< 1 Samuel 23 >

1 Wọ́n sì wí fún Dafidi pé, “Sá wò ó, àwọn ará Filistini ń bá ará Keila jagun, wọ́n sì ja àwọn ilẹ̀ ìpakà lólè.”
A LAILA hai aku la lakou ia Davida, i aku la, Aia hoi, ke kaua mai nei ko Pilisetia i Keila, a hao wale lakou ma kahi hehi palaoa.
2 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa pé, “Ṣé kí èmi ó lọ kọlu àwọn ará Filistini wọ̀nyí bí?” Olúwa sì wí fún Dafidi pé, “Lọ kí o sì kọlu àwọn ará Filistini kí o sì gba Keila sílẹ̀.”
No ia mea, ninau aku la o Davida ia Iehova, i aku la, E hele anei au e pepehi i keia poe o ko Pilisetia? I mai la o Iehova ia Davida, O hele a pepehi aku i ko Pilisetia, a e hoopakele i ko Keila.
3 Àwọn ọmọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Dafidi sì wí fún un pé, “Wò ó, àwa ń bẹ̀rù níhìn-ín yìí ní Juda; ǹjẹ́ yóò ti rí nígbà ti àwa bá dé Keila láti fi ojú ko ogun àwọn ara Filistini?”
Olelo mai na kanaka o Davida ia ia, Aia hoi, ke makau nei kakou maanei maloko o ka Iuda: aole anei he nui aku, ke hele kakou ma Keila e ku e i ka poe kaua no ko Pilisetia?
4 Dafidi sì tún béèrè lọ́dọ̀ Olúwa. Olúwa sì dá a lóhùn, ó sì wí pé, “Dìde, kí o sọ̀kalẹ̀ lọ sí Keila, nítorí pé èmi ó fi àwọn ará Filistini náà lé ọ lọ́wọ́.”
A ninau hou aku la o Davida ia Iehova. Olelo mai la o Iehova ia ia, i mai la, E ku ae e hele ma Keila; no ka mea, e hoolilo au i ko Pilisetia iloko o kou lima.
5 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ sí Keila, wọ́n sì bá àwọn ará Filistini jà, wọ́n sì kó ohun ọ̀sìn wọn, wọ́n sì fi ìparun ńlá pa wọ́n. Dafidi sì gba àwọn ará Keila sílẹ̀.
A hele aku la o Davida me kona poe kanaka ma Keila, a kaua aku i ko Pilisetia, a lawe aku i ko lakou holoholona, a pepehi aku ia lakou me ka luku nui. A hoopakele o Davida i na kanaka o Keila.
6 Ó sì ṣe, nígbà tí Abiatari ọmọ Ahimeleki fi sá tọ Dafidi lọ ní Keila, ó sọ̀kalẹ̀ òun pẹ̀lú efodu kan lọ́wọ́ rẹ̀.
A i ka holo ana o Abiatara ke keiki a Ahimeleka io Davida la i Keila, ua hele no ia me ka epoda ma kona lima.
7 A sì sọ fún Saulu pé Dafidi wá sí Keila. Saulu sì wí pé, “Ọlọ́run ti fi í lé mi lọ́wọ́; nítorí tí ó ti sé ara rẹ̀ mọ́ ní ti wíwá tí ó wá sí ìlú tí ó ní ìlẹ̀kùn àti kẹrẹ.”
Ua haiia ia Saula ko Davida hele ana ma Keila. I mai la o Saula, Ua hoolilo mai ke Akua ia ia iloko o kuu lima; no ka mea, ua paa ia maloko, i kona komo ana i ke kulanakauhale i paa i na ipuka a me na kaola.
8 Saulu sì pe gbogbo àwọn ènìyàn náà jọ sí ogun, láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Keila, láti ká Dafidi mọ́ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀.
Houluulu ae la o Saula i na kanaka a pau i ke kaua, o hele ma Keila, e hoopaa aku ia Davida a me kona poe kanaka.
9 Dafidi sì mọ̀ pé Saulu ti gbèrò búburú sí òun; ó sì wí fún Abiatari àlùfáà náà pé, “Mú efodu náà wá níhìn-ín yìí!”
A ike iho la o Davida, ua manao ino malu mai o Saula ia ia; i aku la oia ia Abiatara ke kahuna, E lawe mai i ka epoda.
10 Dafidi sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, lóòótọ́ ni ìránṣẹ́ rẹ ti gbọ́ pé Saulu ń wá ọ̀nà láti wá sí Keila, láti wá fọ́ ìlú náà nítorí mi.
Alaila i aku la o Davida, E Iehova ke Akua o ka Iseraela, ua lohe akaka iho nei kau kauwa i ka manao ana o Saula e hele mai nei i Keila e luku i ke kulanakauhale no'u nei.
