< 1 Samuel 9 >

1 Ará Benjamini kan wà, ẹni tí ó jẹ́ aláàánú ọlọ́rọ̀, orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Kiṣi, ọmọ Abieli, ọmọ Serori, ọmọ Bekorati, ọmọ Afiah ti Benjamini.
HOOKAHI kanaka no ka Beniamina, o Kisa kona inoa, ke keiki a Abiela, ke keiki a Zerora, ke keiki a Bekorata, ke keiki a Apia, no Beniamina, he kanaka waiwai nui.
2 Ó ní ọmọkùnrin kan tí à ń pè ní Saulu, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó yanjú, tí ó jẹ́ arẹwà, tí kò sí ẹni tó ní ẹwà jù ú lọ láàrín gbogbo àwọn ọmọ Israẹli—láti èjìká rẹ̀ lọ sí òkè, ó ga ju gbogbo àwọn ènìyàn tókù lọ.
He keiki kana, o Saula kona inoa, he opiopio a maikai: aohe kanaka maikai iwaena o na mamo a Iseraela e like ana me ia: mai kona poohiwi aku a hala loa iluna, ka oi ana o kona kiekie mamua o ko na kanaka a pau.
3 Nísinsin yìí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó jẹ́ ti Kiṣi baba Saulu sì sọnù. Nígbà náà, Kiṣi sọ fún Saulu ọmọ rẹ̀ pé, “Mú ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ pẹ̀lú rẹ kí ẹ lọ láti wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.”
Ua nalowale na hoki a Kisa, ka makuakane o Saula; i aku la o Kisa i kana keiki, ia Saula, E lawe oe i kekahi kauwa me oe, a hele e imi i na hoki.
4 Bẹ́ẹ̀ ní ó kọjá láàrín àwọn ìlú olókè Efraimu, ó sì kọjá ní àyíká ilẹ̀ Ṣaliṣa, ṣùgbọ́n wọn kò rí wọn. Wọ́n sì kọjá lọ sí òpópó Ṣaalimu, ṣùgbọ́n àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kò sí níbẹ̀. Nígbà náà, ó kọjá ní agbègbè Benjamini, wọn kò sì rí wọn.
Kaahele no ia ma ka mauna o Eperaima, a kaahele hoi ma ka aina o Salisa, aole i loaa ia laua; alaila kaahele laua ma ka aina o Salima, aole malaila; hele aku la ia ma ka aina o ka Beniamina, aole i loaa ia laua.
5 Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Sufu, Saulu sọ fún ìránṣẹ́ tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí á padà sẹ́yìn, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, baba mi yóò dá ìrònú rẹ̀ dúró nípa àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ yóò sì bẹ̀rẹ̀ àníyàn nípa wa.”
A hiki aku la laua ma ka aina o Zupa, i aku la ia i kana kauwa me ia, Ea, e hoi kaua, o pau auanei ka manao ana o kuu makuakane i na hoki, a hookaumahaia no kaua.
6 Ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ náà fún un ní èsì pé, “Wò ó, ní inú ìlú yìí ọkùnrin ènìyàn Ọlọ́run kan wà; ó jẹ́ ẹni tí wọ́n ń bu ọlá fún, àti gbogbo ohun tí ó bá sọ ní ó máa ń jẹ́ òtítọ́. Jẹ́ kí á lọ síbẹ̀ nísinsin yìí, bóyá yóò sọ fún wá ọ̀nà tí a yóò gbà.”
I mai la kela ia ia, Aia hoi, ma keia kulanakauhale e noho ana kekahi kanaka o ke Akua, he kanaka kaulana: a o ka mea a pau ana e olelo ai, e ko io no ia: e nele kaua malaila, malama e hiki ia ia ke kuhikuhi mai ia kaua i ke ala e pono ai kaua ke hele.
