< 1 Kings 8 >

1 Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli àti gbogbo àwọn olórí àwọn ẹ̀yà àti àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Israẹli jọ papọ̀, níwájú Solomoni ọba ní Jerusalẹmu, láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá láti ìlú Dafidi, tí ń ṣe Sioni.
Tad ķēniņš Salamans sapulcināja pie sevis Israēla vecajus un visus cilšu priekšniekus un Israēla bērnu tēvu namu virsniekus Jeruzālemē pie ķēniņa Salamana, pārvest Tā Kunga derības šķirstu no Dāvida pilsētas, - šī ir Ciāna.
2 Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì pe ara wọn jọ sọ́dọ̀ Solomoni ọba ní àkókò àjọ ọdún ní oṣù Etanimu tí í ṣe oṣù keje.
Un visi Israēla vīri sapulcējās pie ķēniņa Salamana uz svētkiem Etanim mēnesī, šis ir tas septītais mēnesis.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli dé, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí,
Un kad visi Israēla vecaji sanāca, tad priesteri ņēma to šķirstu
4 wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àgọ́ àjọ ènìyàn àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi sì gbé wọn gòkè wá,
Un nesa Tā Kunga šķirstu un saiešanas telti ar visiem svētiem rīkiem, kas bija teltī, tos priesteri un Leviti nesa.
5 àti Solomoni ọba, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí, wọ́n ń fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgùntàn àti màlúù tí a kò le mọ iye, àti tí a kò le kà rú ẹbọ.
Un ķēniņš Salamans un visa Israēla draudze, kas pie viņa bija sapulcējusies, gāja viņam līdz šķirsta priekšā, un upurēja avis un vēršus, neizskaitāmu pulku un neizzināmu skaitu.
6 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
Tā priesteri nesa Tā Kunga derības šķirstu savā vietā, Dieva nama dziļumā, visusvētajā vietā, apakš ķerubu spārniem.
7 Àwọn kérúbù na ìyẹ́ wọn méjèèjì sí ibi àpótí ẹ̀rí, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn ọ̀pá rẹ̀ tí a fi ń gbé e.
Jo tie ķerubi izplēta savus spārnus pār šķirsta vietu, un tie ķerubi apklāja šķirstu un viņa nesamās kārtis no augšienes.
8 Àwọn ọ̀pá yìí ga tó bẹ́ẹ̀ tí a fi le rí orí wọn láti Ibi Mímọ́ níwájú ibi tí a yà sí mímọ́, ṣùgbọ́n a kò sì rí wọn lóde Ibi Mímọ́, wọ́n sì wà níbẹ̀ títí di òní yìí.
Un tās nesamās kārtis bija tik garas, ka kāršu gali bija redzami no tās svētās vietas tās visusvētās vietas priekšā, bet ārpusē tās nebija redzamas, un tās tur ir līdz šai dienai.
9 Kò sí ohun kankan nínú àpótí ẹ̀rí bí kò ṣe wàláà òkúta méjì tí Mose ti fi sí ibẹ̀ ní Horebu, níbi tí Olúwa ti bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Tai šķirstā nebija nekā, kā vien tie abi akmens galdiņi, ko Mozus Horebā bija ielicis, kad Tas Kungs derību derēja ar Israēla bērniem, kad tie izgāja no Ēģiptes zemes.
10 Nígbà tí àwọn àlùfáà jáde láti Ibi Mímọ́, àwọsánmọ̀ sì kún ilé Olúwa.
Kad nu tie priesteri izgāja no tās svētās vietas, tad mākonis piepildīja Tā Kunga namu;
11 Àwọn àlùfáà kò sì le ṣiṣẹ́ wọn nítorí àwọsánmọ̀ náà, nítorí ògo Olúwa kún ilé náà.
Un tie priesteri nevarēja stāvēt un kalpot tā mākoņa dēļ. Jo Tā Kunga godība bija piepildījusi Tā Kunga namu.
12 Nígbà náà ni Solomoni sì wí pé, “Olúwa ti wí pé, òun yóò máa gbé inú òkùnkùn biribiri.
Tad Salamans sacīja: Tas Kungs ir sacījis, ka viņš tumsā gribot dzīvot.