11 Àwọn àgbà ìlú Keila yóò fi mí lé e lọ́wọ́ bí? Saulu yóò ha sọ̀kalẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ rẹ ti gbọ́ bí?” Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èmi bẹ̀ ọ́, wí fún ìránṣẹ́ rẹ. Olúwa sì wí pé, “Yóò sọ̀kalẹ̀ wá.”
E haawi anei na kanaka o Keila ia'u iloko o kona lima? E iho mai anei o Saula e like me kau kauwa i lohe ai? E Iehova ke Akua o ka Iseraela, ke noi aku nei au ia oe, e hai mai oe i kau kauwa. I mai la o Iehova, E iho mai no.
12 Dafidi sì wí pé, “Àwọn àgbà ìlú Keila yóò fi èmi àti àwọn ọmọkùnrin mi lé Saulu lọ́wọ́ bí?” Olúwa sì wí pé, “Wọn ó fi ọ́ lé wọn lọ́wọ́.”
I aku la o Davida, E haawi anei na kanaka o Keila ia'u a me kuu poe kanaka iloko o ka lima o Saula? I mai la o Iehova, E haawi no lakou.
13 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ tí wọ́n tó ẹgbẹ̀ta ènìyàn sì dìde, wọ́n lọ kúrò ní Keila, wọ́n sì lọ sí ibikíbi tí wọ́n lè rìn lọ. A sì wí fún Saulu pé, “Dafidi ti sá kúrò ní Keila; kò sì lọ sí Keila mọ́.”
Alaila ku ae la o Davida a me kona poe kanaka, aono haneri paha, a puka aku la iwaho o Keila, a hele aku ia i ka lakou wahi e hele ai. Ua haiia mai ia Saula ka holo ana o Davida mai Keila aku, a haalele ia i ka hele mai.
14 Dafidi sì ń gbé ní aginjù, níbi tí ó ti sá pamọ́ sí, ó sì ń gbé níbi òkè ńlá kan ní aginjù Sifi. Saulu sì ń wá a lójoojúmọ́, ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò fi lé e lọ́wọ́.
A noho iho la o Davida i ka waonahele, ma na wahi paa, a noho i ka mauna ma ka waonahele o Zipa: a imi aku la o Saula ia ia i kela la i keia la, aole ke Akua i haawi mai ia ia iloko o kona lima.
15 Nígbà tí Dafidi wà ní Horeṣi ní aginjù Sifi, Dafidi sì rí i pé, Saulu ti jáde láti wá ẹ̀mí òun kiri.
A ike iho la o Davida, ua hele mai o Saula e imi i kona ola: aia no o Davida ma ka waonahele a Zipa maloko o ka ululaau.
16 Jonatani ọmọ Saulu sì dìde, ó sì tọ Dafidi lọ nínú igbó Horeṣi, ó sì gbà á ní ìyànjú nípa ti Ọlọ́run.
Ku ae la o Ionatana ke keiki a Saula, a hele io Davida la maloko o ka ululaau, a hooikaika aku la i kona lima ma ke Akua.
17 Òun sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù, nítorí tí ọwọ́ Saulu baba mi kì yóò tẹ̀ ọ́. Ìwọ ni yóò jẹ ọba lórí Israẹli, èmi ni yóò sì ṣe ibìkejì rẹ. Saulu baba mi mọ̀ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.”
I aku la oia ia ia, Mai makau oe, no ka mea, aole e loaa oe i ka lima o Saula ko'u makuakane: a e lilo oe i alii maluna o ka Iseraela, a owau hoi ka lua malalo iho ou: a ua ikeia hoi ia e Saula, e ko'u makuakane.
18 Àwọn méjèèjì sì ṣe àdéhùn níwájú Olúwa; Dafidi sì jókòó nínú igbó Horeṣi. Jonatani sì lọ sí ilé rẹ̀.
A hoopaa iho la laua i kuikahi imua o Iehova. Noho iho la o Davida maloko o ka ululaau, a hoi aku la o Ionatana ma kona hale.
19 Àwọn ará Sifi sì gòkè tọ Saulu wá sí Gibeah, wọ́n sì wí pé, “Ṣé Dafidi ti fi ara rẹ̀ pamọ́ sọ́dọ̀ wa ní ibi gíga ìsápamọ́sí ní Horeṣi, ní òkè Hakila, tí ó wà níhà gúúsù ti Jeṣimoni.
Alaila pii mai la ko Zipa io Saula la ma Gibea, i mai la, Aole anei o Davida i pee iho io makou la ma na wahi paa iloko o ka ululaau ma ka puu o Hakila, ma ka aoao hema o Iesimona?
