< دوم سموئیل 22 >

و داود در روزی که خداوند او را ازدست جمیع دشمنانش و از دست شاول رهایی داد، کلمات این سرود را برای خداوند انشا نمود. ۱ 1
Dafidi sì kọ ọ̀rọ̀ orin yìí sí Olúwa ní ọjọ́ tí Olúwa gbà á kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ Saulu.
و گفت: «خداوند صخره من و قلعه من و رهاننده من است. ۲ 2
Ó sì wí pé, “Olúwa ni àpáta mi, àti Olùgbàlà mi;
خدای صخره من که بر او توکل خواهم نمود، سپر من و شاخ نجاتم، برج بلند و ملجای من، ای نجات‌دهنده من، مرا از ظلم خواهی رهانید. ۳ 3
Ọlọ́run mi, àpáta mi, nínú ẹni tí èmi ní ààbò, àti ìwo ìgbàlà mi, ibi ìsádi gíga mi. Àti ibi ìlùmọ̀ mi, Olùgbàlà mi; ìwọ ni ó ti gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwà ipá.
خداوند را که سزاوار کل حمد است، خواهم خواند. پس از دشمنان خود خلاصی خواهم یافت. ۴ 4
“Èmi ké pe Olúwa, tí ó yẹ láti máa yìn, ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.
زیرا که موجهای موت مرا احاطه نموده، وسیلهای عصیان مرا ترسانیده بود. ۵ 5
Nígbà tí ìbìlù ìrora ikú yí mi káàkiri; tí àwọn ìṣàn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
رسنهای گور مرا احاطه نمودند. دامهای موت مرا دریافتند. (Sheol h7585) ۶ 6
Ọ̀já isà òkú yí mi káàkiri; ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí. (Sheol h7585)
در تنگی خود خداوند را خواندم. و نزد خدای خویش دعا نمودم. و او آواز مرا از هیکل خودشنید. و استغاثه من به گوش وی رسید. ۷ 7
“Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa, èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi. Ó sí gbóhùn mi láti tẹmpili rẹ̀ igbe mí wọ etí rẹ̀.
آنگاه زمین متزلزل و مرتعش گردید. واساسهای آسمان بلرزیدند. و از حدت خشم اومتحرک گردیدند. ۸ 8
Ilẹ̀ sì mì, ó sì wárìrì; ìpìlẹ̀ ọ̀run wárìrì, ó sì mì, nítorí tí ó bínú.
از بینی وی دود متصاعد شد. و از دهان او آتش سوزان درآمد و اخگرها از آن افروخته گردید. ۹ 9
Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá, iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá, ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
و او آسمانها را خم کرده، نزول فرمود. وتاریکی غلیظ زیر پایهایش بود. ۱۰ 10
Ó tẹ orí ọ̀run ba pẹ̀lú, ó sì sọ̀kalẹ̀; òkùnkùn biribiri sì ń bẹ ní àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
بر کروبین سوار شده، پرواز نمود. و بر بالهای باد نمایان گردید. ۱۱ 11
Ó sì gun orí kérúbù, ó sì fò, a sì rí i lórí ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
ظلمت را به اطراف خود سایبانها ساخت. واجتماع آبها و ابرهای متراکم افلاک را. ۱۲ 12
Ó sì fi òkùnkùn ṣe ibùjókòó yí ara rẹ̀, àti àgbájọ omi, àní ìṣúdudu ìkùùkuu àwọ̀ sánmọ̀.
از درخشندگی‌ای که پیش روی وی بود، اخگرهای آتش افروخته گردید. ۱۳ 13
Nípasẹ̀ ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀ ẹ̀yín iná ràn.
خداوند از آسمان رعد نمود. و حضرت اعلی آواز خویش را مسموع گردانید. ۱۴ 14
Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá, Ọ̀gá-ògo jùlọ sì fọhùn rẹ̀.
تیرها فرستاده، ایشان را پراکنده ساخت. و برق را جهانیده، ایشان را سراسیمه گردانید. ۱۵ 15
Ó sì ta ọfà, ó sì tú wọn ká; ó kọ mànàmànà, ó sì ṣẹ́ wọn.
پس عمق های دریا ظاهر شد. و اساسهای ربع مسکون منکشف گردید. از توبیخ خداوند و ازنفخه باد بینی وی. ۱۶ 16
Ìṣàn ibú òkun sì fi ara hàn, ìpìlẹ̀ ayé fi ara hàn, nípa ìbáwí Olúwa, nípa fífún èémí ihò imú rẹ̀.
از اعلی علیین فرستاده، مرا گرفت. و از آبهای بسیار مرا بیرون کشید. ۱۷ 17
“Ó ránṣẹ́ láti òkè wá, ó mú mi; ó fà mí jáde láti inú omi ńlá wá.
مرا از دشمنان زورآورم رهایی داد. و ازمبغضانم، چونکه از من قویتر بودند. ۱۸ 18
Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára, lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, nítorí pé wọ́n lágbára jù mí lọ.
