< 1 Chronicles 6 >

1 Àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
LOS hijos de Leví: Gersón, Coath, y Merari.
2 Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni, àti Usieli.
Los hijos de Coath: Amram, Ishar, Hebrón y Uzziel.
3 Àwọn ọmọ Amramu: Aaroni, Mose àti Miriamu. Àwọn ọmọkùnrin Aaroni: Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
Los hijos de Amram: Aarón, Moisés, y Mariam. Los hijos de Aarón: Nadab, Abiú, Eleazar, é Ithamar.
4 Eleasari jẹ́ baba Finehasi, Finehasi baba Abiṣua
Eleazar engendró á Phinees, y Phinees engendró á Abisua:
5 Abiṣua baba Bukki, Bukki baba Ussi,
Y Abisua engendró á Bucci, y Bucci engendró á Uzzi;
6 Ussi baba Serahiah, Serahiah baba Meraioti,
Y Uzzi engendró á Zeraías, y Zeraías engendró á Meraioth;
7 Meraioti baba Amariah, Amariah baba Ahitubu
Y Meraioth engendró á Amarías, y Amarías engendró á Achîtob;
8 Ahitubu baba Sadoku, Sadoku baba Ahimasi,
Y Achîtob engendró á Sadoc, y Sadoc engendró á Achîmaas;
9 Ahimasi baba Asariah, Asariah baba Johanani,
Y Achîmaas engendró á Azarías, y Azarías engendró á Johanan;
10 Johanani baba Asariah. (Òhun ni ó sìn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà nínú ilé Olúwa tí Solomoni kọ́ sí Jerusalẹmu).
Y Johanan engendró á Azarías, el que tuvo el sacerdocio en la casa que Salomón edificó en Jerusalem;
11 Asariah baba Amariah Amariah baba Ahitubu
Y Azarías engendró á Amarías, y Amarías engendró á Achîtob;
12 Ahitubu baba Sadoku. Sadoku baba Ṣallumu,
Y Achîtob engendró á Sadoc, y Sadoc engendró á Sallum;
13 Ṣallumu baba Hilkiah, Hilkiah baba Asariah,
Y Sallum engendró á Hilcías, é Hilcías engendró á Azarías;
14 Asariah baba Seraiah, pẹ̀lú Seraiah baba Josadaki.
Y Azarías engendró á Seraíah, y Seraíah engendró á Josadec.
15 A kó Josadaki lẹ́rú nígbà tí Olúwa lé Juda àti Jerusalẹmu kúrò ní ìlú nípasẹ̀ Nebukadnessari.
Y Josadec fué [cautivo] cuando Jehová trasportó á Judá y á Jerusalem por mano de Nabucodonosor.
16 Àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Los hijos de Leví: Gersón, Coath, y Merari.
17 Wọ̀nyí ni àwọn orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni: Libni àti Ṣimei.
Y estos son los nombres de los hijos de Gersón: Libni, y Simi.
18 Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.
Los hijos de Coath: Amram, Ishar, Hebrón, y Uzziel.
19 Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Wọ̀nyí ni àwọn ìdílé ará Lefi tí a kọ ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí baba wọn.
Los hijos de Merari: Mahali, y Musi. Estas son las familias de Leví, según sus descendencias.
20 Ti Gerṣoni: Libni ọmọkùnrin rẹ̀, Jahati. Ọmọkùnrin rẹ̀, Simma ọmọkùnrin rẹ̀,
Gersón: Libni su hijo, Joath su hijo, Zimma su hijo,
21 Joah ọmọkùnrin rẹ̀, Iddo ọmọkùnrin rẹ̀, Sera ọmọkùnrin rẹ̀ àti Jeaterai ọmọkùnrin rẹ̀.
Joab su hijo, Iddo su hijo, Zera su hijo, Jeothrai su hijo.
22 Àwọn ìran ọmọ Kohati: Amminadabu ọmọkùnrin rẹ̀, Kora ọmọkùnrin rẹ̀, Asiri ọmọkùnrin rẹ̀.
Los hijos de Coath: Aminadab su hijo, Coré su hijo, Asir su hijo,
23 Elkana ọmọkùnrin rẹ̀, Ebiasafi ọmọkùnrin rẹ̀, Asiri ọmọkùnrin rẹ̀.
Elcana su hijo, Abiasaph su hijo, Asir su hijo,
24 Tahati ọmọkùnrin rẹ̀, Urieli ọmọkùnrin rẹ̀, Ussiah ọmọkùnrin rẹ̀ àti Saulu ọmọkùnrin rẹ̀.
Thahath su hijo, Uriel su hijo, Uzzia su hijo, y Saúl su hijo.
25 Àwọn ìran ọmọ Elkana: Amasai, Ahimoti
Los hijos de Elcana: Amasai, Achîmoth, y Elcana.
