< Lucas 19 >

1 Y Jesus terelando chalado andré, nacaba por Jericho.
Jesu sì wọ Jeriko lọ, ó sì ń kọjá láàrín rẹ̀.
2 Y he acoi manu araquerado Zachéo: y ocona sinaba yeque es mas bares enré os Publícanes, y balbalo:
Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà tí a ń pè ní Sakeu, ó sì jẹ́ olórí agbowó òde kan, ó sì jẹ́ ọlọ́rọ̀.
3 Y orotaba dicar á Jesus, coin sinase: y na le astis pre la baribu sueti, presas sinaba chinoro de trupo.
Ó sì ń fẹ́ láti rí ẹni tí Jesu jẹ́: kò sì lè rí i, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn, àti nítorí tí òun jẹ́ ènìyàn kúkúrú.
4 Y chalando anglal, se costunó andré carschta bruñi heila somia dicarle, presas por oté terelaba de nacar.
Ó sì súré síwájú, ó gun orí igi sikamore kan, kí ó bà lè rí i: nítorí tí yóò kọjá lọ níhà ibẹ̀.
5 Y pur bigoreó Jesus á ocona stano, ardiñelando as aquias, le dicó, y le penó: abillel ostely yescotria, presas jomte ustilarme achibes andré tun quer.
Nígbà tí Jesu sì dé ibẹ̀, ó gbé ojú sókè, ó sì rí i, ó sì wí fún un pé, “Sakeu! Yára, kí o sì sọ̀kalẹ̀; nítorí pé èmi yóò wọ ilé rẹ lónìí.”
6 Y ó chaló ostely yescotría, y le ustiló asaselándose.
Ó sì yára, ó sọ̀kalẹ̀, ó sì fi ayọ̀ gbà á.
7 Y dicando ocono sares, chumasquereláron, penando, que terelaba chalado á sinar andré quer de yeque choro.
Nígbà tí wọ́n sì rí i, gbogbo wọn ń kùn, wí pé, “Ó lọ bá ọkùnrin ẹlẹ́ṣẹ̀ náà ní àlejò.”
8 Tami Zachéo, chibandose anglal e Erañoró, le penó: Eraño, a paque de ma terelo diñelo á os chorores: y si andré buchi terelo jonganado á manu, le voltisarelo star tanto butér.
Sakeu sì dìde, ó sì wí fún Olúwa pé, “Wò ó, Olúwa, ààbọ̀ ohun ìní mi ni mo fi fún tálákà; bí mo bá sì fi èké gba ohun kan lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, èmi san án padà ní ìlọ́po mẹ́rin!”
9 Y Jesus le penó: Achibes ha abillado golipen á ocona quer: presas ó tambien sinela chaboro de Abraham.
Jesu sì wí fún un pé, “Lónìí ni ìgbàlà wọ ilé yìí, níwọ̀n bí òun pẹ̀lú ti jẹ́ ọmọ Abrahamu.
10 Presas o Chaboro e manu abilló á orotar, y á salvar ma sinaba chibado á najabar.
Nítorí Ọmọ Ènìyàn dé láti wá àwọn tí ó nù kiri, àti láti gbà wọ́n là.”
11 Junelando junos ocono, plastañó penandoles yeque parabola, sat ocasion de sinar sunparal de Jerusalem: y presas penchababan que yescotria se mequelaria dicar o chim de Debél:
Nígbà tí wọ́n sì ń gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó sì tẹ̀síwájú láti pa òwe kan, nítorí tí ó súnmọ́ Jerusalẹmu, àti nítorí tí wọn ń rò pé, ìjọba Ọlọ́run yóò farahàn nísinsin yìí.
12 Penó pues: Manu tintin chaló a chim dur, somia ustilar yeque lume oté, y despues limbidiarse.
Ó sì wí pé, “Ọkùnrin ọlọ́lá kan lọ sí ìlú òkèrè láti gba ìjọba kí ó sì padà.
