< دوم سموئیل 7 >

و واقع شد چون پادشاه در خانه خود نشسته، و خداوند او را از جمیع دشمنانش از هر طرف آرامی داده بود، ۱ 1
Ó sì ṣe, nígbà tí ọba ń gbé ní ilé rẹ̀, tí Olúwa sì fún un ní ìsinmi yíkákiri kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀.
که پادشاه به ناتان نبی گفت: «الان مرا می‌بینی که در خانه سرو آزادساکن می‌باشم، و تابوت خدا در میان پرده‌ها ساکن است.» ۲ 2
Ọba sì wí fún Natani wòlíì pé, “Sá wò ó, èmi ń gbé inú ilẹ̀ tí a fi kedari kọ́, ṣùgbọ́n àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ń gbé inú ibi tí a fi aṣọ gé.”
ناتان به پادشاه گفت: «بیا و هر‌آنچه دردلت باشد معمول دار زیرا خداوند با توست.» ۳ 3
Natani sì wí fún ọba pé, “Lọ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn rẹ, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
و در آن شب واقع شد که کلام خداوند به ناتان نازل شده، گفت: ۴ 4
Ó sì ṣe ní òru náà, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Natani wá pé,
«برو و به بنده من داودبگو، خداوند چنین می‌گوید: آیا تو خانه‌ای برای سکونت من بنا می‌کنی؟ ۵ 5
“Lọ, sọ fún ìránṣẹ́ mi, fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ó ha kọ́ ilé fún mi tí èmi yóò gbé.
زیرا از روزی که بنی‌اسرائیل را از مصر بیرون آوردم تا امروز، درخانه‌ای ساکن نشده‌ام بلکه در خیمه و مسکن گردش کرده‌ام. ۶ 6
Nítorí pé, èmi kò ì ti gbé inú ilé kan láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ọmọ Israẹli gòkè ti ilẹ̀ Ejibiti wá, títí di òní yìí, ṣùgbọ́n èmi ti ń rìn nínú àgọ́, fún ibùgbé mi.
و به هر جایی که با جمیع بنی‌اسرائیل گردش کردم آیا به احدی از داوران اسرائیل که برای رعایت قوم خود، اسرائیل، مامور داشتم، سخنی گفتم که چرا خانه‌ای از سروآزاد برای من بنا نکردید؟ ۷ 7
Ní ibi gbogbo tí èmi ti ń rìn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ǹjẹ́ èmi ti bá ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli, tí èmi pa àṣẹ fún láti máa bọ́ àwọn ènìyàn mi àní Israẹli, sọ̀rọ̀ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi kedari kọ́ ilé fún mi.”’
و حال به بنده من، داود چنین بگو که یهوه صبایوت چنین می‌گوید: من تو را از چراگاه از عقب گوسفندان گرفتم تاپیشوای قوم من، اسرائیل، باشی. ۸ 8
“Ǹjẹ́, nítorí náà, báyìí ni ìwọ yóò sì wí fún ìránṣẹ́ mi àní Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, Èmi ti mú ìwọ kúrò láti inú agbo àgùntàn wá láti má tẹ̀lé àwọn àgùntàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli.
و هر جایی که می‌رفتی من با تو می‌بودم و جمیع دشمنانت را ازحضور تو منقطع ساختم، و برای تو اسم بزرگ مثل اسم بزرگانی که بر زمینند، پیدا کردم. ۹ 9
Èmi sì wà pẹ̀lú rẹ níbikíbi tí ìwọ ń lọ, èmi sá à gé gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kúrò níwájú rẹ, èmi sì ti sọ orúkọ rẹ di ńlá, gẹ́gẹ́ bí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá tí ó wà ní ayé.
و به جهت قوم خود، اسرائیل، مکانی تعیین کردم وایشان را غرس نمودم تا در مکان خویش ساکن شده، باز متحرک نشوند، و شریران، دیگر ایشان را مثل سابق ذلیل نسازند. ۱۰ 10
Èmi ó sì yan ibìkan fún àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi ó sì gbìn wọ́n, wọn ó sì má gbé bí ibùjókòó tiwọn, wọn kì yóò sì sípò padà mọ́; àwọn ọmọ ènìyàn búburú kì yóò sì pọ́n wọn lójúmọ́, bí ìgbà àtijọ́.
