< 1 Mosebog 20 >

1 Der På brød Abraham op derfra til Sydlandet og slog sig ned mellem Kadesj og Sjur og boede som fremmed i Gerar.
Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀.
2 Da nu Abraham sagde om sin Hustru Sara, at hun var hans Søster, sendte Kong Abimelek af Gerar Bud og lod Sara hente til sig.
Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.
3 Men Gud kom til Abimelek i en Drøm om Natten og sagde til ham: "Se, du skal dø for den Kvindes Skyld, som du har taget, thi hun er en anden Mands Hustru!"
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ n nì, aya ẹni kan ní íṣe.”
4 Abimelek var imidlertid ikke kommet hende nær; og han sagde: "Herre, vil du virkelig. slå retfærdige Folk ihjel?
Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí?
5 Har han ikke sagt mig, at hun er hans Søster? Og hun selv har også sagt, at han er hendes Broder; i mit Hjertes Troskyldighed og med rene Hænder har jeg gjort dette."
Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘Arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”
6 Da sagde Gud til ham i Drømmen: "Jeg ved, at du har gjort det i dit Hjertes Troskyldighed, og jeg har også hindret dig i at synde imod mig; derfor tilstedte jeg dig ikke at røre hende.
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.
7 Men send nu Mandens Hustru tilbage, thi han er en Profet, så han kan gå i Forbøn for dig, og du kan blive i Live; men sender du hende ikke tilbage, så vid, at du og alle dine er dødsens!"
Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”
8 Tidligt næste Morgen lod Abimelek alle sine Tjenere kalde og fortalte dem det hele, og Mændene blev såre forfærdede.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
9 Men Abimelek lod Abraham kalde og sagde til ham: "Hvad har du dog gjort imod os? Og hvad har jeg forbrudt imod dig, at du bragte denne store Synd over mig og mit Rige? Du har gjort imod mig, hvad man ikke bør gøre!"
Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”
10 Og Abimelek sagde til Abraham: "Hvad bragte dig til at handle således?"
Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”
11 Abraham svarede: "Jo, jeg tænkte: Her er sikkert ingen Gudsfrygt på dette Sted, så de vil slå mig ihjel for min Hustrus Skyld.
Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi.
12 Desuden er hun virkelig min Søster, min Faders Datter, kun ikke min Moders; men hun blev min Hustru.
Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya.
13 Og da nu Gud lod mig flakke om fjernt fra min Faders Hus, sagde jeg til hende: Den Godhed må du vise mig, at du overalt, hvor vi kommer hen, siger, at jeg er din Broder."
Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi. Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.”’”
14 Derpå tog Abimelelk Småkvæg og Hornkvæg, Trælle og Trælkvinder og gav Abraham dem og sendte hans Hustru Sara tilbage til ham;
Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un.
15 og Abimelek sagde til ham: "Se, mit Land ligger åbent for dig; slå dig ned, hvor du lyster!"
Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”
16 Men til Sara sagde han: "Jeg har givet din Broder 1000 Sekel Sølv, det skal være dig Godtgørelse for alt, hvad der er tilstødt dig. Hermed har du fået fuld Oprejsning."
Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”
17 Men Abraham gik i Forbøn hos Gud, og Gud helbredte Abimelek og hans Hustru og Medhustruer, så at de atter fik Børn.
Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ,
18 HERREN havde nemlig lukket for ethvert Moderliv i Abimeleks Hus for Abrahams Hustru Saras Skyld.
nítorí Olúwa ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.

< 1 Mosebog 20 >