< حزقیال 47 >

و مرا نزد دروازه خانه آورد و اینک آبهااز زیر آستانه خانه بسوی مشرق جاری بود، زیرا که روی خانه به سمت مشرق بود وآن آبها اززیر جانب راست خانه از طرف جنوب مذبح جاری بود. ۱ 1
Ọkùnrin náà mú mi padà lọ sí àbáwọlé tẹmpili náà, mo sì rí omi tí ó ń tú jáde láti abẹ́ ìloro tẹmpili náà sí apá ìhà ìlà-oòrùn (nítorí tẹmpili náà dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn). Omi náà ń tú jáde sí ìsàlẹ̀ láti abẹ́, ní ìhà gúúsù tẹmpili náà, ní ìhà gúúsù pẹpẹ.
پس مرا از راه دروازه شمالی بیرون برده، از راه خارج به دروازه بیرونی به راهی که به سمت مشرق متوجه است گردانید و اینک آبها از جانب راست جاری بود. ۲ 2
Ó wá mú mi gba ojú ọ̀nà àríwá jáde, ó sì mú mi yí ìta ojú ọ̀nà ìta tí ó dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn, omi náà sì ń sàn láti ìhà gúúsù wá.
و چون آن مردبسوی مشرق بیرون رفت، ریسمانکاری در دست داشت و هزار ذراع پیموده، مرا از آب عبور داد وآبها به قوزک می‌رسید. ۳ 3
Bí ọkùnrin náà ti lọ sí apá ìhà ìlà-oòrùn pẹ̀lú okùn wíwọ̀n nǹkan lọ́wọ́ rẹ̀, ó wọn ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́, ó sì mú mi gba ibi odò kan tí kò jì jù kókósẹ̀ lọ.
پس هزار ذراع پیمود ومرا از آبها عبور داد و آب به زانو می‌رسید و بازهزار ذراع پیموده، مرا عبور داد و آب به کمرمی رسید. ۴ 4
Ó sì wọn ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ mìíràn kúrò, ó sì mú mi gba ibi odò tí ó jì ní ìwọ̀n orúnkún. Ó tún wọn ẹgbẹ̀rún márùn-ún ìgbọ̀nwọ́ mìíràn kúrò, ó sì mú mi gba odò tí ó dé ìbàdí.
پس هزار ذراع پیمود و نهری بود که از آن نتوان عبور کرد زیرا که آب زیاده شده بود، آبی که در آن می‌شود شنا کرد نهری که از آن عبور نتوان کرد. ۵ 5
Ó wọn ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ mìíràn kúrò, ṣùgbọ́n nísinsin yìí odò tí ń kò lè kọjá rẹ̀ ni, nítorí pé odò tí ó kún, ó sì jì tó èyí tí wọ́n le lúwẹ̀ẹ́ nínú rẹ̀ odò tí ẹnikẹ́ni kò le dá kọjá ni.
و مرا گفت: «ای پسر انسان آیااین را دیدی؟» پس مرا از آنجا برده، به کنار نهربرگردانید. ۶ 6
Ó bi mí léèrè pé, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ o rí èyí?” Lẹ́yìn náà, ó mú mi padà sí etí odò.
و چون برگشتم اینک بر کنار نهر از اینطرف و از آنطرف درختان بی‌نهایت بسیار بود. ۷ 7
Nígbà tí mo dé ibẹ̀, mo rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì odò.
و مراگفت: «این آبها بسوی ولایت شرقی جاری می‌شود و به عربه فرود شده، به دریا می‌رود وچون به دریا داخل می‌شود آبهایش شفا می‌یابد. ۸ 8
Ó sọ fún mi pé, “Odò yìí ń tú jáde sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí pẹ̀tẹ́lẹ̀, wọ́n sì wọ inú Òkun lọ, a sì mú omi wọn láradá.
و واقع خواهد شد که هر ذی حیات خزنده‌ای در هر جایی که آن نهر داخل شود، زنده خواهدگشت و ماهیان از حد زیاده پیدا خواهد شد، زیراچون این آبها به آنجا می‌رسد، آن شفا خواهدیافت و هر جایی که نهر جاری می‌شود، همه‌چیززنده می‌گردد. ۹ 9
Àwọn ohun alààyè tí ó ń rákò yóò máa gbé ní ibikíbi tí odò ti ń sàn. Ẹja yóò pọ̀ ni ọ̀pọ̀lọpọ̀, nítorí pé odò ń sàn síbẹ̀, ó sì mú kí omi iyọ̀ tutù nini; nítorí náà níbi tí omi ti ń sàn, gbogbo nǹkan ni yóò wà ni ààyè.
و صیادان بر کنار آن خواهندایستاد و از عین جدی تا عین عجلایم موضعی برای پهن کردن دامها خواهد بود و ماهیان آنها به حسب جنسها، مثل ماهیان دریای بزرگ از حدزیاده خواهند بود. ۱۰ 10
Àwọn apẹja yóò dúró ní etí bèbè odò; láti En-Gedi títí dé En-Eglaimu ààyè yóò wa láti tẹ́ àwọ̀n wọn sílẹ̀. Oríṣìíríṣìí ẹja ni yóò wà gẹ́gẹ́ bí ẹja omi Òkun ńlá.
اما خلابها و تالابهایش شفانخواهد یافت بلکه به نمک تسلیم خواهد شد. ۱۱ 11
Ṣùgbọ́n ẹrẹ̀ àti àbàtà kò ní tòrò; àwa yóò fi wọn sílẹ̀ fún iyọ̀.