13 Nítòótọ́, èmi ti kọ́ ilé kan fún ọ, ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láéláé.”
Celt esmu cēlis namu tev par dzīvokli, mājokli, tev mājot mūžīgi.
14 Nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì dúró síbẹ̀, ọba sì yí ojú rẹ̀, ó sì bùkún fún wọn.
Tad ķēniņš atgrieza savu vaigu un svētīja visu Israēla draudzi, un visa Israēla draudze stāvēja, un viņš sacīja:
15 Nígbà náà ni ó wí pé, “Ìbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti fi ọwọ́ ara rẹ̀ mú ìlérí tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dafidi baba mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,
Slavēts lai ir Tas Kungs, Israēla Dievs, kas ar Savu muti runājis uz manu tēvu Dāvidu un ar Savu roku to piepildījis, ko Viņš sacījis:
16 ‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti, èmi kò tí ì yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi láti wà níbẹ̀, ṣùgbọ́n èmi ti yan Dafidi láti ṣàkóso àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
No tās dienas, kad Es savus Israēla ļaudis esmu izvedis no Ēģiptes, Es nevienu pilsētu neesmu izredzējis starp visām Israēla ciltīm, taisīt namu, lai Mans vārds tur būtu. Bet Dāvidu Es esmu izredzējis, ka tas būtu pār Maniem Israēla ļaudīm.
17 “Dafidi baba mi sì ní i lọ́kàn láti kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
Un manam tēvam Dāvidam gan bija prātā, taisīt namu Tā Kunga, Israēla Dieva, vārdam.
18 Ṣùgbọ́n Olúwa sì wí fún Dafidi baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi, ó dára láti ní èyí ní ọkàn rẹ.
Bet Tas Kungs sacīja uz manu tēvu Dāvidu: ka tu savā sirdī esi apņēmies, taisīt namu Manam vārdam, to tu gan esi labi darījis, ka tas tavā sirdī.
19 Ṣùgbọ́n, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ ilé náà, ṣùgbọ́n ọmọ rẹ, tí ó tinú ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ jáde; òun ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
Bet tev to namu nebūs taisīt, bet tavam dēlam, kas nāks no taviem gurniem, tas uztaisīs namu Manam vārdam.
20 “Olúwa sì ti pa ìlérí rẹ̀ tí ó ṣe mọ́, èmi sì ti rọ́pò Dafidi baba mi, mo sì jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli báyìí, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí, èmi sì kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
Un Tas Kungs savu vārdu ir apstiprinājis, ko Viņš runājis. Jo es esmu stājies sava tēva Dāvida vietā, un sēžu uz Israēla goda krēsla, itin kā Tas Kungs runājis, un es esmu uztaisījis namu Tā Kunga, Israēla Dieva, vārdam.
21 Èmi sì ti pèsè ibìkan níbẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí, èyí tí í ṣe májẹ̀mú Olúwa tí ó ti bá àwọn baba wa dá, nígbà tí ó mú wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
Un tur esmu taisījis vietu tam šķirstam, kur Tā Kunga derība, ko Viņš derējis ar mūsu tēviem, kad Viņš tos izveda no Ēģiptes zemes.
22 Solomoni sì dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sókè ọ̀run.
Un Salamans stājās Tā Kunga altāra priekšā, visai Israēla draudzei pretī, un izplēta savas rokas pret debesīm un sacīja:
23 Ó sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ lókè ọ̀run tàbí ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ìwọ tí ó pa májẹ̀mú àti àánú mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi gbogbo ọkàn wọn rìn níwájú rẹ.
Kungs, Israēla Dievs, neviena tāda Dieva nav kā Tu, ne augšā debesīs, nedz apakšā virs zemes; derību un žēlastību Tu turi Saviem kalpiem, kas Tavā priekšā staigā no visas savas sirds.
24 O sì ti pa ìlérí rẹ mọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi; pẹ̀lú ẹnu rẹ ni ìwọ ṣe ìlérí, o sì mú u ṣẹ pẹ̀lú ọwọ́ rẹ, bí ó ti rí lónìí.
