< 1 Chronicles 5 >

1 Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí Israẹli. (Nítorí òun ni àkọ́bí; ṣùgbọ́n, bí ó ti ṣe pé ó ba ibùsùn baba rẹ̀ jẹ́, a fi ogún ìbí rẹ̀ fún àwọn ọmọ Josẹfu ọmọ Israẹli: a kì yóò sì ka ìtàn ìdílé náà gẹ́gẹ́ bí ipò ìbí.
Och Rubens söner, Israels förstföddes -- han var nämligen den förstfödde, men därför att han oskärade sin faders bädd, blev hans förstfödslorätt given åt Josefs, Israels sons, söner, dock icke så, att denne skulle upptagas i släktregistret såsom den förstfödde;
2 Nítorí Juda borí àwọn arákùnrin rẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni aláṣẹ ti ń jáde wá; ṣùgbọ́n ogún ìbí jẹ́ ti Josẹfu),
ty väl var Juda den mäktigaste bland sina bröder, och furste blev en av hans avkomlingar, men förstfödslorätten blev dock Josefs --
3 àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku àti Pallu, Hesroni àti Karmi.
Rubens, Israels förstföddes, söner voro Hanok och Pallu, Hesron och Karmi.
4 Àwọn ọmọ Joẹli: Ṣemaiah ọmọ rẹ̀, Gogu ọmọ rẹ̀, Ṣimei ọmọ rẹ̀.
Joels söner voro hans son Semaja, dennes son Gog, dennes son Simei,
5 Mika ọmọ rẹ̀, Reaiah ọmọ rẹ̀, Baali ọmọ rẹ̀.
dennes son Mika, dennes son Reaja, dennes son Baal,
6 Beera ọmọ rẹ̀, tí Tiglat-Pileseri ọba Asiria kó ní ìgbèkùn lọ. Ìjòyè àwọn ọmọ Reubeni ni Beera jẹ́.
så ock dennes son Beera, som Tillegat-Pilneeser, konungen i Assyrien, förde bort i fångenskap; han var hövding för rubeniterna.
7 Àti àwọn arákùnrin rẹ̀ nípa ìdílé wọn, nígbà tí a ń ka ìtàn ìdílé ìran wọn: Jeieli àti Sekariah ni olórí,
Och hans bröder voro, efter sina släkter, när de upptecknades i släktregistret efter sin ättföljd: Jegiel, huvudmannen, Sakarja
8 àti Bela ọmọ Asasi ọmọ Ṣema, ọmọ Joẹli. Wọ́n tí ń gbé Aroeri àní títí dé Nebo àti Baali-Meoni.
och Bela, son till Asas, son till Sema, son till Joel; han bodde i Aroer, och hans boningsplatser nådde ända till Nebo och Baal-Meon.
9 Àti níhà àríwá, o tẹ̀dó lọ títí dé àtiwọ aginjù láti odò Eufurate; nítorí tí ẹran ọ̀sìn wọn pọ̀ sí i ní ilẹ̀ Gileadi.
Och österut nådde hans boningsplatser ända fram till öknen som sträcker sig ifrån floden Frat; ty de hade stora boskapshjordar i Gileads land.
10 Àti ní ọjọ́ Saulu, wọ́n bá àwọn ọmọ Hagari jagun, ẹni tí ó ṣubú nípa ọwọ́ wọn; wọ́n sì ń gbé inú àgọ́ wọn ní gbogbo ilẹ̀ àríwá Gileadi.
Men i Sauls tid förde de krig mot hagariterna, och dessa föllo för deras hand; då bosatte de sig i deras hyddor utefter hela östra sidan av Gilead.
11 Àti àwọn ọmọ Gadi ń gbé lékè wọn, ní ilẹ̀ Baṣani títí dé Saleka:
Och Gads barn hade sina boningsplatser gent emot dem i landet Basan ända till Salka:
12 Joẹli jẹ́ olórí, Ṣafamu ìran ọmọ Janai, àti Ṣafati ni Baṣani.
Joel, huvudmannen, och Safam därnäst, och vidare Jaanai och Safat i Basan.
13 Àti àwọn arákùnrin wọn ti ilẹ̀ àwọn baba wọn ní: Mikaeli, Meṣullamu Ṣeba, Jorai, Jaka, Sia àti Eberi méje.
Och deras bröder voro, efter sina familjer, Mikael, Mesullam, Seba, Jorai, Jaekan, Sia och Eber, tillsammans sju.
14 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Abihaili, ọmọ Huri, ọmọ Jeroa, ọmọ Gileadi, ọmọ Mikaeli, ọmọ Jeṣiṣai, ọmọ Jado, ọmọ Busi.
Dessa voro söner till Abihail, son till Huri, son till Jaroa, son till Gilead, son till Mikael, son till Jesisai, son till Jado, son till Bus.
