< اشعیا 11 >

و نهالی از تنه یسی بیرون آمده، شاخه‌ای از ریشه هایش خواهدشکفت. ۱ 1
Èèkàn kan yóò sọ láti ibi kùkùté Jese, láti ara gbòǹgbò rẹ̀ ni ẹ̀ka kan yóò ti so èso.
و روح خداوند بر او قرار خواهدگرفت، یعنی روح حکمت و فهم و روح مشورت و قوت و روح معرفت و ترس خداوند. ۲ 2
Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé e, ẹ̀mí ọgbọ́n àti ti òye, ẹ̀mí ìmọ̀ràn àti ti agbára, ẹ̀mí ìmọ̀ àti ti ìbẹ̀rù Olúwa.
وخوشی او در ترس خداوند خواهد بود و موافق رویت چشم خود داوری نخواهد کرد و بر وفق سمع گوشهای خویش تنبیه نخواهد نمود. ۳ 3
Òun yóò sì ní inú dídùn nínú ìbẹ̀rù Olúwa. Òun kì yóò ṣe ìdájọ́ pẹ̀lú ohun tí ó fi ojú u rẹ̀ rí, tàbí pẹ̀lú ohun tí ó fi etí i rẹ̀ gbọ́,
بلکه مسکینان را به عدالت داوری خواهد کرد و به جهت مظلومان زمین براستی حکم خواهد نمود. و جهان را به عصای دهان خویش زده، شریران رابه نفخه لبهای خود خواهد کشت. ۴ 4
ṣùgbọ́n pẹ̀lú òdodo ni yóò ṣe ìdájọ́ àwọn aláìní, pẹ̀lú òtítọ́ ni yóò ṣe ìpinnu fún àwọn aláìní ayé. Òun yóò lu ayé pẹ̀lú ọ̀pá tí ó wà ní ẹnu rẹ̀, pẹ̀lú èémí ẹnu rẹ̀ ni yóò pa àwọn ìkà.
و کمربندکمرش عدالت خواهد بود و کمربند میانش امانت. ۵ 5
Òdodo ni yóò jẹ́ ìgbànú rẹ̀ àti òtítọ́ ni yóò ṣe ọ̀já yí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ká.
و گرگ با بره سکونت خواهد داشت و پلنگ با بزغاله خواهد خوابید و گوساله و شیر و پرواری با هم، و طفل کوچک آنها را خواهد راند. ۶ 6
Ìkookò yóò sì máa bá ọmọ àgùntàn gbé, ẹkùn yóò sì sùn ti ewúrẹ́ ọmọ màlúù òun ọmọ kìnnìún àti ọmọ ẹran ó wà papọ̀ ọ̀dọ́mọdé yóò sì máa dà wọ́n.
و گاوبا خرس خواهد چرید و بچه های آنها با هم خواهند خوابید و شیر مثل گاو کاه خواهد خورد. ۷ 7
Màlúù àti beari yóò máa jẹun pọ̀, àwọn ọmọ wọn yóò dùbúlẹ̀ pọ̀, kìnnìún yóò sì máa jẹ koríko gẹ́gẹ́ bí akọ màlúù.
و طفل شیرخواره بر سوراخ مار بازی خواهدکرد و طفل از شیر باز داشته شده دست خود را برخانه افعی خواهد گذاشت. ۸ 8
Ọ̀dọ́mọdé yóò ṣeré lẹ́bàá ihò ọká, ọmọdé yóò ki ọwọ́ rẹ̀ bọ ìtẹ́ paramọ́lẹ̀.
و در تمامی کوه مقدس من ضرر و فسادی نخواهند کرد زیرا که جهان از معرفت خداوند پر خواهد بود مثل آبهایی که دریا را می‌پوشاند. ۹ 9
Wọn kò ní ṣe ni léṣe tàbí pa ni run ní gbogbo òkè mímọ́ mi, nítorí gbogbo ayé yóò kún fún ìmọ̀ Olúwa gẹ́gẹ́ bí omi ti bo Òkun.