Tu Savam kalpam, manam tēvam Dāvidam, esi turējis, ko tam esi runājis. Ar Savu muti Tu esi runājis un ar Savu roku to piepildījis, tā kā tas šodien ir.
25 “Ǹjẹ́ báyìí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, bá ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi pa ohun tí ìwọ ti ṣe ìlérí fún un mọ́ wí pé, ìwọ kì yóò kùnà láti ní ènìyàn kan láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Israẹli, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ bá lè kíyèsi ohun tí wọ́n ń ṣe láti máa rìn níwájú mi bí ìwọ ti rìn.
Un nu Kungs, Israēla Dievs, turi Savam kalpam, manam tēvam Dāvidam, arī to, ko Tu tam vēl esi runājis sacīdams: tev netrūks vīra Manā priekšā, kas sēdēs uz Israēla goda krēsla, ja tikai tavi dēli sargās savu ceļu, staigādami Manā priekša, itin kā tu esi staigājis Manā priekšā.
26 Ǹjẹ́ báyìí, Ọlọ́run Israẹli, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti ṣe ìlérí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi wá sí ìmúṣẹ.
Nu tad, Israēla Dievs, lai jel Tavs vārds tiešām notiek, ko Tu esi runājis Savam kalpam, manam tēvam Dāvidam!
27 “Ṣùgbọ́n nítòótọ́, Ọlọ́run yóò máa gbé ayé bí? Ọ̀run àti ọ̀run àwọn ọ̀run kò le gbà ọ́. Kí a má sọ pé ilé yìí tí mo kọ́ fún ọ!
Vai tad patiesi Tas Kungs dzīvotu virs zemes? Redzi, debesis un visu debesu debesis Tevi nevar saņemt, kā tad nu vēl šis nams, ko es esmu taisījis.
28 Síbẹ̀ ṣe ìfetísílẹ̀ àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi. Gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ lónìí.
Bet griezies pie Sava kalpa lūgšanām un pie viņa piesaukšanām, Kungs, mans Dievs, un klausi to saukšanu un lūgšanu, ko Tavs kalps šodien lūdz priekš Tava vaiga.
29 Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ilé yìí ní òru àti ní ọ̀sán, ibí yìí tí ìwọ ti wí pé, orúkọ mi yóò wà níbẹ̀, nítorí ìwọ yóò gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ gbà sí ibí yìí.
Lai Tavas acis stāv atvērtas dienām naktīm pār šo namu, pār šo vietu, par ko Tu esi sacījis: Mans vārds lai tur ir; ka Tu klausi to lūgšanu, ko Tavs kalps lūgs šinī vietā.
30 Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ àti ti Israẹli, ènìyàn rẹ nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí ibí yìí. Gbọ́ láti ọ̀run wá láti ibùgbé rẹ, àti nígbà tí o bá gbọ́, dáríjì.
Klausi tad Sava kalpa un Savu Israēla ļaužu sirds lūgšanu, ko tie lūgs šinī vietā, un klausi, kur Tu mīti debesīs, ak klausi un piedod!
31 “Nígbà tí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀, tí a sì fi wá lé e láti mú un búra, bí ìbúra náà bá sì dé iwájú pẹpẹ rẹ ní ilé yìí,
Ja kāds būs apgrēkojies pret savu tuvāko un viņam liks zvērēt un nodievoties, un šis nāks un zvērēs priekš Tava altāra šinī namā,
32 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run, kí o sì ṣe. Kí o sì ṣèdájọ́ láàrín àwọn ìránṣẹ́ rẹ, dá ènìyàn búburú lẹ́bi, kí o sì mú wá sí orí òun tìkára rẹ̀ ohun tí ó ti ṣe, dá olóòtítọ́ láre, kí a sì fi ẹsẹ̀ àìlẹ́bi rẹ̀ múlẹ̀.
Tad klausi Tu debesīs un dari un tiesā Savus kalpus, netaisno notiesādams un atmaksādams viņa ceļu uz viņa galvu, un taisno taisnodams, dodams viņam pēc viņa taisnības.
