< 2 Chronicles 8 >

1 And after twentie yeere when Salomon had built the house of the Lord, and his owne house,
Lẹ́yìn ogún ọdún lásìkò ìgbà tí Solomoni kọ́ ilé Olúwa àti ilé òun fúnra rẹ̀.
2 Then Salomon built the cities that Huram gaue to Salomon, and caused the children of Israel to dwell there.
Solomoni tún ìlú tí Hiramu ti fi fún un kọ́, ó sì kó àwọn ọmọ Israẹli jọ níbẹ̀ kí wọn kí ó lè máa gbé nínú ibẹ̀.
3 And Salomon went to Hamath Zobah, and ouercame it.
Nígbà náà Solomoni lọ sí Hamati-Ṣoba ó sì borí rẹ̀.
4 And he built Tadmor in the wildernesse, and repayred all the cities of store which hee built in Hamath.
Ó sì tún kọ́ Tadmori ní aginjù àti gbogbo ìlú ìṣúra tí ó ti kọ́ ní Hamati.
5 And he built Beth-horon the vpper, and Beth-horon the nether, cities defensed with walles, gates and barres:
Ó sì tún kọ́ òkè Beti-Horoni àti ìsàlẹ̀ Beti-Horoni gẹ́gẹ́ bí ìlú olódi, pẹ̀lú ògiri àti pẹ̀lú ìlẹ̀kùn àti ọ̀pá ìdábùú.
6 Also Baalath, and al the cities of store that Salomon had, and all the charet cities, and the cities of the horsemen, and euery pleasant place that Salomon had a minde to builde in Ierusalem, and in Lebanon, and throughout all the lande of his dominion.
Àti gẹ́gẹ́ bí Baalati àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti gbogbo ìlú fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti fún àwọn ẹṣin rẹ̀ ohunkóhun tí ó bá yẹ ní kókó ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo àyíká agbègbè tí ó ń darí.
7 And all the people that were left to ye Hittites, and ye Amorites, and Perizzites, and the Hiuuites, and the Iebusites, which were not of Israel,
Gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kúrò láti ara àwọn ará Hiti, ará Amori, ará Peresi, ará Hifi àti ará Jebusi àwọn ènìyàn wọ̀nyí wọn kì í ṣe àwọn ará Israẹli,
8 But of their children which were left after them in the lande, whome the children of Israel had not consumed, euen them did Salomon make tributaries vntill this day.
èyí ni wí pé, àwọn ọmọ wọn tí ó kù sílé ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò parun àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ìrú fún títí di òní yìí.
9 But of the children of Israel did Salomon make no seruantes for his worke: for they were men of warre, and his chiefe princes, and the captaines of his charets and of his horsemen.
Ṣùgbọ́n Solomoni kò mú ọmọ ọ̀dọ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, wọn jẹ́ ọ̀gágun rẹ̀, olùdarí àwọn oníkẹ̀kẹ́ àti olùdarí kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
10 So these were the chiefe of the officers which Salomon had, euen two hundreth and fiftie that bare rule ouer the people.
Wọ́n sì tún jẹ́ olórí aláṣẹ fún ọba Solomoni, àádọ́ta ó lé nígba àwọn alákòóso lórí àwọn ènìyàn.
11 Then Salomon brought vp the daughter of Pharaoh out of the citie of Dauid, into the house that he had built for her: for he saide, My wife shall not dwel in the house of Dauid King of Israel: for it is holy, because that the Arke of the Lord came vnto it.
Solomoni gbé ọmọbìnrin Farao sókè láti ìlú Dafidi lọ sí ibi tí ó ti kọ́ fún un, nítorí ó wí pé, “Aya mi kò gbọdọ̀ gbé nínú ilé Dafidi ọba Israẹli nítorí ibi tí àpótí ẹ̀rí Olúwa bá tí wọ̀, ibi mímọ́ ni.”
12 Then Salomon offered burnt offrings vnto the Lord, on the altar of the Lord, which he had built before the porche,
Lórí pẹpẹ Olúwa tí ó ti kọ́ níwájú ìloro náà, Solomoni sì rú ẹbọ sísun sí Olúwa,
13 To offer according to the commandement of Moses euery day, in the Sabbaths, and in the newe moones, and in the solemne feastes, three times in the yeere, that is, in the feast of the Vnleauened bread, and in the feast of the Weekes, and in the feast of the Tabernacles.
nípa ìlànà ojoojúmọ́ fún ẹbọ rírú tí a pàṣẹ láti ọ̀dọ̀ Mose wá fún ọjọ́ ìsinmi, oṣù tuntun àti lẹ́rìn mẹ́ta lọ́dún, ní àjọ àìwúkàrà, ní àjọ ọ̀sẹ̀ méje àti àjọ àgọ́.
14 And he set the courses of the Priestes to their offices, according to the order of Dauid his father, and the Leuites in their watches, for to praise and minister before the Priestes euery day, and the porters by their courses, at euery gate: for so was the commandement of Dauid the man of God.
Ní pípamọ́ pẹ̀lú ìlànà baba rẹ̀ Dafidi, ó sì yan ipa àwọn àlùfáà fún iṣẹ́ wọn àti àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ adarí láti máa yin àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ àwọn àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìlànà ojoojúmọ́. Ó sì tún yàn àwọn olùṣọ́nà nípa pípín sí olúkúlùkù ẹnu-ọ̀nà, nítorí èyí ni Dafidi ènìyàn Ọlọ́run ti paláṣẹ.
15 And they declined not from the commandement of the King, concerning the Priests and the Leuites, touching al things, and touching the treasures.
Wọn kò sì yà kúrò nínú àṣẹ ọba sí àwọn àlùfáà tàbí sí àwọn ọmọ Lefi, nínú ohunkóhun, àti pẹ̀lú ti ìṣúra.
16 Nowe Salomon had made prouision for all the worke, from the day of the foundation of the house of the Lord, vntill it was finished: so the house of the Lord was perfite.
Gbogbo iṣẹ́ Solomoni ni a gbé jáde láti ọjọ́ ìfi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀ títí ó fi di ọjọ́ ìparí. Bẹ́ẹ̀ ni ilé Olúwa sì parí.
17 Then went Salomon to Ezion-geber, and to Eloth by the sea side in the lande of Edom.
Nígbà náà ni Solomoni lọ sí Esioni-Geberi àti Elati ní Edomu létí òkun.
18 And Huram sent him by the handes of his seruants, shippes, and seruants that had knowledge of the sea: and they went with the seruants of Salomon to Ophir, and brought thence foure hundreth and fiftie talents of golde, and brought them to King Salomon.
Hiramu sì fi ọ̀kọ̀ ránṣẹ́ sì i nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọkùnrin tí ó mòye Òkun. Èyí pẹ̀lú àwọn ènìyàn Solomoni, lọ sí Ofiri wọ́n sì gbé àádọ́ta lé ní irinwó tálẹ́ǹtì wúrà wá, padà èyí tí wọ́n sì mú tọ ọba Solomoni wá.

< 2 Chronicles 8 >