< 1 Kings 17 >

1 Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
And Elie `of Thesbi, of the dwelleris of Galaad, seide to Achab, The Lord God of Israel lyueth, in whos siyt Y stonde, deeu and reyn schal not be in these yeeris, no but bi the wordis of my mouth.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
And the word of the Lord was maad to hym, and seide,
3 “Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
Go thou awey fro hennus, and go ayens the eest, and be thou hid in the stronde of Carith, which is ayens Jordan,
4 Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
and there thou schalt drynke of the stronde; and Y comaundide to crowis, that thei feede thee there.
5 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
Therfor he yede, and dide bi the word of the Lord; and whanne he hadde go, he sat in the stronde of Carith, which is ayens Jordan.
6 Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
And crowis baren to hym breed and fleisch eerli; in lijk maner in the euentid; and he drank of the stronde.
7 Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
Forsothe after summe daies the stronde was dried; for it hadde not reynede on the erthe.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
Therfor the word of the Lord was maad to hym, and seide,
9 “Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
Rise thou, and go in to Serepta of Sydoneis, and thou schalt dwelle there; for Y comaundide to a womman, widewe there, that sche feede thee.
10 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
He roos, and yede in to Sarepta of Sidoneis; and whanne he hadde come to the yate of the citee, a womman widewe gaderynge stickis apperide to hym; and he clepide hir, and seide to hir, Yyue thou to me a litil of water in a vessel, that Y drynke.
11 Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
And whanne sche yede to bringe, he criede bihynde hir bac, and seide, Y biseche, bringe thou to me also a mussel of breed in thin hond.
12 Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
And sche answeride, Thi Lord God lyueth, for Y haue no breed, no but as myche of mele in a pot, as a fist may take, and a litil of oile in a vessel; lo! Y gadere twei stickis, that Y entre, and make it to me, and to my sone, that we ete and die.
13 Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
And Elie seide to hir, Nyle thou drede, but go, and make as thou seidist; netheles make thou firste to me of that litil mele a litil loof, bakun vndur the aischis, and brynge thou to me; sotheli thou schalt make afterward to thee and to thi sone.
14 Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
Forsothe the Lord God of Israel seith thes thingis, The pot of mele schal not faile, and the vessel of oile schal not be abatid, til to the dai in which the Lord schal yyue reyn on the face of erthe.
15 Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
And sche yede, and dide bi the word of Elie; and he eet, and sche, and hir hows.
16 Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
And fro that dai the pot of mele failide not, and the vessel of oile was not abatid, bi the word of the Lord, which he hadde spoke in the hond of Elie.
17 Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
Forsothe it was doon aftir these wordis, the sone of a womman hosewijf was sijk, and the sijknesse was moost strong, so that breeth dwellide not in hym.
18 Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
Therfor sche seide to Elie, What to me and to thee, thou man of God? Entridist thou to me, that my wickidnessis schulden be remembrid, and that thou schuldist sle my sone?
19 Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
And Elie seide to hir, Yyue thi sone to me. And he took `that sone fro hir bosum, and bar in to the soler, where he dwellide; and he puttide hym on his bed.
20 Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
And he criede to the Lord, and seide, My Lord God, whether thou hast turmentid also the widewe, at whom Y am susteyned in al maner, that thou killidist hir sone?
21 Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
He sprad abrood hym silf, and mat on the child bi thre tymes; and he cryede to the Lord, and seide, My Lord God, Y biseche, the soule of this child turne ayen in to the entrailis of hym.
22 Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
The Lord herde the vois of Elie, and the soule of the child turnede ayen with ynne hym, and he lyuede ayen.
23 Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
And Elie took the child, and puttide hym doun of the soler in to the lower hows, and bitook him to his modir; and he seide to hir, Lo! thi sone lyueth.
24 Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”
And the womman seide to Elie, Now in this Y haue knowe, that thou art the man of God, and the word of God is soth in thi mouth.

< 1 Kings 17 >