33 “Nígbà tí àwọn ọ̀tá bá ṣẹ́gun Israẹli, ènìyàn rẹ, nítorí tí wọ́n ti ṣẹ̀ sí ọ, tí wọ́n bá yípadà sí ọ, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ nínú ilé yìí
Kad Tavi Israēla ļaudis taps kauti savu ienaidnieku priekšā, tāpēc ka tie pret Tevi būs grēkojuši, un kad tie pie Tevis atgriezīsies un dos godu Tavam vārdam un Tevi pielūgs un no sirds piesauks šinī namā,
34 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ènìyàn rẹ̀ jì í, kí o sì mú wọn padà wá sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fún àwọn baba wọn.
Tad klausi Tu debesīs un piedod Savu Israēla ļaužu grēkus un ved tos atkal tai zemē, ko Tu esi devis viņu tēviem.
35 “Nígbà tí ọ̀run bá sé mọ́, tí kò sí òjò, nítorí tí àwọn ènìyàn rẹ ti ṣẹ̀ sí ọ, bí wọ́n bá gbàdúrà sí ìhà ibí yìí, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn nítorí tí ìwọ ti pọ́n wọn lójú,
Kad debess būs aizslēgta, ka lietus nelīst, tāpēc ka tie pret Tevi grēkojuši, un kad tie šinī vietā lūgs un dos godu Tavam vārdam un atgriezīsies no saviem grēkiem, kad Tu tos pazemojis,
36 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ jì wọ́n, à ní Israẹli, ènìyàn rẹ. Kọ́ wọn ní ọ̀nà tí ó tọ́ láti máa rìn, kí o sì rọ òjò sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fi fún ènìyàn rẹ fún ìní.
Tad klausi Tu debesīs un piedod Savu kalpu un Savu Israēla ļaužu grēkus, ka Tu tiem parādi to labo ceļu, kur tiem jāstaigā, un dod lietu tai zemē, ko Tu devis Saviem ļaudīm par mantību.
37 “Nígbà tí ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn bá wá sí ilẹ̀ náà, tàbí ìrẹ̀dànù tàbí ìmúwòdù, eṣú tàbí kòkòrò tí ń jẹ ni run, tàbí nígbà tí àwọn ọ̀tá bá dó tì wọ́n nínú àwọn ìlú wọn, irú ìpọ́njú tàbí ààrùnkárùn tó lè wá,
Kad zemei būs bads, kad būs mēris, bula laiks, rūsa, siseņi, kukaiņi, kad viņu ienaidnieks zemē ielauzīsies pret viņu vārtiem, vai būs kāda cita mocība vai sērga,
38 nígbà tí àdúrà tàbí ẹ̀bẹ̀ bá ti ọ̀dọ̀ ẹnìkan láti ọ̀dọ̀ gbogbo Israẹli wá, tí olúkúlùkù sì mọ ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀, bí ó bá sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí ìhà ilé yìí,
Visas lūgšanas, visas piesaukšanas, lai lūgtu kas lūgdams no visiem Taviem Israēla ļaudīm, kad tie atzīs savas sirds bēdas un izplētīs savas rokas šinī namā,
39 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ. Dáríjì, kí o sì ṣe sí olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí ó ti ṣe, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ mọ ọkàn rẹ̀, nítorí ìwọ nìkan ṣoṣo ni ó mọ ọkàn gbogbo ènìyàn.
Tad klausi Tu debesīs, Savā mājoklī, kur Tu mīti, un piedod un dari un dod ikvienam pēc visiem viņa ceļiem, itin kā Tu pazīsti viņa sirdi, jo Tu vien pazīsti visu cilvēka bērnu sirdis; -
40 Nítorí wọn yóò bẹ̀rù rẹ ní gbogbo ọjọ́ tí wọn yóò wà ní ilẹ̀ tí ìwọ fi fún àwọn baba wa.
Lai tie Tevi bīstas visu savu mūžu, kamēr tie dzīvos tai zemē, ko Tu esi devis mūsu tēviem.
