< 2 Chronicles 24 >

1 Joaṣi jẹ́ ọmọ ọdún méje nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ogójì ọdún. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sibia ti Beerṣeba.
Joas var sju år gammal, när han blev konung, och han regerade fyrtio år i Jerusalem. Hans moder hette Sibja, från Beer-Seba.
2 Joaṣi ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa ní gbogbo àkókò Jehoiada àlùfáà.
Och Joas gjorde vad rätt var i HERRENS ögon, så länge prästen Jojada levde.
3 Jehoiada yan ìyàwó méjì fún un, ó sì ní àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin.
Och Jojada tog åt honom två hustrur, och han födde söner och döttrar.
4 Ní àkókò kan, Joaṣi pinnu láti tún ilé Olúwa ṣe.
Därefter blev Joas betänkt på att upphjälpa HERRENS hus.
5 Ó pe àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi jọ, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí àwọn ìlú Juda, kí ẹ sì gba owó ìtọ́sí láti ọwọ́ gbogbo Israẹli láti fi tún ilé Ọlọ́run yín ṣe.” Ṣùgbọ́n àwọn ará Lefi kò ṣe é lẹ́ẹ̀kan náà.
Och han församlade prästerna och leviterna och sade till dem: "Faren vart år ut till Juda städer, och samlen från hela Israel in penningar till att sätta eder Guds hus i stånd; och I skolen bedriva denna sak med skyndsamhet." Men leviterna skyndade sig icke.
6 Nítorí náà ọba pa á láṣẹ fún Jehoiada olórí àlùfáà ó sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí o kò béèrè lọ́wọ́ àwọn ará Lefi láti mú wá láti Juda àti Jerusalẹmu, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi lélẹ̀ àti nípasẹ̀ àpéjọ gbogbo Israẹli fún àgọ́ ẹ̀rí?”
Då kallade konungen till sig översteprästen Jojada och sade till honom: "Varför har du icke tillhållit leviterna att från Juda och Jerusalem indriva den skatt som HERRENS tjänare Mose pålade, och som Israels församling skulle erlägga till vittnesbördets tabernakel?
7 Nísinsin yìí, àwọn ọmọkùnrin obìnrin búburú ni Ataliah ti fọ́ ilé Ọlọ́run, ó sì ti lo àwọn nǹkan ìyàsọ́tọ̀ fún àwọn Baali.
Ty Ataljas, den ogudaktiga kvinnans, söner hava fördärvat Gud hus; ja, allt som var helgat till HERRENS hus hava de använt till Baalerna."
8 Nípasẹ̀ ọba, wọn ṣe àpótí wọ́n sì gbé e sí ìta, ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa.
På konungens befallning gjorde man därefter en kista och ställde den utanför porten till HERREN hus.
9 A ṣe ìkéde ní Juda àti Jerusalẹmu wí pé wọ́n gbọdọ̀ mú wá fún Olúwa, owó orí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti béèrè lọ́wọ́ Israẹli ní aginjù.
Och man lät utropa i Juda och Jerusalem att den skatt som Guds tjänare Mose hade pålagt Israel i öknen skulle erläggas åt HERREN.
10 Gbogbo àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn ènìyàn sì yọ̀, wọ́n sì mú un wá, wọ́n ń jù ú sínú àpótí títí tí ó fi kún.
Och alla furstarna och allt folket buro fram penningar med glädje och kastade dem i kistan, till dess att allt var insamlat.
11 Nígbàkígbà tí a bá gbé àpótí wọlé láti ọwọ́ àwọn ará Lefi sí ọwọ́ àwọn ìjòyè ọba, tí wọ́n bá sì rí wí pe owó ńlá wà níbẹ̀ àwọn akọ̀wé ọba àti ìjòyè olórí àlùfáà yóò wá láti kó owó rẹ̀ kúrò, wọn yóò sì dá a padà sí ààyè rẹ̀. Wọ́n ṣe èyí déédé, wọ́n sì kó iye owó ńlá.
