< Job 1 >

1 Der levede engang i Landet Uz en mand ved Navn Job. Det var en from og retsindig Mand, der frygtede Gud og veg fra det onde.
Ọkùnrin kan wà ní ilẹ̀ Usi, orúkọ ẹni tí í jẹ́ Jobu; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́, ó dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó kórìíra ìwà búburú.
2 Syv Sønner og tre Døtre fødtes ham;
A sì bi ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta fún un.
3 og hans Ejendom udgjorde 7000 Stykker Småkvæg, 3000 Kameler, 500 Spand Okser, 500 Aseninder og såre mange Trælle, så han var mægtigere end alle Østens Sønner.
Ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ìbákasẹ, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì pọ̀; bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin yìí sì pọ̀jù gbogbo àwọn ará ìlà-oòrùn lọ.
4 Hans Sønner havde for Skik at holde Gæstebud på Omgang hos hverandre, og de indbød deres tre Søstre til at spise og drikke sammen med sig.
Àwọn ọmọ rẹ̀ a sì máa lọ í jẹun àsè nínú ilé ara wọn, olúkúlùkù ní ọjọ́ rẹ̀; wọn a sì máa ránṣẹ́ pé arábìnrin wọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta láti jẹun àti láti pẹ̀lú wọn.
5 Når så Gæstebudsdagene havde nået Omgangen rundt, sendte Job Bud og lod Sønnerne hellige sig, og tidligt om Morgenen ofrede han Brændofre, et for hver af dem. Thi Job sagde: "Måske har mine Sønner syndet og forbandet Gud i deres Hjerte." Således gjorde Job hver Gang.
Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ àsè wọn pé yíká, ni Jobu ránṣẹ́ lọ í yà wọ́n sí mímọ́, ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì rú ẹbọ sísun níwọ̀n iye gbogbo wọn; nítorí tí Jobu wí pé: bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣọpẹ́ fún Ọlọ́run lọ́kàn wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Jobu máa ń ṣe nígbà gbogbo.
6 Nu hændte det en Dag, at Guds Sønner kom og trådte frem for HERREN, og iblandt dem kom også Satan.
Ǹjẹ́ ó di ọjọ́ kan, nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá í pé níwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn.
7 HERREN spurgte Satan: "Hvor kommer du fra?" Satan svarede HERREN: "Jeg har gennemvanket Jorden på Kryds og tværs."
Olúwa sì bi Satani wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Nígbà náà ní Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Ní ìlọsíwá-sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé, àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”
8 HERREN spurgte da Satan: " Har du lagt Mærke til min Tjener Job? Der findes ingen som han på Jorden, så from og retsindig en Mand, som frygter Gud og viger fra det onde."
Olúwa sì sọ fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí í ṣe olóòtítọ́, tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti ó sì kórìíra ìwà búburú.”
9 Men Satan svarede HERREN: "Mon det er for intet, Job frygter Gud?
Nígbà náà ni Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Jobu ha bẹ̀rù Ọlọ́run ní asán bí?”
10 Har du ikke omgærdet ham og hans Hus og alt, hvad han ejer, på alle Kanter? Hans Hænders Idræt har du velsignet, og hans Hjorde breder sig i Landet.
“Ìwọ kò ha ti ṣọgbà yìí ká, àti yí ilé rẹ̀ àti yí ohun tí ó ní ká, ní ìhà gbogbo? Ìwọ bùsi iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì ń pọ̀ si ní ilẹ̀.
11 Men ræk engang din Hånd ud og rør ved alt, hvad han ejer! Sandelig, han vil forbande dig lige op i dit Ansigt!"
Ǹjẹ́, nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó sì fi tọ́ ohun gbogbo tí ó ni; bí kì yóò sì bọ́hùn ni ojú rẹ.”
