< اول سموئیل 6 >

و تابوت خداوند در ولایت فلسطینیان هفت ماه ماند. ۱ 1
Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa sì ti wà ní agbègbè Filistini fún oṣù méje,
و فلسطینیان، کاهنان وفالگیران خود را خوانده، گفتند: «با تابوت خداوند چه کنیم؟ ما را اعلام نمایید که آن را به‌جایش با چه چیز بفرستیم.» ۲ 2
àwọn ará Filistini pe àwọn àlùfáà, àti àwọn alásọtẹ́lẹ̀, wọ́n sì sọ pé, “Kí ni kí a ṣe pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa? Sọ fún wa bí àwa yóò ti dá a padà sí ààyè rẹ̀.”
گفتند: «اگر تابوت خدای اسرائیل را بفرستید آن را خالی مفرستید، بلکه قربانی جرم البته برای او بفرستید، آنگاه شفاخواهید یافت، و بر شما معلوم خواهد شد که ازچه سبب دست او از شما برداشته نشده است.» ۳ 3
Wọ́n dáhùn wí pé, “Tí ẹ bá dá àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ti àwọn ọmọ Israẹli padà, ẹ má ṣe dá a padà ní òfìfo, ṣùgbọ́n bí ó ti wù kí ó rí, ẹ fún un ní ẹbọ ẹ̀bi. Nígbà náà ni a ó mú un yín láradá, ẹ̀yin yóò sì mọ ìdí tí ọwọ́ rẹ̀ kò fi tí ì kúrò lára yín.”
ایشان گفتند: «چه قربانی جرم برای اوبفرستیم؟» ۴ 4
Àwọn ará Filistini béèrè pé, “Irú ẹbọ ẹ̀bi wo ni kí a fi fún un?” Wọ́n dáhùn, “Wúrà oníkókó márùn-ún àti eku ẹ̀lírí wúrà márùn-ún, gẹ́gẹ́ bí iye àwọn aláṣẹ Filistini, nítorí àjàkálẹ̀-ààrùn kan náà ni ó kọlù yín àti olórí yín.
پس تماثیل خراجهای خود و تماثیل موشهای خود را که زمین را خراب می‌کنند بسازید، وخدای اسرائیل را جلال دهید که شاید دست خود را از شما و از خدایان شما و از زمین شمابردارد. ۵ 5
Mọ àwòrán ààrùn oníkókó àti ti eku ẹ̀lírí yin tí ó ń ba orílẹ̀-èdè náà jẹ́ kí o sì bu ọlá fún Ọlọ́run Israẹli. Bóyá yóò gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lára yín, lára ọlọ́run yín àti lára ilẹ̀ yín.
و چرا دل خود را سخت سازید، چنانکه مصریان و فرعون دل خود را سخت ساختند؟ آیابعد از آنکه در میان ایشان کارهای عجیب کرده بود ایشان را رها نکردند که رفتند؟ ۶ 6
Kí ni ó dé tí ẹ fi ń sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí àwọn ará Ejibiti àti Farao ti ṣe? Nígbà tí ó fi ọwọ́ líle mú wọn, ṣé wọn kò rán àwọn ọmọ Israẹli jáde kí wọn kí ó lè lọ ní ọ̀nà wọn?
پس الان ارابه تازه بسازید و دو گاو شیرده را که یوغ برگردن ایشان نهاده نشده باشد بگیرید، و دو گاو رابه ارابه ببندید و گوساله های آنها را از عقب آنها به خانه برگردانید. ۷ 7
“Nísinsin yìí ẹ pèsè kẹ̀kẹ́ ẹrù tuntun sílẹ̀, pẹ̀lú màlúù méjì tí ó ti fi ọmú fún ọmọ, èyí tí a kò tí ì gba àjàgà sí ọrùn rí, kí ẹ sì so ó mọ́ kẹ̀kẹ́ náà, kí ẹ sì mú ọmọ wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn wá sí ilé láti so.