26 Elkana ọmọ rẹ̀, Sofai ọmọ rẹ̀ Nahati ọmọ rẹ̀,
Los hijos de Elcana: Sophai su hijo, Nahath su hijo,
27 Eliabu ọmọ rẹ̀, Jerohamu ọmọ rẹ̀, Elkana ọmọ rẹ̀ àti Samuẹli ọmọ rẹ̀.
Eliab su hijo, Jeroham su hijo, Elcana su hijo.
28 Àwọn ọmọ Samuẹli: Joẹli àkọ́bí àti Abijah ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì.
Los hijos de Samuel: el primogénito Vasni, y Abías.
29 Àwọn ìran ọmọ Merari: Mahili, Libni ọmọ rẹ̀. Ṣimei ọmọ rẹ̀, Ussa ọmọ rẹ̀.
Los hijos de Merari: Mahali, Libni su hijo, Simi su hijo, Uzza su hijo,
30 Ṣimea ọmọ rẹ̀, Haggiah ọmọ rẹ̀ àti Asaiah ọmọ rẹ̀.
Sima su hijo, Haggía su hijo, Assía su hijo.
31 Èyí ní àwọn ọkùnrin Dafidi tí a fi sí ìdí orin nínú ilé Olúwa lẹ́yìn tí àpótí ẹ̀rí ti wá láti sinmi níbẹ̀.
Y estos son á los que David dió cargo de las cosas de la música de la casa de Jehová, después que el arca tuvo reposo:
32 Wọ́n jíṣẹ́ pẹ̀lú orin níwájú àgọ́ ìpàdé títí tí Solomoni fi kọ́ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu. Wọ́n ṣe iṣẹ́ ìsìn wọn ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà tí a fi lélẹ̀ fún wọn.
Los cuales servían delante de la tienda del tabernáculo del testimonio en cantares, hasta que Salomón edificó la casa de Jehová en Jerusalem: después estuvieron en su ministerio según su costumbre.
33 Wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin tí ó sìn pẹ̀lú ọmọ wọn. Láti ọ̀dọ̀ àwọn ará Kohati: Hemani olùkọrin, ọmọ Joẹli, ọmọ Samuẹli,
Estos pues con sus hijos asistían: de los hijos de Coath, Hemán cantor, hijo de Joel, hijo de Samuel;
34 ọmọ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elieli, ọmọ Toha,
Hijo de Elcana, hijo de Jeroham, hijo de Eliel, hijo de Thoa;
35 ọmọ Sufu, ọmọ Elkana, ọmọ Mahati, ọmọ Amasai,
Hijo de Suph, hijo de Elcana, hijo Mahath, hijo de Amasai;
36 ọmọ Elkana, ọmọ Joẹli, ọmọ Asariah, ọmọ Sefaniah,
Hijo de Elcana, hijo de Joel, hijo de Azarías, hijo de Sophonías;
37 ọmọ Tahati, ọmọ Asiri, ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora,
Hijo de Thahat, hijo de Asir, hijo de Abiasaph, hijo de Core;
38 ọmọ Isari, ọmọ Kohati, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli;
Hijo de Ishar, hijo de Coath, hijo de Leví, hijo de Israel.
39 Hemani sì darapọ̀ mọ́ Asafu, ẹni tí o sìn ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀: Asafu ọmọ Berekiah, ọmọ Ṣimea,
Y su hermano Asaph, el cual estaba á su mano derecha: Asaph, hijo de Berachîas, hijo de Sima;
40 ọmọ Mikaeli, ọmọ Baaseiah, ọmọ Malkiah
Hijo de Michâel, hijo de Baasías, hijo de Malchîas;
41 ọmọ Etini, ọmọ Sera, ọmọ Adaiah,
Hijo de Athanai, hijo de Zera, hijo de Adaia;
42 ọmọ Etani, ọmọ Simma, ọmọ Ṣimei,
Hijo de Ethán, hijo de Zimma, hijo de Simi;
43 ọmọ Jahati, ọmọ Gerṣoni, ọmọ Lefi;
Hijo de Jahat, hijo de Gersón, hijo de Leví.
44 láti ìbákẹ́gbẹ́ wọn, àwọn ará Merari wà ní ọwọ́ òsì rẹ̀: Etani ọmọ Kiṣi, ọmọ Abdi, ọmọ Malluki,
Mas los hijos de Merari sus hermanos estaban á la mano siniestra, [es á saber], Ethán hijo de Chîsi, hijo de Abdi, hijo de Maluch;
45 ọmọ Haṣabiah, ọmọ Amasiah, ọmọ Hilkiah,
Hijo de Hasabías, hijo de Amasías, hijo de Hilcías;
46 ọmọ Amisi, ọmọ Bani, ọmọ Ṣemeri,
Hijo de Amasai, hijo de Bani, hijo de Semer;
47 ọmọ Mahili, ọmọ Muṣi, ọmọ Merari, ọmọ Lefi.
