< دوم تواریخ 34 >

یوشیا هشت ساله بود که پادشاه شد ودر اورشلیم سی و یکسال سلطنت نمود. ۱ 1
Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
و آنچه در نظر خداوند پسند بود، به عمل آورد و به طریق های پدر خود داود سلوک نموده، به طرف راست یا چپ انحراف نورزید. ۲ 2
Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
و درسال هشتم سلطنت خود، حینی که هنوز جوان بود، به طلبیدن خدای پدر خود داود شروع کرد ودر سال دوازدهم به طاهر ساختن یهودا واورشلیم از مکان های بلند و اشیره‌ها و تمثالها وبتها آغاز نمود. ۳ 3
Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
و مذبح های بعلیم را به حضوروی منهدم ساختند، و تماثیل شمس را که بر آنهابود قطع نمود، و اشیره‌ها و تمثالها و بتهای ریخته شده را شکست، و آنها را خرد کرده، برروی قبرهای آنانی که برای آنها قربانی می‌گذرانیدند، پاشید. ۴ 4
Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
و استخوانهای کاهنان رابر مذبح های خودشان سوزانید. پس یهودا واورشلیم را طاهر نمود. ۵ 5
Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
و در شهرهای منسی وافرایم و شمعون حتی نفتالی نیز در خرابه هایی که به هر طرف آنها بود (همچنین کرد). ۶ 6
Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
و مذبح هارا منهدم ساخت و اشیره‌ها و تمثالها را کوبیده، نرم کرد و همه تمثالهای شمس را در تمامی زمین اسرائیل قطع نموده، به اورشلیم مراجعت کرد. ۷ 7
Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
و در سال هجدهم سلطنت خود، بعد از آنکه زمین و خانه را طاهر ساخته بود، شافان بن اصلیا ومعسیا رئیس شهر و یوآخ بن یوآحاز وقایع نگاررا برای تعمیر خانه یهوه خدای خود فرستاد. ۸ 8
Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
ونزد حلقیای رئیس کهنه آمدند و نقره‌ای را که به خانه خدا درآورده شده، و لاویان مستحفظان آستانه، آن را از دست منسی و افرایم و تمامی بقیه اسرائیل و تمامی یهودا و بنیامین و ساکنان اورشلیم جمع کرده بودند، به او تسلیم نمودند. ۹ 9
Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
و آن را به‌دست سرکارانی که بر خانه خداوندگماشته شده بودند، سپردند تا آن را به عمله هایی که در خانه خداوند کار می‌کردند، به جهت اصلاح و تعمیر خانه بدهند. ۱۰ 10
Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
پس آن را به نجاران و بنایان دادند تا سنگهای تراشیده وچوب به جهت اردیها و تیرها برای خانه هایی که پادشاهان یهودا آنها را خراب کرده بودند، بخرند. ۱۱ 11
Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
و آن مردان، کار را به امانت بجا می‌آوردند، وسرکاران ایشان که نظارت می‌کردند، یحت وعوبدیای لاویان از بنی مراری و زکریا و مشلام ازبنی قهاتیان بودند، و نیز از لاویان هر‌که به آلات موسیقی ماهر بود. ۱۲ 12
Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
و ایشان ناظران حمالان ووکلاء بر همه آنانی که در هر گونه‌ای خدمت، اشتغال داشتند بودند، و از لاویان کاتبان وسرداران و دربانان بودند. ۱۳ 13
Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
و چون نقره‌ای را که به خانه خداوند آورده شده بود، بیرون می‌بردند، حلقیای کاهن، کتاب تورات خداوند را که به واسطه موسی (نازل شده )بود پیدا کرد. ۱۴ 14
Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
و حلقیا شافان کاتب را خطاب کرده، گفت: «کتاب تورات را در خانه خداوندیافته‌ام.» و حلقیا آن کتاب را به شافان داد. ۱۵ 15
Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
وشافان آن کتاب را نزد پادشاه برد و نیز به پادشاه خبر رسانیده، گفت: «هر‌آنچه به‌دست بندگانت سپرده شده است آن را بجا می‌آورند.» ۱۶ 16
Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
ونقره‌ای را که در خانه خداوند یافت شد، بیرون آوردند و آن را به‌دست سرکاران و به‌دست عمله‌ها دادند. ۱۷ 17
Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
