< 1 Kings 5 >

1 Nígbà tí Hiramu ọba Tire sì gbọ́ pé, a ti fi òróró yan Solomoni ní ọba ní ipò Dafidi baba rẹ̀, ó sì rán àwọn ikọ̀ rẹ̀ sí Solomoni, nítorí ó ti fẹ́ràn Dafidi ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
Et Hiram, Roi de Tyr, députa ses serviteurs vers Salomon, car il avait appris qu'il avait été oint comme Roi à la place de son père; car Hiram avait toujours été l'ami de David.
2 Solomoni sì ránṣẹ́ yìí padà sí Hiramu pé,
A son tour Salomon députa vers Hiram pour lui dire:
3 “Ìwọ mọ̀ pé Dafidi baba mi kò le kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, nítorí ogun tí ó wà yí i káàkiri, títí Olúwa fi fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sábẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
Tu sais que David, mon père, n'a pu bâtir une maison au Nom de l'Éternel, son Dieu, à cause des ennemis qui l'entouraient, jusqu'à ce que l'Éternel les eût mis sous la plante de ses pieds.
4 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run mi ti fún mi ní ìsinmi ní ibi gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni kò sì sí ọ̀tá tàbí ìjàǹbá kan tí ó ṣe.
Or maintenant l'Éternel, mon Dieu, m'a mis en paix avec mes alentours; il n'y a ni adversaire, ni conjoncture fâcheuse.
5 Nítorí náà mo gbèrò láti kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run mi, bí Olúwa ti sọ fún Dafidi baba mi, nígbà tí ó wí pé, ‘Ọmọ rẹ tí èmi yóò gbé ka orí ìtẹ́ rẹ ní ipò rẹ ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
Aussi, voici, je pense à bâtir une maison au Nom de l'Éternel, mon Dieu, aux termes de la déclaration faite par l'Éternel à David, mon père, quand Il dit: Ton fils que Je placerai sur ton Trône pour te succéder, c'est lui qui élèvera la maison à Mon Nom.
6 “Nítorí náà ni kí o pàṣẹ pé kí wọn kí ó gé igi kedari Lebanoni fún mi wá. Àwọn ènìyàn mi yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú tìrẹ, Èmi yóò sì san owó ọ̀yà tí ìwọ bá ránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn rẹ. Ìwọ mọ̀ pé, a kò ní ẹnìkan nínú wa tí ó mọ bí a ti ń gé igi bí àwọn ará Sidoni.”
Maintenant donc, donne l'ordre de couper pour moi des cèdres au Liban; et mes serviteurs se joindront à tes serviteurs, et je te remettrai le salaire de tes serviteurs tel que tu l'indiqueras; car tu sais que chez nous personne ne s'entend à la coupe des bois comme les Sidoniens.
7 Nígbà tí Hiramu sì gbọ́ iṣẹ́ Solomoni, inú rẹ̀ sì dùn gidigidi, ó sì wí pé, “Ògo ni fún Olúwa lónìí, nítorí tí ó ti fún Dafidi ní ọlọ́gbọ́n ọmọ láti ṣàkóso àwọn ìlú ńlá yìí.”
Et lorsque Hiram entendit le message de Salomon, il en eut une grande joie, et il dit: Béni soit l'Éternel en ce jour de ce qu'il a donné à David un fils sage comme chef de ce grand peuple.
8 Hiramu sì ránṣẹ́ sí Solomoni pé, “Èmi ti gbọ́ iṣẹ́ tí ìwọ rán sí mi, èmi yóò sì ṣe gbogbo èyí tí o fẹ́ ní pípèsè igi kedari àti ní ti igi firi.
Et Hiram députa vers Salomon pour lui mander: J'ai entendu ce que tu m'as fait dire; de mon côté, j'accomplirai tout ton désir en fait de bois de cèdre et de bois de cyprès.
