< دوم سموئیل 20 >

و اتفاق مرد بلیعال، مسمی به شبع بن بکری بنیامینی در آنجا بود و کرنا رانواخته، گفت که «ما را در داود حصه‌ای نیست، وبرای ما در پسر یسا نصیبی نی، ای اسرائیل! هرکس به خیمه خود برود.» ۱ 1
Ọkùnrin Beliali kan sì ń bẹ níbẹ̀ orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣeba ọmọ Bikri ará Benjamini; ó sì fún ìpè ó sì wí pé, “Àwa kò ní ipa nínú Dafidi, bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ni ìní nínú ọmọ Jese! Kí olúkúlùkù ọkùnrin lọ sí àgọ́ rẹ̀, ẹ̀yin Israẹli!”
و تمامی مردان اسرائیل از متابعت داود به متابعت شبع ابن بکری برگشتند، اما مردان یهودا از اردن تا اورشلیم، پادشاه را ملازمت نمودند. ۲ 2
Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì lọ kúrò lẹ́yìn Dafidi, wọ́n sì ń tọ́ Ṣeba ọmọ Bikri lẹ́yìn, ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Juda sì fi ara mọ́ ọba wọn láti odò Jordani wá títí ó fi dé Jerusalẹmu.
و داود به خانه خود در اورشلیم آمد، وپادشاه ده زن متعه را که برای نگاهبانی خانه خودگذاشته بود، گرفت و ایشان را در خانه محروس نگاه داشته، پرورش داد، اما نزد ایشان داخل نشدو ایشان تا روز مردن در حالت بیوگی محبوس بودند. ۳ 3
Dafidi sì wà ní ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu; ọba sì mú àwọn obìnrin mẹ́wàá tí í ṣe àlè rẹ̀, àwọn tí ó ti fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, Ó sì há wọn mọ́ ilé, ó sì ń bọ́ wọn, ṣùgbọ́n kò sì tún wọlé tọ̀ wọ́n mọ́. A sì sé wọn mọ́ títí di ọjọ́ ikú wọn, wọ́n sì wà bí opó.
و پادشاه به عماسا گفت: «مردان یهودا را درسه روز نزد من جمع کن و تو در اینجا حاضر شو.» ۴ 4
Ọba sì wí fún Amasa pé, “Pe àwọn ọkùnrin Juda fún mi ní ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta òní, kí ìwọ náà kí o sì wà níhìn-ín yìí.”
پس عماسا رفت تا یهودا را جمع کند، اما اززمانی که برایش تعیین نموده بود تاخیر کرد. ۵ 5
Amasa sì lọ láti pe àwọn ọkùnrin Juda; ṣùgbọ́n ó sì dúró pẹ́ ju àkókò tí a fi fún un.
وداود به ابیشای گفت: «الان شبع بن بکری بیشتر ازابشالوم به ما ضرر خواهد رسانید؛ پس بندگان آقایت را برداشته، او را تعاقب نما مبادا شهرهای حصاردار برای خود پیدا کند و از نظر ما رهایی یابد.» ۶ 6
Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Nísinsin yìí Ṣeba ọmọ Bikri yóò ṣe wá ní ibi ju ti Absalomu lọ; ìwọ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ, kí o sì lépa rẹ̀, kí ó má ba à rí ìlú olódi wọ̀, kí ó sì bọ́ lọ́wọ́ wa.”
و کسان یوآب و کریتیان و فلیتیان و جمیع شجاعان از عقب او بیرون رفتند، و به جهت تعاقب نمودن شبع بن بکری از اورشلیم روانه شدند. ۷ 7
Àwọn ọmọkùnrin Joabu sì jáde tọ̀ ọ́ lọ, àti àwọn Kereti, àti àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ọkùnrin alágbára, wọ́n sì ti Jerusalẹmu jáde lọ, láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
و چون ایشان نزد سنگ بزرگی که درجبعون است رسیدند، عماسا به استقبال ایشان آمد. و یوآب ردای جنگی دربرداشت و بر آن بندشمشیری که در غلافش بود، بر کمرش بسته، و چون می‌رفت شمشیر از غلاف افتاد. ۸ 8
Nígbà tí wọ́n dé ibi òkúta ńlá tí ó wà ní Gibeoni, Amasa sì ṣáájú wọn, Joabu sì di àmùrè sí agbádá rẹ̀ tí ó wọ̀, ó sì sán idà rẹ̀ mọ́ ìdí, nínú àkọ̀ rẹ̀, bí ó sì ti ń lọ, ó yọ́ jáde.