Hijo de Mahali, hijo de Musi, hijo de Merari, hijo de Leví.
48 Àwọn Lefi ẹgbẹ́ wọn ni wọn yan àwọn iṣẹ́ yòókù ti àgọ́ fún, èyí tí í ṣe ilé Ọlọ́run.
Y sus hermanos los Levitas fueron puestos sobre todo el ministerio del tabernáculo de la casa de Dios.
49 Ṣùgbọ́n Aaroni àti àwọn ìran ọmọ rẹ̀ jẹ́ àwọn tí ó gbé ọrẹ kalẹ̀ lórí pẹpẹ ẹbọ sísun àti lórí pẹpẹ tùràrí ní ìbátan pẹ̀lú gbogbo ohun tí a ṣe ní Ibi Mímọ́ Jùlọ. Ṣíṣe ètùtù fún Israẹli, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run ti pàṣẹ.
Mas Aarón y sus hijos ofrecían perfume sobre el altar del holocausto, y sobre el altar del perfume, en toda la obra del lugar santísimo, y para hacer las expiaciones sobre Israel, conforme á todo lo que Moisés siervo de Dios había mandado.
50 Wọ̀nyí ni àwọn ìránṣẹ́ Aaroni: Eleasari ọmọ rẹ̀, Finehasi ọmọ rẹ̀, Abiṣua ọmọ rẹ̀,
Y los hijos de Aarón son estos: Eleazar su hijo, Phinees su hijo, Abisua su hijo;
51 Bukki ọmọ rẹ̀, Ussi ọmọ rẹ̀, Serahiah ọmọ rẹ̀,
Bucci su hijo, Uzzi su hijo, Zeraías su hijo;
52 Meraioti ọmọ rẹ̀, Amariah ọmọ rẹ̀, Ahitubu ọmọ rẹ̀,
Meraioth su hijo, Amarías su hijo, Achîtob su hijo;
53 Sadoku ọmọ rẹ̀ àti Ahimasi ọmọ rẹ̀.
Sadoc su hijo, Achîmaas su hijo.
54 Wọ̀nyí ni ibùgbé wọn tí a pín fún wọn gẹ́gẹ́ bí agbègbè wọn (tí a fi lé àwọn ìran ọmọ Aaroni lọ́wọ́ tí ó wá láti ẹ̀yà Kohati, nítorí kèké alákọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
Y estas son sus habitaciones, conforme á sus domicilios y sus términos, [las] de los hijos de Aarón por las familias de los Coathitas, porque de ellos fué la suerte:
55 A fún wọn ní Hebroni ní Juda pẹ̀lú àyíká pápá oko tútù ilẹ̀ rẹ̀.
Les dieron pues á Hebrón en tierra de Judá, y sus ejidos alrededor de ella.
56 Ṣùgbọ́n àwọn pápá àti ìletò tí ó yí ìlú ńlá náà ká ni a fi fún Kalebu ọmọ Jefunne.
Mas el territorio de la ciudad y sus aldeas se dieron á Caleb, hijo de Jephone.
57 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìran ọmọ Aaroni ni a fún ní Hebroni (ìlú ti ààbò), àti Libina, Jattiri, Eṣitemoa,
Y á los hijos de Aarón dieron las ciudades de Judá de acogimiento, [es á saber], á Hebrón, y á Libna con sus ejidos;
58 Hileni, Debiri,
A Jathir, y Esthemoa con sus ejidos, y á Hilem con sus ejidos, y á Debir con sus ejidos;
59 Aṣani, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ rẹ̀.
A Asán con sus ejidos, y á Beth-semes con sus ejidos:
60 Àti láti inú ẹ̀yà Benjamini, a fún wọn ní Gibeoni, Geba, Alemeti àti Anatoti lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn. Àwọn ìlú wọ̀nyí, tí a pín láàrín àwọn ẹ̀yà Kohati jẹ́ mẹ́tàlá ní gbogbo rẹ̀.
Y de la tribu de Benjamín, á Geba con sus ejidos, y á Alemeth con sus ejidos, y á Anathoth con sus ejidos. Todas sus ciudades fueron trece ciudades, [repartidas] por sus linajes.
61 Ìyókù àwọn ìran ọmọ Kohati ní a pín ìlú mẹ́wàá fún láti àwọn ìdílé ní ti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase.
A los hijos de Coath, que quedaron de su parentela, [dieron] diez ciudades de la media tribu de Manasés por suerte.
62 Àwọn ìran ọmọ Gerṣoni, sí ìdílé ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ẹ̀yà àwọn ẹ̀yà Isakari, Aṣeri àti Naftali, àti láti apá ẹ̀yà Manase tí ó wà ní Baṣani.