13 Y araquerando á deque de desqueres lacrés, les diñó deque estongrias, y les penó: paruguelad entretanto que abillelo.
Ó sì pe àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ mẹ́wàá, ó fi owó mina mẹ́wàá fún wọn, ó sì wí fún wọn pé, ‘Ẹ máa ṣòwò títí èmi ó fi dé!’
14 Tami os de desquero foros na le camelaban, y bichobando palal de ó yeque plastañí, le penáron: Na camelamos que reyne ocona opré de amangue.
“Ṣùgbọ́n àwọn ará ìlù rẹ̀ kórìíra rẹ̀, wọ́n sì rán ikọ̀ tẹ̀lé e, wí pé, ‘Àwa kò fẹ́ kí ọkùnrin yìí jẹ ọba lórí wa.’
15 Y pur limbidió, despues de ustilar o lume, penó araquerar á ocolas lacrés, á coines terelaba diñado o jayere, somia chanelar ma cata yeque terelaba paruguelado.
“Nígbà tí ó gba ìjọba tan, tí ó padà dé, ó pàṣẹ pé, kí a pe àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ wọ̀nyí tí òun ti fi owó fún wá sọ́dọ̀ rẹ̀, nítorí kí ó le mọ iye èrè tí olúkúlùkù ti jẹ nínú iṣẹ́ òwò wọn.
16 Bigoreó pues o brotobo y penó: Erañó; tiri estongri ha ganisarado deque estongrias.
“Èyí èkínní sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, owó mina rẹ jèrè owó mina mẹ́wàá sí i.’
17 Y le penó: Sinela mistos, lacho lacró. Presas andré a fremita has sinado cabalico, terelarás ezor opré deque fores.
“Olúwa rẹ̀ sì wí fún un pé, ‘O ṣeun, ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ rere! Nítorí tí ìwọ ṣe olóòtítọ́ ní ohun kínkínní, gba àṣẹ lórí ìlú mẹ́wàá.’
18 Y abilló aver, y penó: Erañó: Tiri estongri ha ganisarado pansch estongrias.
“Èyí èkejì sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, owó mina rẹ jèrè owó mina márùn.’
19 Y penó á ocona: Tucue terelalo opré pansch fores.
“Olúwa rẹ sì wí fún un pẹ̀lú pé, ‘Ìwọ pẹ̀lú joyè ìlú márùn-ún!’
20 Y abilló o trincho, y penó: Erañó, acoi terelas tiri estongri, sos he terelado ujarada andré yeque diclo.
“Òmíràn sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, wò ó owó mina rẹ tí ń bẹ lọ́wọ́ mi ni mo dì sínú aṣọ pélébé kan;
21 Presas terelaba dal de tucue, sos sinelas manu recio de suncai; Ustilelas ma na chitaste, y chinelas ma na chibelaste.
nítorí mo bẹ̀rù rẹ, àti nítorí tí ìwọ ṣe òǹrorò ènìyàn, ìwọ a máa mú èyí tí ìwọ kò fi lélẹ̀, ìwọ a sì máa ká èyí tí ìwọ kò gbìn!’
22 Entonces ó le penó: Choro lacró, abrí tiro mui condenelo tucue: Chanelabas que menda sinaba manu recio de suncai, que ustilelo ma na chité, y chinelo ma na chibele.
“Olúwa rẹ sì wí fún un pé, ‘Ní ẹnu ara rẹ náà ni èmi ó ṣe ìdájọ́ rẹ, ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ búburú, ìwọ mọ̀ pé òǹrorò ènìyàn ni mí, pé, èmi a máa mú èyí tí èmi kò fi lélẹ̀ èmi a sì máa ká èyí tí èmi kò gbìn.
23 ¿Pues presas na diñaste minrio jayere al banco, somia que pur limbidiase lo ustilára sat ganancia?
Èéha sì ti ṣe tí ìwọ kò fi owó mi pamọ́ sí ilé ìfowópamọ́, pé nígbà tí mo bá dé, èmi ìbá ti béèrè rẹ̀ pẹ̀lú èlé?’