و تابوت خداوند را گرفته، آن رابر ارابه بنهید و اسباب طلا را که به جهت قربانی جرم برای او می‌فرستید در صندوقچه‌ای به پهلوی آن بگذارید، و آن را رها کنید تا برود. ۸ 8
Kí ẹ sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa sí orí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kí ẹ̀yin sì kó àwọn ohun èlò wúrà tí ẹ̀yin fi fún un gẹ́gẹ́ bí ti ẹbọ ẹ̀bi sí inú àpótí ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, kí ẹ̀yin kí ó sì rán an lọ,
ونظر کنید اگر به راه سرحد خود به سوی بیت شمس برود، بدانید اوست که این بلای عظیم را بر ما وارد گردانیده است، و اگرنه، پس خواهیددانست که دست او ما را لمس نکرده است، بلکه آنچه بر ما واقع شده است، اتفاقی است.» ۹ 9
ṣùgbọ́n kí ẹ sì máa ṣọ́ ọ. Tí ó bá ń lọ sí ilẹ̀ rẹ̀, ìlú rẹ̀, níhà Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà ni Olúwa mú àjálù ńlá yìí bá wa. Ṣùgbọ́n bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà náà ni a mọ̀ pé kì í ṣe ọwọ́ rẹ̀ ni ó kọlù wá, ṣùgbọ́n ó wá bẹ́ẹ̀ ni.”
پس آن مردمان چنین کردند و دو گاوشیرده را گرفته، آنها را به ارابه بستند، وگوساله های آنها را در خانه نگاه داشتند. ۱۰ 10
Nígbà náà ni wọ́n ṣe èyí. Wọ́n mú abo màlúù méjì, tí ń fi ọmú fún ọmọ, wọn mọ́ ara, wọ́n sì dè é ni ilé kẹ̀kẹ́ ẹrù, wọn sì so àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀ ni ilé.
و تابوت خداوند و صندوقچه را با موشهای طلا وتماثیل خراجهای خود بر ارابه گذاشتند. ۱۱ 11
Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé orí kẹ̀kẹ́ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni àpótí tí eku ẹ̀lírí wúrà àti àwòrán ààrùn oníkókó wà níbẹ̀.
وگاوان راه خود را راست گرفته، به راه بیت شمس روانه شدند و به شاهراه رفته، بانگ می‌زدند و به سوی چپ یا راست میل نمی نمودند، و سروران فلسطینیان در عقب آنها تا حد بیت شمس رفتند. ۱۲ 12
Nígbà náà; àwọn màlúù lọ tààrà sí ìhà Beti-Ṣemeṣi, wọ́n ń lọ tààrà, wọ́n sì ń dún bí wọ́n ti ń lọ. Wọn kò yà sí ọ̀tún tàbí yà sí òsì. Àwọn aláṣẹ Filistini tẹ̀lé wọn títí dé ibodè Beti-Ṣemeṣi.
و اهل بیت شمس در دره گندم را درومی کردند، و چشمان خود را بلند کرده، تابوت رادیدند و از دیدنش خوشحال شدند. ۱۳ 13
Nísinsin yìí, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi ń kórè jéró wọn ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, nígbà tí wọ́n wo òkè tí wọ́n sì rí àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n yọ̀ níwájú rẹ̀.