در روز شقاوت من، ایشان مرا دریافته بودند. لیکن خداوند تکیه گاه من بود. ۱۹ 19
Wọ́n wá láti borí mi lọ́jọ́ ìpọ́njú mi, ṣùgbọ́n Olúwa ni aláfẹ̀yìntì mi.
مرا به مکان وسیع بیرون آورد. و مرا خلاصی داد چونکه به من رغبت می‌داشت. ۲۰ 20
Ó sì mú mi wá sí ààyè ńlá, ó gbà mi, nítorí tí inú rẹ̀ dún sí mi.
پس خداوند مرا به حسب عدالتم جزا خواهدداد. و به حسب پاکیزگی دستم مرا مکافات خواهد رسانید. ۲۱ 21
“Olúwa sán án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi; ó sì san án fún mi gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi.
زیرا که طریق های خداوند را حفظ نمودم. و ازخدای خویش عصیان نورزیدم. ۲۲ 22
Nítorí pé èmi pa ọ̀nà Olúwa mọ́, èmi kò sì fi ìwà búburú yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.
چونکه جمیع احکام او در مد نظر من است. واز فرایض او انحراف نورزیدم. ۲۳ 23
Nítorí pé gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ ni ó wà níwájú mi; àti ní ti òfin rẹ̀, èmi kò sì yapa kúrò nínú wọn.
و به حضور او کامل شدم. و از عصیان ورزیدن، خویشتن را بازداشتم. ۲۴ 24
Èmi sì wà nínú ìwà títọ́ sí í, èmi sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.
بنابراین خداوند مرا به حسب عدالتم جزا داد. و بر‌حسب صداقتی که در نظر وی داشتم. ۲۵ 25
Olúwa sì san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà mímọ́ mi níwájú rẹ̀.
با شخص رحیم، خویشتن را رحیم خواهی نمود. و با مرد کامل با کاملیت رفتار خواهی کرد. ۲۶ 26
“Fún aláàánú ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ni aláàánú, àti fún ẹni ìdúró ṣinṣin ní òdodo ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní ìdúró ṣinṣin ní òdodo.
با شخص طاهر به طهارت عمل خواهی نمود. و با کج خلقان مخالفت خواهی کرد. ۲۷ 27
Fún onínú funfun ni ìwọ fi ara rẹ hàn ní funfun; àti fún ẹni wíwọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní wíwọ́.
و قوم مستمند را نجات خواهی داد. اماچشمان تو بر متکبران است تا ایشان را پست گردانی. ۲۸ 28
Àwọn ènìyàn tí ó wà nínú ìyà ni ìwọ ó sì gbàlà; ṣùgbọ́n ojú rẹ wà lára àwọn agbéraga, láti rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
زیرا که تو‌ای خداوند، نور من هستی. وخداوند، تاریکی مرا به روشنایی مبدل خواهدساخت. ۲۹ 29
Nítorí ìwọ ni ìmọ́lẹ̀ mi, Olúwa; Olúwa yóò sì sọ òkùnkùn mi di ìmọ́lẹ̀.
زیرا که به استعانت تو بر لشکری تاخت آوردم. و به مدد خدای خود بر حصارها جست وخیز نمودم. ۳۰ 30
Bẹ́ẹ̀ ni nítorí nípa rẹ̀ ni èmi ti la àárín ogun kọjá; nípa Ọlọ́run mi èmi ti fo odi kan.
و اما خدا، طریق وی کامل است؛ و کلام خداوند مصفا؛ و او برای جمیع متوکلانش سپرمی باشد. ۳۱ 31
“Ọlọ́run yìí, pípé ni ọ̀nà rẹ̀; ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ti dánwò. Òun sì ni asà fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e.
زیرا کیست خدا غیر از یهوه؟ و کیست صخره غیر از خدای ما؟ ۳۲ 32
Nítorí ta ni Ọlọ́run, bí kò ṣe Olúwa? Ta ni àpáta, bí kò ṣe Ọlọ́run wa.
خدا قلعه استوار من است. و طریق مرا کامل می سازد. ۳۳ 33
Ọlọ́run alágbára ni ó fún mi ní agbára, ó sì sọ ọ̀nà mi di títọ́.
و پایهایم را مثل پای غزال می‌گرداند، و مرا برمکانهای بلندم برپا می‌دارد. ۳۴ 34
Ó ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín; ó sì mú mi dúró ní ibi gíga mi.
دستهای مرا به جنگ تعلیم می‌دهد، و به بازوی خود کمان برنجین را می‌کشم. ۳۵ 35
Ó kọ́ ọwọ́ mi ní ogun jíjà; tó bẹ́ẹ̀ tí apá mi fa ọrun idẹ.
و سپر نجات خود را به من خواهی داد، و لطف تو مرا بزرگ خواهد ساخت. ۳۶ 36
Ìwọ sì ti fún mi ní asà ìgbàlà rẹ̀; ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ sì ti sọ mí di ńlá.