20 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ọba, sọ̀kalẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bi gbogbo ìfẹ́ tí ó wà ní ọkàn rẹ láti sọ̀kalẹ̀: ipa tí àwa ní láti fi lé ọba lọ́wọ́.”
No ia mea hoi, E ke alii, e iho mai oe, e like me ka makemake a pau o kou naau e iho mai, a na makou ia e haawi aku iloko o ka lima o ke alii.
21 Saulu sì wí pé, “Alábùkún fún ni ẹ̀yin nípa Olúwa; nítorí pé ẹ̀yin ti káàánú fún mi.
I aku la o Saula, E pomaikai oukou ia Iehova; no ka mea, ua lokomaikai mai oukou ia'u.
22 Lọ, èmi bẹ̀ yín, ẹ tún múra, kí ẹ sì mọ̀ ki ẹ si rí ibi tí ẹsẹ̀ rẹ̀ gbé wà, àti ẹni tí ó rí níbẹ̀: nítorí tí a ti sọ fún mi pé, ọgbọ́n ni ó ń lò jọjọ.
Ke noi aku nei au ia oukou, e hele, e hoomakaukau hoi, a e nana a ike i kona wahi a kona wawae i hele ai, a o ka mea i ike ia ia malaila: no ka mea, ua haiia mai ia'u, ua hana maalea loa oia.
23 Ẹ sì wò, kí ẹ sì mọ ibi ìsápamọ́ tí ó máa ń sá pamọ́ sí, kí ẹ sì tún padà tọ̀ mí wá, kí èmi lè mọ̀ dájú; èmi ó sì bá yín lọ: yóò sì ṣe bí ó bá wà ní ilẹ̀ Israẹli, èmi ó sì wá a ní àwárí nínú gbogbo ẹgbẹ̀rún Juda!”
E nana hoi oukou, a ike i na wahi pee a pau ana e pee ai, a hoi hou mai io'u nei me ka oiaio, a e hele pu au me oukou; a ina e noho ana oia ma ka aina, e imi au ia ia mawaena o na tausani a pau o ka Iuda.
24 Wọ́n sì dìde, wọ́n sì ṣáájú Saulu lọ sí Sifi, ṣùgbọ́n Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wà ní aginjù Maoni, ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ níhà gúúsù ti Jeṣimoni.
Ku ae la lakou, a hele ma Zipa mamua o Saula: a o Davida a me kona poe kanaka aia iloko o ka waonahele o Maona i ka papu ma ka aoao hema o Iesimona.
25 Saulu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ ń wá a. Wọ́n sì sọ fún Dafidi: ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí ibi òkúta kan, ó sì jókòó ní aginjù ti Maoni. Saulu sì gbọ́, ó sì lépa Dafidi ní aginjù Maoni.
Hele aku la o Saula a me kona poe kanaka e imi ia ia; a hai aku lakou ia Davida, a iho mai ia i ka pohaku, a noho ma ka waonahele o Maona. A lohe o Saula, hahai aku la ia mahope o Davida ma ka waonahele o Maona.
26 Saulu sì ń rin apá kan òkè kan, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ní apá kejì òkè náà. Dafidi sì yára láti sá kúrò níwájú Saulu; nítorí pé Saulu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ti rọ̀gbà yí Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ká láti mú wọn.
A hele aku la o Saula ma keia aoao o ka mauna, aia o Davida a me kona poe kanaka ma kela aoao o ka mauna: hele koke aku la o Davida no ka makau ia Saula; no ka mea, ua hoopuni o Saula a me kona poe kanaka ia Davida a me kona poe kanaka e hopu ia lakou.
27 Ṣùgbọ́n oníṣẹ́ kan sì tọ Saulu wá ó sì wí pé, “Ìwọ yára kí o sì wá, nítorí tí àwọn Filistini ti gbé ogun ti ilẹ̀ wa.”
A hele mai he elele ia Saula, i mai la, E wikiwiki oe, e hoi mai; no ka mea, ua hiki mai ko Pilisetia ma ka aina.
28 Saulu sì padà kúrò ní lílépa Dafidi, ó sì lọ pàdé àwọn Filistini nítorí náà ni wọ́n sì ṣe ń pe ibẹ̀ náà ní Selahamalekoti (èyí tí ó túmọ̀ sí “Òkúta Ìpinyà”).
No ia mea, hoi aku la o Saula mai ka hahai ana ia Davida, a hele ku e aku la i ko Pilisetia: a kapa aku la lakou i ka inoa o ia wahi, o Selahamalekota.
29 Dafidi sì gòkè láti ibẹ̀ lọ, ó sì jókòó níbi tí ó sá pamọ́ sí ní En-Gedi.
Pii ae la o Davida mailaila aku, a noho iloko o na wahi paa ma Enegedi.

< 1 Samuel 23 >