و ارابه به مزرعه یهوشع بیت شمسی درآمده، در آنجابایستاد و سنگ بزرگی در آنجا بود. پس چوب ارابه را شکسته، گاوان را برای قربانی سوختنی به جهت خداوند گذرانیدند. ۱۴ 14
Kẹ̀kẹ́ ẹrù wá sí pápá Joṣua ti Beti-Ṣemeṣi, níbẹ̀ ni ó ti dúró ní ẹ̀bá àpáta ńlá kan. Àwọn ènìyàn gé igi ara kẹ̀kẹ́ ẹrù sí wẹ́wẹ́ wọ́n sì fi àwọn màlúù náà rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
و لاویان تابوت خداوند و صندوقچه‌ای را که با آن بود و اسباب طلا داشت، پایین آورده، آنها را بر آن سنگ بزرگ نهادند و مردان بیت شمس در همان روز برای خداوند قربانی های سوختنی گذرانیدند و ذبایح ذبح نمودند. ۱۵ 15
Àwọn ará Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àpótí tí ohun èlò wúrà wà níbẹ̀, wọ́n sì gbé wọn ka orí àpáta ńlá náà. Ní ọjọ́ náà, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi rú ẹbọ sísun, wọ́n sì ṣe ìrúbọ sí Olúwa.
و چون آن پنج سرور فلسطینیان این را دیدند، در همان روز به عقرون برگشتند. ۱۶ 16
Àwọn aláṣẹ Filistini márààrún rí gbogbo èyí, wọ́n sì padà ní ọjọ́ náà sí Ekroni.
و این است خراجهای طلایی که فلسطینیان به جهت قربانی جرم نزد خداوند فرستادند: برای اشدود یک، و برای غزه یک، و برای اشقلون یک، و برای جت یک، و برای عقرون یک. ۱۷ 17
Èyí ni kókó wúrà tí àwọn Filistini fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀bi ọ̀kọ̀ọ̀kan fún Aṣdodu, ọ̀kan ti Gasa, ọ̀kan ti Aṣkeloni, ọ̀kan ti Gati, ọ̀kan ti Ekroni.
وموشهای طلا بر‌حسب شماره جمیع شهرهای فلسطینیان که از املاک آن پنج سرور بود، چه ازشهرهای حصاردار و چه از دهات بیرون تا آن سنگ بزرگی که تابوت خداوند را بر آن گذاشتندکه تا امروز در مزرعه یهوشع بیت شمسی باقی است. ۱۸ 18
Wúrà eku ẹ̀lírí jẹ́ iye ìlú tí àwọn aláṣẹ Filistini márààrún ti wá, ìlú olódi pẹ̀lú ìletò wọn. Àpáta ńlá náà, lórí èyí tí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé jẹ́ ẹ̀rí títí di òní ní oko Joṣua ará Beti-Ṣemeṣi.
و مردمان بیت شمس را زد، زیرا که به تابوت خداوند نگریستند، پس پنجاه هزار وهفتاد نفر از قوم را زد و قوم ماتم گرفتند، چونکه خداوند خلق را به بلای عظیم مبتلا ساخته بود. ۱۹ 19
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kọlu díẹ̀ lára àwọn ọkùnrin Beti-Ṣemeṣi, ó pa àádọ́rin wọn, nítorí wọ́n ti wo inú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Àwọn ènìyàn ṣọ̀fọ̀ nítorí àjálù ńlá tí Olúwa fi bá ọ̀pọ̀ wọn jà.
و مردمان بیت شمس گفتند: «کیست که به حضور این خدای قدوس یعنی یهوه می‌تواندبایستد و از ما نزد که خواهد رفت؟» ۲۰ 20
Àwọn ọkùnrin ará Beti-Ṣemeṣi béèrè pé, “Ta ni ó le è dúró ní iwájú Olúwa Ọlọ́run mímọ́ yìí? Ọ̀dọ̀ ta ni àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò gbà gòkè lọ láti ibí yìí?”
پس رسولان نزد ساکنان قریه یعاریم فرستاده، گفتند: «فلسطینیان تابوت خداوند را پس فرستاده‌اند، بیایید و آن را نزد خود ببرید.» ۲۱ 21
Nígbà náà, wọ́n rán àwọn ìránṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí Kiriati-Jearimu wí pé, “Àwọn Filistini ti dá àpótí ẹ̀rí Olúwa padà. Ẹ sọ̀kalẹ̀ wá, kí ẹ gbé e gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ yín.”

< اول سموئیل 6 >