41 “Ní ti àwọn àlejò tí kì í ṣe Israẹli ènìyàn rẹ, ṣùgbọ́n tí ó ti ilẹ̀ òkèèrè jáde wá nítorí orúkọ rẹ,
Kad arī kāds svešinieks būs, kas nav no taviem Israēla ļaudīm, bet atnācis no tālas zemes Tava vārda dēļ,
42 nítorí tí àwọn ènìyàn yóò gbọ́ orúkọ ńlá rẹ, àti ọwọ́ agbára rẹ, àti nínà apá rẹ, nígbà tí ó bá sì wá, tí ó sì gbàdúrà sí ìhà ilé yìí,
(Jo tie dzirdēs par Tavu lielo vārdu un par Tavu stipro roku un par Tavu izstiepto elkoni, ) un kad tas nāks un pielūgs šinī namā,
43 nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí àlejò náà yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ, kí gbogbo ènìyàn ní ayé lè mọ orúkọ rẹ, kí wọn kí ó sì máa bẹ̀rù rẹ, gẹ́gẹ́ bí Israẹli, ènìyàn rẹ ti ṣe, kí wọn kí ó sì le mọ̀ pé orúkọ rẹ ni a fi pe ilé yìí tí mo kọ́.
Tad klausi Tu debesīs, Savā mājoklī, kur Tu mīti, un dari visu, par ko tas svešais Tevi piesauks, lai visas tautas virs zemes atzīst Tavu vārdu un Tevi bīstas, kā Tavi Israēla ļaudis, un lai tie atzīst, ka Tavs vārds ir saukts pār šo namu, ko es esmu uztaisījis.
44 “Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ bá jáde lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá wọn, níbikíbi tí ìwọ bá rán wọn, nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí Olúwa sí ìhà ìlú tí ìwọ ti yàn àti síhà ilé tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ,
Kad Tavi ļaudis ies karā pret saviem ienaidniekiem tai ceļā, kur Tu tos sūtīsi, un pielūgs To Kungu, griezušies uz šo pilsētu, ko Tu esi izredzējis, un uz šo namu, ko es tavam vārdam esmu uztaisījis,
45 nígbà náà ni kí o gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ wọn láti ọ̀run, kí o sì mú ọ̀rọ̀ wọn dúró.
Tad klausi Tu debesīs viņu lūgšanas un viņu sirds saukšanas un nes viņiem tiesu.
46 “Nígbà tí wọ́n bá ṣẹ̀ sí ọ, nítorí kò sí ẹnìkan tí kì í ṣẹ̀, tí ìwọ sì bínú sí wọn, tí ìwọ sì fi wọ́n lé ọ̀tá lọ́wọ́, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ sí ilẹ̀ wọn, jíjìnnà tàbí nítòsí;
Kad tie pret Tevi apgrēkosies, (jo neviena cilvēka nav, kas negrēkotu) un Tu par tiem dusmosies, un tos nodosi ienaidniekiem, ka viņu uzvarētāji tos cietumā noved ienaidnieku zemē, vai tālu, vai tuvu,
47 bí wọ́n bá ní ìyípadà ọkàn ní ilẹ̀ níbi tí a kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n bá sì ronúpìwàdà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ sí ọ ní ilẹ̀ àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀, àwa ti ṣe ohun tí kò tọ́, àwa ti ṣe búburú’;
Un kad tie to atkal ņems pie sirds tai zemē, kur tie cietumā aizvesti, un atgriezīsies un Tevi piesauks sava cietuma zemē sacīdami: mēs esam grēkojuši un ļaunu darījuši, mēs esam bezdievīgi bijuši;
48 bí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà àti gbogbo ọkàn wọn yípadà sí ọ, ní ilẹ̀ àwọn ọ̀tá wọn, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n sì gbàdúrà sí ọ sí ìhà ilẹ̀ wọn tí ìwọ ti fi fún àwọn baba wọn, ìlú tí ìwọ ti yàn, àti ilé tí èmi kọ́ fún orúkọ rẹ;
Un kad tie pie Tevis atgriezīsies no visas savas sirds un no visas savas dvēseles savu ienaidnieku zemē, kas tos aizveduši cietumā, un kad tie Tevi pielūgs, griezušies uz savu zemi, ko Tu devis viņu tēviem, uz to pilsētu, ko Tu izredzējis, un uz to namu, ko es tavam vārdam uztaisījis,
49 nígbà náà ni kí ìwọ kí ó gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn ní ọ̀run, ní ibùgbé rẹ, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró.
