< Josué 12 >

1 Et ce sont ici les rois du pays, que les fils d’Israël frappèrent et dont ils possédèrent le pays, de l’autre côté du Jourdain, vers le soleil levant, depuis le torrent de l’Arnon jusqu’à la montagne de l’Hermon, et toute la plaine au levant:
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí àwọn ará Israẹli ṣẹ́gun, tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, láti odò Arnoni dé òkè Hermoni, pẹ̀lú gbogbo ìhà ìlà-oòrùn aginjù:
2 Sihon, roi des Amoréens, qui habitait à Hesbon, dominant depuis Aroër qui est sur le bord du torrent de l’Arnon et depuis le milieu du torrent, sur la moitié de Galaad, jusqu’au Jabbok, torrent qui est la frontière des fils d’Ammon;
Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni. Ó ṣe àkóso láti Aroeri tí ń bẹ ní etí odò Arnoni, láti ìlú tó wà ní àárín àfonífojì náà dé odò Jabbok, èyí tí ó jẹ́ ààlà àwọn ọmọ Ammoni. Pẹ̀lú ìdajì àwọn ará Gileadi.
3 et [sur] la plaine, jusqu’à la mer de Kinnéreth, vers le levant, et jusqu’à la mer de la plaine, la mer Salée, au levant, du côté de Beth-Jeshimoth, et au midi, sous les pentes du Pisga;
Ó sì ṣe àkóso ní orí ìlà-oòrùn aginjù láti Òkun Kinnereti sí ìhà Òkun ti aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀), sí Beti-Jeṣimoti, àti láti gúúsù lọ dé ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè Pisga.
4 et le territoire d’Og, roi de Basan, du reste des Rephaïm, qui habitait à Ashtaroth et à Édréhi;
Àti agbègbè Ogu ọba Baṣani, ọ̀kan nínú àwọn tí ó kù nínú àwọn ará Refaimu, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei.
5 et il dominait sur la montagne de l’Hermon, et sur Salca, et sur tout Basan, jusqu’à la frontière des Gueshuriens et des Maacathiens, et [sur] la moitié de Galaad, [jusqu’à la] frontière de Sihon, roi de Hesbon.
Ó ṣe àkóso ní orí òkè Hermoni, Saleka, Baṣani títí dé ààlà àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, àti ìdajì Gileadi dé ààlà Sihoni ọba Heṣboni.
6 Moïse, serviteur de l’Éternel, et les fils d’Israël, les frappèrent; et Moïse, serviteur de l’Éternel, en donna la possession aux Rubénites, et aux Gadites, et à la demi-tribu de Manassé.
Mose ìránṣẹ́ Olúwa àti àwọn ọmọ Israẹli sì borí wọn. Mose ìránṣẹ́ Olúwa sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Reubeni, àwọn ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase kí ó jẹ́ ohun ìní wọn.
7 Et ce sont ici les rois du pays, que Josué et les fils d’Israël frappèrent en deçà du Jourdain, vers l’occident, depuis Baal-Gad, dans la vallée du Liban, jusqu’à la montagne de Halak qui s’élève vers Séhir; et Josué en donna la possession aux tribus d’Israël, selon leurs distributions,
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani, láti Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni sí òkè Halaki, èyí tí o lọ sí ọ̀nà Seiri (Joṣua sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn:
8 dans la montagne, et dans le pays plat, et dans la plaine, et sur les pentes des montagnes, et dans le désert, et dans le midi: le Héthien, l’Amoréen, et le Cananéen, le Phérézien, le Hévien, et le Jébusien: –
ilẹ̀ òkè, ní ẹsẹ̀ òkè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn òkè aginjù, ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè, ní aginjù àti nì gúúsù ilẹ̀ àwọn ará: Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi).
9 le roi de Jéricho, un; le roi d’Aï, qui est à côté de Béthel, un;
Ọba Jeriko, ọ̀kan ọba Ai (tí ó wà nítòsí Beteli), ọ̀kan
10 le roi de Jérusalem, un; le roi de Hébron, un;
ọba Jerusalẹmu, ọ̀kan ọba Hebroni, ọ̀kan
11 le roi de Jarmuth, un; le roi de Lakis, un;
ọba Jarmatu, ọ̀kan ọba Lakiṣi, ọ̀kan
12 le roi d’Églon, un; le roi de Guézer, un;
ọba Egloni, ọ̀kan ọba Geseri, ọ̀kan
13 le roi de Debir, un; le roi de Guéder, un;
ọba Debiri, ọ̀kan ọba Gederi, ọ̀kan
14 le roi de Horma, un; le roi d’Arad, un;
ọba Horma, ọ̀kan ọba Aradi, ọ̀kan
15 le roi de Libna, un; le roi d’Adullam, un;
ọba Libina, ọ̀kan ọba Adullamu, ọ̀kan
16 le roi de Makkéda, un; le roi de Béthel, un;
ọba Makkeda, ọ̀kan ọba Beteli, ọ̀kan
17 le roi de Tappuakh, un; le roi de Hépher, un;
ọba Tapua, ọ̀kan ọba Heferi, ọ̀kan
18 le roi d’Aphek, un; le roi de Lassaron, un;
ọba Afeki, ọ̀kan ọba Laṣaroni, ọ̀kan
19 le roi de Madon, un; le roi de Hatsor, un;
ọba Madoni, ọ̀kan ọba Hasori, ọ̀kan
20 le roi de Shimron-Meron, un; le roi d’Acshaph, un;
ọba Ṣimroni-Meroni, ọ̀kan ọba Akṣafu, ọ̀kan
21 le roi de Thaanac, un; le roi de Meguiddo, un;
ọba Taanaki, ọ̀kan ọba Megido, ọ̀kan
22 le roi de Kédesh, un; le roi de Jokneam, au Carmel, un;
ọba Kedeṣi, ọ̀kan ọba Jokneamu ni Karmeli, ọ̀kan
23 le roi de Dor, des hauteurs de Dor, un; le roi de Goïm, à Guilgal, un;
ọba Dori (ní Nafoti Dori), ọ̀kan ọba Goyimu ní Gilgali, ọ̀kan
24 le roi de Thirtsa, un; tous les rois étaient 31.
ọba Tirsa, ọ̀kan. Gbogbo àwọn ọba náà jẹ́ mọ́kànlélọ́gbọ̀n.

< Josué 12 >