و بر کنار نهر به اینطرف و آنطرف هر قسم درخت خوراکی خواهد رویید که برگهای آنهاپژمرده نشود و میوه های آنها لاینقطع خواهد بودو هر ماه میوه تازه خواهد آورد زیرا که آبش از مقدس جاری می‌شود و میوه آنها برای خوراک وبرگهای آنها به جهت علاج خواهد بود.» ۱۲ 12
Àwọn igi eléso ní oríṣìíríṣìí ni yóò máa hù ní bèbè odò ní ìhà ìhín àti ní ìhà ọ̀hún. Ewé wọn kì yóò sì rọ, bẹ́ẹ̀ ní èso wọn kì yóò run, wọn yóò máa ṣe èso tuntun rẹ̀ ní oṣù nítorí pé omi láti ibi mímọ́ ń sàn sí wọn. Èso wọn yóò sì jẹ́ fún jíjẹ àti ewé wọn fún ìwòsàn.”
خداوند یهوه چنین می‌گوید: «این است حدودی که زمین را برای دوازده سبط اسرائیل به آنها تقسیم خواهید نمود. برای یوسف دوقسمت. ۱۳ 13
Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ̀nyí ni àwọn ààlà tí ìwọ yóò fi pín ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ogún ìní ní àárín àwọn ẹ̀yà méjìlá Israẹli, pẹ̀lú ìpín méjì fún Josẹfu.
و شما هر کس مثل دیگری آن را به تصرف خواهید آورد زیرا که من دست خود رابرافراشتم که آن را به پدران شما بدهم پس این زمین به قرعه به شما به ملکیت داده خواهد شد. ۱۴ 14
Ìwọ yóò pín ilẹ̀ náà déédé ní àárín wọn. Nítorí pé mo búra nípa nína ọwọ́ sókè láti fi fún àwọn baba ńlá yin, ilẹ̀ yìí yóò di ogún ìní yín.
و حدود زمین این است. بطرف شمال از دریای بزرگ بطرف حتلون تا مدخل صدد. ۱۵ 15
“Èyí yìí ni yóò jẹ́ ààlà ilẹ̀ náà: “Ní ìhà àríwá yóò lọ láti omi Òkun ńlá ní ibi ọ̀nà Hetiloni gbà tí Hamati lọ sí Sedadi,
حمات وبیروته و سبرایم که در میان سرحد دمشق وسرحد حمات است و حصر وسطی که نزدسرحد حوران است. ۱۶ 16
Berota àti Sibraimu, èyí tí ó wà ní ààlà láàrín Damasku àti Hamati títí dé Hasari Hatikonu, èyí tí ó wà ní agbègbè Haurani.
و حد از دریا حصر عینان نزد سرحد دمشق و بطرف سرحد حمات خواهدبود. و این است جانب شمالی. ۱۷ 17
Ààlà yóò fẹ̀ láti Òkun lọ sí Hasari Enanu, ní apá ààlà ti Damasku, pẹ̀lú ààlà tí Hamati lọ sí apá àríwá. Èyí ni yóò jẹ́ ààlà ní apá ìhà àríwá.
و بطرف شرقی در میان حوران و دمشق و در میان جلعاد و زمین اسرائیل اردن خواهد بود و از این حد تا دریای شرقی خواهی پیمود و این حد شرقی می‌باشد. ۱۸ 18
Ní ìhà ìlà-oòrùn ààlà yóò wá sí àárín Haurani àti Damasku, lọ sí apá Jordani láàrín Gileadi àti ilẹ̀ Israẹli, títí dé Òkun, àti títí dé Tamari. Èyí ní yóò jẹ́ ààlà ìlà-oòrùn.
و طرف جنوبی به‌جانب راست از تامار تا آب مریبوت قادش و نهر (مصر) و دریای بزرگ و این طرف جنوبی به‌جانب راست خواهد بود. ۱۹ 19
Ní ìhà gúúsù yóò lọ láti Tamari títí dé ibi omi Meriba Kadeṣi, lẹ́yìn náà ni ìhà Wadi tí Ejibiti lọ sí Òkun ńlá. Èyí ni yóò jẹ́ ààlà gúúsù.
وطرف غربی دریای بزرگ ازحدی که مقابل مدخل حمات است خواهد بود و این‌جانب غربی باشد. ۲۰ 20
Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, Òkun ńlá ni yóò jẹ́ ààlà títí dé ibi kan ni òdìkejì lẹ́bàá Hamati. Èyí yìí ni yóò jẹ ààlà ìhà ìwọ̀-oòrùn.
پس این زمین را برای خود برحسب اسباط اسرائیل تقسیم خواهید نمود. ۲۱ 21
“Ìwọ ní láti pín ilẹ̀ yìí ní àárín ara yín gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà Israẹli.
وآن را برای خود و برای غریبانی که در میان شماماوا گزینند و در میان شما اولاد بهم رسانند به قرعه تقسیم خواهید کرد و ایشان نزد شما مثل متوطنان بنی‌اسرائیل خواهند بود و با شما درمیان اسباط اسرائیل میراث خواهند یافت. ۲۲ 22
Ìwọ yóò pín gẹ́gẹ́ bí ìní fún ara yín àti fún àwọn àjèjì tí ó ń gbé ní àárín yín tí ó sì ní àwọn ọmọ. Ìwọ yóò sì ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìbílẹ̀ àwọn ará Israẹli; papọ̀ mọ́ yin ni kí ẹ pín ìní fún wọn ní àárín àwọn ẹ̀yà Israẹli.
وخداوند یهوه می‌فرماید: در هر سبط که شخصی غریب در آن ساکن باشد، در همان ملک خود راخواهد یافت. ۲۳ 23
Ní àárín gbogbo ẹ̀yà tí àwọn àlejò ń gbé; wọn gbọdọ̀ fi ìní tirẹ̀ fún un,” ní Olúwa Olódùmarè wí.

< حزقیال 47 >