< Psalms 124 >

1 A song of ascents. Of David. ‘Had it not been the Lord who was for us’ let Israel say
Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi. “Ìbá má ṣe pé Olúwa tí ó ti wà fún wa,” kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;
2 ‘Had it not been the Lord who was for us when enemies rose against us,
ìbá má ṣe pé Olúwa tó wà ní tiwa, nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa,
3 then alive they’d have swallowed us up, when their anger was kindled against us.
nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa,
4 Then the waters would’ve swept us away, and the torrent passed over us clean:
nígbà náà ni omi wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀,
5 then most sure would’ve passed over us clean the wild seething waters.’
nígbà náà ni agbéraga omi ìbá borí ọkàn wa.
6 Blest be the Lord who has given us not to be torn by their teeth.
Olùbùkún ni Olúwa, tí kò fi wá fún wọ́n bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.
7 We are like a bird just escaped from the snare of the fowler. The snare is broken, and we are escaped.
Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ; okùn já àwa sì yọ.
8 Our help is the name of the Lord, the Creator of heaven and earth.
Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ Olúwa, tí ó dá ọ̀run òun ayé.

< Psalms 124 >