< 1 Samuel 30 >

1 Ó sì ṣe nígbà ti Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì bọ̀ sí Siklagi ní ọjọ́ kẹta, àwọn ará Amaleki sì ti kọlu ìhà gúúsù, àti Siklagi, wọ́n sì ti kùn ún ní iná.
Or trois jours après David et ses gens étant revenus à Tsiklag, [trouvèrent] que les Hamalécites s'étaient jetés du côté du Midi, et sur Tsiklag, et qu'ils avaient frappé Tsiklag, et l'avaient brûlée;
2 Wọ́n sì kó àwọn obìnrin tí ń bẹ nínú rẹ̀ ní ìgbèkùn, wọn kò sì pa ẹnìkan, ọmọdé tàbí àgbà, ṣùgbọ́n wọ́n kó wọn lọ, wọ́n sì bá ọ̀nà tiwọn lọ.
Et qu'ils avaient fait prisonnières les femmes qui étaient là, sans avoir tué aucun homme, depuis les plus petits jusqu'aux plus grands: mais ils les avaient emmenés, et s'en étaient allés leur chemin.
3 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin sì wọ ìlú Siklagi, sì wò ó, a ti kùn ún ni iná; àti obìnrin wọn, àti ọmọkùnrin wọn àti ọmọbìnrin wọn ni a kó ni ìgbèkùn lọ.
David donc et ses gens revinrent en la ville: et voici elle était brûlée, et leurs femmes, et leurs fils, et leurs filles avaient été faits prisonniers.
4 Dafidi àti àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún títí agbára kò fi sí fún wọn mọ́ láti sọkún.
C'est pourquoi David et le peuple qui était avec lui élevèrent leur voix, et pleurèrent tellement qu'il n'y avait plus en eux de force pour pleurer.
5 A sì kó àwọn aya Dafidi méjèèjì nígbèkùn lọ, Ahinoamu ará Jesreeli àti Abigaili aya Nabali ará Karmeli.
Et les deux femmes de David avaient été prises prisonnières, [savoir] Ahinoham de Jizréhel, et Abigaïl [qui avait été] femme de Nabal, lequel était de Carmel.
6 Dafidi sì banújẹ́ gidigidi, nítorí pé àwọn ènìyàn náà sì ń sọ̀rọ̀ láti sọ ọ́ lókùúta, nítorí ti inú gbogbo àwọn ènìyàn náà sì bàjẹ́, olúkúlùkù ọkùnrin nítorí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti nítorí ọmọ rẹ̀ obìnrin ṣùgbọ́n Dafidi mú ara rẹ̀ lọ́kàn le nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Mais David fut dans une grande extrémité, parce que le peuple parlait de le lapider; car tout le peuple était outré à cause de leurs fils et de leurs filles; toutefois David se fortifia en l'Eternel son Dieu.
7 Dafidi sì wí fún Abiatari àlùfáà, ọmọ Ahimeleki pé, èmí bẹ̀ ọ́, mú efodu fún mi wá níhìn-ín yìí. Abiatari sì mú efodu náà wá fún Dafidi.
Et il dit à Abiathar le Sacrificateur, fils d'Ahimélec: Mets, je te prie, l'Ephod pour moi; et Abiathar mit l'Ephod pour David.
8 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa wí pé, “Kí èmi ó lépa ogun yìí bi? Èmi lè bá wọn?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Lépa, nítorí pé ni bíbá ìwọ yóò bá wọn, ni gbígbà ìwọ yóò sì rí wọn gbà.”
Et David consulta l'Eternel, en disant: Poursuivrai-je cette troupe-là; l'atteindrai-je? et il lui répondit: Poursuis-la; car tu ne manqueras point de l'atteindre, et de recouvrer [tout].
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wá sí ibi àfonífojì Besori, apá kan sì dúró.
David donc s'en alla avec les six cents hommes qui étaient avec lui, et ils arrivèrent au torrent de Bésor, où s'arrêtèrent ceux qui demeuraient en arrière.
10 Ṣùgbọ́n Dafidi àti irinwó ọmọkùnrin lépa wọn: igba ènìyàn tí àárẹ̀ mú, tiwọn kò lè kọjá odò Besori sì dúró lẹ́yìn.
Ainsi David et quatre cents hommes firent la poursuite, mais deux cents hommes s'arrêtèrent, qui étaient trop fatigués pour pouvoir passer le torrent de Bésor.
11 Wọ́n sì rí ará Ejibiti kan ní oko, wọ́n sì mú un tọ Dafidi wá, wọ́n sì fún un ní oúnjẹ, ó sì jẹ; wọ́n sì fún un ní omi mu.
Or ayant trouvé un homme Egyptien par les champs, ils l'amenèrent à David, et lui donnèrent du pain, et il mangea, puis ils lui donnèrent de l'eau à boire.