15 Ahi, ọmọ Adbeeli, ọmọ Guni, olórí ilé àwọn baba wọn.
Men Ahi, son till Abdiel, son till Guni, var huvudman för deras familjer.
16 Wọ́n sì ń gbé Gileadi ní Baṣani àti nínú àwọn ìlú rẹ̀, àti nínú gbogbo ìgbèríko Ṣaroni, ní agbègbè wọn.
Och de bodde i Gilead i Basan och underlydande orter, så ock på alla Sarons utmarker, så långt de sträckte sig.
17 Gbogbo wọ̀nyí ni a kà nípa ìtàn ìdílé, ní ọjọ́ Jotamu ọba Juda, àti ní ọjọ́ Jeroboamu ọba Israẹli.
Alla dessa blevo upptecknade i släktregistret i Jotams, Juda konungs, och i Jerobeams, Israels konungs, tid.
18 Àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, nínú àwọn ọkùnrin alágbára tí wọ́n ń gbé asà àti idà, tí wọ́n sì ń fi ọrun tafà, tí wọ́n sì mòye ogun, jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹgbẹ̀rìnlélógún dín ogójì ènìyàn, tí ó jáde lọ sí ogún náà.
Rubens barn och gaditerna och ena hälften av Manasse stam, de av dem, som voro krigsdugliga och buro sköld och svärd och spände båge och voro stridskunniga, utgjorde fyrtiofyra tusen sju hundra sextio stridbara män.
19 Wọ́n sì bá àwọn ọmọ Hagari jagun, pẹ̀lú Jeturi, àti Nafiṣi àti Nadabu.
Och de förde krig mot hagariterna och mot Jetur, Nafis och Nodab.
20 Nígbà tí wọ́n sì rí ìrànlọ́wọ́ gbà si, a sì fi àwọn ọmọ Hagari lé wọn lọ́wọ́, àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn; nítorí tiwọn ké pe Ọlọ́run ní ogun náà, òun sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn; nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
Och seger beskärdes dem i striden mot dessa, så att hagariterna och alla som voro med dem blevo givna i deras hand; ty de ropade till Gud under striden, och han bönhörde dem, därför att de förtröstade på honom.
21 Wọ́n sì kó ẹran ọ̀sìn wọn lọ; ìbákasẹ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àti àgùntàn ọ̀kẹ́ méjìlá ó lé ẹgbàárùn-ún, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì, àti ènìyàn ọ̀kẹ́ márùn-ún.
Och såsom byte förde de bort deras boskapshjordar, femtio tusen kameler, två hundra femtio tusen får och två tusen åsnor, så ock ett hundra tusen människor.
22 Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ṣubú tí a pa, nítorí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ogun náà, wọ́n sì jókòó ní ipò wọn títí di ìgbà ìkólọ sí ìgbèkùn.
Ty många hade fallit slagna, eftersom striden var av Gud. Sedan bosatte de sig i deras land och bodde där ända till fångenskapen.
23 Àwọn ọmọkùnrin ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ń gbé ní ilẹ̀ náà: wọ́n bí sí i láti Baṣani títí dé Baali-Hermoni, àti Seniri àti títí dé òkè Hermoni.
Halva Manasse stams barn bodde ock där i landet, från Basan ända till Baal-Hermon och Senir och Hermons berg, och de voro talrika.
24 Wọ̀nyí sì ni àwọn olórí ilé àwọn baba wọn. Eferi, Iṣi, Elieli, Asrieli, Jeremiah, Hodafiah àti Jahdieli àwọn alágbára akọni ọkùnrin, ọkùnrin olókìkí, àti olórí ilé àwọn baba wọn.
Och dessa voro huvudmän för sina familjer: Efer, Jisei, Eliel, Asriel, Jeremia, Hodauja och Jadiel, tappra stridsmän, namnkunniga män, huvudmän för sina familjer.
25 Wọ́n sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì ṣe àgbèrè tọ àwọn ọlọ́run ènìyàn ilẹ̀ náà lẹ́yìn, tí Ọlọ́run ti parun ní iwájú wọn.
Men de blevo otrogna mot sina fäders Gud, i det att de i trolös avfällighet lupo efter de gudar som dyrkades av de folk där i landet, som Gud hade förgjort för dem.
26 Nítorí náà Ọlọ́run Israẹli ru ẹ̀mí Pulu ọba Asiria sókè (èyí ni Tiglat-Pileseri ọba Asiria), ó si kó wọn lọ, àní àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase lọ sí ìgbèkùn. Ó sì kó wọn wá sí Hala, àti Habori, àti Harani, àti sí etí odò Gosani; títí dí òní yìí.
Då uppväckte Israels Gud den assyriske konungen Puls ande och den assyriske konungen Tillegat-Pilnesers ande och lät folket föras bort i fångenskap, såväl rubeniterna och gaditerna som ena hälften av Manasse stam, och lät dem komma till Hala, Habor, Hara och Gosans ström, där de äro ännu i dag.

< 1 Chronicles 5 >