< Lucas 21 >

1 Y sinando diando, dicó os balbales sos bucharaban desquerias ofrendas andré a jestari e manchin.
Nígbà tí ó sì gbé ojú sókè, ó rí àwọn ọlọ́rọ̀ ń fi ẹ̀bùn wọn sínú àpótí ìṣúra.
2 Y dicó tambien yeque piuli chorori, sos chibelaba dui cales chinores.
Ó sì rí tálákà opó kan pẹ̀lú, ó ń sọ owó idẹ wẹ́wẹ́ méjì síbẹ̀.
3 Y penó: Aromali sangue penelo, que ocona chorori piuli ha chibado butér que sares os avéres.
Ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, tálákà opó yìí fi sí i ju gbogbo wọn lọ,
4 Presas sares ocolas terelan bucharado somía ofrendas de Debél, de ma les sobresarela: Tami ocona de desqueri erdicha terela chibado saro o jayere sos terelaba.
nítorí gbogbo àwọn wọ̀nyí fi sínú ẹ̀bùn Ọlọ́run láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní wọn; ṣùgbọ́n òun nínú àìní rẹ̀ ó sọ gbogbo ohun ìní rẹ̀ tí ó ní sínú rẹ̀.”
5 Y rudeló á yeques, sos penaban de la cangri, que sinaba chiti de barias pacuarias, y de diñipenes:
Bí àwọn kan sì ti ń sọ̀rọ̀ nípa tẹmpili, bí a ti fi òkúta dáradára àti ẹ̀bùn ṣe é ní ọ̀ṣọ́, fun Ọlọ́run, Jesu wí pé
6 Oconas buchias sos diquelais, abillarán chibeses, pur na sinará mequelada bar opré bar, sos na sinará demolida.
“Ohun tí ẹ̀yin ń wò wọ̀nyí, ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí a kì yóò fi òkúta kan sílẹ̀ lórí èkejì tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
7 Y le puchabáron, y penáron: ¿Duquendio, pur sinará ocono? y que simache sinará, pur ocono comenzáre á sinar?
Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, pé, “Olùkọ́, nígbà wo ni nǹkan wọ̀nyí yóò rí bẹ́ẹ̀? Àti àmì kín ni yóò wà, nígbà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ?”
8 O penó: Diquelad, que na sineleis jongabados: presas baribustres abillarán andré minrio nao, penando: Menda sinelo, y o chiros sinela sunparal: garabelaos pues de chalar palal de junos.
Ó sì wí pé, “Ẹ máa kíyèsára, kí a má bá à mú yín ṣìnà: nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò wá ní orúkọ mi, tí yóò máa wí pé, ‘Èmi ní Kristi náà àkókò náà sì kù sí dẹ̀dẹ̀.’ Ẹ má ṣe tọ̀ wọ́n lẹ́yìn.
9 Y pur junelareis chingaripenes y jestias, sangue na cangueleis: presas jomte que ocono anaquele brotoboro, tami na sinará yescotria a anda.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá gbúròó ogun àti ìdágìrì, ẹ má ṣe fòyà; nítorí nǹkan wọ̀nyí ní láti kọ́kọ́ ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin náà kì í ṣe lójúkan náà.”
10 Entonces les penaba: Se ardiñará sueti contra sueti, y chim contra chim.
Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé, “Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba.
11 Y sinará bares jolili-motos por os gaues, y salipénes, y boquises y sinará buchias espantosas, y barias simaches e Charos.
Ilẹ̀-rírì ńlá yóò sì wà káàkiri, àti ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn; ohun ẹ̀rù, àti àmì ńlá yóò sì ti ọ̀run wá.
12 Tami anglal de saro ocono sangue ustilarán, y plastañarán, entregisarando sangue á as Synagogas, y á os estaripeles, y lliguerarán sangue á os Crallises, y á os Poresqueres, por minrio nao:
“Ṣùgbọ́n ṣáájú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, wọn ó nawọ́ mú yín, wọn ó sì ṣe inúnibíni sí yín, wọn ó mú yín lọ sí Sinagọgu, àti sínú túbú, wọn ó mú yín lọ sọ́dọ̀ àwọn ọba àti àwọn ìjòyè nítorí orúkọ mi.
