< 2 Chronicles 16 >

1 Ní ọdún kẹrìndínlógójì ìjọba Asa, Baaṣa ọba Israẹli gòkè wá sí Juda ó sì kọlu Rama, láti ma bá a jẹ́ kí ẹnikẹ́ni lè jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba Juda lọ.
Then, in the thirty-sixth year of his reign, Baasha, the king of Israel, ascended against Judah. And he encircled Ramah with a wall, so that no one could safely depart or enter from the kingdom of Asa.
2 Nígbà náà ni Asa mú wúrà àti fàdákà jáde nínú ilé ìṣúra ilé Olúwa àti ààfin ọba ó sì ránṣẹ́ sí Beni-Hadadi ọba Siria, ẹni tí ń gbé ní Damasku, ó wí pé,
Therefore, Asa brought forth silver and gold from the treasuries of the house of the Lord, and from the treasuries of the king. And he sent to Benhadad, the king of Syria, who was living in Damascus, saying:
3 “Májẹ̀mú kan wà láàrín èmi àti ìrẹ, bí ó ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Ẹ wò ó, mo fi wúrà àti fàdákà ránṣẹ́ sí ọ; lọ, ba májẹ̀mú tí o bá Baaṣa ọba Israẹli dá jẹ́, kí ó lè lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.”
“There is a pact between me and you. Also, my father and your father had an agreement. For this reason, I have sent silver and gold to you, so that you may break the pact that you have with Baasha, the king of Israel, and so that you may cause him to withdraw from me.”
4 Beni-Hadadi sì gbọ́ ti Asa ọba, ó sì rán àwọn olórí ogun rẹ̀ lọ sí àwọn ìlú Israẹli, wọ́n sì kọlu Ijoni, Dani, Abeli-Maimu, àti gbogbo ìlú ìṣúra Naftali.
And when he verified this, Benhadad sent the leaders of his armies to the cities of Israel. And they struck Ahion, and Dan, and Abelmaim, and all the walled cities of Naphtali.
5 Nígbà tí Baaṣa gbọ́ èyí, ó sì dá kíkọ́ Rama dúró, ó sì dá iṣẹ́ rẹ̀ dúró.
And when Baasha had heard of it, he ceased to build around Ramah, and he interrupted his work.
6 Nígbà náà ní ọba Asa kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda jọ, wọ́n sì kó òkúta àti igi Rama lọ èyí ti Baaṣa ń fi kọ́lé; ó sì fi kọ́ Geba àti Mispa.
Then king Asa took all of Judah, and they carried away from Ramah the stones and the wood that Baasha had prepared for the things to be built. And he built up Gibeah and Mizpah with them.
7 Ní àkókò náà wòlíì Hanani wá sí ọ̀dọ̀ Asa ọba Juda, ó sì wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ọba Siria, ìwọ kò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run rẹ, nítorí náà ni ogún ọba Siria ṣe bọ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ.
In that time, the prophet Hanani went to Asa, the king of Judah, and he said to him: “Because you have faith in the king of Syria, and not in the Lord your God, therefore the army of the king of Syria has escaped from your hand.
8 Àwa kì í ṣe ará Etiopia àti àwọn ará Libia àwọn alágbára ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin? Síbẹ̀ nígbà tí ìwọ bá gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sì fi wọ́n lé ọwọ́ rẹ.
Were not the Ethiopians and the Libyans much more numerous in chariots, and horsemen, and an exceedingly great multitude? Yet when you believed in the Lord, he delivered them into your hand.
9 Nítorí ojú Olúwa yí gbogbo ayé ká láti fi agbára fún àwọn ẹni tí ó ní ọkàn pípé sí i. Ìwọ ti ṣe ohun aṣiwèrè, láti ìsinsin yìí lọ, ìwọ yóò wà lójú ogun.”
For the eyes of the Lord contemplate the entire earth, and offer fortitude to those who believe in him with a perfect heart. And so, you acted foolishly. And so, because of this, from the present time wars shall rise up against you.”
10 Asa sì bínú pẹ̀lú sí wòlíì nítorí èyí, ó sì mú un bínú gidigidi tí ó sì fi mú un sínú túbú. Ní àkókò náà Asa sì ni díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn náà lára.
And Asa was angry against the seer, and he ordered him to be sent into prison. For indeed, he had been very indignant over this. And in that time, he put to death very many of the people.
11 Àwọn iṣẹ́ ìjọba Asa, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni akọ sínú ìwé ọba Juda àti Israẹli.
But the works of Asa, the first and the last, have been written in the book of the kings of Judah and Israel.
12 Ní ọdún kọkàndínlógójì ìjọba rẹ̀, Asa sì ṣe àìsàn pẹ̀lú ààrùn nínú ẹsẹ̀ rẹ̀. Bi ó tilẹ̀ jẹ pé ààrùn rẹ̀ lágbára, síbẹ̀ kódà nínú àìsàn rẹ̀ kò wá ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ àwọn oníṣègùn nìkan.
And now Asa became ill, in the thirty-ninth year of his reign, with a very severe pain in his feet. And yet, in his infirmity, he did not seek the Lord. Instead, he trusted more in the skill of physicians.
13 Nígbà náà tí ó pé ọdún kọ́kànlélógójì rẹ̀, Asa kú, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn ìjọba baba rẹ̀,
And he slept with his fathers. And he died in the forty-first year of his reign.
14 wọ́n sì sin ín sínú isà òkú tí ó ti gbẹ́ jáde fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Wọ́n sì tẹ sí orí àkéte tí ó fi òórùn dídùn kún, àti onírúurú tùràrí tí a fi ọgbọ́n pèsè, wọ́n sì da iná ńlá nítorí rẹ̀.
And they buried him in his own sepulcher, which he had made for himself in the City of David. And they placed him upon his bed, full of the aromatics and ointments of courtesans, which were composed with the skill of the perfumers. And they burned these over him with very great ostentation.

< 2 Chronicles 16 >