و مثل روزهایی که داوران را بر قوم خود، اسرائیل، تعیین نموده بودم و تو را از جمیع دشمنانت آرامی دادم، و خداوندتو را خبر می‌دهد که خداوند برای تو خانه‌ای بناخواهد نمود. ۱۱ 11
Àti gẹ́gẹ́ bí àkókò ìgbà tí èmi ti fi àṣẹ fún àwọn onídàájọ́ lórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi fi ìsinmi fún ọ lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ. “‘Olúwa sì wí fún ọ pé Olúwa yóò kọ ilé kan fún ọ.
زیرا روزهای تو تمام خواهدشد و با پدران خود خواهی خوابید و ذریت تو راکه از صلب تو بیرون آید، بعد از تو استوار خواهم ساخت، و سلطنت او را پایدار خواهم نمود. ۱۲ 12
Nígbà tí ọjọ́ rẹ bá pé, tí ìwọ ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ, èmi yóò sì gbé irú-ọmọ rẹ lékè lẹ́yìn rẹ, èyí tí ó ti inú rẹ jáde wá, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀.
او برای اسم من خانه‌ای بنا خواهد نمود وکرسی سلطنت او را تا به ابد پایدار خواهم ساخت. ۱۳ 13
Òun ó sì kọ́ ilé fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀ láéláé.
من او را پدر خواهم بود و او مرا پسرخواهد بود، و اگر او گناه ورزد، او را با عصای مردمان و به تازیانه های بنی آدم تادیب خواهم نمود. ۱۴ 14
Èmi ó máa ṣe baba fún un, òun yóò sì máa jẹ́ ọmọ mi. Bí òun bá dẹ́ṣẹ̀, èmi yóò sì fi ọ̀pá ènìyàn nà án, àti ìnà àwọn ọmọ ènìyàn.
ولیکن رحمت من از او دور نخواهد شد، به طوری که آن را از شاول دور کردم که او را ازحضور تو رد ساختم. ۱۵ 15
Ṣùgbọ́n àánú mi kì yóò yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú un kúrò lọ́dọ̀ Saulu, tí èmi ti mú kúrò níwájú rẹ.
و خانه و سلطنت تو، به حضورت تا به ابد پایدار خواهد شد، و کرسی توتا به ابد استوار خواهد ماند.» ۱۶ 16
A ó sì fi ìdílé rẹ àti ìjọba rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ títí láé, a ó sì fi ìdí ìtẹ́ rẹ múlẹ̀ títí láé.’”
بر‌حسب تمامی این کلمات و مطابق تمامی این‌رویا ناتان به داودتکلم نمود. ۱۷ 17
Gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, àti gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìran yìí, bẹ́ẹ̀ ni Natani sì sọ fún Dafidi.
و داود پادشاه داخل شده، به حضورخداوند نشست و گفت: «ای خداوند یهوه، من کیستم و خاندان من چیست که مرا به این مقام رسانیدی؟ ۱۸ 18
Dafidi ọba sì wọlé lọ, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, “Olúwa Olódùmarè, ta ni èmi, àti kí sì ni ìdílé mi, tí ìwọ fi mú mi di ìsinsin yìí?
و این نیز در نظر تو‌ای خداوند یهوه امر قلیل نمود زیرا که درباره خانه بنده ات نیزبرای زمان طویل تکلم فرمودی. و آیا این‌ای خداوند یهوه عادت بنی آدم است؟ ۱۹ 19
Nǹkan kékeré ni èyí sá à jásí lójú rẹ, Olúwa Olódùmarè; ìwọ sì ti sọ nípa ìdílé ìránṣẹ́ rẹ pẹ̀lú ní ti àkókò tí o jìnnà. Èyí ha ṣe ìwà ènìyàn bí, Olúwa Olódùmarè?
و داوددیگر به تو چه تواند گفت زیرا که تو‌ای خداوندیهوه، بنده خود را می‌شناسی، ۲۰ 20
“Àti kín ní ó tún kù tí Dafidi ìbá tún máa wí fún ọ? Ìwọ, Olúwa Olódùmarè mọ̀ ìránṣẹ́ rẹ.
و بر‌حسب کلام خود و موافق دل خود تمامی این کارهای عظیم را بجا آوردی تا بنده خود را تعلیم دهی. ۲۱ 21
Nítorí ọ̀rọ̀ rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ, ni ìwọ ṣe ṣe gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí, kí ìránṣẹ́ rẹ lè mọ̀.