قدمهای مرا در زیر من وسعت دادی که پایهایم نلغزید. ۳۷ 37
Ìwọ sì sọ ìtẹ̀lẹ̀ di ńlá ní abẹ́ mi; tó bẹ́ẹ̀ tí ẹsẹ̀ mi kò fi yọ̀.
دشمنان خود را تعاقب نموده، ایشان را هلاک خواهم ساخت، و تا نابود نشوند بر نخواهم گشت. ۳۸ 38
“Èmi ti lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì ti run wọ́n, èmi kò pẹ̀yìndà títí èmi fi run wọ́n.
ایشان را خراب کرده، خرد خواهم ساخت تادیگر برنخیزند، و زیر پایهایم خواهند افتاد. ۳۹ 39
Èmi ti pa wọ́n run, èmi sì ti fọ́ wọn, wọn kò sì le dìde mọ́, wọ́n ṣubú lábẹ́ mi.
زیرا کمر مرا برای جنگ به قوت خواهی بست، و آنانی را که به ضد من برخیزند در زیر من خم خواهی ساخت. ۴۰ 40
Ìwọ sì ti fi agbára dì mí ní àmùrè fún ìjà; àwọn tí ó ti dìde sí mi ni ìwọ sì ti tẹ̀ lórí ba fún mi.
و دشمنانم را پیش من منهزم خواهی کرد تاخصمان خود را منقطع سازم. ۴۱ 41
Ìwọ sì mú àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà fún mi, èmi ó sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
فریاد برمی آورند، اما رهاننده‌ای نیست؛ و به سوی خداوند، لیکن ایشان را اجابت نخواهدکرد. ۴۲ 42
Wọ́n wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti gbà wọ́n; wọ́n wo Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá àwọn lóhùn.
پس ایشان را مثل غبار زمین نرم می‌کنم. و مثل گل کوچه‌ها کوبیده، پایمال می‌سازم. ۴۳ 43
Nígbà náà ni èmi sì gún wọn wẹ́wẹ́ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, èmi sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ ìta, èmi sì tẹ́ wọn gbọrọ.
و تو مرا از مخاصمات قوم من خواهی رهانید، و مرا برای سرداری امت‌ها حفظ خواهی کرد، وقومی را که نشناخته بودم، مرا بندگی خواهندنمود. ۴۴ 44
“Ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìjà àwọn ènìyàn mi, ìwọ pa mi mọ́ ki èmi lè ṣe olórí àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè. Àwọn ènìyàn tí èmi kò tí mọ̀ yóò máa sìn mí.
غریبان نزد من تذلل خواهند کرد و به مجردشنیدن من، مرا اطاعت خواهند نمود. ۴۵ 45
Àwọn àjèjì wá láti tẹríba fún mi; bí wọ́n bá ti gbúròó mi, wọ́n á sì gbọ́ tèmi.
غریبان پژمرده خواهند گردید و از مکان های مخفی خود با ترس بیرون خواهند آمد. ۴۶ 46
Àyà yóò pá àwọn àlejò, wọ́n ó sì fi ìbẹ̀rù sá kúrò níbi kọ́lọ́fín wọn.
خداوند زنده است و صخره من متبارک وخدای صخره نجات من متعال باد. ۴۷ 47
“Olúwa ń bẹ́; olùbùkún sì ni àpáta mi! Gbígbéga sì ni Ọlọ́run àpáta ìgbàlà mi.
‌ای خدایی که برای من انتقام می‌کشی و قومهارا زیر من پست می‌سازی. ۴۸ 48
Ọlọ́run ni ẹni tí ń gbẹ̀san mi, àti ẹni tí ń rẹ àwọn ènìyàn sílẹ̀ lábẹ́ mi.
و مرا از دست دشمنانم بیرون می‌آوری و برمقاومت کنندگانم مرا بلند می‌گردانی. تو مرا ازمرد ظالم خلاصی خواهی داد. ۴۹ 49
Àti ẹni tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi. Ìwọ sì gbé mi sókè ju àwọn tí ó kórìíra mi lọ; ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin oníwà ipá.
بنابراین‌ای خداوند، تو را در میان امت‌ها حمدخواهم گفت. و به نام تو ترنم خواهم نمود. ۵۰ 50
Nítorí náà èmi ó fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa, láàrín àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè, èmi ó sì kọrin sí orúkọ rẹ.
نجات عظیمی برای پادشاه خود می‌نماید. وبرای مسیح خویش رحمت را پدید می‌آورد. به جهت داود و ذریت وی تا ابدالاباد.» ۵۱ 51
“Òun ni ilé ìṣọ́ ìgbàlà fún ọba rẹ̀; ó sì fi àánú hàn fún ẹni àmì òróró rẹ̀, fún Dafidi, àti fún irú-ọmọ rẹ̀ títí láéláé.”

< دوم سموئیل 22 >