24 Y penó á junos sos sinaban oté: Nicabeladle a estongri, y diñadsela al lacró sos terela deque estongrias.
“Ó sì wí fún àwọn tí ó dúró létí ibẹ̀ pé, ‘Ẹ gba owó mina náà lọ́wọ́ rẹ̀, kí ẹ sì fi í fún ẹni tí ó ní owó mina mẹ́wàá.’
25 Y junos le penáron: Eraño, que terela deque estongrias.
“Wọ́n sì wí fún un pé, ‘Olúwa, ó ní owó mina mẹ́wàá.’
26 Pues menda sangue penelo, que á saro ocola sos terelará, se le diñará, y terelará butér: tami al sos na terela, se le nicobará aun ma terele.
“Mo wí fún yín pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó ní, ni a ó fi fún, àti lọ́dọ̀ ẹni tí kò ní èyí tí ó ní pàápàá a ó gbà á lọ́wọ́ rẹ̀.
27 Y en quanto á ocolas minres daschmanuces, sos na cameláron que menda reynase opré junos, laneladmelos acoi, y mareladlos anglal de mangue.
Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá mi wọ̀nyí, tí kò fẹ́ kí èmi jẹ ọba lórí wọn ẹ mú wọn wá ìhín yìí, kí ẹ sì pa wọ́n níwájú mi!’”
28 Y penado ocono guillaba anglal costunando á Jerusalém.
Nígbà tí ó sì ti wí nǹkan wọ̀nyí tan, ó lọ síwájú, ó ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
29 Y anacó, que pur bigoreó sunparal de Bethphage, y de Bethania, al bur, sos se araquerela e Urucal, bichabó dui es desqueres discipules,
Ó sì ṣe, nígbà tí ó súnmọ́ Betfage àti Betani ní òkè tí a ń pè ní òkè olifi, ó rán àwọn méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
30 Penando: Chalad á ocona gau, sos sinela de mamui: y yescotria que chalareis andré, alachareis ternoro de gel pandado, y opré coin nunca se besteló cayque: despandadlo, y laneladlo.
Wí pé, “Ẹ lọ sí ìletò tí ó kọjú sí yín; nígbà tí ẹ̀yin bá wọ̀ ọ́ lọ, ẹ̀yin ó rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan tí a so, tí ẹnikẹ́ni kò gùn rí, ẹ tú u, kí ẹ sì fà á wá.
31 Y si manu puchabelare sangue: ¿Por qué lo despandais? A ó rudelareis andiar: Porque o Erañó terela menester de ó.
Bí ẹnikẹ́ni bá sì bi yín pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń tú u?’ Kí ẹ̀yin wí báyìí pé, ‘Olúwa ń fẹ́ lò ó.’”
32 Chaláron pues junos sos habian sinado bichabados, y alacháron o ternoro, sos sinaba sasta les habia penado.
Àwọn tí a rán sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n, wọ́n sì bá a gẹ́gẹ́ bí ó ti wí fún wọn.
33 Y pur despandaban al ternoro, les penáron os julais: ¿Por qué despandais al ternoro?
Bí wọ́n sì ti ń tú ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà, àwọn Olúwa rẹ̀ bi wọ́n pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń tu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà?”
34 Y junos rudeláron: Porque o Erañó terela menester de ó.
Wọ́n sì wí pé, “Olúwa fẹ́ lò ó.”
35 Y lo laneláron á Jesus. Y chibando opré o ternoro desqueres talalores: chitáron á Jesus opré.
Wọ́n sì fà á tọ Jesu wá, wọ́n sì tẹ́ aṣọ sí ẹ̀yìn ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà, wọ́n sì gbé Jesu kà á.
36 Y chalando ó andiar, bucharáron desqueres coneles andré a feda.
Bí ó sì ti ń lọ wọ́n tẹ́ aṣọ wọn sí ọ̀nà.
