< 2 Samuel 1 >

1 Lẹ́yìn ikú Saulu, Dafidi ti ibi tí ó ti ṣẹ́gun àwọn ará Amaleki bọ̀, ó sì dúró ní Siklagi ní ọjọ́ méjì.
And so it was, after the death of Saul, when David had returned from the smiting of the Amalekites, and David had abode in Ziklag two days,
2 Ní ọjọ́ kẹta, ọkùnrin kan dé láti ibi ibùdó Saulu, pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ tí ó ti ya; àti erùpẹ̀ ní orí rẹ̀. Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ Dafidi, ó wólẹ̀ fún un láti bu ọlá fún un.
yea so it was, on the third day, that lo! a man came out of the camp, from Saul, with his clothes rent, and earth upon his head, —and so it was, when he came in unto David, that he fell to the earth, and did homage.
3 Dafidi sì béèrè pé, “Ibo ni ìwọ ti wá?” “Èmi sá láti ibùdó àwọn ọmọ Israẹli.”
And David said unto him, From whence comest thou? And he said unto him, Out of the camp of Israel, am I escaped.
4 Dafidi béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” “Sọ fún mi.” Ó wí pé, “Àwọn ọkùnrin náà sá láti ojú ogun. Ọ̀pọ̀ wọn ṣubú, wọ́n sì kú. Saulu àti ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Jonatani sì kú pẹ̀lú.”
And David said unto him—How turned out the matter? tell me, I pray thee. And he said—The people have fled from the battle, yea moreover, many, of the people have fallen, and died, Yea moreover, Saul, and Jonathan his son, are dead.
5 Nígbà náà, ní Dafidi sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Báwo ni o ṣe mọ̀ pé Saulu àti ọmọkùnrin rẹ̀ Jonatani ti kú.”
Then said David unto the young man who was telling him, —How knowest thou that Saul and Jonathan his son are dead?
6 Ọ̀dọ́mọkùnrin náà sọ pé, “Mo wà ní orí òkè Gilboa níbẹ̀ ni Saulu fi ara tí ọkọ̀ rẹ̀, àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin sì ń lépa rẹ̀.
And the young man who was telling him said, It, so happened, that I was on Mount Gilboa, when lo! Saul, leaning upon his spear, and lo! the chariots and horsemen, hotly pursued him;
7 Nígbà tí ó wò yíká, tí ó rí mí, ó pè mi, mo sì wí pé, ‘Kí ni mo lè ṣe?’
so he turned behind him, and saw me, —and cried out unto me, and I said, Behold me!
8 “Ó bi mí wí pé, ‘Ta ni ìwọ?’ “Mo dáhùn pé, ‘Ará a Amaleki.’
And he said unto me, Who art thou? And I said unto him, An Amalekite, am I.
9 “Nígbà náà ó wí fún mi pé, ‘Dúró lórí ì mi kí o sì pa mí! Èmi wà nínú ìrora ikú, ṣùgbọ́n mo wà láààyè.’
And he said unto me, I pray thee, take thy stand by me, and put me to death, for the cramp hath seized me, —even for as long as my life shall be in me.
10 “Nígbà náà, mo dúró lórí i rẹ̀, mo sì pa á nítorí mo mọ̀ wí pé, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣubú, kò le è yè mọ́. Mo sì mú adé tí ó wà lórí rẹ̀, idẹ tí ó wà ní apá a rẹ̀, mo sì kó wọn wá síbí fún olúwa mi.”
So I took my stand by him, and put him to death, for I perceived that he could not survive his fall, —so I took the crown that was on his head, and the bracelet that was on his arm, and have brought them in unto my lord, here.
11 Nígbà náà ni, Dafidi àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, di aṣọ wọn mú, wọ́n sì fà á ya.
Then David took hold of his clothes, and rent them, —yea moreover, [so did] all the men who were with him.
12 Wọ́n ṣọ̀fọ̀, wọ́n sì sọkún, wọ́n sì gbààwẹ̀ títí di ìrọ̀lẹ́ fún Saulu àti ọmọ rẹ̀ Jonatani àti fún àwọn ọmọ-ogun Olúwa, àti fún àwọn ilé Israẹli, nítorí wọ́n ti ṣubú nípa idà.
And they lamented aloud, and wept, and fasted until the evening, —for Saul, and for Jonathan his son, and for the people of Yahweh, and for the house of Israel, because they had fallen by the sword.
13 Dafidi sọ fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Níbo ni ó ti wá?” O dáhùn pé, “Ọmọ àlejò ni mo jẹ́, ará Amaleki.”
And David said unto the young man who was telling him, Whence art thou? And he said, Son of a sojourner—an Amalekite, am I.