و یوآب به عماسا گفت: «ای برادرم آیا به سلامت هستی؟» ویوآب ریش عماسا را به‌دست راست خود گرفت تا او را ببوسد. ۹ 9
Joabu sì bi Amasa léèrè pé, “Àlàáfíà ha kọ́ ni bí, ìwọ arákùnrin mi?” Joabu sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, di Amasa ní irùngbọ̀n mú láti fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
و عماسا به شمشیری که دردست یوآب بود، اعتنا ننمود. پس او آن را به شکمش فرو برد که احشایش به زمین ریخت و اورا دوباره نزد و مرد. ۱۰ 10
Ṣùgbọ́n Amasa kò sì kíyèsi idà tí ń bẹ lọ́wọ́ Joabu, bẹ́ẹ̀ ni òun sì fi gún un ní ikùn, ìfun rẹ̀ sì tú dà sílẹ̀, òun kò sì tún gún un mọ́, Amasa sì kú. Joabu àti Abiṣai arákùnrin rẹ̀ sì lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
و یکی از خادمان یوآب نزدوی ایستاده، گفت: «هرکه یوآب را می‌خواهد وهرکه به طرف داود است، در عقب یوآب بیاید.» ۱۱ 11
Ọ̀kan nínú àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Joabu sì dúró tì Amasa, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni tí ó fẹ́ràn Joabu? Ta ni ó sì ń ṣe ti Dafidi, kí ó máa tọ Joabu lẹ́yìn.”
و عماسا در میان راه در خونش می‌غلطید، وچون آن شخص دید که تمامی قوم می‌ایستند، عماسا را از میان راه در صحرا کشید و لباسی بر اوانداخت زیرا دید که هر‌که نزدش می‌آید، می‌ایستد. ۱۲ 12
Amasa sì ń yíràá nínú ẹ̀jẹ̀ láàrín ọ̀nà. Ọkùnrin náà sì rí i pé gbogbo ènìyàn sì dúró tì í, ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà lọ sínú igbó, ó sì fi aṣọ bò ó, nígbà tí ó rí i pé ẹnikẹ́ni tí ó bá dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, á dúró.
پس چون از میان راه برداشته شد، جمیع مردان در عقب یوآب رفتند تا شبع بن بکری را تعاقب نمایند. ۱۳ 13
Nígbà tí ó sì gbé Amasa kúrò lójú ọ̀nà gbogbo ènìyàn sì tọ Joabu lẹ́yìn láti lépa Ṣeba ọmọ Bikri.
و او از جمیع اسباط اسرائیل تا آبل و تا بیت معکه و تمامی بیریان عبور کرد، و ایشان نیز جمع شده، او را متابعت کردند. ۱۴ 14
Ṣeba kọjá nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli sí Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo àwọn ará Beri; wọ́n sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn pẹ̀lú.
و ایشان آمده، او رادر آبل بیت معکه محاصره نمودند و پشته‌ای دربرابر شهر ساختند که در برابر حصار برپا شد، وتمامی قوم که با یوآب بودند، حصار را می‌زدند تاآن را منهدم سازند. ۱۵ 15
Wọ́n wá, wọ́n sì dó tì Ṣeba ní Abeli-Beti-Maaka, wọ́n sì mọ odi ti ìlú náà, odi náà sì dúró ti odi ìlú náà, gbogbo ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ Joabu sì ń gbìyànjú láti wó ògiri náà lulẹ̀.
و زنی حکیم از شهر صدادرداد که بشنوید: «به یوآب بگویید: اینجا نزدیک بیا تا با تو سخن گویم.» ۱۶ 16
Obìnrin ọlọ́gbọ́n kan sì kígbe sókè láti ìlú náà wá pé, “Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀! Èmi bẹ̀ yín, ẹ sọ fún Joabu pé, ‘Súnmọ́ ìhín yìí èmi ó sì bá a sọ̀rọ̀.’”