37 Y pur bigoreó sunparal al luchipen e bur e Urucal, sares os discipules en plastañias, perelales de pesquital se chibáron á majarificar á Un-debél á goles bares pre sarias as buchias, sos habian dicado,
Bí ó sì ti súnmọ́ etí ibẹ̀ ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè olifi, gbogbo àwọn ọmọ-ẹ̀yìn bẹ̀rẹ̀ sí í yọ̀, wọ́n sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run, nítorí iṣẹ́ ńlá gbogbo tí wọ́n ti rí,
38 Penando: Majarificado o Crallis, sos abillela andré o nao e Erañoró, paz andré o Charos, y chimusolano andré o Tarpe.
wí pé, “Olùbùkún ni ọba tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa!” “Àlàáfíà ní ọ̀run, àti ògo ni òkè ọ̀run!”
39 Y yeques es Phariseyes sos sinaban enré á sueti, le penáron: Duquendio, reprehende á tires discipules.
Àwọn kan nínú àwọn Farisi nínú àwùjọ náà sì wí fún un pé, “Olùkọ́ bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ wí.”
40 O les rudeló: Sangue penelo, que si oconas mequelaren, as baras diñarán goles.
Ó sì dá wọn lóhùn, ó wí fún wọn pé, “Mo wí fún yín, bí àwọn wọ̀nyí bá pa ẹnu wọn mọ́, àwọn òkúta yóò kígbe sókè.”
41 Y pur bigoreó sunparal, al dicar o Foros, orobó opré ó, penando:
Nígbà tí ó sì súnmọ́ etílé, ó síjú wo ìlú náà, ó sọkún sí i lórí,
42 ¡Ysna! si pincharases buchi andré ocona tun chibes, ma astisarela lanelartucue a paz! Tami acana sinela ucharado de tirias aquias.
Ó ń wí pé, “Ìbá ṣe pé ìwọ mọ̀, lónìí yìí, àní ìwọ, ohun tí í ṣe tí àlàáfíà rẹ! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n pamọ́ kúrò lójú rẹ.
43 Presas abillarán chibeses contra tucue, pur tires daschmanuces te chibarán al crugos trincheras, y te chibarán cerco, y te pandarán pre sarias aricatas.
Nítorí ọjọ́ ń bọ̀ fún ọ, tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò mọ odi bèbè yí ọ ká, àní tí wọn yóò sì yí ọ ká, wọn ó sì ká ọ mọ́ níhà gbogbo.
44 Y chibarán tucue ostely, y á tires chabores, sos sinelan andré tucue, y na mequelarán andré tucue bar opré bar; presas na pincharaste o chiros de tiri visitacion.
Wọn ó sì wó ọ palẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú rẹ; wọn kì yóò sì fi òkúta kan sílẹ̀ lórí ara wọn; nítorí ìwọ kò mọ ọjọ́ ìbẹ̀wò rẹ.”
45 Y chalando andré a cangri se chitó á bucharar abrí á sares junos sos quinaban y binaban andré siró,
Ó sì wọ inú tẹmpili lọ, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí lé àwọn tí ń tà nínú rẹ̀ sóde;
46 Penandoles: Libanado sinela: Minrio quer, quer de beda sinela. Tami sangue lo terelais querdi tunia de randes.
Ó sì wí fún wọn pé, “A ti kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ilé mi yóò jẹ́ ilé àdúrà?’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti sọ ọ́ di ihò àwọn ọlọ́ṣà.”
47 Y cata chibes bedaba andré a cangri. Tami os Manclayes es erajais, y os Libanes, y os tintines e sueti le camelaban marar.
Ó sì ń kọ́ni lójoojúmọ́ ní tẹmpili, ṣùgbọ́n àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, àti àwọn olórí àwọn ènìyàn ń wá ọ̀nà láti pa á.
48 Y na chanelaban que querelarse sat ó. Presas sari a sueti sinaba moscabis pur le junelaba.
Wọn kò sì rí nǹkan kan tí wọn ìbá ṣe; nítorí gbogbo ènìyàn ṣù mọ́ ọn láti gbọ́rọ̀ rẹ̀.

< Lucas 19 >