Tad klausi Tu debesīs, Savā mājoklī, kur Tu mīti, viņu lūgšanu un viņu sirds saukšanu un nes viņiem tiesu,
50 Kí o sì dáríjì àwọn ènìyàn rẹ, tí wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ; dárí gbogbo ìrékọjá wọn tí wọ́n ṣe sí ọ jì, kí o sì bá àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ wí, kí wọn kí ó lè ṣàánú fún wọn;
Un piedod Saviem ļaudīm, ko tie pret Tevi grēkojuši, un visus viņu pārkāpumus, ar ko tie pret Tevi noziegušies, un dod tiem žēlastību atrast pie tiem, kas tos cietumā tur, ka tie par viņiem apžēlojās;
51 nítorí ènìyàn rẹ àti ìní rẹ ni wọ́n, àwọn ẹni tí ìwọ ti mú ti Ejibiti jáde wá, láti inú irin ìléru.
Jo tie ir Tavi ļaudis un Tavs īpašums, ko Tu esi izvedis no Ēģiptes no tā dzelzs cepļa.
52 “Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, àti sí ẹ̀bẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ Israẹli, kí o sì tẹ́tí sílẹ̀ sí wọn nígbà tí wọ́n bá kégbe sí ọ.
Lai Tavas acis atvērtas stāv uz Tava kalpa lūgšanu un uz Tavu Israēla ļaužu lūgšanu, ka Tu tos klausi visās lietās, par ko tie Tevi piesauc.
53 Nítorí tí ìwọ ti yà wọ́n kúrò nínú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, láti máa jẹ́ ìní rẹ, bí ìwọ ti sọ láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ, nígbà tí ìwọ Olúwa Olódùmarè, mú àwọn baba wa ti Ejibiti jáde wá.”
Jo Tu tos Sev esi izredzējis par īpašumu no visām pasaules tautām, itin kā Tu esi runājis caur Savu kalpu Mozu, kad Tu mūsu tēvus izvedi no Ēģiptes zemes, Kungs, Dievs!
54 Nígbà tí Solomoni ti parí gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ yìí sí Olúwa tán, ó dìde kúrò lórí eékún rẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa níbi tí ó ti kúnlẹ̀ tí ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí òkè ọ̀run
Un notikās, kad Salamans bija pabeidzis lūgt šo lūgšanu un sirds saukšanu uz To Kungu, tad viņš pacēlās priekš Tā Kunga altāra, kur viņš bija ceļos nometies un savas rokas izpletis pret debesīm,
55 Ó sì dìde dúró ó sì fi ohùn rara súre fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli wí pé,
Un viņš nostājās un svētīja visu Israēla draudzi ar stipru balsi un sacīja:
56 “Ìbùkún ni fún Olúwa tí ó ti fi ìsinmi fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀ bí ó ti ṣèlérí. Kò sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kan tí ó kùnà nínú gbogbo ìlérí rere tí ó ti ṣe láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ̀ wá.
Slavēts lai ir Tas Kungs, kas dusu devis Saviem Israēla ļaudīm, itin kā Viņš runājis; neviens vārds nav zemē kritis no visiem Viņa labiem vārdiem, ko Viņš runājis caur Savu kalpu Mozu.
57 Kí Olúwa Ọlọ́run wa kí ó wà pẹ̀lú wa bí ó ti wà pẹ̀lú àwọn baba wa; kí ó má sì ṣe fi wá sílẹ̀ tàbí kọ̀ wá sílẹ̀.
Lai Tas Kungs, mūsu Dievs, ir ar mums, itin kā Viņš bijis ar mūsu tēviem. Viņš lai mūs neatstāj un lai mūs neatmet.