9 Àwọn ènìyàn mi yóò mú igi náà sọ̀kalẹ̀ láti Lebanoni wá sí Òkun, èmi ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí ọ ní fífò lójú omi Òkun Ńlá títí dé ibi tí ìwọ ó na ìka sí fún mi. Níbẹ̀ ni èmi yóò ti yà wọ́n sọ́tọ̀, ìwọ yóò sì kó wọn lọ. Ìwọ yóò sì gba ìfẹ́ mi nípa pípèsè oúnjẹ fún ilé mi.”
Mes serviteurs le descendront du Liban à la mer, et j'en ferai des radeaux qui par mer se porteront au lieu que tu me feras savoir, et là je les disloquerai, et tu les feras prendre. En retour tu accompliras aussi mon désir en fournissant des denrées à ma maison.
10 Báyìí ni Hiramu sì pèsè igi kedari àti igi firi tí Solomoni ń fẹ́ fún un,
Et Hiram donna à Salomon des bois de cèdre et des bois de cyprès en tout point selon son désir.
11 Solomoni sì fún Hiramu ní ogún ẹgbẹ̀rún òsùwọ̀n ọkà oúnjẹ fún ilé rẹ̀, àti ogún òsùwọ̀n òróró dáradára. Solomoni sì ń tẹ̀síwájú láti ṣe èyí fún Hiramu lọ́dọọdún.
De son côté Salomon donna à Hiram vingt mille cors de froment pour l'entretien de sa maison, et vingt cors d'huile d'olives concassées; c'est ce que Salomon donna à Hiram annuellement.
12 Olúwa sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún un. Ìrẹ́pọ̀ àlàáfíà sì wà láàrín Hiramu àti Solomoni, àwọn méjèèjì sì ṣe àdéhùn.
Et l'Éternel dota Salomon de la sagesse selon Sa promesse, et il y eut paix entre Hiram et Salomon, et ils firent alliance l'un avec l'autre.
13 Solomoni ọba sì ṣa asìnrú ènìyàn jọ ní gbogbo Israẹli; àwọn tí ń sìnrú náà jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ènìyàn.
Et le Roi Salomon commanda une corvée à tout Israël, et pour la corvée il y eut trente mille hommes.
14 Ó sì rán wọn lọ sí Lebanoni, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá lóṣooṣù, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n lo oṣù kan ní Lebanoni, wọn a sì gbé ilé ní oṣù méjì. Adoniramu ni ó ṣe olórí àwọn asìnrú náà.
Et il les envoya au Liban, dix mille par mois à tour; ils passaient un mois au Liban, et deux mois chez eux, et Adoniram était préposé sur la corvée.
15 Solomoni sì ní ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin ènìyàn tí ń ru ẹrù àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin gbẹ́nàgbẹ́nà lórí òkè,
Et Salomon avait soixante-dix mille porte-faix et quatre-vingt mille carriers,
16 àti àwọn ìjòyè nínú àwọn tí a fi ṣe olórí iṣẹ́ Solomoni jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún ó lé ọgọ́rùn-ún ènìyàn, tí ó ń ṣe aláṣẹ àwọn ènìyàn tí ń ṣiṣẹ́ náà.
non compris les chefs préposés par Salomon sur l'ouvrage, au nombre de trois mille trois cents, piqueurs des gens qui faisaient l'ouvrage.
17 Ọba sì pàṣẹ, wọ́n sì mú òkúta wá, òkúta iyebíye, àti òkúta gbígbẹ́ láti fi ìpìlẹ̀ ilé náà lé ilẹ̀.
Et le Roi leur ordonna d'extraire de grandes pierres, des pierres massives, pour asseoir les fondements de la Maison sur pierres équarries.
18 Àwọn oníṣọ̀nà Solomoni àti Hiramu àti àwọn òṣìṣẹ́ láti Gebali sì gbẹ́ wọn, wọ́n sì pèsè igi àti òkúta láti fi kọ́ ilé náà.
Et les maçons de Salomon et les maçons de Hiram et les Giblites les taillèrent, et préparèrent le bois et les pierres pour la construction de la Maison.

< 1 Kings 5 >