< حزقیال 21 >
و کلام خداوند بر من نازل شده، گفت: | ۱ 1 |
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
«ای پسر انسان روی خود را بسوی اورشلیم بدار و به مکان های بلند مقدس تکلم نما. و به زمین اسرائیل نبوت کن. | ۲ 2 |
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí ìhà Jerusalẹmu, kí o sì wàásù lòdì sí ibi mímọ́. Sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí ilẹ̀ Israẹli.
و به زمین اسرائیل بگو: خداوند چنین میفرماید: اینک من به ضد توهستم. و شمشیر خود را از غلافش کشیده، عادلان و شریران را از میان تو منقطع خواهم ساخت. | ۳ 3 |
Kí ó sì sọ fún un pe, ‘Èyí yìí ni Olúwa wí, Èmi lòdì sí ọ. Èmi yóò fa idà mi yọ kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀, Èmi yóò sì ké olódodo àti ènìyàn búburú kúrò ni àárín yín.
و چونکه عادلان و شریران را از میان تومنقطع میسازم، بنابراین شمشیر من بر تمامی بشر از جنوب تا شمال از غلافش بیرون خواهدآمد. | ۴ 4 |
Nítorí pé, èmi yóò ké olódodo àti olùṣe búburú kúrò, idà mi yóò jáde láti inú àkọ̀ rẹ̀ lòdì sí gbogbo ènìyàn láti gúúsù títí dé àríwá.
و تمامی بشر خواهند فهمید که من یهوه شمشیر خود را از غلافش بیرون کشیدم تا باز به آن برنگردد. | ۵ 5 |
Nígbà náà gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti yọ idà mi kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀; kì yóò sì padà sínú rẹ̀ mọ́.’
پس توای پسر انسان آه بکش! باشکستگی کمر و مرارت سخت به نظر ایشان آه بکش. | ۶ 6 |
“Nítorí náà, mí ìmí ẹ̀dùn ìwọ ọmọ ènìyàn! Mí ìmí ẹ̀dùn pẹ̀lú ọkàn ìbànújẹ́ àti ẹ̀dùn ọkàn kíkorò ní iwájú wọn.
و اگر به تو گویند که چرا آه میکشی؟ بگو: بهسبب آوازهای که میآید. زیرا که همه دلهاگداخته و تمامی دستها سست گردیده و همه جانها کاهیده و جمیع زانوها مثل آب بیتاب خواهد شد. خداوند یهوه میگوید: همانا آن میآید و به وقوع خواهد پیوست.» | ۷ 7 |
Bí wọ́n bá sì bi ọ́, wí pé, ‘Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń mí ìmí ẹ̀dùn?’ Ìwọ yóò wí pé, ‘Nítorí ìròyìn tí ó ń bẹ. Gbogbo ọkàn ni yóò yọ́, gbogbo ọwọ́ ni yóò sì di aláìlera; gbogbo ọkàn ní yóò dákú, gbogbo eékún ni yóò sì di aláìlera bí omi?’ Ó ń bọ̀! Yóò sì wa sí ìmúṣẹ dandan, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
و کلام خداوند بر من نازل شده، گفت: | ۸ 8 |
Ọ̀rọ̀ Olúwa si tún tọ̀ mí wá pé:
«ای پسر انسان نبوت کرده، بگو: خداوند چنین میفرماید: بگو که شمشیر، شمشیر تیز شده و نیزصیقلی گردیده است. | ۹ 9 |
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ wí pé, èyí yìí ní Olúwa wí pé, “‘Idà kan, idà kan, tí a pọ́n, tí a sì dán pẹ̀lú,
تیز شده است تا کشتارنماید و صیقلی گردیده تا براق شود. پس آیا ما شادی نماییم؟ عصای پسر من همه درختان راخوار میشمارد. | ۱۰ 10 |
a pọ́n láti pa ènìyàn púpọ̀, a dán an láti máa kọ mọ̀nà! “‘Àwa o ha máa ṣe àríyá ọ̀gọ ọmọ mi? Idà gán gbogbo irú igi bẹ́ẹ̀.
و آن برای صیقلی شدن داده شد تا آن را بهدست گیرند. و این شمشیر تیز شده و صیقلی گردیده است تا بهدست قاتل داده شود. | ۱۱ 11 |
“‘Idà ní a yàn láti pọ́n, kí ó lè ṣe é gbámú; a pọ́n ọn, a sì dán an, ó ṣetán fún ọwọ́ àwọn apani.