58 Kí ó fa ọkàn wa sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀, láti máa rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, tí ó ti pàṣẹ fún àwọn baba wa.
Lai Viņš mūsu sirdis griež pie Sevis, ka mēs staigājam visos Viņa ceļos, turēdami Viņa baušļus un Viņa likumus un Viņa tiesas, ko Viņš pavēlējis mūsu tēviem.
59 Àti kí ó sì jẹ́ kí àwọn ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí, tí mo ti gbà ní àdúrà níwájú Olúwa, kí ó wà nítòsí Olúwa Ọlọ́run wa ní ọ̀sán àti ní òru, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró àti ọ̀rọ̀ Israẹli ènìyàn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àìní wa ojoojúmọ́,
Un lai šie vārdi, ar ko es lūdzis Tā Kunga priekšā, tuvu ir pie Tā Kunga, mūsu Dieva, dienām naktīm, lai Viņš tiesu nes Savam kalpam un Saviem Israēla ļaudīm dienu no dienas,
60 kí gbogbo ènìyàn ayé lè mọ̀ pé Olúwa òun ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn.
Lai visas pasaules tautas atzīst, ka Tas Kungs ir Dievs un cits neviens.
61 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí ọkàn yín pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run wa, láti máa rìn nínú àṣẹ rẹ̀ àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, bí i ti òní yìí.”
Un lai jūsu sirds paliek pilnīgi pie Tā Kunga, mūsu Dieva, ka jūs staigājat Viņa likumos un turat Viņa baušļus, tāpat kā šodien.
62 Nígbà náà ni ọba àti gbogbo Israẹli rú ẹbọ níwájú Olúwa.
Un ķēniņš un viss Israēls līdz ar viņu upurēja upurus Tā Kunga priekšā.
63 Solomoni rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa: ẹgbẹ̀rún méjìlélógún màlúù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ya ilé Olúwa sí mímọ́.
Un Salamans upurēja pateicības upurus, ko viņš Tam Kungam atnesa, divdesmit un divtūkstoš vēršus un simts un divdesmit tūkstoš avis. Tā ķēniņš ar visiem Israēla bērniem iesvētīja Tā Kunga namu.
64 Ní ọjọ́ kan náà ni ọba ya àgbàlá àárín tí ń bẹ níwájú ilé Olúwa sí mímọ́, níbẹ̀ ni ó sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ oúnjẹ, àti ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ń bẹ níwájú Olúwa kéré jù láti gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọrẹ ẹbọ àlàáfíà.
Tai dienā ķēniņš svētīja to iekšējo pagalmu, kas Tā Kunga nama priekšā, jo viņš tur upurēja dedzināmu upuri un ēdamu upuri un pateicības upuru taukus. Jo tas vara altāris Tā Kunga priekšā bija pa mazu priekš tā dedzināma upura un tā ēdama upura un tiem pateicības upuru taukiem.
65 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àpéjọ nígbà náà, àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀, àjọ ńlá ńlá ni, láti ìwọ Hamati títí dé odò Ejibiti. Wọ́n sì ṣàjọyọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ọjọ́ méje àti ọjọ́ méje sí i, ọjọ́ mẹ́rìnlá papọ̀.
Un tanī laikā Salamans noturēja svētkus ar visu Israēli, lielu draudzi no Hamata robežas līdz Ēģiptes upei Tā Kunga, mūsu Dieva, priekšā, septiņas dienas un atkal septiņas dienas, pavisam četrpadsmit dienas; astotā dienā viņš tos ļaudis atlaida.
66 Ní ọjọ́ kẹjọ ó rán àwọn ènìyàn lọ. Wọ́n súre fún ọba, wọ́n sì lọ sí ilé wọn pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn fún gbogbo ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, àti fún Israẹli ènìyàn rẹ̀.
Un tie svētīja ķēniņu un gāja uz saviem dzīvokļiem priecīgi un ar līksmu sirdi par visu to labumu, ko Tas Kungs bija darījis Savam kalpam Dāvidam un Saviem Israēla ļaudīm.

< 1 Kings 8 >