7 Saulu sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀, “Tí àwa bá lọ, kín ni àwa lè fún ọkùnrin náà? Oúnjẹ inú àpò wa ti tán. A kò sì ní ẹ̀bùn láti mú lọ sọ́dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Kí ni a ní?”
I aku la o Saula i kana kauwa, Ina paha e hele kaua, heaha ka kaua e lawe aku ai i ua kanaka la? No ka mea, ua pau ka berena maloko o ko kaua ipu, aole he manawalea e lawe aku i ua kanaka la o ke Akua: heaha ka mea ia kaua?
8 Ìránṣẹ́ sì dá a lóhùn lẹ́ẹ̀kan sí i. “Wò ó,” ó wí pé, “Mo ní ìdámẹ́rin ṣékélì fàdákà lọ́wọ́. Èmi yóò fún ènìyàn Ọlọ́run náà kí ó lè fi ọ̀nà hàn wá.”
Olelo hou mai la ke kauwa ia Saula, i mai la, Eia ma kuu lima ka hapaha o ke sekela kala; o keia ka'u e haawi aku ai i ua kanaka la o ke Akua, i kuhikuhi mai ai ia i ke ala o kaua.
9 (Tẹ́lẹ̀ ní Israẹli tí ọkùnrin kan bá lọ béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run, yóò wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì náà,” nítorí àwọn alásọtẹ́lẹ̀ ìsinsin yìí ni wọ́n ń pè ní wòlíì).
(I ka manawa mamua iloko o ka Iseraela, a i hele ke kanaka e ninau i ke Akua, peneia ia i olelo ai, Ina kakou e hele i ka mea ike; no ka mea, o ke kaula i keia manawa, ua kapaia oia mamua, he mea ike.)
10 Saulu sọ fún ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ pé ó dára, “Jẹ́ kí a lọ.” Wọ́n jáde lọ sí ìlú tí ènìyàn Ọlọ́run náà ń gbé.
I aku la o Saula i kana kauwa, Ua pono kau olelo; ina kaua e hele aku: a hele aku la laua i ke kulanakauhale, i kahi o ke kanaka o ke Akua.
11 Bí wọ́n ṣe ń lọ ní orí òkè sí ìlú náà, wọ́n pàdé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin tí ó ń jáde í bọ̀ láti wá pọn omí. Wọ́n sì bi wọ́n, “Ṣé wòlíì náà wà níbí?”
A i ka laua pii ana i ke kulanakauhale, loaa ia laua na kaikamahine e hele ana e huki wai, i aku la ia lakou, Maanei anei ke kanaka ike?
12 “Ó wà,” wọ́n dáhùn. “Ó ń bẹ níwájú u yín, múra nísinsin yìí, ó ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ wa lónìí ni, nítorí àwọn ènìyàn ní ẹbọ rírú ni ibi gíga.
Olelo mai la lakou ia laua, i mai la, Maanei no: aia hoi ia mamua ou, e wikiwiki, no ka mea, i hele mai ia i ke kulanakauhale i keia la; no ka mea, he ahaaina na na kanaka i keia la ma kahi kiekie.
13 Kété tí ẹ bá ti wọ ìlú, ẹ ó rí i kí ó tó lọ sí ibi gíga láti lọ jẹun. Àwọn ènìyàn kò sì ní bẹ̀rẹ̀ sí jẹun títí tí yóò fi dé. Torí ó gbọdọ̀ bùkún ẹbọ náà; lẹ́yìn náà, àwọn tí a pè yóò jẹun. Gòkè lọ nísinsin yìí, ó yẹ kí ẹ rí i ní àkókò yìí.”
A hiki aku olua maloko o ke kulanakauhale, e loaa koke oia ia olua, mamua o kona pii ana ae ma kahi kiekie e ai ai; aole e ai na kanaka a hiki aku ia; no ka mea, nana no e hoomaikai aku i ka ahaaina, a mahope iho, ai no ka poe i oleloia. No ia mea, e pii olua; no ka mea, eia ka la e loaa'i ia olua ia.