بنابرین‌ای یهوه خدا، تو بزرگ هستی زیراچنانکه به گوشهای خود شنیده‌ایم مثل تو کسی نیست و غیر از تو خدایی نیست. ۲۲ 22
“Ìwọ sì tóbi, Olúwa Olódùmarè! Kò sì sí ẹni tí ó dàbí rẹ, kò sì sí Ọlọ́run kan lẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí àwa fi etí wá gbọ́.
و مثل قوم تواسرائیل کدام‌یک امت بر روی زمین است که خدابیاید تا ایشان را فدیه داده، برای خویش قوم بسازد، و اسمی برای خود پیدا نماید، و چیزهای عظیم و مهیب برای شما و برای زمین خود بجاآورد به حضور قوم خویش که برای خود از مصرو از امتها و خدایان ایشان فدیه دادی. ۲۳ 23
Orílẹ̀-èdè kan wo ni ó sì ń bẹ ní ayé tí ó dàbí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli, àwọn tí Ọlọ́run lọ rà padà láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ̀, àti láti sọ wọ́n ní orúkọ, àti láti ṣe nǹkan ńlá fún un yín, àti nǹkan ìyanu fún ilé rẹ̀, níwájú àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ ti rà padà fún ara rẹ láti Ejibiti wá, àní àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn òrìṣà wọn.
و قوم خود اسرائیل را برای خود استوار ساختی، تاایشان تا به ابد قوم تو باشند، و تو‌ای یهوه، خدای ایشان شدی. ۲۴ 24
Ìwọ sì fi ìdí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli kalẹ̀ fún ara rẹ láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ títí láé; ìwọ Olúwa sì wá di Ọlọ́run fún wọn.
و الان‌ای یهوه خدا، کلامی را که درباره بنده خود و خانه‌اش گفتی تا به ابد استوارکن، و بر‌حسب آنچه گفتی، عمل نما. ۲۵ 25
“Ǹjẹ́, Olúwa Ọlọ́run, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ náà tí ìwọ sọ ní ti ìránṣẹ́ rẹ, àti ní ti ìdílé rẹ̀, kí ó dúró títí láé, kí ó sí ṣe bí ìwọ ti wí.
و اسم توتا به ابد معظم بماند، تا گفته شود که یهوه صبایوت، خدای اسرائیل است، و خاندان بنده ات داود به حضور تو پایدار بماند. ۲۶ 26
Jẹ́ kí orúkọ rẹ ó ga títí láé, pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run lórí Israẹli!’ Sì jẹ́ kí a fi ìdílé Dafidi ìránṣẹ́ rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ.
زیرا توای یهوه صبایوت، خدای اسرائیل، به بنده خوداعلان نموده، گفتی که برای تو خانه‌ای بنا خواهم نموده، بنابرین بنده تو جرات کرده است که این دعا را نزد تو بگوید. ۲۷ 27
“Nítorí pé ìwọ, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli ti sọ létí ìránṣẹ́ rẹ, pé, ‘Èmí ó kọ́ ilé kan fún ọ.’ Nítorí náà ni ìránṣẹ́ rẹ sì ṣe ní i lọ́kàn rẹ̀ láti gbàdúrà yìí sí ọ.
و الان‌ای خداوند یهوه توخدا هستی و کلام تو صدق است و این نیکویی رابه بنده خود وعده داده‌ای. ۲۸ 28
Ǹjẹ́, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni Ọlọ́run náà, àwọn ọ̀rọ̀ rẹ sì jásí òtítọ́, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ nǹkan rere yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.
و الان احسان فرموده، خاندان بنده خود را برکت بده تا آنکه درحضورت تا به ابد بماند، زیرا که تو‌ای خداوندیهوه گفته‌ای و خاندان بنده ات از برکت تو تا به ابدمبارک خواهد بود.» ۲۹ 29
Ǹjẹ́, jẹ́ kí ó wù ọ́ láti bùkún ìdílé ìránṣẹ́ rẹ, kí ó wà títí láé níwájú rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa Olódùmarè, ni ó ti sọ ọ́: sì jẹ́ kí ìbùkún wà ní ìdílé ìránṣẹ́ rẹ títí láé, nípasẹ̀ ìbùkún rẹ.”

< دوم سموئیل 7 >