و در آن روز واقع خواهد شد که ریشه یسی به جهت علم قوم‌ها برپا خواهد شد و امت هاآن را خواهند طلبید و سلامتی او با جلال خواهدبود. ۱۰ 10
Ní ọjọ́ náà, gbòǹgbò Jese yóò dúró gẹ́gẹ́ bí àsíá fún gbogbo ènìyàn, àwọn orílẹ̀-èdè yóò pagbo yí i ká, ibùdó ìsinmi rẹ̀ yóò jẹ́ èyí tí ó lógo.
و در آن روز واقع خواهد گشت که خداوند بار دیگر دست خود را دراز کند تا بقیه قوم خویش را که از آشور و مصر و فتروس وحبش و عیلام و شنعار و حمات و از جزیره های دریا باقی‌مانده باشند باز آورد. ۱۱ 11
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò na ọwọ́ rẹ̀ jáde nígbà kejì láti tún gba àwọn tí ó ṣẹ́kù àní àwọn tí a ṣẹ́kù nínú àwọn ènìyàn an rẹ̀ láti Asiria wá, láti ìsàlẹ̀ Ejibiti àti òkè Ejibiti, láti Kuṣi, láti Elamu láti Babiloni, láti Hamati àti láti àwọn erékùṣù inú Òkun.
و به جهت امت‌ها علمی برافراشته، رانده شدگان اسرائیل را جمع خواهد کرد، وپراکندگان یهودا را از چهار طرف جهان فراهم خواهد آورد. ۱۲ 12
Òun yóò gbé àsíá sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè, yóò sì kó àwọn ìgbèkùn Israẹli jọ, yóò kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda tí a ti fọ́n káàkiri jọ, láti igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ ayé.
و حسد افرایم رفع خواهد شد ودشمنان یهودا منقطع خواهند گردید. افرایم بریهودا حسد نخواهد برد و یهودا افرایم را دشمنی نخواهد نمود. ۱۳ 13
Owú jíjẹ Efraimu yóò pòórá, àwọn ọ̀tá Juda ni a ó ké kúrò, Efraimu kò ní jowú Juda, tàbí Juda kó dojúkọ Efraimu.
و به‌جانب مغرب بر دوش فلسطینیان پریده، بنی مشرق را با هم غارت خواهند نمود. و دست خود را بر ادوم و موآب دراز کرده، بنی عمون ایشان را اطاعت خواهندکرد. ۱۴ 14
Wọn yóò fò mọ́ èjìká Filistini sí apá ìwọ̀-oòrùn, wọn yóò pawọ́pọ̀ kọlu àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn. Wọn yóò gbé ọwọ́ wọn lé Edomu àti Moabu, àwọn ará Ammoni yóò sì di ìwẹ̀fà wọn.
و خداوند زبانه دریای مصر را تباه ساخته، دست خود را با باد سوزان بر نهر درازخواهد کرد، و آن را با هفت نهرش خواهد زد ومردم را با کفش به آن عبور خواهد داد. ۱۵ 15
Olúwa yóò sọ di gbígbé àyasí Òkun Ejibiti, pẹ̀lú atẹ́gùn gbígbóná ni yóò na ọwọ́ rẹ̀, kọjá lórí odò Eufurate. Òun yóò sì sọ ọ́ di ọmọdò méje tó fi jẹ́ pé àwọn ènìyàn yóò máa là á kọjá pẹ̀lú bàtà.
و به جهت بقیه قوم او که از آشور باقی‌مانده باشند شاه راهی خواهد بود. چنانکه به جهت اسرائیل در روز بر‌آمدن ایشان از زمین مصربود. ۱۶ 16
Ọ̀nà gidi yóò wà fún àwọn ènìyàn an rẹ̀ tí ó ṣẹ́kù tí ó kù sílẹ̀ ní Asiria, gẹ́gẹ́ bí ó ti wà fún Israẹli nígbà tí wọ́n gòkè láti Ejibiti wá.

< اشعیا 11 >