< 2 Chronicles 7 >

1 Nígbà tí Solomoni sì ti parí àdúrà, iná sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó ẹbọ sísun àti ẹbọ, ògo Ọlọ́run sì kún ilé Olúwa.
När Salomo hade slutat sin bön, kom eld ned från himmelen och förtärde brännoffret och slaktoffren, och HERRENS härlighet uppfyllde huset.
2 Àwọn àlùfáà kò sì le wo ilé Olúwa náà nítorí pé ògo Olúwa kún un.
Och prästerna kunde icke gå in i HERRENS hus, eftersom HERRENS härlighet uppfyllde HERRENS hus.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí iná tí ó ń sọ̀kalẹ̀ àti ògo Olúwa lórí ilé Olúwa náà, wọ́n sì kúnlẹ̀ lórí eékún wọn pẹ̀lú ojú ni dídàbolẹ̀, wọ́n sì sin Olúwa, wọ́n sì fi ìyìn fún Olúwa wí pé, “Nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ sì dúró títí láéláé.”
Då nu alla Israels barn sågo huru elden kom ned, och sågo HERRENS härlighet över huset, föllo de ned på den stenlagda gården, med ansiktena mot jorden, och tillbådo HERREN och tackade honom, därför att han är god, och därför att hans nåd varar evinnerligen.
4 Nígbà náà ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn sì rú ẹbọ níwájú Olúwa.
Och konungen och allt folket offrade slaktoffer inför HERRENS ansikte.
5 Ọba Solomoni sì rú ẹbọ ti ẹgbẹ̀rún méjìlélógún, orí màlúù àti àgùntàn àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn àti ẹranko. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn ya ilé Ọlọ́run sí mímọ́.
Konung Salomo offrade såsom slaktoffer tjugutvå tusen tjurar och ett hundra tjugu tusen av småboskapen. Så invigdes Guds hus av konungen och allt folket.
6 Àwọn àlùfáà dúró ní ààyè wọn, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Lefi ti ṣe pẹ̀lú ohun èlò orin Olúwa, tí ọba Dafidi ti ṣe fún ìyìn Olúwa àti tí á lò nígbà tí ó dúpẹ́, wí pé, “Àánú rẹ̀ sì dúró láéláé,” níwájú àwọn ọmọ Lefi, àwọn àlùfáà sì fọn ìpè, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dúró.
Och prästerna stodo där i sina tjänstförrättningar, och leviterna stodo med HERRENS musikinstrumenter, som konung David hade låtit göra, för att de med dem skulle tacka HERREN, därför att hans nåd varar evinnerligen; David lät nämligen dem utföra lovsången. Men prästerna stodo mitt emot dem och blåste i trumpeter, medan hela Israel förblev stående.
7 Solomoni sì yà àgbàlá níwájú ilé Olúwa sọ́tọ̀, níbẹ̀ sì ni ó ti ṣe ìrúbọ ẹbọ sísun àti ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ó ti ṣe kò lè gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọ̀rá náà.
Och Salomo helgade den mellersta delen av förgården framför HERRENS hus; ty där offrade han brännoffren och fettstyckena av tackoffret eftersom kopparaltaret som Salomo hade låtit göra icke kunde rymma brännoffret, spisoffret och fettstyckena.
8 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àsè ní àkókò náà fún ọjọ́ méje àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ àti ìjọ ènìyàn ńlá, àwọn ènìyàn láti Lebo-Hamati títí dé odò Ejibiti.
Tid detta tillfälle firade Salomo högtiden i sju dagar, och med honom hela Israel, en mycket stor församling ifrån hela landet, allt ifrån det ställe där vägen går till Hamat ända till Egyptens bäck.
9 Ní ọjọ́ kẹjọ, wọ́n sì pe ìjọ ènìyàn jọ nítorí tí wọ́n pe àpèjẹ ìyàsímímọ́ ti orí pẹpẹ fún ọjọ́ méje àti àsè náà fún ọjọ́ méje sí i.
Och på åttonde dagen höllo de högtidsförsamling. Ty altarets invigning firade de i sju dagar och högtiden i sju dagar.
10 Ní ọjọ́ kẹtàlélógún tí oṣù keje, ó sì rán àwọn ènìyàn padà sí ilé wọn, pẹ̀lú ayọ̀ àti ìdùnnú nínú wọn fún ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi àti Solomoni, àti fún àwọn ènìyàn Israẹli.
Men på tjugutredje dagen i sjunde månaden lät han folket gå hem till sina hyddor; och de voro fulla av glädje och fröjd över det goda som HERREN hade gjort mot David och Salomo och mot sitt folk Israel.
11 Nígbà tí Solomoni ti parí ilé Olúwa àti ibi ilé ọba, nígbà tí ó sì ti ṣe àṣeyọrí láti gbé jáde gbogbo ohun tí ó ní lọ́kàn láti ṣe nínú ilé Olúwa àti nínú ilé òun tìkára rẹ̀,
Så fullbordade Salomo HERRENS hus och konungshuset; och allt vad Salomo hade haft i sinnet att utföra i HERRENS hus och i sitt eget hus hade lyckats honom väl.