12 Wọ́n sì fún un ní àkàrà, èso ọ̀pọ̀tọ́ àti síírí àjàrà gbígbẹ́ méjì: nígbà tí ó sì jẹ ẹ́ tán, ẹ̀mí rẹ̀ sì sọjí: nítorí pé kò jẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi ní ọjọ́ mẹ́ta ní ọ̀sán, àti ní òru.
Ils lui donnèrent aussi quelques figues sèches, et deux grappes de raisins secs, et il mangea, et le cœur lui revint; car il y avait trois jours et trois nuits qu'il n'avait point mangé de pain, ni bu d'eau.
13 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ? Àti níbo ni ìwọ ti wá?” Òun sì wí pé, “Ọmọ ará Ejibiti ni èmi, ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin kan ará Amaleki. Olúwa mi fi mí sílẹ̀, nítorí pé láti ọjọ́ mẹ́ta ni èmi ti ṣe àìsàn.
Et David lui dit: A qui es-tu? et d'où es-tu? Et il répondit: Je suis un garçon Egyptien, serviteur d'un homme Hamalécite; et mon maître m'a abandonné, parce que je tombai malade il y a trois jours.
14 Àwa sì gbé ogun lọ sí ìhà gúúsù tí ará Kereti, àti sí ìhà ti Juda, àti sí ìhà gúúsù ti Kalebu; àwa sì kun Siklagi ní iná.”
Nous nous étions jetés du côté du Midi des Keréthiens, et sur ce qui est de Juda, et du côté du Midi de Caleb, et nous avons brûlé Tsiklag par feu.
15 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ìwọ lè mú mí sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun yìí lọ bí?” Òun sì wí pé, “Fi Ọlọ́run búra fún mi pé, ìwọ kì yóò pa mí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò sì fi mi lé olúwa mi lọ́wọ́; èmi yóò sì mú ọ sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun náà lọ.”
Et David lui dit: Me conduiras-tu bien vers cette troupe-là? Et il répondit: Jure-moi par [le nom de] Dieu que tu ne me feras point mourir, et que tu ne me livreras point entre les mains de mon maître, et je te conduirai vers cette troupe-là.
16 Ó sì mú un sọ̀kalẹ̀, sì wò ó, wọ́n sì tàn ká ilẹ̀, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n sì ń jó, nítorí ìkógun púpọ̀ tí wọ́n kó láti ilẹ̀ àwọn Filistini wá, àti láti ilẹ̀ Juda.
Et il le conduisit dans ce lieu-là. Et voici, ils étaient dispersés sur toute la terre, mangeant, buvant, et dansant, à cause de ce grand butin qu'ils avaient pris au pays des Philistins, et au pays de Juda.
17 Dafidi sì pa wọ́n láti àfẹ̀mọ́júmọ́ títí ó fi di àṣálẹ́ ọjọ́ kejì: kò sí ẹnìkan tí ó là nínú wọn, bí kọ̀ ṣe irinwó ọmọkùnrin tí wọ́n gun ìbákasẹ tí wọ́n sì sá.
Et David les frappa depuis l'aube du jour jusqu'au soir du lendemain qu'il s'était mis à les poursuivre; et il n'en échappa aucun d'eux, hormis quatre cents jeunes hommes qui montèrent sur des chameaux, et qui s'enfuirent.
18 Dafidi sì gbà gbogbo nǹkan tí àwọn ará Amaleki ti kó: Dafidi sì gba àwọn obìnrin rẹ̀ méjèèjì.
Et David recouvra tout ce que les Hamalécites avaient emporté; il recouvra aussi ses deux femmes.
19 Kò sì ṣí nǹkan tí ó kù fún wọn, kékeré tàbí ńlá, ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin, tàbí ìkógun, tàbí gbogbo nǹkan tí wọ́n ti kó: Dafidi sì gba gbogbo wọn.
Et ils trouvèrent que rien ne leur manquait, depuis le plus petit jusqu'au plus grand, tant des fils que des filles, et du butin, et de tout ce qu'ils leur avaient emporté; David recouvra le tout.
20 Dafidi sì kó gbogbo àgùntàn, àti màlúù tí àwọn ènìyàn rẹ̀ dà ṣáájú àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn tí wọ́n gbà, wọ́n sì wí pé, “Èyí yìí ni ìkógun ti Dafidi.”
David prit aussi tout le [reste du] gros et du menu bétail, qu'on mena devant les troupeaux [qu'on leur avait pris]; [et] on disait: C'est ici le butin de David.