14 Wọ́n gòkè lọ sí ìlú náà, bí wọ́n ti ń wọlé, níbẹ̀ ni Samuẹli, ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ wọn bí ó ti ń lọ ibi gíga náà.
A pii aku la laua i ke kulanakauhale: a hiki laua iloko o ke kulanakauhale, aia hoi, halawai laua me Samuela e pii ana ma kahi kiekie.
15 Olúwa ti sọ létí Samuẹli ní ọjọ́ kan kí Saulu ó tó dé pé,
Ua olelo e mai o Iehova i ka pepeiao o Samuela i ka la mamua o ko Saula hiki ana mai, i mai la,
16 “Ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò ran ọmọkùnrin kan sí ọ láti ilẹ̀ Benjamini. Fi òróró yàn án gẹ́gẹ́ bí olórí lórí àwọn ọmọ Israẹli, yóò gba àwọn ènìyàn mi kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Filistini. Mo ti bojú wo àwọn ènìyàn mi, nítorí igbe wọn ti dé ọ̀dọ̀ mi.”
Apopo ma keia manawa, e hoouna aku au i ou la i kekahi kanaka no ka aina o ka Beniamina, a e poni aku oe ia ia i alii maluna o kuu poe kanaka o ka Iseraela, i hoopakele mai ai ia i ko'u poe kanaka mai ka lima mai o ko Pilisetia: ua nana aku au i ko'u poe kanaka, no ka mea, ua hiki mai ko lakou uwe ana io'u nei.
17 Nígbà tí Samuẹli fojúrí Saulu, Olúwa sọ fún un pé, “Èyí ni ọkùnrin tí mo sọ fún ọ nípa rẹ̀, yóò darí àwọn ènìyàn mi.”
A ike aku la o Samuela ia Saula, olelo mai la o Iehova ia ia, Eia ke kanaka a'u i olelo ai ia oe; oia ka mea e alii ai maluna o kuu poe kanaka.
18 Saulu sì súnmọ́ Samuẹli ní ẹnu-ọ̀nà ìlú, ó sì wí pé, “Sọ fún mi èmi ń bẹ̀ ọ́ níbo ni ilé wòlíì náà wà.”
Hookokoke aku la o Saula ia Samuela ma ka ipuka pa, i aku la, Ke noi aku nei au ia oe, e hai mai oe ia'u i ka hale o ka mea ike.
19 Samuẹli dáhùn pé, “Èmi ni wòlíì náà. Ẹ máa gòkè lọ ṣáájú mi, ní ibi gíga, ẹ ó sì bá mi jẹun lónìí. Ní òwúrọ̀ ni èmi yóò tó jẹ́ kí ẹ lọ, gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ ní èmi yóò sọ fún ọ.
Olelo mai la o Samuela ia Saula, i mai la, Owau no ka mea ike; e pii ae oe mamua o'u i kahi kiekie: no ka mea, e ai pu olua me au i keia la; apopo e kuu aku au ia oe, a e hai aku au i na mea a pau maloko o kou naau.
20 Fún ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó sọnù fún ọjọ́ mẹ́ta sẹ́yìn, má ṣe dààmú nípa wọ́n: a ti rí wọn. Sí ta ni gbogbo ìfẹ́ Israẹli wà? Bí kì í ṣe sí ìwọ àti sí gbogbo ilé baba à rẹ.”
A no kau mau hoki i nalowale i na la ekolu ae nei, mai manao oe ia lakou, no ka mea, ua loaa lakou. Maluna owai anei ka makemake a pau o ka Iseraela? Aole anei maluna ou, a me ko ka hale a pau o kou makuakane?
21 Saulu dáhùn pé, “Ṣùgbọ́n èmi kì í há ṣe ẹ̀yà Benjamini? Kékeré nínú ẹ̀yà Israẹli. Ìdílé mi kò ha rẹ̀yìn jùlọ nínú gbogbo ẹ̀yà Benjamini? Èéṣì ti ṣe tí ìwọ sọ̀rọ̀ yìí sí mi?”
