< 2 Corinthians 2 >

1 Nítorí náà mo tí pinnu nínú ara mí pé, èmi kì yóò tún fi ìbànújẹ́ tọ̀ yin wá.
ܕܢܬ ܕܝܢ ܗܕܐ ܒܢܦܫܝ ܕܠܐ ܬܘܒ ܒܟܪܝܘܬܐ ܐܬܐ ܠܘܬܟܘܢ
2 Nítorí pé bí èmi bá mú inú yín bàjẹ́, ǹjẹ́ ta ni ẹni ti ìbá mú inú mí dùn ní àkókò tí inú mi bá bàjẹ́ bí kò ṣe ẹni tí mo ti ba nínú jẹ́?
ܐܢ ܐܢܐ ܓܝܪ ܡܟܪܐ ܐܢܐ ܠܟܘܢ ܡܢܘ ܢܚܕܝܢܝ ܐܠܐ ܗܘ ܕܐܢܐ ܐܟܪܝܬ ܠܗ
3 Èmi sì kọ̀wé bí mo tí kọ sí yín pé, nígbà tí mo bá sì de, kí èmi má ṣe ni ìbànújẹ́ lọ́dọ̀ àwọn ti ìbá mú mi ní ayọ̀, nítorí tí mo ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú gbogbo yín, wí pé ẹ̀yin yóò jẹ́ alábápín ayọ̀ mi.
ܘܕܟܬܒܬ ܠܟܘܢ ܗܝ ܗܕܐ ܕܠܐ ܟܕ ܐܬܐ ܢܟܪܘܢ ܠܝ ܗܢܘܢ ܐܝܠܝܢ ܕܘܠܐ ܗܘܐ ܠܗܘܢ ܕܗܢܘܢ ܢܚܕܘܢܢܝ ܬܟܝܠ ܐܢܐ ܕܝܢ ܥܠ ܟܠܟܘܢ ܕܚܕܘܬܝ ܕܟܠܟܘܢ ܗܝ
4 Nítorí pé nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàhálà àti ìrora ọkàn mí ni mo ti fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ omijé kọ̀wé sí yín; kì í ṣe nítorí kí a lè bà yín nínú jẹ́, ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin bá a lè mọ bí ìfẹ́ tí mo ní sí yín ṣe jinlẹ̀ tó.
ܘܡܢ ܐܘܠܨܢܐ ܪܒܐ ܘܡܢ ܐܢܘܤܝܐ ܕܠܒܐ ܟܬܒܬ ܠܟܘܢ ܗܠܝܢ ܒܕܡܥܐ ܤܓܝܐܬܐ ܠܐ ܡܛܠ ܕܬܟܪܐ ܠܟܘܢ ܐܠܐ ܡܛܠ ܕܬܕܥܘܢ ܚܘܒܐ ܝܬܝܪܐ ܕܐܝܬ ܠܝ ܠܘܬܟܘܢ
5 Bí ẹnikẹ́ni bá fa ohun ìbànújẹ́ kì í ṣe èmi ni ó bà nínú jẹ́, bí kò ṣe ẹ̀yin fúnra yín, níwọ̀n ìyówù kí ó jẹ́; n kò fẹ́ sọ ọ́ lọ́nà líle jù.
ܐܢ ܕܝܢ ܐܢܫ ܐܟܪܝ ܠܐ ܗܘܐ ܠܝ ܐܟܪܝ ܐܠܐ ܒܨܝܪܐ ܩܠܝܠ ܠܟܠܟܘܢ ܕܠܐ ܬܐܩܪ ܡܠܬܐ ܥܠܝܟܘܢ
6 Ìyà náà tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ti fi jẹ́ irú ènìyàn bẹ́ẹ̀ tó fún un.
ܟܕܘ ܠܗ ܕܝܢ ܠܗܢܐ ܟܐܬܐ ܕܡܢ ܤܓܝܐܐ
7 Kàkà bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ìbá kúkú dáríjì í, kí ẹ sí tù ú nínú ní gbogbo ọ̀nà, kí ìbànújẹ́ má bà á bo irú ènìyàn bẹ́ẹ̀ mọ́lẹ̀.
ܘܡܟܝܠ ܐܚܪܢܝܐܝܬ ܘܠܐ ܕܬܫܒܩܘܢ ܠܗ ܘܬܒܝܐܘܢܗ ܕܠܡܐ ܒܟܪܝܘܬܐ ܝܬܝܪܬܐ ܢܬܒܠܥ ܠܗ ܗܘ ܡܢ ܕܗܟܢܐ ܗܘ
8 Nítorí náà mo bẹ̀ yín, ẹ fi ìdánilójú ìfẹ́ yín hàn sí irú ẹni náà.
ܡܛܠ ܗܢܐ ܒܥܐ ܐܢܐ ܡܢܟܘܢ ܕܬܫܪܪܘܢ ܒܗ ܚܘܒܟܘܢ
9 Ìdí tí mo ṣe kọ̀wé ni kí èmi ba à lè rí ẹ̀rí dìímú nípa ìgbọ́ràn yín nínú ohun gbogbo.