12 Olúwa sì farahàn Solomoni ní òru ó sì wí pé: “Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti yàn ibí yìí fún ara mi gẹ́gẹ́ bí ilé fún ẹbọ.
Och HERREN uppenbarade sig för Salomo om natten och sade till honom: "Jag har hört din bön och utvalt denna plats åt mig till offerplats.
13 “Nígbà tí mo bá sé ọ̀run kí ó ma bá à sí òjò, tàbí láti pàṣẹ fún eṣú láti jẹ ilẹ̀ náà run tàbí rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí àárín àwọn ènìyàn mi,
Om jag tillsluter himmelen, så att regn icke faller, om jag bjuder gräshoppor att fördärva landet, eller om jag sänder pest bland mitt folk,
14 tí àwọn ènìyàn, tí a fi orúkọ mi pè, tí wọ́n bá rẹ ara wọn sílẹ̀, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì rí ojú mi, tí wọ́n sì yí kúrò nínú ọ̀nà búburú wọn, nígbà náà, èmi yóò gbọ́ láti ọ̀run, èmi yóò sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n èmi yóò sì wo ilẹ̀ wọn sàn.
men mitt folk, det som är uppkallat efter mitt namn, då ödmjukar sig och beder och söker mitt ansikte och omvänder sig från sina onda vägar, så vill jag höra det från himmelen och förlåta deras synd och skaffa bot åt deras land.
15 Nísinsin yìí, ojú mi yóò sì là etí mi yóò sì là, sí àdúrà ọrẹ níbí yìí.
Så skola nu mina ögon vara öppna och mina öron akta på vad som bedes på denna plats.
16 Èmi sì ti yàn, èmi sì ti ya ilé yìí sí mímọ́ bẹ́ẹ̀ ni kí orúkọ mi kí ó le wà níbẹ̀ títí láéláé.
Och nu har jag utvalt och helgat detta hus, för att mitt namn skall vara där till evig tid. Och mina ögon och mitt hjärta skola vara där alltid.
17 “Ní ti bí ìwọ bá rìn níwájú mi gẹ́gẹ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, tí o sì ṣe gbogbo ohun tí mo paláṣẹ, tí ìwọ sì ṣe àkíyèsí àṣẹ mi láti ọ̀run,
Om du nu vandrar inför mig, såsom din fader David vandrade, så att du gör allt vad jag har bjudit dig och håller mina stadgar och rätter,
18 Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe pẹ̀lú Dafidi baba rẹ nígbà tí mo bá a dá májẹ̀mú wí pé, ìwọ kò ní fẹ́ ẹnìkan kù láti ṣe alákòóso lórí Israẹli.
då skall jag upprätthålla din konungatron, såsom jag lovade din fader David, när jag sade: 'Aldrig skall den tid komma, då en avkomling av dig icke råder över Israel.'
19 “Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá yípadà tí o sì kọ òfin mi sílẹ̀ àti àṣẹ tí mo ti fi fún yín tí ẹ sì lọ sókè láti lọ sin ọlọ́run mìíràn tí ẹ sì bọ wọ́n,
Men om I vänden om och övergiven de stadgar och bud som jag har förelagt eder, och gån bort och tjänen andra gudar och tillbedjen dem,
20 nígbà náà ni èmi yóò fa Israẹli tu kúrò láti ilẹ̀ mi, èyí tí èmi ti fi fún wọn, èmi yóò sì kọ̀ ilé náà sílẹ̀ èyí tí èmi ti yà sọ́tọ̀ fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ṣe ọ̀rọ̀ òwe, n ó fi ṣe ẹlẹ́yà láàrín gbogbo ènìyàn,
då skall jag rycka upp dem som så göra ur mitt land, det som jag har givit dem; och detta hus som jag har helgat åt mitt namn skall jag förkasta ifrån mitt ansikte; och jag skall göra det till ett ordspråk och en visa bland alla folk.
21 àti ní gbogbo àyíká ilé yìí nísinsin yìí, bẹ́ẹ̀ ni yóò di ohun ìtànjẹ; gbogbo àwọn tí ó bá sì kọjá níbẹ̀ ni yóò jáláyà, wọn yóò sì wí pé, ‘Kí ni ó dé tí Olúwa fì ṣe irú èyí sí ilẹ̀ yí àti sí ilé yìí?’
Och över detta hus, som har varit så upphöjt, skall då var och en som går därförbi bliva häpen. Och när någon frågar: 'Varför har HERREN gjort så mot detta land och detta hus?',
22 Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé, ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run baba wọn ẹni tí ó mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n sì ti fi ọwọ́ gba ọlọ́run mìíràn mọ́ra, wọ́n bọ wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyí tí ó fi mú gbogbo ìjàǹbá náà wá sórí wọn.’”
då skall man svara: 'Därför att de övergåvo HERREN, sina fäders Gud, som hade fört dem ut ur Egyptens land, och höllo sig till andra gudar och tillbådo dem och tjänade dem, därför har han låtit allt detta onda komma över dem.'"

< 2 Chronicles 7 >