Och när tid blev att genom leviternas försorg föra kistan till de granskningsmän som konungen hade förordnat, och dessa då märkte att mycket penningar fanns i den, då kommo konungens sekreterare och översteprästens tillsyningsman och tömde kistan och buro den sedan tillbaka till dess plats. Så gjorde de gång efter annan och samlade in penningar i myckenhet.
12 Ọba àti Jehoiada fi fún àwọn ọkùnrin náà tí ó sì ń ṣiṣẹ́ nínú ilé Olúwa. Wọ́n fi owó gba ẹni tí ń fi òkúta mọ ilé àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ilé Olúwa padà, àti àwọn òṣìṣẹ́ pẹ̀lú irin àti idẹ láti tún ilé Olúwa ṣe.
Därefter lämnade konungen och Jojada dessa åt den som skulle utföra arbetet på HERRENS hus, och lejde stenhuggare och timmermän till att upphjälpa HERRENS hus, så ock järn- och kopparsmeder till att sätta HERRENS hus i stånd.
13 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ náà, sì lọ síwájú àti síwájú ní ọwọ́ wọn, wọ́n sì tún mú ilé Ọlọ́run dúró sí ipò rẹ̀, wọ́n mú un le.
Och de som utförde arbetet bedrevo det så, att arbetet gick framåt under deras händer, Och de återställde Guds hus i dess förra skick och satte det i gott stånd.
14 Nígbà tí wọ́n sì parí rẹ̀ tán, wọ́n mú owó ìyókù wá sí iwájú ọba àti Jehoiada, a sì fi ohun èlò fún ilé Olúwa, àní ohun èlò fún ìsìn àti fún ẹbọ pẹ̀lú ọpọ́n, àní ohun èlò wúrà àti fàdákà. Wọ́n sì ń rú ẹbọ sísun ní ilé Olúwa nígbà gbogbo ní gbogbo ọjọ́ Jehoiada.
Och när de hade slutat, buro de återstoden av penningarna till konungen och Jojada; och man gjorde därav kärl till HERRENS hus, kärl till gudstjänsten och offren, skålar och andra kärl av guld och silver Och man offrade brännoffer i HERRENS hus beständigt, så länge Jojada levde.
15 Ṣùgbọ́n Jehoiada di arúgbó, ó sì kún fún ọjọ́, ó sì kú, ẹni àádóje ọdún ni nígbà tí ó kú.
Men Jojada blev gammal och mätt på att leva och dog så; ett hundra trettio år gammal var han vid sin död.
16 Wọ́n sì sin ín ní ìlú Dafidi pẹ̀lú àwọn ọba, nítorí tí ó ṣe rere ní Israẹli, àti sí Ọlọ́run àti sí ilé rẹ̀.
Och man begrov honom i Davids stad bland konungarna, därför att han hade gjort vad gott var mot Israel och mot Gud och hans hus.
17 Lẹ́yìn ikú Jehoiada, àwọn oníṣẹ́ Juda wá láti fi ìforíbalẹ̀ wọn hàn sí ọba. Ó sì fèsì sí wọn.
Men efter Jojadas död kommo Juda furstar och föllo ned för konungen; då lyssnade konungen till dem.
18 Wọ́n pa ilé Olúwa tì, Ọlọ́run baba a wọn. Wọ́n sì ń sin àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yìí, ìbínú Ọlọ́run dé sórí Juda àti Jerusalẹmu.
Och de övergåvo HERRENS, sina fäders Guds, hus och tjänade Aserorna och avgudarna. Då kom förtörnelse över Juda och Jerusalem genom den skuld de så ådrogo sig.
19 Bí ó ti wù kí ó rí, Olúwa rán àwọn wòlíì sí àwọn ènìyàn láti mú wọn padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, wọ́n jẹ́rìí nípa wọn, wọn kì yóò gbọ́.
Och profeter sändes ibland dem för att omvända dem till HERREN; och dessa varnade dem, men de lyssnade icke därtill.
