< 2 Chronicles 16 >

1 Ní ọdún kẹrìndínlógójì ìjọba Asa, Baaṣa ọba Israẹli gòkè wá sí Juda ó sì kọlu Rama, láti ma bá a jẹ́ kí ẹnikẹ́ni lè jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba Juda lọ.
In yac aktolngoul onkosr ma Tokosra Asa el leum lun Judah, Tokosra Baasha lun Israel el utyak ke ku lal nu fin acn Judah, ac mutawauk in kuhlasak acn Ramah, in tulokinya utyak ac illa lun mwet uh in facl Judah.
2 Nígbà náà ni Asa mú wúrà àti fàdákà jáde nínú ilé ìṣúra ilé Olúwa àti ààfin ọba ó sì ránṣẹ́ sí Beni-Hadadi ọba Siria, ẹni tí ń gbé ní Damasku, ó wí pé,
Ke ma inge, Asa el eis silver ac gold liki nien fwil ma saok in Tempul ac in lohm sin tokosra, ac supwala nu Damascus nu sel Benhadad, tokosra lun Syria, wi kas inge:
3 “Májẹ̀mú kan wà láàrín èmi àti ìrẹ, bí ó ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Ẹ wò ó, mo fi wúrà àti fàdákà ránṣẹ́ sí ọ; lọ, ba májẹ̀mú tí o bá Baaṣa ọba Israẹli dá jẹ́, kí ó lè lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
“Lela nga kom in akasrui, oana papa tumasr. Eis silver ac gold ingan mwe lung luk nu sum. Inge, kunausla kupasr lom nu sel Tokosra Baasha lun Israel, tuh elan usla mwet lal liki acn sik.”
4 Beni-Hadadi sì gbọ́ ti Asa ọba, ó sì rán àwọn olórí ogun rẹ̀ lọ sí àwọn ìlú Israẹli, wọ́n sì kọlu Ijoni, Dani, Abeli-Maimu, àti gbogbo ìlú ìṣúra Naftali.
Benhadad el insesela nu ke pusra se lal Asa inge, ac el supwala captain lun un mwet mweun lal, wi mwet mweun lalos, in mweuni siti lun Israel. Elos sruokya siti lun Ijon, Dan, Abel Beth Maacah, ac siti nukewa in acn Naphtali, yen kufwen mweun lalos oan we.
5 Nígbà tí Baaṣa gbọ́ èyí, ó sì dá kíkọ́ Rama dúró, ó sì dá iṣẹ́ rẹ̀ dúró.
Ke Tokosra Baasha el lohng ma sikyak inge, el tui ke musa se Ramah, ac el tiana aksafyela.
6 Nígbà náà ní ọba Asa kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda jọ, wọ́n sì kó òkúta àti igi Rama lọ èyí ti Baaṣa ń fi kọ́lé; ó sì fi kọ́ Geba àti Mispa.
Na Tokosra Asa el orani mwet in acn nukewa in Judah, ac sap elos in usla eot ac sak nukewa ma Baasha el orekmakin in acn Ramah, ac elos sang kuhlasak siti lun Geba ac Mizpah.
7 Ní àkókò náà wòlíì Hanani wá sí ọ̀dọ̀ Asa ọba Juda, ó sì wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ọba Siria, ìwọ kò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run rẹ, nítorí náà ni ogún ọba Siria ṣe bọ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ.
In pacl se ingan mwet palu Hanani el som nu yorol Tokosra Asa ac fahk, “Ke sripen kom nget nu sin tokosra lun Syria ac tia filiya finsrak lom in LEUM GOD, pwanang mwet mweun lun tokosra Israel elos kaingla liki inpoum.
8 Àwa kì í ṣe ará Etiopia àti àwọn ará Libia àwọn alágbára ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin? Síbẹ̀ nígbà tí ìwọ bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sì fi wọ́n lé ọwọ́ rẹ.
Ya tia puslana mwet mweun lun Ethiopia ac Libya, oayapa pukanten pac chariot ac mwet kasrusr fin horse? Tuh mweyen kom filiya finsrak lom sin LEUM GOD, pa oru El tuh sot kutangla nu sum.
9 Nítorí ojú Olúwa yí gbogbo ayé ká láti fi agbára fún àwọn ẹni tí ó ní ọkàn pípé sí i. Ìwọ ti ṣe ohun aṣiwèrè, láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ yóò wà lójú ogun.”
LEUM GOD El arulana suiya faclu nufon in sang ku nu selos su pwaye insialos nu sel. Kom orala ouiya na lalfon, na pa ingela tokosrai lom ac fah mweun pacl nukewa.”
10 Asa sì bínú pẹ̀lú sí wòlíì nítorí èyí, ó sì mú un bínú gidigidi tí ó sì fi mú un sínú túbú. Ní àkókò náà Asa sì ni díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn náà lára.
Kas inge oru Asa el kasrkusrak sin mwet palu sac, ac sapkin in kapuri el. In pacl se pacna inge Asa el mutawauk in akkeokye kutu mwet uh.
11 Àwọn iṣẹ́ ìjọba Asa, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni akọ sínú ìwé ọba Juda àti Israẹli.
Ma sikyak nukewa ke pacl Asa el tokosra, mutawauk nwe ke safla, simla oasr ke [Sramsram Matu ke Tokosra lun Judah ac Israel.]
12 Ní ọdún kọkàndínlógójì ìjọba rẹ̀, Asa sì ṣe àìsàn pẹ̀lú ààrùn nínú ẹsẹ̀ rẹ̀. Bi ó tilẹ̀ jẹ pé ààrùn rẹ̀ lágbára, síbẹ̀ kódà nínú àìsàn rẹ̀ kò wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ àwọn oníṣègùn nìkan.
In yac aktolngoul eu ke Asa el tokosra, nial ulla ke sie mas upa. Ne ouinge, el tiana forla in nget nu sin LEUM GOD in eis kasru sel, a el suk kasru sin mwet orek ono.
13 Nígbà náà tí ó pé ọdún kọ́kànlélógójì rẹ̀, Asa kú, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn ìjọba baba rẹ̀,
Yac luo toko na el misa,
14 wọ́n sì sin ín sínú isà òkú tí ó ti gbẹ́ jáde fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Wọ́n sì tẹ sí orí àkéte tí ó fi òórùn dídùn kún, àti onírúurú tùràrí tí a fi ọgbọ́n pèsè, wọ́n sì da iná ńlá nítorí rẹ̀.
ac el pukpuki inkulyuk eot se ma el taflela lal sifacna in Siti sel David. Elos mosrwela manol ke mwe akkeng ac oil keng in akoella nu ke pukpuki, ac elos tanak sie e lulap in akfulatyal.

< 2 Chronicles 16 >