و شافان کاتب پادشاه را خبرداده، گفت: «حلقیای کاهن کتابی به من داده است.» پس شافان آن را به حضور پادشاه خواند. ۱۸ 18
Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
و چون پادشاه سخنان تورات را شنید، لباس خود را درید. ۱۹ 19
Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
و پادشاه، حلقیای کاهن واخیقام بن شافان و عبدون بن میکا و شافان کاتب وعسایا خادم پادشاه را امر فرموده، گفت: ۲۰ 20
Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
«بروید و از خداوند برای من و برای بقیه اسرائیل و یهودا درباره سخنانی که در این کتاب یافت می‌شود، مسئلت نمایید زیرا غضب خداوند که بر ما ریخته شده است، عظیم می‌باشدچونکه پدران ما کلام خداوند را نگاه نداشتند و به هر‌آنچه در این کتاب مکتوب است عمل ننمودند.» ۲۱ 21
“Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
پس حلقیا و آنانی که پادشاه ایشان را امر فرمود، نزد حلده نبیه زن شلوم بن توقهه بن حسره لباس دار رفتند، و او در محله دوم اورشلیم ساکن بود و او را بدین مضمون سخن‌گفتند. ۲۲ 22
Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
واو به ایشان گفت: «یهوه خدای اسرائیل چنین می‌فرماید: به کسی‌که شما را نزد من فرستاده است بگویید: ۲۳ 23
Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
خداوند چنین می‌فرماید: اینک من بلایی بر این مکان و ساکنانش خواهم رسانید، یعنی همه لعنتهایی که در این کتاب که آن را به حضور پادشاه یهودا خواندند، مکتوب است. ۲۴ 24
‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
چونکه مرا ترک کرده، برای خدایان دیگربخور‌سوزانیدند تا به تمامی اعمال دستهای خودخشم مرا به هیجان بیاورند، پس غضب من بر این مکان افروخته شده، خاموشی نخواهد پذیرفت. ۲۵ 25
Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
لیکن به پادشاه یهودا که شما را به جهت مسئلت نمودن از خداوند فرستاده است، بگویید: یهوه خدای اسرائیل چنین می‌فرماید: درباره سخنانی که شنیده‌ای، ۲۶ 26
Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
چونکه دل تو نرم بود وهنگامی که کلام خداوند را درباره این مکان وساکنانش شنیدی، در حضور وی تواضع نمودی و به حضور من متواضع شده، لباس خود رادریدی و به حضور من گریستی، بنابراین خداوندمی گوید: من نیز تو را اجابت فرمودم. ۲۷ 27
Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
اینک من تو را نزد پدرانت جمع خواهم کرد و در قبر خودبه سلامتی گذارده خواهی شد، و چشمان توتمامی بلا را که من بر این مکان و ساکنانش می رسانم نخواهد دید.» پس ایشان نزد پادشاه جواب آوردند. ۲۸ 28
Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
و پادشاه فرستاد که تمامی مشایخ یهودا واورشلیم را جمع کردند. ۲۹ 29
Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
و پادشاه و تمامی مردان یهودا و ساکنان اورشلیم و کاهنان و لاویان و تمامی قوم، چه کوچک و چه بزرگ، به خانه خداوند برآمدند و او همه سخنان کتاب عهدی راکه در خانه خداوند یافت شد، در گوش ایشان خواند. ۳۰ 30
Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
و پادشاه بر منبر خود ایستاد و به حضور خداوند عهد بست که خداوند را پیروی نموده، اوامر و شهادات و فرایض او را به تمامی دل و تمامی جان نگاه دارند و سخنان این عهد راکه در این کتاب مکتوب است، بجا آورند. ۳۱ 31
Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
وهمه آنانی را که در اورشلیم و بنیامین حاضربودند، بر این متمکن ساخت و ساکنان اورشلیم، برحسب عهد خدا یعنی خدای پدران خود، عمل نمودند. ۳۲ 32
Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
و یوشیا همه رجاسات را ازتمامی زمینهایی که از آن بنی‌اسرائیل بودبرداشت، و همه کسانی را که در اسرائیل یافت شدند، تحریض نمود که یهوه خدای خود راعبادت نمایند و ایشان در تمامی ایام او از متابعت یهوه خدای پدران خود انحراف نورزیدند. ۳۳ 33
Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.

< دوم تواریخ 34 >