14 Dafidi béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ kò fi bẹ̀rù láti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè láti fi pa ẹni àmì òróró Olúwa?”
And David said unto him, —How wast thou not afraid to thrust forth thy hand, to destroy the Anointed of Yahweh?
15 Nígbà náà Dafidi pe ọ̀kan nínú ọkùnrin, ó sì wí pé, “Lọ, gbé e lulẹ̀!” Nígbà náà ó gbé e lulẹ̀, ó sì kú.
So David called one of the young men, and said, —Go near—fall upon him. And he smote him, that he died.
16 Nítorí Dafidi wí fún un pé, “Ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò wà lórí ara rẹ, nítorí ẹnu ara rẹ ni o fi sọ pé, ‘Mo pa ẹni àmì òróró Olúwa.’”
And David said unto him, Thy blood, be upon thine own head, —for, thine own mouth, hath testified against thee, saying, I myself, put to death the Anointed of Yahweh.
17 Dafidi sì fi orin ọ̀fọ̀ yìí ṣọ̀fọ̀ lórí Saulu àti lórí Jonatani ọmọ rẹ̀,
Then chanted David this dirge, —over Saul and over Jonathan his son;
18 Ó sì pàṣẹ pé kí a kọ́ àwọn ọkùnrin Juda ní orin arò yìí tí ó jẹ́ ti ọrun (a kọ ọ́ sí inú ìwé Jaṣari):
and he thought to teach the sons of Judah [the song of] the Bow, —lo! it is written in the Book of the Upright: —
19 “Ògo rẹ, Israẹli ni a pa ní òkè gíga rẹ. Wò bí àwọn alágbára ṣe ń ṣubú!
The beauty of Israel! on thy high plumes—slain! How have fallen—the mighty!
20 “Ẹ má ṣe sọ ọ́ ní Gati, ẹ má ṣe kéde rẹ̀ ní òpópónà Aṣkeloni, kí àwọn ọmọbìnrin Filistini má bá à yọ̀, kí àwọn ọmọbìnrin aláìkọlà má ba à dunnú.
Do not tell it in Gath, Do not publish it in the streets of Ashkelon, —lest the daughters of the Philistines rejoice, lest the daughters of the Uncircumcised triumph.
21 “Ẹ̀yin òkè Gilboa, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe rí ìrì tàbí òjò, tàbí oko tí ó mú èso ọrẹ wá. Nítorí ibẹ̀ ni asà alágbára ti ṣègbé, asà Saulu, bí ẹni pé a kò fi òróró yàn án.
Ye mountains in Gilboa! Be there neither dew nor rain upon you, nor fields of offerings, —for, there, were cast away, the shields of the mighty, The shield of Saul, unanointed with oil.
22 “Ọrun Jonatani kì í padà bẹ́ẹ̀ ni idà Saulu kì í padà lásán, láì kan ẹ̀jẹ̀ àwọn tí a pa, àti ẹran àwọn alágbára.
From the blood of the slain, from the fat of the mighty, the bow of Jonathan ne’er drew back, —and, the sword of Saul, ne’er returned, empty.
23 Saulu àti Jonatani— ní ọjọ́ ayé, wọ́n fẹ́ràn ara, wọn sì dùn, ní ikú, wọn kò sì yà ara wọ́n. Wọ́n yára ju idì lọ, wọ́n lágbára ju kìnnìún lọ.
Saul and Jonathan, delightfully loving in their lives, even, in their death, were not divided, —Beyond eagles, were they swift, beyond lions, were they strong!
24 “Ẹ̀yin ọmọbìnrin Israẹli, ẹ sọkún lórí Saulu, ẹni tí ó fi aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára wọ̀ yín, ẹni tí ó fi wúrà sí ara aṣọ yín.
Ye daughters of Israel! For Saul, weep ye, —who clothed you in crimson, [decked] with lovely things, who hung ornaments of gold on your apparel!
25 “Wò ó bí alágbára ti ṣubú ní ojú ogun! Jonatani, ìwọ tí a pa ní òkè gíga.
How have fallen the mighty, in the midst of the battle! Jonathan, on thy high places, slain!
26 Ọkàn mi gbọgbẹ́ fún ọ Jonatani arákùnrin mi; ìwọ ṣọ̀wọ́n fún mi. Ìfẹ́ rẹ sí mi jẹ́ ìyanu, ó jẹ́ ìyanu ju ti obìnrin lọ.
I am distressed for thee, my brother, Jonathan! Delightful to me, exceedingly, —Wonderful, was thy love to me, passing the love of women.
27 “Wò ó bí alágbára ti ṣubú! Ohun ìjà sì ti ṣègbé!”
How have fallen the mighty, and perished the weapons of war!

< 2 Samuel 1 >