ای پسر انسان فریاد برآور و ولوله نما زیرا که این بر قوم من و بر جمیع سروران اسرائیل واردمی آید. ترسها بهسبب شمشیر بر قوم من عارض شده است. لهذا بر ران خود دست بزن. | ۱۲ 12 |
Sọkún síta, kí ó sì pohùnréré ẹ̀kún, ọmọ ènìyàn, nítorí yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi; yóò wá sórí gbogbo ọmọ-aládé Israẹli ìbẹ̀rù ńlá yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi nítorí idà náà; nítorí náà lu oókan àyà rẹ.
زیرا که امتحان است. و چه خواهد بود اگر عصایی که (دیگران را) خوار میشمارد، دیگر نباشد. قول خداوند یهوه این است: | ۱۳ 13 |
“‘Ìdánwò yóò dé dandan. Tí ọ̀pá aládé Juda èyí tí idà kẹ́gàn, kò bá tẹ̀síwájú mọ́ ń kọ́? Ni Olúwa Olódùmarè wí.’
و توای پسر انسان نبوت کن و دستهای خود را بهم بزن و شمشیردفعه سوم تکرار بشود. شمشیر مقتولان است. شمشیر آن مقتول عظیم که ایشان را احاطه میکند. | ۱۴ 14 |
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́. Jẹ́ kí idà lu ara wọn lẹ́ẹ̀méjì, kódà ní ẹ̀ẹ̀mẹta. Ó jẹ́ idà fún ìpànìyàn idà fún ìpànìyàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, tí yóò sé wọn mọ́ níhìn-ín àti lọ́hùnnún.
شمشیر برندهای به ضد همه دروازه های ایشان قرار دادم تا دلها گداخته شود وهلاکتها زیاده شود. آه (شمشیر) براق گردیده وبرای کشتار تیز شده است. | ۱۵ 15 |
Kí ọkàn kí ó lè yọ́ kí àwọn tí ó ṣubú le pọ̀, mo ti gbé idà sí gbogbo bodè fún ìparun. Háà! A mú kí ó kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná, a gbá a mú fún ìparun.
جمع شده، بهجانب راست برو و آراسته گردیده، بهجانب چپ توجه نما. بهر طرف که رخسارهایت متوجه میباشد. | ۱۶ 16 |
Ìwọ idà, jà sí ọ̀tún kí o sì jà sí òsì lọ ibikíbi tí ẹnu rẹ bá dojúkọ.
و من نیز دستهای خود را بهم خواهم زد و حدت خشم خویش را ساکن خواهم گردانید. من یهوه هستم که تکلم نمودهام.» | ۱۷ 17 |
Èmi gan an yóò pàtẹ́wọ́ ìbínú mi yóò sì rẹlẹ̀. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀.”
و کلام خداوند بر من نازل شده، گفت: | ۱۸ 18 |
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
«وتوای پسر انسان دو راه به جهت خود تعیین نما تاشمشیر پادشاه بابل از آنها بیاید. هر دوی آنها ازیک زمین بیرون میآید. و علامتی بر پا کن. آن رابر سر راه شهر بر پا نما. | ۱۹ 19 |
“Ọmọ ènìyàn la ọ̀nà méjì fún idà ọba Babeli láti gbà, kí méjèèjì bẹ̀rẹ̀ láti ìlú kan náà. Ṣe àmì sí ìkóríta ọ̀nà tí ó lọ sí ìlú náà.
راهی تعیین نما تاشمشیر به ربه بنی عمون و به یهودا در اورشلیم منیع بیاید. | ۲۰ 20 |
La ọ̀nà kan fún idà láti wá kọlu Rabba ti àwọn ará Ammoni kí òmíràn kọlu Juda, kí ó sì kọlu Jerusalẹmu ìlú olódi.
زیرا که پادشاه بابل بر شاهراه، بهسر دو راه ایستاده است تا تفال زند و تیرها را بهم زده، از ترافیم سوال میکند و به جگر مینگرد. | ۲۱ 21 |
Nítorí ọba Babeli yóò dúró ni ìyànà ní ojú ọ̀nà, ní ìkóríta, láti máa lo àfọ̀ṣẹ. Yóò fi ọfà di ìbò, yóò béèrè lọ́wọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀, òun yóò ṣe àyẹ̀wò ẹ̀dọ̀.
