< 1 Chronicles 5 >

1 Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí Israẹli. (Nítorí òun ni àkọ́bí; ṣùgbọ́n, bí ó ti ṣe pé ó ba ibùsùn baba rẹ̀ jẹ́, a fi ogún ìbí rẹ̀ fún àwọn ọmọ Josẹfu ọmọ Israẹli: a kì yóò sì ka ìtàn ìdílé náà gẹ́gẹ́ bí ipò ìbí.
Torej sinovi Izraelovega prvorojenca Rubena, (kajti on je bil prvorojenec; toda, ker je omadeževal posteljo svojega očeta, je bila njegova pravica prvorojenstva dana sinovoma Izraelovega sina Jožefa; in rodovnik ni štet po pravici prvorojenstva.
2 Nítorí Juda borí àwọn arákùnrin rẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni aláṣẹ ti ń jáde wá; ṣùgbọ́n ogún ìbí jẹ́ ti Josẹfu),
Kajti Juda je prevladal nad svojimi brati in od njega je prišel glavni vladar; toda pravica prvorojenstva je bila Jožefova.)
3 àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku àti Pallu, Hesroni àti Karmi.
Sinovi, pravim, od Izraelovega prvorojenca Rubena so bili: Hénoh, Palú, Hecrón in Karmí.
4 Àwọn ọmọ Joẹli: Ṣemaiah ọmọ rẹ̀, Gogu ọmọ rẹ̀, Ṣimei ọmọ rẹ̀.
Joélovi sinovi: njegov sin Šemajá, njegov sin Gog, njegov sin Šimí,
5 Mika ọmọ rẹ̀, Reaiah ọmọ rẹ̀, Baali ọmọ rẹ̀.
njegov sin Miha, njegov sin Reajá, njegov sin Báal,
6 Beera ọmọ rẹ̀, tí Tiglat-Pileseri ọba Asiria kó ní ìgbèkùn lọ. Ìjòyè àwọn ọmọ Reubeni ni Beera jẹ́.
njegov sin Beerá, ki ga je asirski kralj Tiglát Pilnéser, odvedel ujetega. On je bil princ Rubenovcev.
7 Àti àwọn arákùnrin rẹ̀ nípa ìdílé wọn, nígbà tí a ń ka ìtàn ìdílé ìran wọn: Jeieli àti Sekariah ni olórí,
Njegovi bratje po njihovih družinah, ko je bil preštet rodovnik njihovih rodov, so bili vodja Jeiél, Zeharjá,
8 àti Bela ọmọ Asasi ọmọ Ṣema, ọmọ Joẹli. Wọ́n tí ń gbé Aroeri àní títí dé Nebo àti Baali-Meoni.
Bela, sin Azáza, sinú Šemaá, sinú Joéla, ki je prebival v Aroêrju, celo do Nebója in Báal Meóna;
9 Àti níhà àríwá, o tẹ̀dó lọ títí dé àtiwọ aginjù láti odò Eufurate; nítorí tí ẹran ọ̀sìn wọn pọ̀ sí i ní ilẹ̀ Gileadi.
in proti vzhodu je naseljeval do vstopa v divjino, od reke Evfrat, ker je bila njihova živina pomnožena v deželi Gileád.
10 Àti ní ọjọ́ Saulu, wọ́n bá àwọn ọmọ Hagari jagun, ẹni tí ó ṣubú nípa ọwọ́ wọn; wọ́n sì ń gbé inú àgọ́ wọn ní gbogbo ilẹ̀ àríwá Gileadi.
V Savlovih dneh so se bojevali s Hagríjevci, ki so padli po njihovi roki in prebivali so v njihovih šotorih po vsej vzhodni deželi Gileád.
11 Àti àwọn ọmọ Gadi ń gbé lékè wọn, ní ilẹ̀ Baṣani títí dé Saleka:
Gadovi otroci so prebivali nasproti njih, v deželi Bašán do Salhe;
12 Joẹli jẹ́ olórí, Ṣafamu ìran ọmọ Janai, àti Ṣafati ni Baṣani.
vodja Joél, naslednji Šafám, Janáj in Šafát v Bašánu.
13 Àti àwọn arákùnrin wọn ti ilẹ̀ àwọn baba wọn ní: Mikaeli, Meṣullamu Ṣeba, Jorai, Jaka, Sia àti Eberi méje.
Njihovi bratje iz hiše njihovih očetov so bili: Mihael, Mešulám, Šeba, Joráj, Jakán, Ziá in Heber, sedem.
14 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Abihaili, ọmọ Huri, ọmọ Jeroa, ọmọ Gileadi, ọmọ Mikaeli, ọmọ Jeṣiṣai, ọmọ Jado, ọmọ Busi.
Ti so otroci Abihájila, sinú Huríja, sinú Jaróaha, sinú Gileáda, sinú Mihaela, sinú Ješišája, sinú Jahdója, Buzovega sina;
15 Ahi, ọmọ Adbeeli, ọmọ Guni, olórí ilé àwọn baba wọn.
Ahí, sin Abdiéla, Guníjevega sina, vodja hiše njihovih očetov.
