< اعداد 36 >

و روسای خاندان آبای قبیله بنی جلعادبن ماکیربن منسی که از قبایل بنی یوسف بودند نزدیک آمده به حضور موسی وبه حضور سروران و روسای خاندان آبای بنی‌اسرائیل عرض کرده، ۱ 1
Àwọn olórí ìdílé Gileadi, ọmọkùnrin Makiri ọmọ Manase tí ó wá láti ara ìdílé ìran Josẹfu wá, wọ́n sì sọ̀rọ̀ níwájú Mose àti àwọn olórí, àwọn ìdílé Israẹli.
گفتند: «خداوند، آقای ما را امر فرمود که زمین را به قرعه تقسیم کرده، به بنی‌اسرائیل بدهد، و آقای ما از جانب خداوند مامور شده است که نصیب برادر ماصلفحاد را به دخترانش بدهد. ۲ 2
Wọ́n sọ pé, “Nígbà tí Olúwa pàṣẹ fún olúwa mi láti fi ilẹ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ogún nípa kèké ṣíṣẹ́. Ó pa á láṣẹ fún ọ láti fi ogún Selofehadi arákùnrin wa fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀.
پس اگر ایشان به یکی از پسران سایر اسباط بنی‌اسرائیل منکوحه شوند، ارث ما از میراث پدران ما قطع شده، به میراث سبطی که ایشان به آن داخل شوند، اضافه خواهد شد، و از بهره میراث ما قطع خواهد شد. ۳ 3
Wàyí, tí wọn bá fẹ́ ọkùnrin láti ẹ̀yà Israẹli mìíràn; nígbà náà a ó gba ogún un wọn kúrò nínú ogún ìran wa, a ó sì fi kún ogún ẹ̀yà tí a fẹ́ wọn sí. Bẹ́ẹ̀ ni a ó sì gbà á kúrò nínú ìpín ilẹ̀ ogún ti wa.
و چون یوبیل بنی‌اسرائیل بشود ملک ایشان به ملک سبطی که به آن داخل شوند اضافه خواهدشد، و ملک ایشان از ملک پدران ما قطع خواهدشد.» ۴ 4
Nígbà tí ọdún ìdásílẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli bá dé, a ó pa ogún wọn pọ̀ mọ́ ẹ̀yà tí wọ́n fẹ́ wọn sí, a ó sì gba ogún ẹ̀yà wọn kúrò lọ́wọ́ baba ńlá wọn.”
پس موسی بنی‌اسرائیل را برحسب قول خداوند امر فرموده، گفت: «سبط بنی یوسف راست گفتند. ۵ 5
Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa, Mose pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ohun ti ẹ̀yà àwọn ìran Josẹfu ń sọ tọ̀nà.
این است آنچه خداوند درباره دختران صلفحاد امر فرموده، گفته است: به هر‌که در نظر ایشان پسند آید، به زنی داده شوند، لیکن در قبیله سبط پدران خود فقط به نکاح داده شوند. ۶ 6
Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ fún àwọn ọmọbìnrin Selofehadi: wọ́n lè fẹ́ ẹni tí ọkàn wọn fẹ́, kìkì pé wọ́n fẹ́ nínú ẹ̀yà ìdílé baba wọn.
پس میراث بنی‌اسرائیل از سبط به سبط منتقل نشود، بلکه هر یکی از بنی‌اسرائیل به میراث سبطپدران خود ملصق باشند. ۷ 7
Kò sí ogún kan ní Israẹli tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà mìíràn, nítorí gbogbo ọmọ Israẹli ni yóò fi ilẹ̀ ogún ẹ̀yà tí wọ́n jogún láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn pamọ́.
و هر دختری که وارث ملکی از اسباط بنی‌اسرائیل بشود، به کسی از قبیله سبط پدر خود به زنی داده شود، تا هریکی از بنی‌اسرائیل وارث ملک آبای خود گردند. ۸ 8
Gbogbo ọmọbìnrin tí ó bá jogún ilẹ̀ nínú ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ fẹ́ ènìyàn nínú ẹ̀yà ìdílé baba rẹ̀, kí gbogbo ọmọ Israẹli lè ní ìpín nínú ogún baba wọn.
و ملک از یک سبط به سبط دیگر منتقل نشود، بلکه هرکس از اسباط بنی‌اسرائیل به میراث خودملصق باشند.» ۹ 9
Kò sí ogún kankan tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà òmíràn, nítorí olúkúlùkù ẹ̀yà ọmọ Israẹli gbọdọ̀ tọ́jú ilẹ̀ tí ó jogún.”
پس چنانکه خداوند موسی را امر فرمود، دختران صلفحاد چنان کردند. ۱۰ 10
Nígbà náà, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
و دختران صلفحاد، محله و ترصه و حجله و ملکه و نوعه به پسران عموهای خود به زنی داده شدند. ۱۱ 11
Nítorí pé a gbé Mahila, Tirsa, Hogla, Milka, àti Noa, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ní ìyàwó fún àwọn ọmọ arákùnrin baba wọn.
درقبایل بنی منسی ابن یوسف منکوحه شدند وملک ایشان در سبط قبیله پدر ایشان باقی ماند. ۱۲ 12
Wọ́n fẹ́ ọkọ nínú ìdílé ìran Manase, ọmọ Josẹfu ogún wọn kù nínú ìdílé àti ẹ̀yà baba wọn.
این است اوامر و احکامی که خداوند به واسطه موسی در عربات موآب نزد اردن در مقابل اریحا به بنی‌اسرائیل امر فرمود. ۱۳ 13
Wọ̀nyí ni àṣẹ àti ìdájọ́ tí Olúwa ti ipasẹ̀ Mose fún àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani létí Jeriko.

< اعداد 36 >