بهدست راستش تفال اورشلیم است تامنجنیقها بر پا کند و دهان را برای کشتار بگشایدو آواز را به گلبانگ بلند نماید و منجنیقها بردروازهها بر پا کند و سنگرها بسازد و برجها بنانماید. | ۲۲ 22 |
Nínú ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni ìbò Jerusalẹmu yóò ti wá, ní ibi tí yóò ti gbé afárá kalẹ̀, láti pàṣẹ fún àwọn apànìyàn, láti mú ki wọn hó ìhó ogun láti gbé òòlù dí ẹnu-ọ̀nà ibodè, láti mọ odi, àti láti kọ́ ilé ìṣọ́.
لیکن در نظر ایشان که قسم برای آنهاخوردهاند، تفال باطل مینماید. و او گناه ایشان رابه یاد میآورد تا گرفتار شوند.» | ۲۳ 23 |
Àfọ̀ṣẹ náà yóò dàbí àmì èké sí àwọn tí ó ti búra ìtẹríba fún un, ṣùgbọ́n òun yóò ran wọn létí ẹbí wọn yóò sì mú wọn lọ sí ìgbèkùn.
بنابراین خداوند یهوه چنین میگوید: «چونکه شما تقصیرهای خویش را منکشف ساخته و خطایای خود را در همه اعمال خویش ظاهر نموده، عصیان خود را یاد آورانیدید، پس چون به یاد آورده شدید دستگیر خواهید شد. | ۲۴ 24 |
“Nítorí náà èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí ti ẹ̀yin ti mú ẹ̀bi yín wá sí ìrántí nípa ìṣọ̀tẹ̀ ní gbangba, ní ṣíṣe àfihàn àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nínú gbogbo ohun tí ó ṣe, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí, a yóò mú yín ní ìgbèkùn.
و توای رئیس شریر اسرائیل که به زخم مهلک مجروح شدهای و اجل تو در زمان عقوبت آخررسیده است، | ۲۵ 25 |
“‘Ìwọ aláìmọ́ àti ẹni búburú ọmọ-aládé Israẹli, ẹni ti ọjọ́ rẹ̀ ti dé, ẹni tí àsìkò ìjìyà rẹ̀ ti dé góńgó,
خداوند یهوه چنین میگوید: عمامه را دور کن و تاج را بردار. چنین نخواهدماند. آنچه را که پست است بلند نما و آنچه را که بلند است پست کن. | ۲۶ 26 |
èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, tú ìwérí kúrò kí o sì gbé adé kúrò. Kò ní rí bí ti tẹ́lẹ̀, ẹni ìgbéga ni a yóò sì rẹ̀ sílẹ̀.
و من آن را سرنگون، سرنگون، سرنگون خواهم ساخت. و این دیگرواقع نخواهد شد تا آنکس بیاید که حق اومی باشد. و من آن را به وی عطا خواهم نمود. | ۲۷ 27 |
Ìparun! Ìparun! Èmi yóò ṣé e ni ìparun! Kì yóò padà bọ̀ sípò bí kò ṣe pé tí ó bá wá sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ni in; òun ni èmi yóò fi fún.’
«و توای پسر انسان نبوت کرده، بگو: خداوند یهوه درباره بنی عمون و سرزنش ایشان چنین میفرماید: بگو که شمشیر، شمشیر برای کشتار کشیده شده است و به غایت صیقلی گردیده تا براق بشود. | ۲۸ 28 |
“Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn: “‘Idà kan idà kan tí á fa yọ fún ìpànìyàn tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
چونکه برای تو رویای باطل دیدهاند و برای تو تفال دروغ زدهاند تا تو رابر گردنهای مقتولان شریر بگذارند که اجل ایشان در زمان عقوبت آخر رسیده است. | ۲۹ 29 |
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín a yóò gbé e lé àwọn ọrùn ènìyàn búburú ti a ó pa, àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé, àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.
لهذا آن رابه غلافش برگردان و بر تو در مکانی که آفریده شدهای و در زمینی که تولد یافتهای داوری خواهم نمود. | ۳۰ 30 |
“‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀. Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín, ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
و خشم خود را بر تو خواهم ریخت و آتش غیظ خود را بر تو خواهم دمید. وتو را بهدست مردان وحشی که برای هلاک نمودن چالاکند تسلیم خواهم نمود. | ۳۱ 31 |
Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín, èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná mi bá yín jà.
و تو برای آتش هیزم خواهی شد و خونت در آن زمین خواهدماند. پس به یاد آورده نخواهی شد زیرا من که یهوه هستم تکلم نمودهام.» | ۳۲ 32 |
Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà, a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín, a kì yóò rántí yín mọ́; nítorí Èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’”