< 1 Crônicas 2 >

1 Estes são os filhos de Israel: Rúben, Simeão, Levi, Judá, Issacar, Zebulom,
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli. Reubeni, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Sebuluni,
2 Dã, José, Benjamim, Naftali, Gade, e Aser.
Dani, Josẹfu, Benjamini; Naftali, Gadi: àti Aṣeri.
3 Os filhos de Judá foram: Er, Onã, e Selá. [Estes] três lhe nasceram de Bete-Suá, Cananeia. E Er, primogênito, de Judá, foi mau diante do Senhor, que o matou.
Àwọn ọmọ Juda: Eri, Onani àti Ṣela, àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí ni wọ́n bí fún un láti ọ̀dọ̀ arábìnrin Kenaani, ọmọbìnrin Ṣua. Eri àkọ́bí Juda, ó sì burú ní ojú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì pa á.
4 E Tamar, sua nora, lhe deu à luz Perez e a Zerá. Todos os filhos de Judá foram cinco.
Tamari, aya ọmọbìnrin Juda, ó sì bí Peresi àti Sera sì ní ọmọ márùn-ún ní àpapọ̀.
5 Os filhos de Perez: Hezrom e Hamul.
Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
6 E os filhos de Zerá: Zinri, Etã, Hemã, e Calcol, e Darda; cinco ao todo.
Àwọn ọmọ Sera: Simri, Etani, Hemani, Kalkoli àti Dara, gbogbo wọn jẹ́ márùn-ún.
7 O filho de Carmi foi Acar, o perturbador de Israel, porque transgrediu naquilo que estava separado por maldiçãos.
Àwọn ọmọ Karmi: Akani, ẹni tí ó mú ìyọnu wá sórí Israẹli nípa ẹ̀ṣẹ̀ ìfibú lórí mímú ohun ìyàsọ́tọ̀.
8 O filho de Etã foi Azarias.
Àwọn ọmọ Etani: Asariah.
9 Os filhos que nasceram a Hezrom foram: Jerameel, Rão, e Quelubai.
Àwọn ọmọ tí a bí fún Hesroni ni: Jerahmeeli, Ramu àti Kalebu.
10 E Rão gerou a Aminadabe; e Aminadabe gerou a Naasom, príncipe dos filhos de Judá;
Ramu sì ni baba Amminadabu, àti Amminadabu baba Nahiṣoni olórí àwọn ènìyàn Juda.
11 E Naasom gerou a Salmom, e Salmom gerou a Boaz;
Nahiṣoni sì ni baba Salmoni, Salmoni ni baba Boasi,
12 E Boaz gerou a Obede, e Obede gerou a Jessé;
Boasi baba Obedi àti Obedi baba Jese.
13 E Jessé gerou a Eliabe, seu primogênito, e o segundo Abinadabe, o terceiro Simeia;
Jese sì ni baba Eliabu àkọ́bí rẹ̀; ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì sì ni Abinadabu, ẹlẹ́ẹ̀kẹta ni Ṣimea,
14 O quarto Natanael, o quinto Radai;
ẹlẹ́ẹ̀kẹrin Netaneli, ẹlẹ́ẹ̀karùnún Raddai,
15 O sexto Ozém, o sétimo Davi;
ẹlẹ́ẹ̀kẹfà Osemu àti ẹlẹ́ẹ̀keje Dafidi.
16 As irmãs dos quais foram Zeruia e Abigail. Os filhos de Zeruia foram três: Abisai, Joabe, e Asael.
Àwọn arábìnrin wọn ni Seruiah àti Abigaili. Àwọn ọmọ mẹ́ta Seruiah ni Abiṣai, Joabu àti Asaheli.
17 E Abigail deu à luz Amasa, cujo pai foi Jéter, o Ismaelita.
Abigaili ni ìyá Amasa, ẹni tí baba rẹ̀ sì jẹ́ Jeteri ará Iṣmaeli.
18 E Calebe filho de Hezrom gerou de sua mulher Azuba, e de Jeriote. E os filhos dela foram: Jeser, Sobabe, e Ardom.
Kalebu ọmọ Hesroni ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó rẹ̀ Asuba (láti ọ̀dọ̀ Jerioti). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ rẹ̀: Jeṣeri, Ṣobabu àti Ardoni.
19 E Azuba morreu, e Calebe tmou por mulher a Efrate, a qual lhe gerou a Hur.
Nígbà tí Asuba sì kú, Kalebu sì fẹ́ Efrata ní aya, ẹni tí ó bí Huri fún un.
20 E Hur gerou a Uri, e Uri gerou a Bezalel.
Huri ni baba Uri, Uri sì jẹ́ baba Besaleli.