20 Nígbà náà, Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Sekariah ọmọ Jehoiada wòlíì, ó dúró níwájú àwọn ènìyàn ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Kí ni ó dé tí ẹ̀yin kò fi tẹ̀lé àṣẹ Olúwa? Ìwọ kì yóò ṣe rere. Nítorí tí ìwọ ti kọ Olúwa sílẹ̀, òun pẹ̀lú ti kọ̀ yín sílẹ̀.’”
Men Sakarja, prästen Jojadas son, hade blivit beklädd med Guds Andes kraft, och han trädde fram inför folket och sade till dem: "Så säger Gud: Varför överträden I HERRENS bud, eder själva till ingen fromma? Eftersom I haven övergivit HERREN, har han ock övergivit eder."
21 Ṣùgbọ́n wọ́n dìtẹ̀ sí i, àti nípa àṣẹ ọba, wọ́n sọ ọ́ lókùúta pa nínú àgbàlá ààfin ilé Olúwa.
Då sammansvuro de sig mot honom och stenade honom, enligt konungens befallning, på förgården till HERRENS hus.
22 Ọba Joaṣi kò rántí inú rere tí Jehoiada baba Sakariah ti fihàn án ṣùgbọ́n, ó pa ọmọ rẹ̀, tí ó wí bí ó ti ń kú lọ pé, “Kí Olúwa kí ó rí èyí kí ó sì pè ọ́ sí ìṣirò.”
Ty konung Joas tänkte icke på den kärlek som Jojada, dennes fader, hade bevisat honom, utan dräpte hans son. Men denne sade i sin dödsstund: "Må HERREN se detta och utkräva det."
23 Ní òpin ọdún, àwọn ọmọ-ogun Aramu yàn láti dojúkọ Joaṣi; wọ́n gbógun ti Juda àti Jerusalẹmu, wọ́n sì pa gbogbo àwọn aṣáájú àwọn ènìyàn. Wọ́n rán gbogbo àwọn ìkógun sí ọba wọn ní Damasku.
Och när året hade gått till ända, drog araméernas här upp mot honom, och de kommo till Juda och Jerusalem och utrotade ur folket alla folkets furstar. Och allt byte som de togo sände de till konungen i Damaskus.
24 Bí ó ti wù kí ó rí, àwọn ọmọ-ogun Aramu ti wá pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀ Olúwa sì fi ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ogun lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn sílẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe ìdájọ́ Joaṣi.
Ty fastän araméernas här som då ryckte an utgjorde allenast en ringa skara, gav HERREN likväl i deras hand en mycket talrik här, därför att folket hade övergivit HERREN, sina fäders Gud. Så fingo de utföra straffdomen över Joas.
25 Nígbà tí àwọn ará Aramu kúrò, wọ́n fi Joaṣi sílẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ọgbẹ́. Àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ dìtẹ̀ si fún pípa ọmọ Jehoiada àlùfáà, wọ́n sì pa á ní orí ibùsùn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, a sì sin ín sínú ìlú ńlá ti Dafidi, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú àwọn ibojì àwọn ọba.
Och när dessa drogo bort ifrån honom -- ty de lämnade honom kvar illa sjuk -- sammansvuro sig hans tjänare mot honom, därför att han hade utgjutit prästen Jojadas söners blod, och dräpte honom på hans säng; detta blev hans död. Och man begrov honom i Davids stad; dock begrov man honom icke i konungagravarna.
26 Àwọn tí ó dìtẹ̀ sì jẹ́ Sabadi, ọmọ Ṣimeati arábìnrin Ammoni àti Jehosabadi ọmọ Ṣimiriti arábìnrin Moabu.
Och de som sammansvuro sig mot honom voro Sabad, son till ammonitiskan Simeat, och Josabad, son till moabitiskan Simrit.
27 Àkọsílẹ̀ àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀, àti àkọsílẹ̀ ti ìmúpadà sípò ilé Ọlọ́run ní a kọ sínú ìwé ìtumọ̀ ti àwọn ọba. Amasiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Men om hans söner, och om de många profetior som förkunnades mot honom, och om huru Guds hus åter upprättades, härom är skrivet i "Utläggning av Konungaboken". Och hans son Amasja blev konung efter honom.

< 2 Chronicles 24 >