و چون نزدیک وی شد، زن گفت که «آیا تو یوآب هستی؟» او گفت: «من هستم.» وی را گفت: «سخنان کنیز خود را بشنو.» او گفت: «می‌شنوم.» ۱۷ 17
Nígbà tí òun sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, obìnrin náà sì wí pé, “Ìwọ ni Joabu bí?” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi náà ni.” Obìnrin náà sì wí fún un pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.” Òun sì dáhùn wí pé, “Èmi ń gbọ́.”
پس زن متکلم شده، گفت: «در زمان قدیم چنین می‌گفتند که هرآینه درآبل می‌باید مشورت بجویند و همچنین هر امری را ختم می‌کردند. ۱۸ 18
Ó sì sọ̀rọ̀ wí pé, “Wọ́n ti ń wí ṣáájú pé, ‘Gba ìdáhùn rẹ ní Abeli,’ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì parí ọ̀ràn náà.
من در اسرائیل سالم و امین هستم و تو می‌خواهی شهری و مادری را دراسرائیل خراب کنی، چرا نصیب خداوند را بالکل هلاک می‌کنی؟» ۱۹ 19
Èmi ni ọ̀kan nínú àwọn ẹni àlàáfíà àti olóòtítọ́ ní Israẹli, ìwọ ń wá ọ̀nà láti pa ìlú kan run tí ó jẹ́ ìyá ní Israẹli, èéṣe tí ìwọ ó fi gbé ìní Olúwa mì.”
پس یوآب در جواب گفت: «حاشا از من حاشا از من! که هلاک یا خراب نمایم. ۲۰ 20
Joabu sì dáhùn wí pé, “Kí a má rí i, kí a má rí i lọ́dọ̀ mi pé èmi gbé mì tàbí èmi sì parun.
کار چنین نیست بلکه شخصی مسمی به شبع بن بکری از کوهستان افرایم دست خود را برداود پادشاه بلند کرده است. او را تنها بسپارید واز نزد شهر خواهم رفت.» زن در جواب یوآب گفت: «اینک سر او را از روی حصار نزد توخواهند انداخت.» ۲۱ 21
Ọ̀ràn náà kò sì rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ọkùnrin kan láti òkè Efraimu, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ṣeba, ọmọ Bikri, ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí ọba, àní sí Dafidi: fi òun nìkan ṣoṣo lé wa lọ́wọ́, èmi ó sì fi ìlú sílẹ̀.” Obìnrin náà sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, orí rẹ̀ ni a ó sì sọ láti inú odi wá.”
پس آن زن به حکمت خودنزد تمامی قوم رفت و ایشان سر شبع بن بکری رااز تن جدا کرده، نزد یوآب انداختند و او کرنا رانواخته، ایشان از نزد شهر، هر کس به خیمه خودمتفرق شدند. و یوآب به اورشلیم نزد پادشاه برگشت. ۲۲ 22
Obìnrin náà sì mú ìmọ́ràn rẹ̀ tọ gbogbo àwọn ènìyàn náà, wọ́n sì bẹ Ṣeba ọmọ Bikri lórí, wọ́n sì sọ ọ́ sí Joabu. Òun sì fún ìpè, wọ́n sì túká ní ìlú náà, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀. Joabu sí padà lọ sí Jerusalẹmu àti sọ́dọ̀ ọba.
و یوآب، سردار تمامی لشکر اسرائیل بود، و بنایاهو ابن یهویاداع سردار کریتیان و فلیتیان بود. ۲۳ 23
Joabu sì ni olórí gbogbo ogun Israẹli; Benaiah ọmọ Jehoiada sì jẹ́ olórí àwọn Kereti, àti ti àwọn Peleti.
و ادورام سردار باجگیران و یهوشافاط بن اخیلود وقایع نگار، ۲۴ 24
Adoniramu sì jẹ́ olórí àwọn agbowó òde; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi sì jẹ́ olùkọsílẹ̀ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ ní ìlú.
و شیوا کاتب و صادوق وابیاتار، کاهن بودند، ۲۵ 25
Ṣefa sì jẹ́ akọ̀wé; Sadoku àti Abiatari sì ni àwọn àlùfáà.
و عیرای یائیری نیز کاهن داود بود. ۲۶ 26
Ira pẹ̀lú, ará Jairi ni ń ṣe àlùfáà lọ́dọ̀ Dafidi.

< دوم سموئیل 20 >