Y á los hijos de Gersón, por sus linajes, [dieron] de la tribu de Issachâr, y de la tribu de Aser, y de la tribu de Nephtalí, y de la tribu de Manasés en Basán, trece ciudades.
63 Sebuluni àwọn ìran ọmọ Merari, ìdílé sí ìdílé, ní a pín ìlú méjìlá fún láti ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
Y á los hijos de Merari, por sus linajes, de la tribu de Rubén, y de la tribu de Gad, y de la tribu de Zabulón, [se dieron] por suerte doce ciudades.
64 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli fún àwọn ará Lefi ní ìlú wọ̀nyí pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Y dieron los hijos de Israel á los Levitas ciudades con sus ejidos.
65 Láti ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini ni a pín ìlú tí a ti dárúkọ wọn sẹ́yìn fún.
Y dieron por suerte de la tribu de los hijos de Judá, y de la tribu de los hijos de Simeón, y de la tribu de los hijos de Benjamín, las ciudades que nombraron por sus nombres.
66 Lára àwọn ìdílé Kohati ni a fún ní ìlú láti ẹ̀yà Efraimu gẹ́gẹ́ bí ìlú agbègbè wọn.
Y á los linajes de los hijos de Coath [dieron] ciudades con sus términos de la tribu de Ephraim.
67 Ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, a fún wọn ní Ṣekemu (ìlú ńlá ti ààbò), àti Geseri
Y diéronles las ciudades de acogimiento, á Sichêm con sus ejidos en el monte de Ephraim, y á Gezer con sus ejidos,
68 Jokimeamu, Beti-Horoni.
Y á Jocmeam con sus ejidos, y á Beth-oron con sus ejidos,
69 Aijaloni àti Gati-Rimoni lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Y á Ajalón con sus ejidos, y á Gath-rimmón con sus ejidos.
70 Pẹ̀lú láti apá ààbọ̀ ẹ̀yà Manase àwọn ọmọ Israẹli fún Aneri àti Bileamu lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn, fún ìyókù àwọn ìdílé Kohati.
De la media tribu de Manasés, á Aner con sus ejidos, y á Bilam con sus ejidos, para los del linaje de los hijos de Coath que habían quedado.
71 Àwọn ará Gerṣoni gbà nǹkan wọ̀nyí. Láti ààbọ̀ ẹ̀yà ti Manase wọ́n gba Golani ní Baṣani àti pẹ̀lú Aṣtarotu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù wọn.
Y á los hijos de Gersón [dieron] de la familia de la media tribu de Manasés, á Golan en Basán con sus ejidos y á Astharoth con sus ejidos;
72 Láti ẹ̀yà Isakari wọ́n gba Kedeṣi, Daberati
Y de la tribu de Issachâr, á Cedes con sus ejidos, á Dobrath con sus ejidos,
73 Ramoti àti Anenu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Y á Ramoth con sus ejidos, y á Anem con sus ejidos;
74 Láti ẹ̀yà Aṣeri wọ́n gba Maṣali, Abdoni,
Y de la tribu de Aser, á Masal con sus ejidos, y á Abdón con sus ejidos,
75 Hukoki àti Rehobu lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Y á Ucoc con sus ejidos, y á Rehob con sus ejidos;
76 Pẹ̀lú láti ẹ̀yà Naftali wọ́n gba Kedeṣi ní Galili, Hammoni àti Kiriataimu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Y de la tribu de Nephtalí, á Cedes en Galilea con sus ejidos, y á Ammón con sus ejidos, á Chîriath-jearim con sus ejidos.
77 Àwọn ará Merari (ìyókù àwọn ará Lefi) gbà nǹkan wọ̀nyí. Láti ẹ̀yà Sebuluni wọ́n gba Jokneamu, Karta, Rimoni àti Tabori, lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Y á los hijos de Merari que habían quedado, [dieron] de la tribu de Zabulón á Rimmono con sus ejidos, y á Thabor con sus ejidos;
78 Láti ẹ̀yà Reubeni rékọjá Jordani ìlà-oòrùn Jeriko wọ́n gba Beseri nínú aginjù Jahisa,
Y de la otra parte del Jordán de Jericó, al oriente del Jordán, [dieron], de la tribu de Rubén, á Beser en el desierto con sus ejidos; y á Jasa con sus ejidos,
79 Kedemoti àti Mefaati, lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Y á Chêdemoth con sus ejidos, y á Mephaath con sus ejidos;
80 Pẹ̀lú láti ẹ̀yà Gadi wọ́n gba Ramoti ní Gileadi Mahanaimu,
Y de la tribu de Gad, á Ramot en Galaad con sus ejidos, y á Mahanaim con sus ejidos,
81 Heṣboni àti Jaseri lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Y á Hesbón con sus ejidos, y á Jacer con sus ejidos.

< 1 Chronicles 6 >