Olelo aku la o Saula, i aku la, Aole anei wau no ka Beniamina, no ka mea uuku o na hanauna a pau o ka Iseraela? a o kuu ohana ka mea uuku o na ohana a pau o ka Beniamina? no ke aha la oe i olelo mai ai ia'u pela?
22 Nígbà náà ni Samuẹli mú Saulu pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ inú gbọ̀ngán, ó sì mú wọn jókòó sí iwájú àwọn tí a pè—tí wọn tó ọgbọ̀n.
Lawe aku la o Samuela ia Saula a me kana kauwa, alakai ia laua maloko o ke keena ai, a hoonoho ia laua ma kahi maikai iwaena o ka poe i oleloia, he kanakolu paha lakou.
23 Samuẹli sọ fún alásè pé, “Mú ìpín ẹran tí mo fún ọ wá, èyí tí mo sọ fún ọ pé kí o yà sọ́tọ̀.”
Olelo aku la o Samuela i ke kahu ai, E lawe mai i kahi a'u i haawi aku ai ia oe, i ka mea a'u i olelo ai ia oe, E waiho ia me oe.
24 Alásè náà sì gbé ẹsẹ̀ náà pẹ̀lú ohun tí ó wà lórí i rẹ̀, ó sì gbé e síwájú Saulu. Samuẹli wí pé, “Èyí ni ohun tí a fi pamọ́ fún ọ. Jẹ, nítorí a yà á sọ́tọ̀ fún ọ, fún ìdí yìí, láti ìgbà tí mo ti wí pé, ‘Mo ní àlejò tí a pè.’” Saulu sì jẹun pẹ̀lú Samuẹli ní ọjọ́ náà.
Lawe ae la ke kahu ai i ka uha mua, a me ka mea maluna, a waiho imua o Saula. I aku la o [Samuela, ] Aia hoi o ke koena, e waiho ia imua ou, a e ai oe; no ka mea, ua hookaawale ia mea nau no ka manawa a'u i olelo ai, ua kahea aku au i na kanaka. A ai pu iho la o Saula me Samuela ia la.
25 Lẹ́yìn ìgbà tí wọn ti sọ̀kalẹ̀ láti ibí gíga náà wá sí inú ìlú, Samuẹli sì bá Saulu sọ̀rọ̀ lórí òrùlé ilé e rẹ̀.
A iho mai lakou mai kahi kiekie mai a i ke kulanakauhale, kamailio pu oia me Saula maluna o ka hale.
26 Wọ́n sì dìde ní àfẹ̀mọ́júmọ́, ó pe Saulu sórí òrùlé pé, “Múra, èmi yóò rán ọ lọ.” Nígbà tí Saulu múra tán òun àti Samuẹli jọ jáde lọ síta.
Ala ae la lakou i kakahiaka nui; a i ka wanaao, kahea aku la o Samuela ia Saula maluna o ka hale, i aku la, E ala, a hoouna aku au ia oe. Ala mai o Saula, a hele aku la laua iwaho, oia a me Samuela.
27 Bí wọ́n ti ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìpẹ̀kun ìlú náà, Samuẹli wí fún Saulu pé, “Sọ fún ìránṣẹ́ náà kí ó máa lọ ṣáájú u wa,” ìránṣẹ́ náà sì ṣe bẹ́ẹ̀, “Ṣùgbọ́n kí ìwọ kí ó dúró díẹ̀, kí èmi kí ó lè sọ ọrọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run fún ọ.”
A i ko laua iho ana ma ka mokuna o ke kulanakauhale, i aku la o Samuela ia Saula, E i aku oe i ke kauwa, e hele e aku ia mamua o kaua, (a hele aku la ia, ) aka, e ku malie oe i keia wa, i hoike aku ai au ia oe i ka olelo a ke Akua.

< 1 Samuel 9 >