16 Wọ́n sì ń gbé Gileadi ní Baṣani àti nínú àwọn ìlú rẹ̀, àti nínú gbogbo ìgbèríko Ṣaroni, ní agbègbè wọn.
Prebivali so v Gileádu, v Bašánu in v njihovih mestih in v vseh predmestjih Šaróna, na njihovih mejah.
17 Gbogbo wọ̀nyí ni a kà nípa ìtàn ìdílé, ní ọjọ́ Jotamu ọba Juda, àti ní ọjọ́ Jeroboamu ọba Israẹli.
Vsi ti so bili šteti po rodovnikih v dneh Judovega kralja Jotáma in v dneh Izraelovega kralja Jerobeáma.
18 Àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, nínú àwọn ọkùnrin alágbára tí wọ́n ń gbé asà àti idà, tí wọ́n sì ń fi ọrun tafà, tí wọ́n sì mòye ogun, jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹgbẹ̀rìnlélógún dín ogójì ènìyàn, tí ó jáde lọ sí ogún náà.
Sinovi Rubena, Gádovcev in polovice Manásejevega rodu izmed hrabrih mož, mož zmožnih, da nosijo ščit in meč in da streljajo z lokom in veščih v vojni, je bilo štiriinštirideset tisoč sedemsto šestdeset, ki so odšli ven na vojsko.
19 Wọ́n sì bá àwọn ọmọ Hagari jagun, pẹ̀lú Jeturi, àti Nafiṣi àti Nadabu.
Bojevali so se s Hagríjevci, z Jetúrjem, Nafíšem in Nodábom.
20 Nígbà tí wọ́n sì rí ìrànlọ́wọ́ gbà si, a sì fi àwọn ọmọ Hagari lé wọn lọ́wọ́, àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn; nítorí tiwọn ké pe Ọlọ́run ní ogun náà, òun sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn; nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
Pomagano jim je bilo zoper njih in Hagríjevci so bili izročeni v njihovo roko in vsi tisti, ki so bili z njimi; kajti v bitki so vpili k Bogu in izprošen je bil od njih, ker so svoje zaupanje položili vanj.
21 Wọ́n sì kó ẹran ọ̀sìn wọn lọ; ìbákasẹ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àti àgùntàn ọ̀kẹ́ méjìlá ó lé ẹgbàárùn-ún, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì, àti ènìyàn ọ̀kẹ́ márùn-ún.
Odvzeli so njihovo živino; od njihovih kamel petdeset tisoč in od ovc dvesto petdeset tisoč in od oslov dva tisoč in od ljudi sto tisoč.
22 Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ṣubú tí a pa, nítorí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ogun náà, wọ́n sì jókòó ní ipò wọn títí di ìgbà ìkólọ sí ìgbèkùn.
Kajti tam je padlo mnogo umorjenih, ker je bila vojna od Boga. In namesto njih so tam prebivali do ujetništva.
23 Àwọn ọmọkùnrin ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ń gbé ní ilẹ̀ náà: wọ́n bí sí i láti Baṣani títí dé Baali-Hermoni, àti Seniri àti títí dé òkè Hermoni.
Otroci polovice Manásejevega rodu so prebivali v deželi. Množili so se od Bašána do Báal Hermona in Senírja in do gore Hermon.
24 Wọ̀nyí sì ni àwọn olórí ilé àwọn baba wọn. Eferi, Iṣi, Elieli, Asrieli, Jeremiah, Hodafiah àti Jahdieli àwọn alágbára akọni ọkùnrin, ọkùnrin olókìkí, àti olórí ilé àwọn baba wọn.
Ti so bili poglavarji hiše njihovih očetov, celo Efer, Jiší, Eliél, Azriél, Jeremija, Hodavijá in Jahdiél, močni junaški možje, slavni možje in poglavarji hiše njihovih očetov.
25 Wọ́n sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì ṣe àgbèrè tọ àwọn ọlọ́run ènìyàn ilẹ̀ náà lẹ́yìn, tí Ọlọ́run ti parun ní iwájú wọn.
Pregrešili so se zoper Boga svojih očetov in se odšli vlačugat za bogovi ljudstva dežele, ki jih je Bog uničil pred njimi.
26 Nítorí náà Ọlọ́run Israẹli ru ẹ̀mí Pulu ọba Asiria sókè (èyí ni Tiglat-Pileseri ọba Asiria), ó si kó wọn lọ, àní àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase lọ sí ìgbèkùn. Ó sì kó wọn wá sí Hala, àti Habori, àti Harani, àti sí etí odò Gosani; títí dí òní yìí.
Izraelov Bog pa je razvnel duha asirskega kralja Pula in duha asirskega kralja Tiglát Pilnéserja in ta jih je odvedel proč, celo Rubenovce, Gádovce in polovico Manásejevega rodu in jih privedel v Haláh, Habór, Haro in k reki Gozán do današnjega dne.

< 1 Chronicles 5 >