13 Y ocono sinará sasta machiria á sangue.
Ẹ o si jẹ́rìí nípa mi.
14 Terelad yeque buchi silni andré jires carlés, o na penchabar anglal ma terelais de rudelar.
Nítorí náà ẹ pinnu rẹ̀ ní ọkàn yín pé ẹ ko ronú ṣáájú, bí ẹ ó ti dáhùn.
15 Presas menda diñaré sangue mui y chaneleria, al que n’astisarelarán resistir, ni contrapenar sares jires daschmanuces:
Nítorí tí èmi ó fún yín ní ẹnu àti ọgbọ́n, tí gbogbo àwọn ọ̀tá yín kì yóò lè sọ̀rọ̀-òdì sí, tí wọn kì yóò sì lè kò lójú.
16 Y sinareis entregados de jires batuces, y plalores, y rati, y monrés, y querelarán merar a yéques de sangue.
A ó sì fi yín hàn láti ọwọ́ àwọn òbí yín wá, àti àwọn arákùnrin, àti àwọn ìbátan, àti àwọn ọ̀rẹ́; òun ó sì mú kì a pa nínú yín.
17 Y sares aborrecerán á sangue pre minrio nao.
A ó sì kórìíra yín lọ́dọ̀ gbogbo ènìyàn nítorí orúkọ mi.
18 Tami na se najabará yeque bal de jires jerés.
Ṣùgbọ́n irun orí yín kan kì yóò ṣègbé.
19 Sat jiri paciencia listrabareis jirias ochias.
Nínú ìdúró ṣinṣin yín ni ẹ̀yin ó jèrè ọkàn yín.
20 Pues pur dicáreis á Jerusalém pandada al crugos de jundunares, entonces chanelad que sun najipen sinela sunparal.
“Nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí ti a fi ogun yí Jerusalẹmu ká, ẹ mọ̀ nígbà náà pé, ìsọdahoro rẹ̀ kù sí dẹ̀dẹ̀.
21 Entonces junos sos sinelan andré la Judéa, najalelen á os bures: y junos en medio de siró se sicobelen abrí; y junos andré os bures na chalen andré de siró.
Nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ní Judea sálọ sórí òkè; àti àwọn tí ń bẹ láàrín rẹ̀ kí wọn jáde kúrò; kí àwọn tí ó sì ń bọ̀ ní ìgbèríko má ṣe wọ inú rẹ̀ wá.
22 Presas oconas sinelan chibeses de venganza, somia se perelalen sarias as buchias, sos sinelan libanadas.
Nítorí ọjọ́ ẹ̀san ni ọjọ́ wọ̀nyí, kì a lè mú ohun gbogbo tí a ti kọ̀wé rẹ̀ ṣẹ.
23 Tami ysna de las cambrias, y de ocolas sos diñelan de mamisarar andré ocolas chibeses! Presas sinará bari apretura opré a pu, y ira para ocona sueti.
Ṣùgbọ́n ègbé ni fún àwọn tí ó lóyún, àti àwọn tí ó fi ọyàn fún ọmọ mu ní ọjọ́ wọ̀nyí! Nítorí tí ìpọ́njú púpọ̀ yóò wà lórí ilẹ̀ àti ìbínú sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
24 Y perarán á filo e estuche: y sinarán lliguerados utildes á sares os chimes, y Jerusalém sinará hollada de los Busnés: disde que se perele o chiros es Busnes.
Wọn ó sì ti ojú idà ṣubú, a ó sì dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ sí orílẹ̀-èdè gbogbo; Jerusalẹmu yóò sì di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ lẹ́sẹ̀ àwọn aláìkọlà, títí àkókò àwọn aláìkọlà yóò fi kún.
25 Y terelará simáches Cam, y andré a Chimutra, y andré as cherdillas; y andré la pu tráqui es manuces pre a confusion sos querelara a chumas e moros, y de sus panias.
“Àmì yóò sì wà ní oorun, àti ní òṣùpá, àti ní ìràwọ̀; àti lórí ilẹ̀ ayé ìdààmú fún àwọn orílẹ̀-èdè nínú ìpayà híhó Òkun àti ìgbì omi.