21 Depois Hezrom se deitou com a filha de Maquir, pai de Gileade, a qual ele tomou por esposa quando ele tinha sessenta anos, e ela lhe gerou a Segube.
Nígbà tí ó yá, Hesroni sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ọmọbìnrin Makiri baba Gileadi (ó sì ti fẹ́ ní aya láti ìgbà tí ó ti wà ní ẹni ọgọ́ta ọdún) ó sì bí Segubu.
22 E Segube gerou a Jair, que teve vinte e três cidades na terra de Gileade.
Segubu sì jẹ́ baba Jairi, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí ìlú mẹ́tàlélógún ní ilẹ̀ Gileadi.
23 E Gesur e Arã tomaram deles as cidades de Jair, e a Quenate com suas aldeias, sessenta cidades. Todos estes foram filhos de Maquir, pai de Gileade.
(Ṣùgbọ́n Geṣuri àti Aramu sì fi agbára gba Hafoti-Jairi, àti Kenati pẹ̀lú gbogbo agbègbè rẹ̀ tí wọn tẹ̀dó sí jẹ́ ọgọ́ta ìlú.) Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Makiri baba Gileadi.
24 E depois da morte de Hezrom, em Calebe de Efrata, Abia mulher de Hezrom, lhe gerou a Asur, pai de Tecoa.
Lẹ́yìn tí Hesroni sì kú ni Kalebu Efrata, Abijah ìyàwó rẹ̀ ti Hesroni sì bí Aṣihuri baba Tekoa fún un.
25 E os filhos de Jerameel primogênito de Hezrom foram: Rão (seu primogênito), Buna, Orém, Ozém, e Aías.
Ọmọ Jerahmeeli àkọ́bí Hesroni: Ramu ọmọ àkọ́bí rẹ̀ Buna, Oreni, Osemu àti Ahijah.
26 Jerameel também teve outra mulher chamada Atara, que foi mãe de Onã.
Jerahmeeli ní ìyàwó mìíràn, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Atara; ó sì jẹ́ ìyá fún Onamu.
27 E os filhos de Rão, primogênito de Jerameel, foram: Maaz, Jamim, e Equer.
Àwọn ọmọ Ramu àkọ́bí Jerahmeeli: Maasi, Jamini àti Ekeri.
28 E os filhos de Onã foram: Samai, e Jada. E os filhos de Samai: Nadabe, e Abisur.
Àwọn ọmọ Onamu: Ṣammai àti Jada. Àwọn ọmọ Ṣammai: Nadabu àti Abiṣuri.
29 E o nome da mulher de Abisur era Abiail, a qual lhe gerou a Abã e a Molide.
Orúkọ ìyàwó Abiṣuri ni Abihaili ẹni tí ó bí Ahbani àti Molidi.
30 E os filhos de Nadabe foram: Selede e Apaim. E Selede morreu sem filhos.
Àwọn ọmọ Nadabu Seledi àti Appaimu. Seledi sì kú láìsí ọmọ.
31 E o filho de Apaim foi Isi; o filho de Isi foi Sesã; e o filho de Sesã foi Alai.
Àwọn ọmọ Appaimu: Iṣi, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Ṣeṣani. Ṣeṣani sì jẹ́ baba fún Ahlai.
32 E os filhos de Jada, irmão de Simmai, foram: Jéter e Jônatas. E Jéter morreu sem filhos.
Àwọn ọmọ Jada, arákùnrin Ṣammai: Jeteri àti Jonatani. Jeteri sì kú láìní ọmọ.
33 E os filhos de Jônatas foram: Pelete, e Zaza. Estes foram os filhos de Jerameel.
Àwọn ọmọ Jonatani: Peleti àti Sasa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Jerahmeeli.
34 E Sesã não teve filhos, mas somente filhas. E Sesã tinha um servo egípcio, cujo nome era Jará.
Ṣeṣani kò sì ní ọmọkùnrin àwọn ọmọbìnrin nìkan ni ó ní. Ó sì ní ìránṣẹ́ ará Ejibiti tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jariha.
35 Sesã deu sua filha a seu servo Jará, e ela lhe gerou a Atai.
Ṣeṣani sì fi ọmọ obìnrin rẹ̀ ní aya fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Jariha, ó sì bí ọmọ fún tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ Attai.