21 Dafidi sì wá sọ́dọ̀ igba ọkùnrin tí àárẹ̀ ti mú jú, tiwọn kò lè tọ́ Dafidi lẹ́yìn mọ́, ti òun ti fi sílẹ̀, ni àfonífojì Besori: wọ́n sì lọ pàdé Dafidi, àti láti pàdé àwọn ènìyàn tí ó lọ pẹ̀lú rẹ̀: Dafidi sì pàdé àwọn ènìyàn náà, ó sì kí wọn.
Puis David vint vers les deux cents hommes qui avaient été tellement fatigués qu'ils n'avaient pu marcher après David, qui les avait fait demeurer auprès du torrent de Bésor; et ils sortirent au devant de David, et au devant du peuple qui était avec lui; et David s'étant approché du peuple, il les salua aimablement.
22 Gbogbo àwọn ènìyàn búburú àti àwọn ọmọ Beliali nínú àwọn tí o bá Dafidi lọ sì dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Bí wọn kò ti bá wa lọ, àwa ki yóò fi nǹkan kan fún wọn nínú ìkógun ti àwa rí gbà bí kò ṣe obìnrin olúkúlùkù wọn, àti ọmọ wọn; ki wọn sì mú wọn, ki wọn sì máa lọ.”
Mais tous les mauvais et méchants hommes qui étaient allés avec David, prirent la parole, et dirent: Puisqu'ils ne sont point venus avec nous, nous ne leur donnerons rien du butin que nous avons recouvré, sinon à chacun d'eux sa femme et ses enfants, et qu'ils les emmènent, et s'en aillent.
23 Dafidi sì wí pé, “Ẹ má ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ara mi: Olúwa ni ó fi nǹkan yìí fún wa, òun ni ó sì pa wá mọ́, òun ni ó sì fi ẹgbẹ́ ogun ti ó dìde sí wa lé wa lọ́wọ́.
Mais David dit: Mes frères, vous ne ferez pas ainsi de ce que l'Eternel nous a donné, lequel nous a gardés, et a livré entre nos mains la troupe qui était venue contre nous.
24 Ta ni yóò gbọ́ tiyín nínú ọ̀ràn yìí? Ṣùgbọ́n bi ìpín ẹni tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ si ìjà ti rí, bẹ́ẹ̀ ni ìpín ẹni ti ó dúró ti ẹrù; wọn ó sì pín in bákan náà.”
Qui vous croirait en ce cas-ci? car celui qui demeure au bagage doit avoir autant de part que celui qui descend à la bataille; ils partageront également.
25 Láti ọjọ́ náà lọ, ó sì pàṣẹ, ó sì sọ ọ di òfin fún Israẹli títí di òní yìí.
Ce qui fut ainsi pratiqué depuis ce jour-là, et il en fut fait une ordonnance et une loi en Israël, jusqu'à ce jour.
26 Dafidi sì padà sí Siklagi, ó sì rán nínú ìkógun náà si àwọn àgbàgbà Juda, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ni ẹ̀bùn fún un yín, láti inú ìkógun àwọn ọ̀tá Olúwa wa.”
David donc revint à Tsiklag, et envoya du butin aux Anciens de Juda, [savoir] à ses amis, en disant: Voici, un présent pour vous, du butin des ennemis de l'Eternel.
27 Ó sì rán an sí àwọn tí ó wà ni Beteli àti sí àwọn tí ó wà ní gúúsù tí Ramoti, àti sí àwọn tí ó wà ní Jattiri.
[Il en envoya] à ceux qui étaient à Béthel, et à ceux qui étaient à Ramoth du Midi, et à ceux qui étaient à Jattir,
28 Àti sí àwọn tí ó wà ní Aroeri, àti sí àwọn tí ó wà ní Sifimoti, àti sí àwọn tí ó wà ni Eṣitemoa.
Et à ceux qui étaient à Haroher, et à ceux qui étaient à Siphamoth, et à ceux qui étaient à Estemoah,
29 Àti si àwọn tí ó wà ni Rakeli, àti sí àwọn tí ó wà ní ìlú àwọn Jerahmeeli, àti sí àwọn tí ó wà ni ìlú àwọn ará Keni,
Et à ceux qui étaient à Racal, et à ceux qui étaient dans les villes des Jerahméeliens, et à ceux qui étaient dans les villes des Kéniens,
30 àti sí àwọn tí ó wà ni Horma, àti sí àwọn ti ó wà ní Bori-Aṣani, àti sí àwọn tí ó wà ni Ataki.
Et à ceux qui étaient à Horma, et à ceux qui étaient à Cor-hasan, et à ceux qui étaient à Hathac,
31 Àti àwọn tí ó wà ni Hebroni, àti sí gbogbo àwọn ìlú ti Dafidi tìkára rẹ̀ àti tí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ máa ń rìn ká.
Et à ceux qui étaient à Hébron, et dans tous les lieux où David avait demeuré, lui et ses gens.

< 1 Samuel 30 >