12 Da sagde HERREN til Satan: "Se, alt hvad han ejer, er i din Hånd; kun mod ham selv må du ikke udrække din Hånd!" Så gik Satan bort fra HERRENs Åsyn.
Olúwa sì dá Satani lóhùn wí pé, “Kíyèsi i, ohun gbogbo tí ó ní ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, kìkì òun tìkára rẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ rẹ kàn.” Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa.
13 Da nu en Dag hans Sønner og Døtre spiste og drak i den ældste Broders Hus,
Ó sì di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, tí wọ́n mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkùnrin,
14 kom et Sendebud til Job og sagde: "Okserne gik for Ploven, og Aseninderne græssede i Nærheden;
oníṣẹ́ kan sì tọ Jobu wá wí pé, “Àwọn ọ̀dá màlúù ń tulẹ̀, àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì ń jẹ ní ẹ̀gbẹ́ wọn,
15 så faldt Sabæerne over dem og tog dem; Karlene huggede de ned med Sværdet; jeg alene undslap for at melde dig det."
àwọn ará Sabeani sì kọlù wọ́n, wọ́n sì ń kó wọn lọ pẹ̀lú, wọ́n ti fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa, èmi nìkan ṣoṣo ní ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ.”
16 Medens han endnu talte, kom en anden og sagde: "Guds Ild faldt ned fra Himmelen og slog ned iblandt Småkvæget og Karlene og fortærede dem; jeg alene undslap for at melde dig det."
Bí ó ti ń sọ ní ẹnu; ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé, “Iná ńlá Ọlọ́run ti ọ̀run bọ́ sí ilẹ̀, ó sì jó àwọn àgùntàn àti àwọn ìránṣẹ́; èmi nìkan ṣoṣo ní ó sálà láti ròyìn fún ọ.”
17 Medens han endnu talte, kom en tredje og sagde: "Kaldæerne kom i tre Flokke og kastede sig over Kamelerne og tog dem; Karlene huggede de ned med Sværdet; jeg alene undslap for at melde dig det."
Bí ó sì ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan sì dé pẹ̀lú tí ó wí pé, “Àwọn ará Kaldea píngun sí ọ̀nà mẹ́ta, wọ́n sì kọlù àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì kó wọn lọ, pẹ̀lúpẹ̀lú wọ́n sì fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ!”
18 Medens han endnu talte, kom en fjerde og sagde: "Dine Sønner og Døtre spiste og drak i deres ældste Broders Hus;
Bí ó ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin ń jẹ, wọ́n ń mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n.
19 og se, da for der et stærkt Vejr hen over Ørkenen, og det tog i Husets fire Hjørner, så det styrtede ned over de unge Mænd, og de omkom; jeg alene undslap for at melde dig det."
Sì kíyèsi i, ẹ̀fúùfù ńlá ńlá ti ìhà ijù fẹ́ wá kọlu igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilé, ó sì wó lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wọ́n sì kú, èmi nìkan ṣoṣo ni ó yọ láti ròyìn fún ọ.
20 Da stod Job op, sønderrev sin Kappe, skar sit Hovedhår af og kastede sig til Jorden, tilbad
Nígbà náà ni Jobu dìde, ó sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, ó sì fá orí rẹ̀ ó wólẹ̀ ó sì gbàdúrà
21 og sagde: Nøgen kom jeg af Moders Skød, og nøgen vender jeg did tilbage. HERREN gav, og HERREN tog, HERRENs Navn være lovet!"
wí pé, “Ní ìhòhò ní mo ti inú ìyá mi jáde wá, ni ìhòhò ní èmi yóò sì tún padà lọ. Olúwa fi fún ni, Olúwa sì gbà á lọ, ìbùkún ni fún orúkọ Olúwa.”
22 I alt dette syndede Job ikke og tillagde ikke Gud noget vrangt.
Nínú gbogbo èyí Jobu kò ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi òmùgọ̀ pe Ọlọ́run lẹ́jọ́.

< Job 1 >