36 E Atai gerou a Natã, e Natã gerou a Zabade;
Attai sì jẹ́ baba fún Natani, Natani sì jẹ́ baba fún Sabadi,
37 E Zabade gerou a Eflal, e Eflal gerou a Obede;
Sabadi ni baba Eflali, Eflali jẹ́ baba Obedi,
38 E Obede gerou a Jeú, e Jeú gerou a Azarias;
Obedi sì ni baba Jehu, Jehu ni baba Asariah,
39 E Azarias gerou a Helez, Helez gerou a Eleasá;
Asariah sì ni baba Helesi, Helesi ni baba Eleasa,
40 Eleasá gerou a Sismai, e Sismai gerou a Salum;
Eleasa ni baba Sismai, Sismai ni baba Ṣallumu,
41 E Salum gerou a Jecamias, e Jecamias gerou a Elisama.
Ṣallumu sì ni baba Jekamiah, Jekamiah sì ni baba Eliṣama.
42 Os filhos de Calebe, irmão de Jerameel, foram: Messa seu primogênito, que foi o pai de Zife; e os filhos de Maressa, pai de Hebrom.
Àwọn ọmọ Kalebu arákùnrin Jerahmeeli: Meṣa àkọ́bí rẹ̀, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Sifi, àti àwọn ọmọ rẹ̀ Meraṣa, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Hebroni.
43 E os filhos de Hebrom foram: Corá, Tapua, Requém, e Sema.
Àwọn ọmọ Hebroni: Kora, Tapua, Rekemu, àti Ṣema.
44 E Sema gerou a Raão, pai de Jorqueão; e Requém gerou a Samai.
Ṣema ni baba Rahamu, Rahamu sì jẹ́ baba fún Jorkeamu. Rekemu sì ni baba Ṣammai.
45 E o filho de Samai foi Maom, e Maom foi pai de Bete-Zur.
Àwọn ọmọ Ṣammai ni Maoni, Maoni sì ni baba Beti-Suri.
46 E Efá, a concubina de Calebe, lhe gerou a Harã, Moza, e a Gazez. E Harã gerou a Gazez.
Efani obìnrin Kalebu sì ni ìyá Harani, Mosa àti Gasesi, Harani sì ni baba Gasesi.
47 E os filhos de Jadai foram: Regém, Jotão, Gesã, Pelete, Efá, e Saafe.
Àwọn ọmọ Jahdai: Regemu, Jotamu, Geṣani, Peleti, Efani àti Ṣaafu.
48 Maaca, concubina de Calebe, lhe gerou a Seber, e a Tiraná.
Maaka obìnrin Kalebu sì ni ìyá Seberi àti Tirhana.
49 Ela também deu à luz a Saafe, pai de Madmana, e a Seva, pai de Macbena e pai de Gibeá. E a filha de Calebe foi Acsa.
Ó sì bí Ṣaafu baba Madmana, Ṣefa baba Makbena àti baba Gibeah, ọmọbìnrin Kalebu sì ni Aksa.
50 Estes foram os filhos de Calebe, filho de Hur, primogênito de Efrata: Sobal, pai de Quiriate-Jearim;
Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Kalebu. Àwọn ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata: Ṣobali baba Kiriati-Jearimu.
51 Salma, pai dos belemitas; e Harefe, pai de Bete-Gader.
Salma baba Bẹtilẹhẹmu àti Harefu baba Beti-Gaderi.
52 E os filhos de Sobal, pai de Quiriate-Jearim foram: Haroé, a metade dos Manaatitas.
Àwọn ọmọ Ṣobali baba Kiriati-Jearimu ni: Haroe, ìdajì àwọn ará Manaheti.
53 E as famílias de Quiriate-Jearim foram os itreus, os puteus, os sumateus, e os misraeus; destes saíram os zorateus e os estaoleus.
Àti ìdílé Kiriati-Jearimu: àti àwọn ara Itri, àti àwọn ará Puti, àti àwọn ará Ṣumati àti àwọn ará Miṣraiti: láti ọ̀dọ̀ wọn ni àwọn ọmọ ará Sorati àti àwọn ará Eṣtaoli ti wá.
54 Os filhos de Salma foram: Belém, e os netofatitas, Atarote, Bete-Joabe; e da metade dos manaatitas, [e] os zoritas.
Àwọn ọmọ Salma: Bẹtilẹhẹmu, àti àwọn ará Netofa, Atrotu Beti-Joabu, ìdajì àwọn ará Manahati, àti ará Sori,
55 E as famílias dos escribas, que habitavam em Jabez, foram os tiratitas, os simeatitas, [e] os sucatitas; estes foram os queneus que vieram de Hamate, pai da casa de Recabe.
àti àwọn ìdílé àwọn akọ̀wé, ẹni tí ń gbé ní Jabesi: àti àwọn ọmọ Tirati àti àwọn ará Ṣimeati àti àwọn ará Sukati. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ará Keni, ẹni tí ó wá láti ọ̀dọ̀ Hamati, baba ilé Rekabu.

< 1 Crônicas 2 >