́ ẹ́ lórí.”
Då sade Abisai, Serujas son, till konungen: "Varför skall den döda hunden där få förbanna min herre konungen? Låt mig gå dit och hugga huvudet av honom."
10 Ọba sì wí pé, “Kín ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Seruiah? Bí ó bá ń bú èébú, nítorí tí Olúwa ti wí fún un pé, ‘Bú Dafidi!’ Ta ni yóò sì wí pé, ‘Kín ni ìdí tí o fi ṣe bẹ́ẹ̀.’”
Men konungen svarade: "Vad haven I med mig att göra, I Serujas söner? Om han förbannar, och om det är HERREN som har bjudit honom att förbanna David, vem törs då fråga: 'Varför gör du så?'
11 Dafidi sì wí fún Abiṣai, àti fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, ọmọ mi tí ó ti inú mi wá, ń wá mi kiri, ǹjẹ́ mélòó mélòó ni ará Benjamini yìí yóò sì ṣe? Fi í sílẹ̀, sì jẹ́ kí o máa yan èébú; nítorí pé Olúwa ni ó sọ fún un.
Och David sade ytterligare till Abisai och till alla sina tjänare: "Min son, han som har utgått från mitt eget liv, står mig ju efter livet; med huru mycket mer skäl då denne benjaminit! Låten honom vara, må han förbanna; ty HERREN har befallt honom det.
12 Bóyá Ọlọ́run yóò wo ìpọ́njú mi, Olúwa yóò sì fi ìre san án fún mi ní ipò èébú rẹ̀ lónìí.”
Kanhända skall HERREN se till den orätt mig sker, så att HERREN åter giver mig lycka, till gengäld för den förbannelse som i dag uttalas över mig."
13 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń lọ ní ọ̀nà, Ṣimei sì ń rìn òdìkejì òkè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, ó sì ń yan èébú bí ó ti ń lọ, ó sì ń sọ ọ́ lókùúta, ó sì ń fọ́n erùpẹ̀.
Och David gick med sina män vägen fram, under det att Simei gick längs utmed berget, jämsides med honom, och for ut i förbannelser och kastade stenar och grus, där han gick jämsides med honom.
14 Ọba, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì dé Jordani, ó sì rẹ̀ wọ́n, wọ́n sì sinmi níbẹ̀.
När så konungen, med allt folket som följde honom, hade kommit till Ajefim, rastade han där.
15 Absalomu àti gbogbo àwọn ènìyàn, àwọn ọkùnrin Israẹli sì wá sí Jerusalẹmu, Ahitofeli sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Men Absalom hade med allt sitt folk, Israels män, kommit till Jerusalem; han hade då också Ahitofel med sig.
16 Ó sì ṣe, nígbà tí Huṣai ará Arki, ọ̀rẹ́ Dafidi tọ Absalomu wá, Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Kí ọba ó pẹ́! Kí ọba ó pẹ́.”
När nu arkiten Husai, Davids vän, kom till Absalom, ropade Husai till Absalom: "Leve konungen! Leve konungen!"
17 Absalomu sì wí fún Huṣai pé, “Oore rẹ sí ọ̀rẹ́ rẹ ni èyí? Èéṣe tí ìwọ kò bá ọ̀rẹ́ rẹ lọ?”
Absalom sade till Husai: "Är det så du visar din kärlek mot din vän? Varför har du icke följt med din vän?"
18 Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ nítorí ẹni tí Olúwa, àti gbogbo àwọn ènìyàn yìí, àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli bá yàn, tirẹ̀ lèmi ó jẹ́, òun lèmi ó sì bá jókòó.
Husai svarade Absalom: "Nej, den som HERREN och detta folk och alla Israels män hava utvalt, honom vill jag tillhöra, och hos honom vill jag stanna.
19 Àti pé, ta ni èmi ó sì sìn? Kò ha yẹ kí èmi ó máa sìn níwájú ọmọ rẹ̀? Gẹ́gẹ́ bí èmi ti ń sìn rí níwájú baba rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sìn níwájú rẹ.”
Och dessutom, vilken bör jag tjäna? Bör jag icke tjäna inför hans son? Jo, såsom jag har tjänat inför din fader, så vill jag ock göra det inför dig."
20 Absalomu sì wí fún Ahitofeli pé, “Ẹ bá ará yín gbìmọ̀ ohun tí àwa ó ṣe.”
Och Absalom sade till Ahitofel: "Given nu ett råd om vad vi skola göra."
21 Ahitofeli sì wí fún Absalomu pé, “Wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ lọ, tí ó fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́ pé, ìwọ di ẹni ìríra sí baba rẹ, ọwọ́ gbogbo àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ yóò sì le.”
Ahitofel sade till Absalom: "Gå in till din faders bihustrur, som han har lämnat kvar för att vakta huset. Då får hela Israel höra att du har gjort dig förhatlig för din fader, och så styrkes modet hos alla dem som hålla med dig.
22 Wọ́n sì tẹ́ àgọ́ kan fún Absalomu ní òrùlé; Absalomu sì wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ̀ lójú gbogbo Israẹli.
Därefter slog man upp ett tält åt Absalom ovanpå taket, och så gick Absalom in till sin faders bihustrur inför hela Israels ögon.
23 Ìmọ̀ Ahitofeli tí ó máa ń gbà ni ìgbà náà, ó dàbí ẹni pé ènìyàn béèrè nǹkan lọ́wọ́ Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ìmọ̀ Ahitofeli fún Dafidi àti fún Absalomu sì rí.
Den tiden gällde nämligen ett råd som Ahitofel gav lika mycket som om man hade frågat Gud till råds; så mycket gällde vart råd av Ahitofel både för David och för Absalom.

< 2 Samuel 16 >