< 2 Chronicles 15 >

1 Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Asariah ọmọ Odedi.
Och över Asarja, Odeds son, kom Guds Ande.
2 Ó jáde lọ bá Asa, ó sì wí fún un pé, “Tẹ́tí si mi Asa, àti gbogbo Juda àti Benjamini. Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nígbà tí ìwọ bá wà pẹ̀lú rẹ̀. Ti ìwọ bá wá a, ìwọ yóò rí i ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ bá kọ̀ ọ́ sílẹ̀, òun yóò kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
Han gick ut mot Asa och sade till honom: "Hören mig, du, Asa, och I, hela Juda och Benjamin. HERREN är med eder, när I ären med honom, och om I söken honom, så låter han sig finnas av eder; men om I övergiven honom, så övergiver han ock eder.
3 Fún ọjọ́ pípẹ́ ni Israẹli ti wà láì sin Ọlọ́run òtítọ́, àti láìní àlùfáà ti ń kọ́ ni, àti láìní òfin.
En lång tid var ju Israel utan den sanne Guden, utan präster som undervisade dem, och utan någon lag.
4 Ṣùgbọ́n nínú ìpọ́njú wọn, wọ́n yí padà si Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wọ́n sì wa kiri. Wọ́n sì ri i ní ẹ̀gbẹ́ wọn.
Men i sin nöd omvände de sig till HERREN, Israels Gud, och när de sökte honom, lät han sig finnas av dem.
5 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ó léwu kí ènìyàn máa rìn ìrìnàjò kiri, nítorí tí gbogbo àwọn olùgbé ilẹ̀ náà wà nínú làálàá ńlá.
Under de tiderna fanns ingen trygghet, när man gick ut eller in; utan stor förvirring rådde bland alla dem som bodde här i länderna,
6 Orílẹ̀-èdè kan ń run èkejì àti ìlú kan sí òmíràn nítorí Ọlọ́run ń yọ wọ́n lẹ́nu pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ìpọ́njú.
och folk drabbade samman med folk och stad med stad; ty Gud förvirrade dem med allt slags nöd.
7 Ṣùgbọ́n fun ìwọ, jẹ́ alágbára, kí ó má sì ṣe ṣàárẹ̀. Nítorí tí a ó fi èrè sí iṣẹ́ ẹ̀ rẹ.”
Men varen I frimodiga, låten icke modet falla, ty edert verk skall få sin lön."
8 Nígbà tí Asa gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí àti àsọtẹ́lẹ̀ Asariah ọmọ Odedi wòlíì, ó mú àyà rẹ̀ le. Ó sì mú gbogbo ohun ìríra kúrò ní gbogbo ilẹ̀ Juda àti Benjamini àti kúrò nínú àwọn ìlú tí ó ti fi agbára mú ní orí òkè Efraimu. Ó tún pẹpẹ Olúwa ṣe tí ó wà ní iwájú portiko ti ilé Olúwa.
När Asa hörde dessa ord och denna profetia av profeten Oded, tog han mod till sig och skaffade bort styggelserna ur Judas och Benjamins hela land och ur de städer som han hade tagit i Efraims bergsbygd, och upprättade åter HERRENS altare, det som stod framför HERRENS förhus.
9 Nígbà náà, ó pe gbogbo Juda àti Benjamini jọ àti àwọn ènìyàn láti Efraimu, Manase àti Simeoni tí ó ti ṣe àtìpó ní àárín wọn. Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Israẹli nígbà tí wọ́n rí i wí pé Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
Och han församlade hela Juda och Benjamin, så ock de främlingar ifrån Efraim, Manasse och Simeon, som bodde ibland dem; ty många från Israel hade gått över till honom, när de sågo att HERREN, hans Gud, var med honom.
10 Wọ́n péjọ sí Jerusalẹmu ní oṣù kẹta ọdún kẹ́ẹ̀dógún ti ìjọba Asa.
Och de församlade sig till Jerusalem i tredje månaden av Asas femtonde regeringsår,
11 Ní àkókò yìí, wọ́n rú ẹbọ sí Olúwa ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin akọ màlúù àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn àti àwọn ewúrẹ́ láti ibi ìkógun tí wọ́n ti kó padà.
och offrade på den dagen åt HERREN sju hundra tjurar och sju tusen djur av småboskapen, uttagna av det byte som de hade fört med sig.
12 Wọ́n sì tún dá májẹ̀mú láti wá Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn tinútinú wọn àti tọkàntọkàn wọn.
Och de ingingo det förbundet att de skulle söka HERREN, sina fäders Gud, av allt sitt hjärta och av all sin själ,
13 Pé ẹnikẹ́ni tí kò bá wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli, pípa ni á ó pa á láti ẹni kékeré dé orí ẹni ńlá àti ọkùnrin àti obìnrin.
och att var och en som icke sökte HERREN, Israels Gud, han skulle bliva dödad, liten eller stor, man eller kvinna.
14 Wọ́n sì búra ní ohùn rara fún Olúwa àti pẹ̀lú ìhó ńlá àti pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú fèrè.
Och de gåvo HERREN sin ed med hög röst och under jubel, och under det att trumpeter och basuner ljödo.
15 Gbogbo Juda yọ̀ nípa ìbúra náà nítorí wọ́n ti búra tinútinú wọn wọ́n sì fi gbogbo ìfẹ́ inú wọn wá a, wọ́n sì rí i, Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi yí káàkiri.
Och hela Juda gladde sig över eden; ty de hade svurit den av allt sitt hjärta, och de sökte HERREN med hela sin vilja, och han lät sig finnas av dem, och han lät dem få ro på alla sidor.
16 Ọba Asa sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
Konung Asa avsatte ock sin moder Maaka från hennes drottningsvärdighet, därför att hon hade satt upp en styggelse åt Aseran; Asa högg nu ned styggelsen och krossade de och brände upp den i Kidrons dal.
17 Ṣùgbọ́n a kò mú àwọn ibi gíga náà kúrò ní Israẹli; síbẹ̀síbẹ̀ ọkàn Asa wà ní pípé ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
Men offerhöjderna blevo icke avskaffade ur Israel; dock var Asas hjärta gudhängivet, så länge han levde.
18 Ó sì mú àwọn ohun mímọ́ náà ti baba rẹ̀ àti àwọn ohun mímọ́ ti òun tìkára rẹ̀ tirẹ̀ wá sínú ilé Ọlọ́run, wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò náà.
Och han förde in i Guds hus både vad hans fader och vad han själv hade helgat åt HERREN: silver, guld och kärl.
19 Kò sí ogun mọ́ títí fún ọdún márùndínlógójì ti ìjọba Asa.
Och intet krig uppstod förrän i Asas trettiofemte regeringsår.

< 2 Chronicles 15 >