26 Sinando os manuces yertos por o dal y canguelo es buchias, sos opre abillaran á sari a sueti: presas as silas e Tarpe sinarán conmovidas:
Àyà àwọn ènìyàn yóò máa já fún ìbẹ̀rù, àti ìrètí nǹkan wọ̀nyí tí ń bọ̀ sórí ayé: nítorí àwọn agbára ọ̀run ni a ó mì tìtì.
27 Entonces diquelarán al Chaboro e manu abíllar opré yeque paros sat ezor baro y chimusolano.
Nígbà náà ni wọn ó sì rí Ọmọ Ènìyàn tí yóò máa bọ̀ wá nínú àwọsánmọ̀ pẹ̀lú agbára àti ògo ńlá.
28 Pur comenzaren pues á perelarse oconas buchias, diquelad, y ardiñelad jires jeres; presas sunparal sinela jire mestepé.
Ṣùgbọ́n nígbà tí nǹkan wọ̀nyí bá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣẹ, ǹjẹ́ kí ẹ wo òkè, kí ẹ sì gbé orí yín sókè; nítorí ìdáǹdè yín kù sí dẹ̀dẹ̀.”
29 Y les penó yeque semejanza: Diquelad a carschta-heila, y sarias as carschtas.
Ó sì pa òwe kan fún wọn pé, “Ẹ kíyèsi igi ọ̀pọ̀tọ́, àti sí gbogbo igi.
30 Pur bucharelan ya abrí de sí o mibao, jabillais que sunparal sinela o canriano.
Nígbà tí wọ́n bá rúwé, ẹ̀yin rí i, ẹ sì mọ̀ fúnra ara yín pé, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn kù fẹ́ẹ́rẹ́.
31 Andiar tambien sangue, pur dicalareis querelarse oconas buchias, chanelad que sunparal sinela o chim de Debél.
Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀yin, nígbà tí ẹ̀yin bá rí nǹkan wọ̀nyí tí o ṣẹ, kí ẹ̀yin mọ̀ pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.
32 Aromali sangue penelo, que na nacará ocona generacion, disde que sarias oconas buchias sinarán quereladas.
“Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ìran yìí kì yóò rékọjá, títí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ.
33 O Charos y la pu nacabarán: tami minrias vardas na nacarán.
Ọ̀run àti ayé yóò rékọjá, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi kì yóò rékọjá.
34 Diquelad pues por sangue, na sinele que jires carlés se carguisarelen de glotoneria y de matipen, y de las gramias de ocona chipen: y que abillele de repente opré sangue ocola chibes.
“Ṣùgbọ́n ẹ máa kíyèsára yín, kí ọkàn yín má ṣe kún fún wọ̀bìà, àti fún ọtí àmupara, àti fún àníyàn ayé yìí, tí ọjọ́ náà yóò sì fi dé bá yín lójijì bí ìkẹ́kùn.
35 Presas andiar sasta yeque maluno abillará opré sares sos sinelan opré a chichi de sari a jolili.
Nítorí bẹ́ẹ̀ ni yóò dé bá gbogbo àwọn tí ń gbé orí gbogbo ilẹ̀ ayé.
36 Pues sinelad de vela manguelando á Un-debél andré saro chiros, somia que sineleis cabalicos de najar sarias oconas buchias, sos jomte sinar, y de sinar andre pindré, anglal e Chaboro e manu.
Ǹjẹ́ kì ẹ máa ṣọ́nà, kí ẹ sì máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí ẹ ba à lè la gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí yóò ṣẹlẹ̀, kí ẹ sì lè dúró níwájú Ọmọ Ènìyàn.”
37 Y sinaba bedando andré a cangri: ta arachis chalaba abrí, y lo nacaba andré o bur, araquerado e Urucal.
Lọ́sàn án, Jesu a sì máa kọ́ni ní tẹmpili, lóru, a sì máa jáde lọ í wọ̀ ní òkè tí à ń pè ní Òkè Olifi.
38 Y sari a sueti se ardiñeló de clarico, somia abillar, a junarle andré a cangri.
Gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá ní tẹmpili ní kùtùkùtù òwúrọ̀, láti gbọ́rọ̀ rẹ̀.

< Lucas 21 >