ܡܛܠ ܗܢܐ ܓܝܪ ܟܬܒܬ ܐܦ ܕܐܕܥ ܒܢܤܝܢܐ ܐܢ ܒܟܠܡܕܡ ܡܫܬܡܥܝܢ ܐܢܬܘܢ
10 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá dáríjì ẹnikẹ́ni, èmi pẹ̀lú dáríjì í. Ohun tí èmi pẹ̀lú bá fi jì, nítorí tiyín ní mo fi jì níwájú Kristi.
ܠܡܢ ܕܐܢܬܘܢ ܕܝܢ ܫܒܩܝܢ ܐܢܬܘܢ ܐܦ ܐܢܐ ܐܦ ܐܢܐ ܓܝܪ ܡܕܡ ܕܫܒܩܬ ܠܡܢ ܕܫܒܩܬ ܡܛܠܬܟܘܢ ܗܘ ܫܒܩܬ ܒܦܪܨܘܦܗ ܕܡܫܝܚܐ
11 Kí Satani má ba à rẹ́ wa jẹ. Nítorí àwa kò ṣe aláìmọ́ àrékérekè rẹ̀.
ܕܠܐ ܢܥܠܒܢ ܤܛܢܐ ܝܕܥܝܢܢ ܓܝܪ ܡܚܫܒܬܗ
12 Ṣùgbọ́n nígbà ti mo dé Troasi láti wàásù ìyìnrere Kristi, tí mo sì rí i wí pé Olúwa ti ṣí ìlẹ̀kùn fún mi,
ܟܕ ܐܬܝܬ ܕܝܢ ܠܛܪܘܐܤ ܒܤܒܪܬܗ ܕܡܫܝܚܐ ܘܐܬܦܬܚ ܠܝ ܬܪܥܐ ܒܡܪܝܐ
13 síbẹ̀ èmi kò ní àlàáfíà lọ́kàn mi, nítorí tí èmi kò rí Titu arákùnrin mi níbẹ̀. Nítorí ìdí èyí ni mo ṣe dágbére fún wọn, mo si rékọjá lọ sí Makedonia.
ܠܐ ܗܘܐ ܠܝ ܢܝܚܐ ܒܪܘܚܝ ܕܠܐ ܐܫܟܚܬ ܠܛܛܘܤ ܐܚܝ ܐܠܐ ܫܪܝܬ ܐܢܘܢ ܘܢܦܩܬ ܠܝ ܠܡܩܕܘܢܝܐ
14 Ṣùgbọ́n ọpẹ́ ni fún Ọlọ́run, ẹni tí ń yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí wá nígbà gbogbo nínú Kristi, tí a sì ń fi òórùn dídùn ìmọ̀ rẹ̀ hàn nípa wa níbi gbogbo.
ܛܝܒܘ ܕܝܢ ܠܐܠܗܐ ܕܒܟܠ ܙܒܢ ܚܙܬܐ ܥܒܕ ܠܢ ܒܡܫܝܚܐ ܘܓܠܐ ܒܢ ܪܝܚܐ ܕܝܕܥܬܗ ܒܟܠ ܐܬܪ
15 Nítorí òórùn dídùn Kristi ni àwa jẹ́ fún Ọlọ́run, nínú àwọn tí a ń gbàlà àti nínú àwọn tí ó ń ṣègbé.
ܪܝܚܐ ܚܢܢ ܓܝܪ ܒܤܝܡܐ ܒܡܫܝܚܐ ܠܐܠܗܐ ܒܐܝܠܝܢ ܕܚܐܝܢ ܘܒܐܝܠܝܢ ܕܐܒܕܝܢ
16 Fún àwọn kan, àwa jẹ́ òórùn sí ikú, àti fún àwọn mìíràn òórùn ìyè sí ìyè. Ta ni ó ha si tọ́ fún nǹkan wọ̀nyí?
ܠܐܝܠܝܢ ܕܪܝܚܐ ܕܡܘܬܐ ܠܡܘܬܐ ܘܠܐܝܠܝܢ ܕܪܝܚܐ ܕܚܝܐ ܠܚܝܐ ܘܠܗܠܝܢ ܡܢܘ ܢܫܘܐ
17 Nítorí àwa kò dàbí àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀, tí ń fi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ṣòwò jẹun; ṣùgbọ́n nínú òtítọ́ inú àwa ń sọ̀rọ̀ níwájú Ọlọ́run nínú Kristi gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a rán láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.
ܠܐ ܗܘܝܢ ܓܝܪ ܐܝܟ ܫܪܟܐ ܕܡܡܙܓܝܢ ܡܠܘܗܝ ܕܐܠܗܐ ܐܠܐ ܐܝܟ ܕܒܫܪܪܐ ܘܐܝܟ ܕܡܢ ܐܠܗܐ ܩܕܡ ܐܠܗܐ ܒܡܫܝܚܐ ܡܡܠܠܝܢܢ

< 2 Corinthians 2 >