< Jeremiasza 16 >

1 I doszło do mnie słowo PANA mówiące:
Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Nie pojmiesz sobie żony ani nie będziesz miał synów i córek na tym miejscu.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
3 Tak bowiem mówi PAN o synach i córkach urodzonych na tym miejscu, o ich matkach, które ich urodzą, i o ich ojcach, którzy ich spłodzą w tej ziemi:
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
4 Pomrą od ciężkich śmiertelnych [chorób]; nie będą opłakiwani ani pogrzebani, [lecz] staną się nawozem na powierzchni ziemi. Wyginą od miecza i głodu, a ich trupy będą pokarmem dla ptactwa nieba i zwierząt ziemi.
“Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
5 Tak bowiem mówi PAN: Nie wchodź do domu żałoby i nie chodź opłakiwać ani żałować ich, bo odjąłem mój pokój od tego ludu, miłosierdzie i litość, mówi PAN.
Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
6 Pomrą wielcy i mali w tej ziemi. Nie będą pogrzebani ani opłakiwani, nikt nie będzie dla nich się nacinał ani robił sobie łysiny;
“Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
7 Nikt nie będzie łamać [chleba] z tymi, którzy są w żałobie, aby ich pocieszyć po zmarłym, ani nie dadzą im pić z kubka pocieszenia za ich ojca lub matkę.
Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
8 Nie wchodź do domu uczty, by zasiąść z nimi do jedzenia i picia.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
9 Tak bowiem mówi PAN zastępów, Bóg Izraela: Oto sprawię, że na waszych oczach i za waszych dni ustanie na tym miejscu głos wesela i głos radości, głos oblubieńca i głos oblubienicy.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
10 A gdy ogłosisz temu ludowi wszystkie te słowa, a zapytają cię: Czemu PAN zapowiedział przeciwko nam całe to wielkie nieszczęście? I jaka jest nasza nieprawość, i jaki nasz grzech, który popełniliśmy przeciwko PANU, naszemu Bogu?
“Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
11 Wtedy powiesz im: Dlatego, że wasi ojcowie opuścili mnie, mówi PAN, i poszli za innymi bogami, służyli im i oddawali im pokłon, mnie zaś opuścili i nie przestrzegali mojego prawa.
Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
12 A wy czyniliście jeszcze gorzej niż wasi ojcowie, bo oto każdy [z was] postępuje według uporu swego złego serca, nie słuchając mnie;
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
13 Dlatego wyrzucę was z tej ziemi do ziemi, której nie znaliście, [ani] wy, ani wasi ojcowie, i tam będziecie służyć innym bogom dniem i nocą, gdzie nie okażę wam miłosierdzia.
Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
14 Dlatego oto nadchodzą dni, mówi PAN, że już nie będą mówić: Jak żyje PAN, który wyprowadził synów Izraela z ziemi Egiptu;
“Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
15 Ale: Jak żyje PAN, który wyprowadził synów Izraela z ziemi północnej i ze wszystkich ziem, do których ich wygnał. I sprowadzę ich znowu do ich ziemi, którą dałem ich ojcom.
Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
16 Oto poślę po wielu rybaków, mówi PAN, i ci ich wyłowią; potem poślę po wielu myśliwych, i ci ich upolują na każdej górze i na każdym pagórku, i w rozpadlinach skalnych.
“Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
17 Moje oczy bowiem patrzą na wszystkie ich drogi. Nie są ukryte przed moim obliczem ani ich nieprawość nie jest zakryta przed moimi oczami.
Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
18 Najpierw odpłacę im podwójnie za ich nieprawości i za ich grzechy, za to, że zbezcześcili moją ziemię trupami swoich obrzydliwości i napełnili moje dziedzictwo swoimi ohydami.
Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
19 PANIE, moja mocy i siło, moja ucieczko w dniu utrapienia! Do ciebie przyjdą poganie od krańców ziemi i powiedzą: Zaprawdę, nasi ojcowie odziedziczyli kłamstwa i marności, w których nie było żadnego pożytku.
Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
20 Czy człowiek może uczynić sobie bogów? Przecież to nie są bogowie.
Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
21 Dlatego oto ja sprawię, że poznają tym razem; sprawię, że poznają moją rękę i moc, i dowiedzą się, że moje imię to PAN.
“Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.

< Jeremiasza 16 >